< 2 Kings 10 >

1 Nísinsin yìí, Ahabu ṣì ní àádọ́rin ọmọkùnrin ní ìdílé rẹ̀ ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni, Jehu kọ lẹ́tà, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Samaria: sí àwọn oníṣẹ́ Jesreeli, sí àwọn àgbàgbà àti sí àwọn olùtọ́jú àwọn ọmọ Ahabu. Ó wí pé,
А Ахаав имаше седемдесет сина в Самария. И Ииуй написа писма та прати в Самария до езраелските началници, до старейшините и до възпитателите на Ахаавовите деца, в които рече:
2 “Ní kété tí lẹ́tà bá ti dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọmọ ọ̀gá rẹ wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ sì ní àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹṣin, ìlú olódi kan pẹ̀lú ohun ìjà,
Щом пристигне до вас това писмо, понеже синовете на господаря ви са при вас, и имате колесници и коне, укрепен град и оръжия,
3 yan èyí tí ó dára àti èyí tí ó níye jùlọ nínú àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ, kí o sì gbé e lé orí ìtẹ́ baba a rẹ̀. Nígbà náà, kí o sì jà fún ilé ọ̀gá à rẹ.”
то вижте кой е най-добър и на-способен от синовете на господаря ви та го поставете на бащиния му престол, и бийте се за дома на господаря си.
4 Ṣùgbọ́n ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì wí pé, “Tí ọba méjì kò bá le kojú ìjà sí i, báwo ni a ṣẹ le è ṣe é?”
Но те твърде много се уплашиха, и рекоха: Ето, двамата царе не устояха пред него; и как ще устоим ние?
5 Bẹ́ẹ̀ ẹni tí ń ṣe olórí ilé, ẹni tí ń ṣe olórí ìlú ńlá, àwọn àgbàgbà àti àwọn olùtọ́jú náà rán iṣẹ́ yìí sí Jehu, pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni àwa jẹ́ pẹ̀lú, àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá sọ. Àwa kì yóò yan ẹnikẹ́ni gẹ́gẹ́ bí ọba; ìwọ ṣe ohunkóhun tí o rò pé ó dára jù lójú rẹ.”
И така, домоуправителят, градоначалникът, старейшините и възпитателите на децата пратиха до Ииуя да рекат: Ние сме твои слуги, и ще сторим всичко, каквото ни кажеш; няма да направим никого цар; стори каквото ти се вижда угодно.
6 Nígbà náà ni Jehu kọ lẹ́tà kejì sí wọn, wí pé, “Tí ìwọ bá wà ní ìhà tèmi, tí o sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, mú orí àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ wá sí ọ̀dọ̀ mi ní Jesreeli ní ìwòyí ọ̀la.” Nísinsin yìí, àwọn ọmọ-aládé àádọ́rin ọkùnrin, ń bẹ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ńlá ìlú náà tí ń tọ́ wọn.
Тогава им писа второ писмо, в което рече: Ако сте откъм мене, и ако послушате моя глас, отнемете главите на тия човеци, синовете на господаря ви, и утре по това време, дойдете при мене в Езраел. (А царските синове, седемдесетте човека, бяха при градските голезци, които ги възпитаваха).
7 Nígbà tí ìwé náà dé ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí mú gbogbo àwọn ọmọ ọba tí gbogbo wọ́n jẹ́ àádọ́rin wọ́n sì pa gbogbo wọn. Wọ́n gbé orí wọn sí inú apẹ̀rẹ̀, wọ́n fi ránṣẹ́ sí Jehu ní Jesreeli.
И като стигна писмото до тях, хванаха царските синове, седемдесетте човека, та го изклаха, и туриха главите им в кошници та му ги пратиха в Езраел.
8 Nígbà tí ìránṣẹ́ náà dé, ó sọ fún Jehu, “Wọ́n ti gbé orí àwọn ọmọ ọba náà wá.” Nígbà náà Jehu pàṣẹ, “Ẹ tò wọ́n ní òkìtì méjì ní àtiwọ ẹnu ibodè ìlú ńlá títí di òwúrọ̀.”
