< 2 Kings 10 >

1 Nísinsin yìí, Ahabu ṣì ní àádọ́rin ọmọkùnrin ní ìdílé rẹ̀ ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni, Jehu kọ lẹ́tà, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Samaria: sí àwọn oníṣẹ́ Jesreeli, sí àwọn àgbàgbà àti sí àwọn olùtọ́jú àwọn ọmọ Ahabu. Ó wí pé,
Ahab loe Samaria ah capa quisarihto tawnh; Jehu mah ca tarik moe, Jezreel vangpui ukkung, kacoehtanawk, Ahab ih caanawk khenzawn kaminawk ohhaih Samaria vangpui ah pat pae,
2 “Ní kété tí lẹ́tà bá ti dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọmọ ọ̀gá rẹ wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ sì ní àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹṣin, ìlú olódi kan pẹ̀lú ohun ìjà,
tarik ih ca thungah, Nangcae loe nangmacae angraeng ih caanawk, hrang lakoknawk, hrang angthueng kaminawk, sipae thungh ih kacak vangpui, maiphaw maica hoi kakoep ah na oh o pongah, hae ca nangcae khae phak pacoengah,
3 yan èyí tí ó dára àti èyí tí ó níye jùlọ nínú àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ, kí o sì gbé e lé orí ìtẹ́ baba a rẹ̀. Nígbà náà, kí o sì jà fún ilé ọ̀gá à rẹ.”
nangmacae angraeng thungah kahoih koek capanawk to qoi oh loe, anih to ampa ih angraeng tangkhang nuiah anghnu o sak ah; na angraeng ih imthung takoh hanah misatuh oh, tiah tarik.
4 Ṣùgbọ́n ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì wí pé, “Tí ọba méjì kò bá le kojú ìjà sí i, báwo ni a ṣẹ le è ṣe é?”
Toe nihcae loe paroeai zit o moe, khenah, siangpahrang Joram hoi Ahaziah loe anih hmaa ah angdoe hoi thai ai; aicae taoe cae loe kawbangmaw angdoe thai tih?
5 Bẹ́ẹ̀ ẹni tí ń ṣe olórí ilé, ẹni tí ń ṣe olórí ìlú ńlá, àwọn àgbàgbà àti àwọn olùtọ́jú náà rán iṣẹ́ yìí sí Jehu, pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni àwa jẹ́ pẹ̀lú, àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá sọ. Àwa kì yóò yan ẹnikẹ́ni gẹ́gẹ́ bí ọba; ìwọ ṣe ohunkóhun tí o rò pé ó dára jù lójú rẹ.”
To pongah siangpahrang im ukkung, vangpui ukkung, kacoehtanawk hoi nawktanawk khenzawn kaminawk mah Jehu khaeah, Kaicae loe na tamna ah ka oh o boeh pongah, na thuih ih hmuen to ka sak o boih han; mi doeh siangpahrang ah ka suem o mak ai; na mikhnukah hoih, tiah na poek ih baktih toengah sah ah, tiah a naa o.
6 Nígbà náà ni Jehu kọ lẹ́tà kejì sí wọn, wí pé, “Tí ìwọ bá wà ní ìhà tèmi, tí o sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, mú orí àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ wá sí ọ̀dọ̀ mi ní Jesreeli ní ìwòyí ọ̀la.” Nísinsin yìí, àwọn ọmọ-aládé àádọ́rin ọkùnrin, ń bẹ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ńlá ìlú náà tí ń tọ́ wọn.
To pacoengah Jehu mah nihcae khaeah, vai hnetto haih ca tarik pae let; nangcae loe kai ih kami ah na oh o moe, kai ih lok tahngai han, tiah na thuih o nahaeloe, na angraeng capanawk ih lu to Jezreel ah khawnbang hae atue ah, kai khaeah na sin oh, tiah a naa. Siangpahrang capa, kami quisarihtonawk loe vangpui zaehoikungnawk hoi nawnto oh o, nihcae mah khetzawn o.
7 Nígbà tí ìwé náà dé ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí mú gbogbo àwọn ọmọ ọba tí gbogbo wọ́n jẹ́ àádọ́rin wọ́n sì pa gbogbo wọn. Wọ́n gbé orí wọn sí inú apẹ̀rẹ̀, wọ́n fi ránṣẹ́ sí Jehu ní Jesreeli.
Nihcae khaeah ca phak naah loe, to kaminawk mah siangpahrang capa, kami quisarihtonawk to hum o boih; nihcae ih lu to pahang pongah pacaengh o moe, Jehu khaeah Jezreel ah pat pae o.
8 Nígbà tí ìránṣẹ́ náà dé, ó sọ fún Jehu, “Wọ́n ti gbé orí àwọn ọmọ ọba náà wá.” Nígbà náà Jehu pàṣẹ, “Ẹ tò wọ́n ní òkìtì méjì ní àtiwọ ẹnu ibodè ìlú ńlá títí di òwúrọ̀.”
