< 2 Kings 1 >

1 Lẹ́yìn ikú Ahabu, Moabu ṣọ̀tẹ̀ sí Israẹli.
Potem se je, po Ahábovi smrti, Moáb uprl zoper Izraela.
2 Nísinsin yìí Ahasiah ti ṣubú láàrín fèrèsé láti òkè yàrá rẹ̀ tí ó wà ní Samaria, ó sì fi ara pa. Ó sì rán oníṣẹ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni, bóyá èmi ó lè rí ìwòsàn ìfarapa yìí.”
Ahazjá je padel dol skozi mrežo v svoji gornji sobi, ki je bila v Samariji in je bil bolan. Poslal je poslance in jim rekel: »Pojdite, poizvedite od Báal Zebúba, boga v Ekrónu, ali si bom opomogel od te bolezni.«
3 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa wí fún Elijah ará Tiṣibi pé, “Lọ sókè kí o lọ bá ìránṣẹ́ ọba Samaria kí o sì béèrè lọ́wọ́ wọn, ‘Ṣé nítorí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli ni ẹ̀yìn fi jáde lọ ṣèwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu òrìṣà Ekroni?’
Toda Gospodov angel je rekel Tišbéjcu Eliju: »Vstani, pojdi gor, da srečaš poslance samarijskega kralja in jim reci: › Mar ni zato, ker ni Boga v Izraelu, da greste povpraševat ekrónskega boga Báal Zebúba?‹
4 Nítorí náà ohun tí Olúwa sọ ní èyí, ‘Ìwọ kò ní kúrò lórí ibùsùn tí o dùbúlẹ̀ lé. Dájúdájú ìwọ yóò kú!’” Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ.
Zdaj torej tako govori Gospod: ›Ne boš prišel dol iz svoje postelje, na katero si zlezel, temveč boš zagotovo umrl.‹« In Elija je odšel.
5 Nígbà tí ìránṣẹ́ náà padà sí ọ̀dọ̀ ọba, ó béèrè ní ọwọ́ wọn pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi tètè padà wá?”
Ko so se poslanci obrnili nazaj k njemu, jim je rekel: »Zakaj ste se torej obrnili nazaj?«
6 Wọ́n dáhùn pé, “Ọkùnrin kan wá láti pàdé wa, ó sì wí fún wa pé, ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ ọba tí ó rán an yín kí ẹ sì wí fún un pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli ni o fi ń rán àwọn ènìyàn láti lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni? Nítorí náà ìwọ kò ní fi orí ibùsùn tí ìwọ dùbúlẹ̀ lé sílẹ̀. Láìsí àní àní ìwọ yóò kùú!”’”
Rekli so mu: »Vzdignil se je mož, da nas sreča in nam rekel: ›Pojdite, ponovno se obrnite h kralju, ki vas je poslal in mu recite: ›Tako govori Gospod: › Mar ni zato, ker ni Boga v Izraelu, da pošiljaš povpraševat ekrónskega boga Báal Zebúba?‹ Zato ne boš prišel dol iz svoje postelje, na katero si zlezel, temveč boš zagotovo umrl.‹«
7 Ọba béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Irú ọkùnrin wo ni ó wá pàdé yín, tí ó sì sọ irú èyí fún un yín?”
Rekel jim je: »Kakšne vrste mož je bil ta, ki se je vzdignil, da vas sreča in vam je povedal te besede?«
8 Wọ́n dáhùn pé, “Ó jẹ́ ọkùnrin tí ó wọ ẹ̀wù onírun lára pẹ̀lú ọ̀já àmùrè aláwọ tí ó gbà yíká ìbàdí rẹ̀.” Ọba sì wí pé, “Elijah ará Tiṣibi ni.”
Odgovorili so mu: » Bil je kosmat človek in z usnjenim pasom opasan okoli ledij.« Rekel je: »To je Tišbéjec Elija.«
9 Ó sì rán balógun pẹ̀lú àwọn ẹgbẹ́ ogun àádọ́ta rẹ̀. Balógun náà sì gòkè tọ Elijah lọ, ẹni tí ó jókòó ní orí òkè, wọ́n sì wí fún un pé, “Ènìyàn Ọlọ́run, ọba wí pé, ‘Sọ̀kalẹ̀ wá!’”
Potem je kralj poslal k njemu petdesetnika z njegovimi petdesetimi. Ta je odšel gor k njemu, in glej, sedel je na vrhu hriba. Nagovoril ga je: »Božji mož, kralj je rekel: ›Pridi dol.‹«
10 Elijah sì dá balógun lóhùn pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ènìyàn Ọlọ́run ni mí, kí iná kí ó sọ̀kalẹ̀ láti òkè ọ̀run wá kí ó sì jó ìwọ àti àwọn àádọ́ta ọkùnrin rẹ!” Nígbà náà iná náà sì sọ̀kalẹ̀ wá láti òkè ọ̀run ó sì jó balógun àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
Elija je odgovoril in petdesetniku rekel: »Če sem Božji mož, potem naj dol z neba pride ogenj in použije tebe in tvojih petdeset.« Dol z neba je prišel ogenj in použil njega in njegovih petdeset.
11 Ọba sì tún rán balógun àádọ́ta pẹ̀lú àwọn ènìyàn àádọ́ta rẹ̀ sí Elijah. Balógun náà sì wí fún un pé, “Ènìyàn Ọlọ́run, èyí ni ohun tí ọba sọ, ‘Sọ̀kalẹ̀ kánkán!’”
Ponovno je k njemu poslal drugega petdesetnika z njegovimi petdesetimi. Ta je odgovoril in mu rekel: »Oh Božji mož, tako je rekel kralj: ›Pridi hitro dol.‹«
12 “Tí èmi bá jẹ́ ènìyàn Ọlọ́run,” Elijah sì dáhùn, “Ǹjẹ́ kí iná kí ó sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run kí ó sì jó ọ run àti àwọn àádọ́ta ènìyàn rẹ!” Nígbà náà iná Ọlọ́run sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run ó sì jó o run pẹ̀lú àwọn àádọ́ta ènìyàn rẹ̀.
Elija je odgovoril in jim rekel: »Če sem Božji mož, naj dol z neba pride ogenj in použije tebe in tvojih petdeset.« In ogenj od Boga je prišel z neba in použil njega in njegovih petdeset.
13 Bẹ́ẹ̀ ni ọba tún rán balógun kẹta pẹ̀lú àwọn àádọ́ta ọkùnrin. Balógun ẹ̀ẹ̀kẹ́ta lọ sí òkè, ó sì kúnlẹ̀ lórí orókún rẹ̀ níwájú Elijah. “Ènìyàn Ọlọ́run,” Ó sì bẹ̀bẹ̀ pé, “Ìwọ ènìyàn Ọlọ́run, jọ̀wọ́ jẹ́ kí ẹ̀mí mi àti ẹ̀mí àwọn àádọ́ta ìránṣẹ́ rẹ wọ̀nyí ṣọ̀wọ́n ní ojú rẹ!
Ponovno je poslal tretjega petdesetnika z njegovimi petdesetimi. Tretji petdesetnik je odšel gor, prišel in pred Elijem padel na kolena, ga rotil in mu rekel: »Oh Božji mož, prosim te, naj bodo moje življenje in življenja teh petdesetih tvojih služabnikov dragocena v tvojih očeh.
14 Wò ó, iná ti sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run láti jó àwọn balógun méjì àràádọ́ta àkọ́kọ́ pẹ̀lú àràádọ́ta wọn. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ní ojúrere fún ẹ̀mí mi!”
Glej, prišel je ogenj dol z neba in sežgal dva poveljnika prejšnjih petdesetih z njunimi petdesetimi. Zatorej naj bo moje življenje sedaj dragoceno v tvojih očeh.«
15 Angẹli Olúwa sọ fún Elijah pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú rẹ̀; má ṣe bẹ̀rù rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni Elijah dìde ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú rẹ̀ sí ọ̀dọ̀ ọba.
Gospodov angel je rekel Eliju: »Z njim pojdi dol. Ne boj se ga.« In vstal je in z njim odšel dol h kralju.
16 Ó sọ fún ọba pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli fún ọ láti pè ni ìwọ fi rán ìránṣẹ́ lọ sí ọ̀dọ̀ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni láti lọ ṣe ìwádìí?’ Nítorí pé o ṣe èyí, ìwọ kò ní dìde lórí ibùsùn tí o dùbúlẹ̀ lé láìsí àní àní ìwọ yóò kú!”
Rekel mu je: »Tako govori Gospod: ›Ker kakor si poslal poslance, da poizvejo od ekrónskega boga Báal Zebúba, mar ni to zato, ker ni Boga v Izraelu, da bi povprašal po njegovi besedi? Zato ne boš prišel dol iz postelje, na katero si zlezel, temveč boš zagotovo umrl.‹«
17 Bẹ́ẹ̀ ó sì kú, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí Elijah ti sọ. Nítorí Ahasiah kò ní ọmọ, Jehoramu jẹ ọba ní ọdún kejì tí Jehoramu ọmọ Jehoṣafati ọba Juda.
Tako je umrl glede na Gospodovo besedo, ki jo je Elija govoril. Namesto njega je zakraljeval Jehorám, v drugem letu Józafatovega sina Jehoráma, Judovega kralja, ker ni imel sina.
18 Àti ní ti gbogbo àwọn ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nígbà ìjọba Ahasiah, àti ohun tí ó ṣe, ṣe a kò ha kọ wọ́n sí inú ìwé ọdọọdún ti àwọn ọba Israẹli?
Torej preostala izmed Ahazjájevih dejanj, ki jih je storil, mar niso zapisana v kroniški knjigi Izraelovih kraljev?

< 2 Kings 1 >