И един пратеник дойде та му извести, казвайки: Донесоха главите на царските синове. А той рече: Турете ги на два купа във входа на портата да стоят до утре.
9 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Jehu jáde lọ. Ó dúró níwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin jẹ́ aláìjẹ̀bi. Èmi ni mo dìtẹ̀ sí ọ̀gá mi, tí mo sì pa á, ṣùgbọ́n ta ni ó pa gbogbo àwọn wọ̀nyí?
И на сутрента излезе та застана и рече на всичките люде: Вие сте праведни; ето, аз направих заговор против господря си и го убих; но кой изби всички тези?
10 Nígbà yìí, kò sí ọ̀rọ̀ kan tí Olúwa ti sọ sí ilé Ahabu tí yóò kùnà. Olúwa ti ṣe ohun tí ó ṣèlérí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah.”
Знайте сега, че няма да падне на земята нищо от Господното слово, което Господ говори против Ахаавовия дом; защото Господ извести онова, което говори чрез слугата Си Илия.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa gbogbo ẹni tí ó kù Jesreeli ní ilé Ahabu, pẹ̀lúpẹ̀lú gbogbo àwọn ọkùnrin ìjòyè rẹ̀, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ àti àwọn àlùfáà rẹ̀, láì ku ẹni tí ó yọ nínú ewu fún un.
И тъй, Ииуй порази всичкоте останали от Ахаавовия дом в Езраел, и всичките му големци, близките му приятели и свещениците му, докле не му остави остатък.
12 Jehu jáde lọ, ó sì lọ sí ọ̀kánkán Samaria. Ní Beti-Ekedi tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn.
Сетне стана та тръгна и дойде в Самария. И по пътя, като бягаше близо при овчарската стригачница,
13 Jehu pàdé díẹ̀ lára àwọn ìbátan Ahasiah ọba Juda, ó sì béèrè, “Ta ni ẹ̀yin ń ṣe?” Wọ́n wí pé, “Àwa jẹ́ ìbátan Ahasiah, àwa sì ti wá láti kí ìdílé ọba àti ti màmá ayaba.”
Ииуй срещна братята на Юдовия цар Охозия, и попита: Кои сте вие? А те отговориха: Ние сме братя на Охозия, и слизаме да поздравим чадата на царя и чадата на царицата.
14 “Mú wọn láààyè!” ó pàṣẹ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú wọn láààyè, wọ́n sì pa wọ́n ní ẹ̀bá kọ̀nga Beti-Ekedi, ọkùnrin méjìlélógójì. Kò sì fi ẹnìkan sílẹ̀ láìkù.
И рече: Хванете ги живи. И хванаха ги живи та ги изклаха при рова на стригачницата, четиридесет и двама човека; не остави ни един от тях.
15 Nígbà tí a sì jáde níbẹ̀, ó rí Jehonadabu ọmọ Rekabu ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, ó sì súre fún un, ó sì wí fún pé, “Ọkàn rẹ ha ṣe déédé bí ọkàn mi ti rí sí ọkàn rẹ?” Jehonadabu dáhùn wí pé, “Èmi wà.” Jehu wí pé, “Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, fún mi ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe pẹ̀lú, Jehu sì fà á lọ́wọ́ sókè sọ́dọ̀ rẹ̀ nínú kẹ̀kẹ́.
И като тръгна от там събра се с Ионадава Рихавовия сен, който идеше да ги посрещне; Ииуй го поздрави и му рече: Право ли е твоито сърце към мене, както е моето сърце към твоето? И Ионадав отговори: Право е. Ако е тъй, каза Ииуй, дай ръката си. И Ииуй го качи при себе си на колесницата, и рече:
16 Jehu wí pé, “Wá pẹ̀lú mi, kí o sì rí ìtara mi fún Olúwa.” Nígbà náà ó jẹ́ kí ó gun kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
Дойди с мене та виж ревността ми за Господа. Така го качиха в колесницата му.