Laicaeh maeto phak naah, Jehu khaeah, Siangpahrang capanawk ih lu to ang sin o boeh, tiah thuih pae o. Anih mah, Hnetto ah tapraek oh loe, vangpui khongkha akunhaih ahmuen ah akhawnbang khoek to suem oh, tiah a naa.
9 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Jehu jáde lọ. Ó dúró níwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin jẹ́ aláìjẹ̀bi. Èmi ni mo dìtẹ̀ sí ọ̀gá mi, tí mo sì pa á, ṣùgbọ́n ta ni ó pa gbogbo àwọn wọ̀nyí?
Jehu loe akhawnbang khawnthaw ah caeh moe, kaminawk boih hmaa ah angdoet pacoengah, Nangcae loe zaehaih na tawn o ai; khenah, kaimah ni ka angraeng hae misa ah ka suek moe, anih to ka hum; toe mi mah maw hae kaminawk hae hum boih?
10 Nígbà yìí, kò sí ọ̀rọ̀ kan tí Olúwa ti sọ sí ilé Ahabu tí yóò kùnà. Olúwa ti ṣe ohun tí ó ṣèlérí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah.”
Angraeng mah thuih ih Ahab imthung takoh kawng loe maeto doeh anghmaa ai, tiah vaihi panoek oh; Angraeng loe a tamna Elijah khaeah thuih ih lok to sak boeh, tiah a naa.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa gbogbo ẹni tí ó kù Jesreeli ní ilé Ahabu, pẹ̀lúpẹ̀lú gbogbo àwọn ọkùnrin ìjòyè rẹ̀, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ àti àwọn àlùfáà rẹ̀, láì ku ẹni tí ó yọ nínú ewu fún un.
To pongah Jehu mah Jezreel ah kaom Ahab ih imthung takoh boih, anih ih angraengnawk boih, anih ih nawkamyanawk boih, anih ih qaimanawk to maeto doeh tahmat ai ah hum bit.
12 Jehu jáde lọ, ó sì lọ sí ọ̀kánkán Samaria. Ní Beti-Ekedi tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn.
Jehu loe angthawk moe, Samaria vangpui ah caeh; loklam taeng ih tuumui aahhaih im phak naah,
13 Jehu pàdé díẹ̀ lára àwọn ìbátan Ahasiah ọba Juda, ó sì béèrè, “Ta ni ẹ̀yin ń ṣe?” Wọ́n wí pé, “Àwa jẹ́ ìbátan Ahasiah, àwa sì ti wá láti kí ìdílé ọba àti ti màmá ayaba.”
Jehu mah Judah siangpahrang Ahaziah ih nawkamyanawk to hnuk naah, Nangcae loe mi aa? tiah a naa. Nihcae mah, Kaicae loe Ahaziah ih nawkamya ah ka oh o; siangpahrang ih caanawk hoi siangpahrang zu ih caanawk khet hanah kang zoh o tathuk, tiah a naa o.
14 “Mú wọn láààyè!” ó pàṣẹ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú wọn láààyè, wọ́n sì pa wọ́n ní ẹ̀bá kọ̀nga Beti-Ekedi, ọkùnrin méjìlélógójì. Kò sì fi ẹnìkan sílẹ̀ láìkù.
Anih mah, Nihcae to kahing ah caeh o haih ah, tiah a naa. To pongah nihcae to kahing ah a hoih o moe, tuumui aahhaih im ah hum o; kami quipali, hnetto oh o; maeto doeh pathlung o ai.
15 Nígbà tí a sì jáde níbẹ̀, ó rí Jehonadabu ọmọ Rekabu ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, ó sì súre fún un, ó sì wí fún pé, “Ọkàn rẹ ha ṣe déédé bí ọkàn mi ti rí sí ọkàn rẹ?” Jehonadabu dáhùn wí pé, “Èmi wà.” Jehu wí pé, “Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, fún mi ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe pẹ̀lú, Jehu sì fà á lọ́wọ́ sókè sọ́dọ̀ rẹ̀ nínú kẹ̀kẹ́.
To ahmuen to tacawt taak pacoengah, anih hnuk hanah angzo, Rekap capa Jehonadab to anih mah hnuk; Jehu mah anih to ban sin pacoengah, Ka poekhaih palungthin nang khaeah oh baktih toengah, na poekhaih palungthin loe toeng hmang maw? tiah a naa. Jehonadab mah, Toeng hmang, tiah a naa. Jehu mah, To tiah toeng nahaeloe, na ban to na paek ah, tiah a naa. Anih mah a ban to paek naah, Jehu mah a ohhaih hrang lakok nuiah anih to zaeh tahang.
