< 2 Corinthians 9 >
1 Nísinsin yìí, nípa ti ìpín fún ni fún àwọn ènìyàn mímọ́, kò tún yẹ mọ́ fún mi láti kọ̀wé sí yin ju bẹ́ẹ̀ lọ.
ⲁ̅ⲉⲑⲃⲉ ϯⲇⲓ⳿ⲁⲕⲟⲛⲓ⳿ⲁ ⲅⲁⲣ ⲙⲉⲛ ⲉⲧⲟⲩⲣⲁ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⳿ⲛⲛⲓⲁⲅⲓⲟⲥ ⲟⲩϩⲟⲩ⳿ⲟ ⲛⲏⲓ ⲡⲉ ⲫⲁⲓ ⳿ⲉ⳿ⲥϧⲁⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ.
2 Nítorí mo mọ ìtara láti ṣe ìrànlọ́wọ́ yín, èyí tí mo ti ṣògo fún àwọn ará Makedonia nítorí yín, pé, àwọn ara Akaia ti múra tan níwọ̀n ọdún kan tí ó kọjá ìtara yín sì ti rú ọ̀pọ̀lọpọ̀ sókè.
ⲃ̅ϯⲥⲱⲟⲩⲛ ⲅⲁⲣ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲉⲛⲣⲱⲟⲩⲧϥ ⲫⲁⲓ ⳿ⲉϯⲣⲁ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲛϣⲟⲩϣⲟⲩ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϧⲁⲧⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲁ ⳿ⲑⲙⲁⲕⲉⲇⲟⲛⲓ⳿ⲁ ϫⲉ ⲁ ⲛⲁ ϯ ⳿ⲁⲭⲁⲓ⳿ⲁ ⲥⲉⲃⲧⲟⲧⲟⲩ ⲓⲥϫⲉⲛ ⳿ⲥⲛⲟⲩϥ ⲁⲗⲗⲁ ⲡⲉⲧⲉⲛⲭ ⲟϩ ⲁϥϯⲭⲟϩ ⳿ⲙⲡⲟⲩϩⲟⲩ⳿ⲟ.
3 Ṣùgbọ́n mo ti rán àwọn arákùnrin, kí ìṣògo wa nítorí yín má ṣe jásí asán ní ti ọ̀ràn yìí; pé gẹ́gẹ́ bí mó ti wí, kí ẹ̀yin lè múra tẹ́lẹ̀.
ⲅ̅ⲁⲛⲟⲩⲱⲣⲡ ⲇⲉ ⳿ⲛⲛⲓ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ϩⲁⲣⲱⲧⲉⲛ ϩⲓⲛⲁ ⲡⲉⲛϣⲟⲩϣⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉⲛⲣⲁ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ϣⲧⲉⲙϣⲱⲡⲓ ⲉϥϣⲟⲩⲓⲧ ϧⲉⲛ ⲡⲁⲓⲙⲉⲣⲟⲥ ϩⲓⲛⲁ ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲉⲛⲁⲓϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛϣⲱⲡⲓ ⳿ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲥⲉⲃⲧⲱⲧ.
4 Kí ó má ba à jẹ́ pé, bí àwọn nínú ara Makedonia bá bá mi wá, tí wọ́n sì bá yín ní àìmúra sílẹ̀, ojú a sì tì wá kì í ṣe ẹ̀yin, ní ti ìgbẹ́kẹ̀lé yìí.
ⲇ̅ⲙⲏⲡⲱⲥ ⲁⲩϣⲁⲛ⳿ⲓ ⲛⲉⲙⲏⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲁ ⲑⲙⲁⲕⲉⲇⲟⲛⲓ⳿ⲁ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲥⲉϫⲉⲙ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛⲥⲉⲃⲧⲱⲧ ⲁⲛ ⳿ⲛⲧⲉⲛϣⲓⲡⲓ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ϩⲓⲛⲁ ϫⲉ ⳿ⲛⲛⲉⲛϫⲟⲥ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛ⳿ϩⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲁⲓϣⲓ.
5 Nítorí náà ni mo ṣe rò pé ó yẹ láti gba àwọn arákùnrin níyànjú, kí wọn kọ́kọ́ tọ̀ yín wá, kí ẹ sì múra ẹ̀bùn yín, tí ẹ ti ṣe ìlérí tẹ́lẹ̀ sílẹ̀, kí ó lè ti wà ní lẹ́bi ẹ̀bùn gidi, kí ó má sì ṣe dàbí ohun ti a fi ìkùnsínú ṣe.