17 Nígbà tí Jehu wá sí Samaria, ó pa gbogbo àwọn tí a fi kalẹ̀ ní ìdílé Ahabu; ó pa wọ́n run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ sí Elijah.
И когато стигна в Самария, поразяваше всичките останали от Ахаава в Самария догде го изтреби, според словото, което Господ говори на Илия.
18 Nígbà náà, Jehu kó gbogbo àwọn ènìyàn jọ, ó sì wí fún wọn pé, “Ahabu sin Baali díẹ̀; ṣùgbọ́n Jehu yóò sìn ín púpọ̀.
Тогава Ииуй събра всичките люде та им рече: Ахаав е малко служил на Ваала; Ииуй ще му служи много.
19 Nísinsin yìí, ẹ pe gbogbo àwọn wòlíì Baali jọ fún mi, gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti gbogbo àlùfáà rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan kí ó kù, nítorí èmí yóò rú ẹbọ ńlá sí Baali. Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti wá, kò ní wà láààyè mọ́.” Ṣùgbọ́n Jehu fi ẹ̀tàn ṣe é, kí ó lè pa àwọn òjíṣẹ́ Baali run.
Сега, прочее, повикайте ми всичките пророци на Ваала, всичкоте му служители и всичките му жреци; никой де не отсъствува, защото имам да принеса голяма жертва на Ваала; никой, който отсъствува, нама да остане жив. Но Ииуй направи това с хитрост, с намарение да изтреби Вааловите служители.
20 Jehu wí pé, “ẹ pe àpéjọ ní ìwòyí ọ̀la fún Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kéde rẹ.
И тъй, Ииуй рече: Прогласете тържествено събрание за Ваала. И те прогласиха.
21 Nígbà náà, Jehu rán ọ̀rọ̀ káàkiri Israẹli, gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali sì wá: kò sí ẹnìkan tí ó dúró lẹ́yìn. Wọ́n kún ilé tí a kọ́ fún òrìṣà títí tí ó fi kún láti ìkangun èkínní títí dé èkejì.
И Ииуй прати на целия Израил, та дойдоха всичките Ваалови служители, така че не остана никой, който да не дойде. Дойдоха в капището на Ваала; и Вааловото капище се напълни от край до край.
22 Jehu sì sọ fún olùṣọ́ pé, “Kí ó mú aṣọ ìgúnwà wá fún gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni ó mú aṣọ ìgúnwà jáde wá fún wọn.
И каза на одеждопазителя: Извади одежди за всичките Ваалови служители. И той им извади одежди.
23 Nígbà náà, Jehu àti Jehonadabu ọmọ Rekabu lọ sí inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali. Jehu sì wí fún àwọn òjíṣẹ́ Baali pé, “Wò ó yíká, kí o sì rí i pé kò sí ìránṣẹ́ Olúwa kankan pẹ̀lú yín níbí—kìkì òjíṣẹ́ Baali.”
Тогава Ииуй и Ионадав, Рихавовият син, влязоха във Вааловото капище; и рече на Вааловите служители: Прегледайте и внимавайте да няма някой между вас някой от слегите на Иеова, но да мъдат само служители на Ваала.
24 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọ inú ilé lọ láti lọ rú ẹbọ àti ẹbọ sísun. Nísinsin yìí Jehu ti rán ọgọ́rin ọkùnrin sí ìta pẹ̀lú ìkìlọ̀ yìí: “Tí ẹnikẹ́ni nínú yín bá jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọkùnrin tí mo ń gbé sí ọwọ́ yín ó sálọ, yóò jẹ́ ẹ̀mí yín fún ẹ̀mí rẹ.”
И когато влязоха да принесат жертви и всеизгаряния, Ииуй нареди отдън осемдесет мъже, на които рече: Който остава да избяга някой от тия човеци, които доведох в ръцете ви, животът му ще се вземе вместо неговия живот.