16 Jehu wí pé, “Wá pẹ̀lú mi, kí o sì rí ìtara mi fún Olúwa.” Nígbà náà ó jẹ́ kí ó gun kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
Jehu mah, Kai khaeah angzoh loe, Angraeng ah tha ka pathokhaih to khen ah, tiah a naa. To pongah anih to hrang lakok hoiah caeh haih poe.
17 Nígbà tí Jehu wá sí Samaria, ó pa gbogbo àwọn tí a fi kalẹ̀ ní ìdílé Ahabu; ó pa wọ́n run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ sí Elijah.
Jehu mah Samaria vangpui phak naah, Angraeng mah Elijah khaeah thuih ih lok baktih toengah, kanghmat Ahab imthung takoh hum boih ai karoek to maeto doeh anghmat ai ah hum.
18 Nígbà náà, Jehu kó gbogbo àwọn ènìyàn jọ, ó sì wí fún wọn pé, “Ahabu sin Baali díẹ̀; ṣùgbọ́n Jehu yóò sìn ín púpọ̀.
Jehu mah kaminawk boih nawnto pakueng pacoengah, nihcae khaeah, Ahab loe Baal ih tok zetta ni sak; Jehu loe anih pong pop aep ah sah tih.
19 Nísinsin yìí, ẹ pe gbogbo àwọn wòlíì Baali jọ fún mi, gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti gbogbo àlùfáà rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan kí ó kù, nítorí èmí yóò rú ẹbọ ńlá sí Baali. Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti wá, kò ní wà láààyè mọ́.” Ṣùgbọ́n Jehu fi ẹ̀tàn ṣe é, kí ó lè pa àwọn òjíṣẹ́ Baali run.
To pongah vaihiah, Baal tahmaanawk boih, anih ih toksah tamnanawk boih, anih ih qaimanawk to kawk o boih ah; Baal han kalen parai angbawnhaih sak ka koeh pongah, mi doeh tahmat o hmah; mi kawbaktih doeh angzo ai kami loe, hing mak ai, tiah a naa. Jehu mah Baal bok kaminawk hum han koeh pongah, nihcae to athlaeng.
20 Jehu wí pé, “ẹ pe àpéjọ ní ìwòyí ọ̀la fún Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kéde rẹ.
Jehu mah, Baal kawng thuih hanah amkhueng oh, tiah a naa. Kaminawk loe Baal kawng thuih hanah amkhueng o.
21 Nígbà náà, Jehu rán ọ̀rọ̀ káàkiri Israẹli, gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali sì wá: kò sí ẹnìkan tí ó dúró lẹ́yìn. Wọ́n kún ilé tí a kọ́ fún òrìṣà títí tí ó fi kún láti ìkangun èkínní títí dé èkejì.
Israel prae boih ah lok pat o; to tiah Baal toksah kaminawk loe, maeto doeh anghmat ai ah angzoh o. Baal tempul thungah angzoh o, Baal tempul loe hae bang hoi ho bang khoek to koi o khik.
22 Jehu sì sọ fún olùṣọ́ pé, “Kí ó mú aṣọ ìgúnwà wá fún gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni ó mú aṣọ ìgúnwà jáde wá fún wọn.
Jehu mah khukbuen toep kami to kawk moe, Baal toksah kaminawk boih hanah khukbuen sinh pae hanah a thuih pae. To pongah anih mah nihcae hanah khukbuen to sinh pae.
23 Nígbà náà, Jehu àti Jehonadabu ọmọ Rekabu lọ sí inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali. Jehu sì wí fún àwọn òjíṣẹ́ Baali pé, “Wò ó yíká, kí o sì rí i pé kò sí ìránṣẹ́ Olúwa kankan pẹ̀lú yín níbí—kìkì òjíṣẹ́ Baali.”
Jehu loe Rakab capa Jehonadab hoi nawnto Baal tempul thungah akun hoi, Jehu mah, Baal bok kaminawk khaeah, Khenah, nangcae salakah Angraeng ih tamna maeto doeh om hmah nasoe, Baal bok kaminawk khue omsak ah, tiah a thuih pae.
24 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọ inú ilé lọ láti lọ rú ẹbọ àti ẹbọ sísun. Nísinsin yìí Jehu ti rán ọgọ́rin ọkùnrin sí ìta pẹ̀lú ìkìlọ̀ yìí: “Tí ẹnikẹ́ni nínú yín bá jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọkùnrin tí mo ń gbé sí ọwọ́ yín ó sálọ, yóò jẹ́ ẹ̀mí yín fún ẹ̀mí rẹ.”
Angbawnhaih sak moe, hmai angbawnhaih sak hanah athung ah akun o naah, Jehu mah tasa bangah kami quitazetto kawk moe, Mi kawbaktih doeh nangcae ban ah ka suek ih, hae kaminawk loisak kami loe, a hinghaih boeng tih, tiah a naa.
