< 2 Corinthians 1 >

1 Paulu aposteli Jesu Kristi nípa ìfẹ́ Ọlọ́run, àti Timotiu arákùnrin wá, Sí ìjọ Ọlọ́run tí ó wà ní Kọrinti pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ tí ó wà ní gbogbo Akaia:
[I], Paul, who [write this letter to you], became an apostle of Christ Jesus because God chose me for that. [Timothy, our] fellow believer, [is with me. I am sending this letter] to you who are God’s people in the congregations in Corinth [city. I want] the believers who live in [other places] in Achaia [province to also read this letter].
2 Oore-ọ̀fẹ́ sí yín àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa, àti Jesu Kristi Olúwa.
[We(exc) desire] that you will [experience] God our Father and our Lord Jesus Christ [acting] kindly toward you and causing you to have [inner] peace.
3 Olùbùkún ni Ọlọ́run, àti Baba Jesu Kristi Olúwa wa, Baba ìyọ́nú, àti Ọlọ́run ìtùnú gbogbo.
[We should] praise God, who is the father of our [(inc)] Lord Jesus Christ. He always pities us and helps us [because he is like] [MET] a father to us [and we are like his children]. He always encourages us [(inc)].
4 Ẹni tí ń tù wá nínú ni gbogbo ìdààmú wa, ki àwa pẹ̀lú lè máa tu àwọn tí ó wá nínú ìdààmú nínú, nípá ìtùnú náà ti a fi ń tú àwa fúnra wa nínú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.
He has encouraged us [(exc)] whenever we suffered hardships. As a result, we [(exc)] are able to encourage others whenever they suffer hardships, just as/just like God has encouraged us [(exc)].
5 Nítorí pé bí àwa ti pín nínú ìjìyà Kristi, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ nì ìtùnú wa dí púpọ̀ pẹ̀lú nípa Kristi.
It is true that just like Christ suffered, we [who serve him] also continually suffer [because we belong to him]. But also, because we [belong to] Christ, God greatly strengthens us (just as/just like) [God strengthened him].
6 Ṣùgbọ́n bí a bá sì ń pọ́n wa lójú, ó jẹ́ fún ìtùnú àti ìgbàlà yín; tàbí bi a bá ń tù wá nínú, ó jẹ́ fún ìtùnú yín ti ń ṣiṣẹ́ sùúrù láti mú yin ní irú ìfaradà ìyà kan náà ti àwa pẹ̀lú ń jẹ́.
So, whenever we [(exc)] experience sufferings, we [learn how to encourage] you [when you experience sufferings. As a result, you will become more and more the kind of people God] wants you to be. Whenever [God] strengthens us [(exc) when we are suffering, he] does that in order that you [may see how he makes us strong when we are suffering. Then, as God] encourages [you in that way], you will learn to continue patiently [trusting him] when you suffer as we do.
7 Àti pé ìrètí wa nípa tiyín dúró ṣinṣin, àwa si mọ̀ pé, bí ẹ̀yin ti jẹ alábápín nínú ìyà wa, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ń pín nínú ìtùnú náà pẹ̀lú.
As a result, we [(exc)] strongly expect that because you suffer just as/just like we do, [God] will encourage you (just as/just like) [he] encourages us.
8 Arákùnrin àti arábìnrin, àwa kò fẹ́ kí ẹ̀yin jẹ́ òpè nípa wàhálà tí ó dé bá wa ní agbègbè Asia, ní ti pé a pọ́n wa lójú gidigidi rékọjá agbára ìfaradà wa, tó bẹ́ẹ̀ tí ìrètí kò tilẹ̀ sí fún ẹ̀mí wa mọ́.
[Our] fellow believers, we [(exc)] want you to know [LIT] about the trouble that we suffered in Asia [province]. That trouble was so very great that it was much more than we were able to endure. As a result, we [(exc)] thought that we would certainly die.
9 Nítòótọ́, nínú ọkàn wa a tilẹ̀ ní ìmọ̀lára wí pé a tí gba ìdálẹ́bi ikú, ṣùgbọ́n èyí farahàn láti má mú wa gbẹ́kẹ̀lé ara wa bí kò ṣe Ọlọ́run tí ń jí òkú dìde.
Indeed, we felt [like a person feels when he has heard a judge say], “I condemn you to die/be executed [MET].” But [God allowed us to think that we were going to die] so that we would not (rely on/trust in) our own [strength. He wanted us] instead [to rely] only on his [strength, because he] is the one who [has power even to make] those who have died live [again].
10 Ẹni tí ó gbà wá kúrò nínú irú ikú tí ó tóbi bẹ́ẹ̀, yóò sí tún gbà wá; òun ní àwa gbẹ́kẹ̀lé pé yóò sí máa gbà wá síbẹ̀síbẹ̀,
And [even though] we [(exc)] were [in terrible danger and were] about to die, God rescued us. And he will continue to rescue us [whenever we are in trouble]. We confidently expect that he will continue to rescue us [time after time].
11 bí ẹ̀yin pẹ̀lú ti ń fi àdúrà yín ràn wá lọ́wọ́. Àti pé ọ̀pọ̀ ènìyàn ni yóò dúpẹ́ nítorí wa fún oore-ọ̀fẹ́ ojúrere tí a rí gbà nípa ìdáhùn sí àdúrà ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn.
[And we are also relying on] you to help us by praying for us [(exc)]. [If many people pray for us], many people will also thank [God] when [he] kindly answers those many prayers [and delivers us from danger].
12 Nítorí èyí ní ìṣògo wá, ẹ̀rí láti inú ọkàn wa pẹ̀lú si jẹ́rìí wí pé àwa ń gbé ìgbésí ayé tí ó ní ìtumọ̀ pàápàá jùlọ nínú ìbágbépọ̀ wa pẹ̀lú yín, nínú ìwà mímọ́ àti òtítọ́ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá. Kì í ṣe nípa ọgbọ́n ti ara ni àwa ń ṣe èyí bí kò ṣe nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.
I am happy [to say] that I have behaved toward all people [MTY] in an honest and sincere way. My conscience assures me [that this is true]. Especially, I have behaved toward you [honestly and sincerely because that is what] God wants us to do. As I have done that, [my thoughts] have not been the thoughts that unbelieving people [MTY] [think are] wise. Instead, [I have behaved toward people only as God wants me to, depending on] God to help me in ways that I do not deserve.
13 Nítorí pé àwa kò kọ̀wé ohun tí eyín kò lè kà àti ni mòye rẹ̀ sí yín. Mo sì tún ní ìrètí wí pé.
[I say that] because [in all my letters to you] I have always written [LIT] clearly in a way that you can easily and completely understand [when you] read them.
14 Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin pẹ̀lú ti ní ìmọ̀ nípa wa ní apá kan, bákan náà ni ẹ ó ní ìmọ̀ lẹ́kùnrẹ́rẹ́ tí ẹ ó sì fi wá yangàn, bí àwa pẹ̀lú yóò ṣe fi yín yangàn ní ọjọ́ Jesu Olúwa.
[Previously some of] you, but not all of you, have completely understood [that I am always honest and sincere with you]. But I confidently expect that [soon] you will all be fully convinced [about that]. Then when the Lord Jesus [MTY] [returns, you will all be able to say that] you are pleased with me, just like I will [be able to say that] I am pleased with you.
15 Nítorí mo ní ìdánilójú yìí wí pé, mo pinnu láti kọ́kọ́ bẹ̀ yín wò kí ẹ lè jẹ àǹfààní ìgbà méjì.
It was because I felt sure [that all of you were pleased with me] that I was planning to visit you on my way from [here] to Macedonia [province]. I also planned to visit you again on my way back from there, so that I could [spend time with you] twice, and be able to help you more, and I was hoping that you would [give me things that I needed] [EUP] for my journey to Judea [province].
16 Mo pinnu láti bẹ̀ yín wò ní ìrìnàjò mi sí Makedonia àti láti tún bẹ̀ yín wò nígbà tí mo bá ń padà bọ̀ láti Makedonia àti wí pé kí ẹ̀yin kí ó lè rán mi láti ọ̀dọ̀ yín ní ìrìnàjò mi sí Judea.
17 Nítorí náà nígbà tí èmi ń gbèrò bẹ́ẹ̀, èmi ha ṣiyèméjì bí? Tàbí àwọn ohun tí mo pinnu, mo ha pinnu wọn gẹ́gẹ́ bí ti ará bí, pé kí ó jẹ́ “Bẹ́ẹ̀ ní, bẹ́ẹ̀ ní” àti “Bẹ́ẹ̀ kọ́, bẹ́ẹ̀ kọ́”?
So then, even though I [changed my mind later and did not do what] I [first] planned to do, [it was not because I did not have an important reason for changing my plans]. Surely you do not [really think] that I decide what I am going to do like people who do not know God do! [RHQ] I am [not like that]. I am not [a person who] says [to people], “Yes, [certainly I will do that],” and then [for no good reason changes his mind and says], “No, [I will not do it].”
18 Ṣùgbọ́n bí Ọlọ́run tí jẹ́ olóòtítọ́, ọ̀rọ̀ wa fún yín kí í ṣe bẹ́ẹ̀ ni àti bẹ́ẹ̀ kọ́.
Just as surely as God always does what he says [he will do, it is true that I have never said], “Yes, [I will do this]” when I [really meant] “No.”
19 Nítorí pé Jesu Kristi, Ọmọ Ọlọ́run, ẹni tí a tí wàásù rẹ̀ láàrín yín nípasẹ̀ èmí àti Silfanu àti Timotiu, kì í ṣe bẹ́ẹ̀ ni bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n nínú rẹ̀ ni bẹ́ẹ̀ ní.
[I follow the example of] God’s Son, Jesus Christ. When I, along with Silas and Timothy, taught you [about Christ], we told you that he was not [someone who said that he] would do [something] and [then] did not [do it]. Jesus Christ never [said to anyone], “Yes, [I will do what you desire],” and [then did] not [do it].
20 Nítorí tí gbogbo ìlérí Ọlọ́run dí bẹ́ẹ̀ ni nínú Kristi. Nítorí ìdí èyí ní a ṣe ń wí pé “Àmín” nípasẹ̀ rẹ̀ sí ògo Ọlọ́run.
[We(inc) know that is true], because everything that God promised to do [for his people], he has done completely by [sending] Christ [to save us]. That is why we say, “Yes, it is true! [God has done everything that he promised to do]!” And we praise him for that!
21 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, Ọlọ́run ni ó fi ẹsẹ̀ wa múlẹ̀ pẹ̀lú yín nínú Kristi, Òun ni ó ti fi àmì òróró yàn wá,
Now it is only God himself who causes us [(exc)], as well as you, to keep on [believing] strongly in Christ. God is the one who chose us [(inc) to belong to him and to have a close relationship] with Christ.
22 ó sì fi èdìdì rẹ̀ dì wá pẹ̀lú, ó sì tí fi Ẹ̀mí rẹ́ sí wa ní ọkàn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí ìdánilójú ohun tí ó ń bọ̀.
He also sent his Holy Spirit into our [(inc)] lives to mark us as belonging to himself [MET]. Also, since he has sent his Spirit to live in us [(inc)], [he wants us to know by this that] he guarantees [MET] [to give us every other] ([blessing/good thing]) [that he has promised].
23 Mo sì pe Ọlọ́run ṣe ẹlẹ́rìí ọkàn mi pé nítorí àti dá yín sí ní èmi kò ṣe padà sí Kọrinti.
So now [I will tell you why I changed my mind and did not visit you as I intended to do]: God himself knows [that what I am telling you is true]. The reason that I did not return to Corinth was so that I might not have to [speak to you severely about the wrong that you had done].
24 Kì í ṣe nítorí tí àwa jẹ gàba lórí ìgbàgbọ́ yín, ṣùgbọ́n àwa ń ṣiṣẹ́ pọ̀ pẹ̀lú yín fún ayọ̀ yín nítorí nípa ìgbàgbọ́ ni ẹ̀yin dúró ṣinṣin.
It is not that Silas, Timothy and I want to boss you [and tell you that you must] believe only what we say. [Not at all]! On the contrary, we [(exc)] are working as partners [with you] in order to make you happy. [We do not try to force you to believe everything that we believe, because we are sure that you are continuing to] trust [the Lord Jesus Christ] and that you are remaining firmly committed to him.

< 2 Corinthians 1 >