ⲉ̅ⲟⲩⲁⲛⲁⲅⲕⲉⲟⲛ ⲟⲩⲛ ⲁⲓⲙⲉⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲉⲑⲉⲧ ϩⲏⲧ ⳿ⲛⲛⲓ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲥⲉⲉⲣϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛ⳿ⲓ ϩⲁⲣⲱⲧⲉⲛ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲥⲉⲉⲣϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛⲥⲉⲃⲧⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛ⳿ⲥⲙⲟⲩ ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲱϣ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲓⲥϫⲉⲛ ϣⲟⲣⲡ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥϣⲱⲡⲓ ⲉϥⲥⲉⲃⲧⲱⲧ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲇⲉ ϩⲱⲥ ⲟⲩ⳿ⲥⲙⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲉⲧϭⲓ⳿ⲛϫⲟⲛⲥ ⲁⲛ.
6 Ṣùgbọ́n èyí ni mo wí pé, ẹni tí ó bá fúnrúgbìn kín ún, kín ún ni yóò ká; ẹni tí ó bá sì fúnrúgbìn púpọ̀, púpọ̀ ni yóò ká.
ⲋ̅ⲫⲁⲓ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲉ ⲫⲏⲉⲧϯ⳿ⲁⲥⲟ ⲉϥⲥⲓϯ ⲉϥ⳿ⲉⲱⲥϧ ⲟⲛ ϧⲉⲛ ⲟⲩϯ⳿ⲁⲥⲟ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏⲉⲧⲥⲓϯ ϧⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲥⲙⲟⲩ ⲉϥ⳿ⲉⲱⲥϧ ⲟⲛ ϧⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲥⲙⲟⲩ.
7 Kí olúkúlùkù ènìyàn ṣe gẹ́gẹ́ bí ó ti pinnu ní ọkàn rẹ̀; kì í ṣe àfi ìkùnsínú ṣe, tàbí ti àìgbọdọ̀ má ṣe; nítorí Ọlọ́run fẹ́ onínúdídùn ọlọ́rẹ.
ⲍ̅ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⲕⲁⲧⲁ ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲉⲧⲁϥⲥⲱⲧⲡ ⲛⲁϥ ϧⲉⲛ ⲡⲉϥϩⲏⲧ ⲛⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲙⲕⲁϩ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲁⲛ ⲓⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲁⲛⲁⲅⲕⲏ ⲟⲩⲣⲉϥϯ ⲅⲁⲣ ⲉϥⲣⲁϣⲓ ⳿ⲉⲧⲉ ⲫϯ ⲙⲉⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
8 Ọlọ́run sì lè mú kí gbogbo oore-ọ̀fẹ́ máa bí sí i fún yín; kí ẹ̀yin tí ó ní ànító ohun gbogbo, nígbà gbogbo, lè máa pọ̀ sí i ní iṣẹ́ rere gbogbo.
ⲏ̅ⲟⲩⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⲇⲉ ⳿ⲙⲫϯ ⲉⲑⲣⲉ ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲁϣⲁⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲉⲣⲉ ⳿ⲫⲣⲱϣⲓ ϣⲟⲡ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲛⲥⲏⲟⲩ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛⲉⲣϩⲟⲩ⳿ⲟ ϧⲉⲛ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲛⲁⲅⲁⲑⲟⲛ.
9 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ́ ọ pé: “Ó tí fọ́nká; ó ti fi fún àwọn tálákà, òdodo rẹ̀ dúró láéláé.” (aiōn )
ⲑ̅ⲕⲁⲧⲁ ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧ⳿ⲥϧⲏⲟⲩⲧ ϫⲉ ⲁϥⲥⲱⲣ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁϥϯ ⳿ⲛⲛⲓϩⲏⲕⲓ ⲧⲉϥⲙⲉⲑⲙⲏⲓ ϣⲟⲡ ϣⲁ ⳿ⲉⲛⲉϩ. (aiōn )
10 Ǹjẹ́ ẹni tí ń fi irúgbìn fún afúnrúgbìn, àti àkàrà fún oúnjẹ, yóò fi irúgbìn fún un yín, yóò sì sọ ọ́ di púpọ̀, yóò sì mú èso òdodo yín bí sí i.