25 Ní kété tí Jehu ti parí ṣíṣe ẹbọ sísun, ó pàṣẹ fún àwọn olùṣọ́ àti àwọn ìjòyè: “Wọlé lọ, kí o sì pa wọ́n, má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kí ó sálọ.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà. Àwọn olùṣọ́ àti ìjòyè ju ara wọn síta, wọ́n sì wọ inú ojúbọ ti ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali.
Hmai angbawnhaih sak pacoengah, Jehu mah katoep kami hoi misatuh angraengnawk khaeah, Athung ah caeh oh loe, hum oh, mi doeh loih o sak hmah, tiah a naa. To pongah nihcae mah sumsen hoiah takroek o; katoep kami hoi misatuh angraengnawk mah kami qok to tasa bangah vah o moe, Baal im ohhaih vangpui bangah caeh o.
26 Wọ́n gbé òkúta bíbọ náà jáde láti inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali, wọ́n sì jó o.
Baal tempul thung ih krangnawk to lak o moe, hmai hoiah qoeng o.
27 Wọ́n fọ́ òkúta bíbọ ti Baali náà túútúú, wọ́n sì ya ilé òrìṣà Baali bolẹ̀. Àwọn ènìyàn sì ń lò ó fún ilé ìgbẹ́ títí di ọjọ́ òní.
Baal ih krangnawk to pakhoih o moe, Baal ih tempul doeh a phraek o; to ahmuen to vaihni ni khoek to tamzun thakhhaih hoi aek thakhaih ahmuen ah patoh o.
28 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa sí sin Baali run ní Israẹli.
To tiah Jehu mah Israel prae thungah Baal bokhaih to phraek.
29 Bí ó ti wù kí ó rí, Jehu kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá—ti sí sin ẹgbọrọ màlúù wúrà ní Beteli àti Dani.
Toe Jehu loe Israel caanawk zaesakkung Nebat capa Jeroboam zaehaih, Bethel hoi Dan vangpui ah kaom sui hoi sak ih, maitaw caanawk bokhaih to caehtaak ai.
30 Olúwa sì sọ fún Jehu pé, “Nítorí ìwọ ti ṣe dáradára ní ṣíṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú mi, tí o sì ti ṣe sí ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn mi, àwọn ọmọ ọ̀ rẹ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
Angraeng mah Jehu khaeah, Ka mikhnukah kaciim hmuen to na sak moe, Ahab imthung takoh ah sak han ka poek ih hmuen to na sak pongah, na caanawk adung pali khoek to Israel angraeng tangkhang nuiah nang hnu o tih, tiah a naa.
31 Síbẹ̀ Jehu kò ṣe pẹ̀lẹ́ láti pa òfin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli mọ́ pẹ̀lú tọkàntọkàn. Òun kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu èyí tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá.
Toe Jehu loe Israel Angraeng Sithaw ih daannawk to palungthin boih hoi pazui hanah poek ai; Israel caanawk zaesak Jeroboam zaehaih to caehtaak ai.
32 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Olúwa ti bẹ̀rẹ̀ sí ní dín iye Israẹli kù. Hasaeli fi agbára jẹ ọba lórí àwọn ọmọ Israẹli ní gbogbo agbègbè wọn.
To nathuem ah Angraeng mah Israel prae to tamcaeksak kue; to pongah Hazael mah Israel prae to pazawk boih;
33 Ìlà-oòrùn ti Jordani ni gbogbo ilẹ̀ ti Gileadi (ẹ̀kún ilẹ̀ ti ará Gadi, Reubeni, àti Manase) láti Aroeri, tí ó wà létí kòtò Arnoni láti ìhà Gileadi sí Baṣani.
Jordan prae ni angyae bang, Gilead prae thung boih, Gad, Reuben hoi Manasseh prae boih, Arnon vapui taeng ih Aroer vangpui hoi Gilead prae, Bashan prae khoek to pazawk.
34 Fún ti òmíràn ti iṣẹ́ ìjọba Jehu, gbogbo ohun tí ó ṣe, gbogbo àṣeyọrí rẹ̀, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
Jehu siangpahrang ah oh nathung kaom hmuennawk hoi a sak ih hmuennawk boih loe, Israel siangpahrangnawk ahmin pakuemhaih cabu thungah tarik o na ai maw?
35 Jehu sinmi pẹ̀lú baba a rẹ̀, a sì sin ín sí Samaria Jehoahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Jehu loe ampanawk khaeah anghak moe, Samaria vangpui ah aphum o. Anih zuengah a capa Jehoahaz to siangpahrang ah oh.
36 Àkókò tí Jehu fi jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria jẹ́ ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n.
Jehu loe Israel kaminawk nuiah Samaria ah saning pumphae tazetto thung siangpahrang ah oh.

< 2 Kings 10 >