25 Ní kété tí Jehu ti parí ṣíṣe ẹbọ sísun, ó pàṣẹ fún àwọn olùṣọ́ àti àwọn ìjòyè: “Wọlé lọ, kí o sì pa wọ́n, má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kí ó sálọ.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà. Àwọn olùṣọ́ àti ìjòyè ju ara wọn síta, wọ́n sì wọ inú ojúbọ ti ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali.
И като свърши принасянето на всеизгарянето, Ииуй рече на телохранителите и на полководците: Влезте, избийте ги; никой да не избяга. И телохранителите и полководците ги избиха с острото на ножа и ги изхвърлиха вън. После, кото отидоха в града на Вааловото капище,
26 Wọ́n gbé òkúta bíbọ náà jáde láti inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali, wọ́n sì jó o.
извадиха кумирите на Вааловото капище та ги озгориха,
27 Wọ́n fọ́ òkúta bíbọ ti Baali náà túútúú, wọ́n sì ya ilé òrìṣà Baali bolẹ̀. Àwọn ènìyàn sì ń lò ó fún ilé ìgbẹ́ títí di ọjọ́ òní.
строшиха идола на Ваала, съсипаха Вааловото капище, и направиха го бунище, както е до днес.
28 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa sí sin Baali run ní Israẹli.
Така Ииуй изтреби Ваала от Израиля.
29 Bí ó ti wù kí ó rí, Jehu kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá—ti sí sin ẹgbọrọ màlúù wúrà ní Beteli àti Dani.
Но Ииуй не са естови от греховете на Еровоама, Наватовия син, който непреви Израиля да греши, то ест, от златните телета, които бяха във Ветил и в Дан.
30 Olúwa sì sọ fún Jehu pé, “Nítorí ìwọ ti ṣe dáradára ní ṣíṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú mi, tí o sì ti ṣe sí ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn mi, àwọn ọmọ ọ̀ rẹ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
Тогава Господ рече на Ииуя: Понеже ти добре стори, като извърши това, което е право пред очите Ми, и направи на Ахаавовия дом напълно според това, което бе в сърцето Ми, затова твоите синове до четвъртото поколение ще седят на Израилевия престол.
31 Síbẹ̀ Jehu kò ṣe pẹ̀lẹ́ láti pa òfin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli mọ́ pẹ̀lú tọkàntọkàn. Òun kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu èyí tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá.
Обаче, Ииуй не внимаваше да ходи с цялото си сърце в закона на Господа Израилевия Бог; не се остави от греховете на Еровоама, с които направи Израиля да греши.
32 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Olúwa ti bẹ̀rẹ̀ sí ní dín iye Israẹli kù. Hasaeli fi agbára jẹ ọba lórí àwọn ọmọ Israẹli ní gbogbo agbègbè wọn.
В това време Господ почна да кастри Израиля; защото Азаил ги порази във всичките Израилеви предели,
33 Ìlà-oòrùn ti Jordani ni gbogbo ilẹ̀ ti Gileadi (ẹ̀kún ilẹ̀ ti ará Gadi, Reubeni, àti Manase) láti Aroeri, tí ó wà létí kòtò Arnoni láti ìhà Gileadi sí Baṣani.
от Иордан на изток цялата галаадска земя, гадците, рувимците и манасийците, от Ароир при потока Арнон и Галаад и Васан.
34 Fún ti òmíràn ti iṣẹ́ ìjọba Jehu, gbogbo ohun tí ó ṣe, gbogbo àṣeyọrí rẹ̀, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
А останалите дела на Ииуя, всичко що извърши и всичките му юначества, не са ли написани в Книгата на лутописите на Израилевите царе?
35 Jehu sinmi pẹ̀lú baba a rẹ̀, a sì sin ín sí Samaria Jehoahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
И Ииуй заспа с бащите си; и погребаха го в Самария. И вместо него се възцари син му Иоахаз.
36 Àkókò tí Jehu fi jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria jẹ́ ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n.
И времето, през което Ииуй царува над Израиля в Самария, бе двадесет и осем години.

< 2 Kings 10 >