ⲓ̅ⲡⲉⲧⲥⲁϩⲛⲓ ⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ϫⲣⲟϫ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲥⲓϯ ⲉϥ⳿ⲉⲥⲉϩⲛⲉ ⲡⲓⲕⲉⲱⲓⲕ ⲛⲁϥ ⲟⲛ ⳿ⲉⲟⲩⲱⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲉϥ⳿ⲉ⳿ⲑⲣⲉ ⲛⲉⲧⲉⲛϭⲟ ⳿ⲁϣⲁⲓ ⲉϥ⳿ⲉ⳿ⲑⲣⲟⲩⲁⲓⲁⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲟⲩⲧⲁϩ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛⲙⲉⲑⲙⲏⲓ.
11 Bẹ́ẹ̀ ni a ó sọ yín di ọlọ́rọ̀ nínú ohun gbogbo, fún ìlawọ́ yín gbogbo tí ń ṣiṣẹ́ ọpẹ́ sí Ọlọ́run nípa wa.
ⲓ̅ⲁ̅ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲟⲓ ⳿ⲛⲣⲁⲙⲁ⳿ⲟ ϧⲉⲛ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϧⲉⲛ ⲙⲉⲧϩⲁⲡⲗⲟⲩⲥ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲑⲁⲓ ⲉⲧⲉⲣϩⲱⲃ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲧⲉⲛ ⲉⲩϣⲉⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉⲛ ⲫϯ.
12 Nítorí iṣẹ́ ìránṣẹ́ ìsìn yìí kò kún ìwọ̀n àìní àwọn ènìyàn mímọ́ nìkan, ṣùgbọ́n ó túbọ̀ pọ̀ sí i nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọpẹ́ sí Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲃ̅ϫⲉ ⲧⲁⲓⲇⲓ⳿ⲁⲕⲟⲛⲓ⳿ⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲧⲁⲓⲫⲁϣⲛⲓ ⲟⲩ ⲙⲟⲛⲟⲛ ⲉⲥϣⲟⲡ ⲉⲥϫⲱⲕ ⳿ⲛⲛⲓ⳿ⲭⲣⲓⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲁⲅⲓⲟⲥ ⳿ⲙⲙⲁⲩⲁⲧⲟⲩ ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲥⲉⲣ⳿ⲡⲕⲉⲟⲓ ⳿ⲛϩⲟⲩⲟ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛϣⲉⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉⲛ ⲫϯ.
13 Nítorí ìdúró yin lábẹ́ ìdánwò iṣẹ́ ìsìn yìí, wọn yóò yin Ọlọ́run lógo fún ìgbọ́ràn yín ní gbígba ìyìnrere Kristi àti nípa ìlawọ́ ìdáwó yín fún wọn àti fún gbogbo ènìyàn.
ⲓ̅ⲅ̅⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ϯⲇⲟⲕⲓⲙⲏ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲁⲓϣⲉⲙϣⲓ ⳿ⲉⲣⲉⲧⲉⲛϯ⳿ⲱⲟⲩ ⳿ⲙⲫϯ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲓ ⳿ϭⲛⲉϫⲱϥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛⲟⲩⲱⲛϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲉⲡⲓⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲛⲉⲙ ϯⲙⲉⲧⲁⲡⲗⲟⲩⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲙⲉⲧ⳿ϣⲫⲏⲣ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
14 Àti nínú àdúrà fún un yín, ọkàn wọn ń ṣe àfẹ́rí yín nítorí ọ̀pọ̀ oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run ti ń bẹ nínú yín.
ⲓ̅ⲇ̅ⲛⲉⲙ ⲡⲟⲩⲧⲱⲃϩ ⳿ⲉⲧⲟⲩⲣⲁ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏ ⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲉⲩϣⲟⲡ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲓ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⲉⲑⲃⲉ ⲡⲓ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⳿ⲉⲧⲉⲣϩⲟⲩ⳿ⲟ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
15 Ọpẹ́ ni fún Ọlọ́run nítorí aláìlèfẹnusọ ẹ̀bùn rẹ̀!
ⲓ̅ⲉ̅⳿ⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲇⲉ ⳿ⲙⲫϯ ϣⲏⲡ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲧⲉϥⲇⲱⲣⲉ⳿ⲁ ⳿ⲛⲁⲧⲥⲁϫⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲥ.