< 2 John 1 >
1 Alàgbà, Sì àyànfẹ́ obìnrin ọlọ́lá àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn tí mo fẹ́ ní òtítọ́, kì í sì í ṣe èmi nìkan, ṣùgbọ́n gbogbo àwọn tí ó mọ òtítọ́ pẹ̀lú;
Bătrânul, către aleasa doamnă și către copiii ei, pe care îi iubesc în adevăr; și nu doar eu, ci și toți cei ce au cunoscut adevărul,
2 nítorí òtítọ́ tí ń gbé inú wa, yóò sì bá wa gbé títí: (aiōn )
Datorită adevărului care rămâne în noi și va fi cu noi pentru totdeauna. (aiōn )
3 Oore-ọ̀fẹ́, àánú, àti àlàáfíà, láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba, àti láti ọ̀dọ̀ Jesu Kristi, Ọmọ Baba, yóò wà pẹ̀lú wa nínú òtítọ́ àti nínú ìfẹ́.
Har fie cu voi, milă și pace, de la Dumnezeu Tatăl și de la Domnul Isus Cristos, Fiul Tatălui, în adevăr și în dragoste.
4 Mo yọ̀ gidigidi pé mo rí nínú àwọn ọmọ rẹ tí ń rìn nínú òtítọ́, gẹ́gẹ́ bí Baba ti pa àṣẹ fún wa.
M-am bucurat foarte mult că am găsit pe unii dintre copiii tăi umblând în adevăr, așa cum noi am primit poruncă de la Tatăl.
5 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, mo bẹ̀ ọ́, obìnrin ọlọ́lá, kì í ṣe bí ẹni pé èmi ń kọ̀wé òfin tuntun kan sí ọ, bí kò ṣe èyí ti àwa tí ní ní àtètèkọ́ṣe, pé kí àwa fẹ́ràn ara wa.
Și acum te implor, doamnă, nu că ți-am scris o poruncă nouă, ci aceea pe care am avut-o de la început: să ne iubim unii pe alții.
6 Èyí sì ni ìfẹ́, pé, kí àwa máa rin nípa òfin rẹ̀, èyí ni òfin náà, àní bí ẹ ti gbọ́ ni àtètèkọ́ṣe, pé, kí ẹ̀yin rìn nínú rẹ̀.
Și aceasta este dragostea: să umblăm după poruncile lui. Porunca este aceasta: ca așa cum ați auzit de la început, să umblați în ea.
7 Nítorí ẹlẹ́tàn púpọ̀ ti jáde wa sínú ayé, àwọn tí kò jẹ́wọ́ pé Jesu Kristi wá nínú ara. Èyí ni ẹlẹ́tàn àti aṣòdì sí Kristi.
Pentru că în lume au intrat mulți înșelători care nu mărturisesc că Isus Cristos a venit în carne. Acesta este un înșelător și un anticrist.
8 Ẹ kíyèsára yín, kí ẹ má ba à sọ iṣẹ́ tí ẹ tí ṣe nù, ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin lè rí èrè kíkún gbà.
Uitați-vă la voi înșivă, ca să nu pierdem cele ce am lucrat, ci să primim o răsplată deplină.
9 Olúkúlùkù ẹni tí ó bá ń rú òfin tí kò si dúró nínú ẹ̀kọ́ Kristi, kò mọ Ọlọ́run. Ẹni tí ó bá dúró nínú ẹ̀kọ́, òun ni ó mọ Baba àti Ọmọ.
Oricine încalcă legea și nu rămâne în doctrina lui Cristos nu îl are pe Dumnezeu. Cel ce rămâne în doctrina lui Cristos, acela îl are și pe Tatăl și pe Fiul.
10 Bí ẹnikẹ́ni bá tọ̀ yín wá, tí kò sì mu ẹ̀kọ́ yìí wá, ẹ má ṣe gbà á sí ilé, kí ẹ má sì ṣe kí i kú ààbọ̀.
Dacă vine cineva la voi și nu aduce această doctrină, să nu îl primiți în casă și să nu îi spuneți: Salutare!
11 Nítorí ẹni tí ó bá kí kú ààbọ̀, ó ní ọwọ́ nínú iṣẹ́ búburú rẹ̀.
Fiindcă cine îi spune: Salutare! Este părtaș faptelor lui rele.
12 Bí mo tilẹ̀ ní ohun púpọ̀ láti ṣe alábápín pẹ̀lú yín, síbẹ̀ èmi kò fẹ́ lo ìwé ìkọ̀wé àti jẹ́lú ìkọ̀wé. Ṣùgbọ́n èmi ní ìrètí láti tọ̀ yín wá àti láti bá a yín sọ̀rọ̀ lójúkojú, kí ayọ̀ yín bá à le è kún.
Având multe să vă scriu, nu doresc să le scriu cu hârtie și cerneală; dar mă încred să vin la voi și să vă vorbesc față în față, pentru ca bucuria noastră să fie deplină.
13 Àwọn ọmọ arábìnrin rẹ àyànfẹ́ kí ọ.
Te salută copiii surorii tale alese. Amin.