< 2 Corinthians 9 >
1 Nísinsin yìí, nípa ti ìpín fún ni fún àwọn ènìyàn mímọ́, kò tún yẹ mọ́ fún mi láti kọ̀wé sí yin ju bẹ́ẹ̀ lọ.
ⲁ̅ⲈⲐⲂⲈ ϮⲆⲒⲀⲔⲞⲚⲒⲀ ⲄⲀⲢ ⲘⲈⲚ ⲈⲦⲞⲨⲢⲀ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲚⲒⲀⲄⲒⲞⲤ ⲞⲨϨⲞⲨⲞ ⲚⲎⲒ ⲠⲈ ⲪⲀⲒ ⲈⲤϦⲀⲒ ⲚⲰⲦⲈⲚ.
2 Nítorí mo mọ ìtara láti ṣe ìrànlọ́wọ́ yín, èyí tí mo ti ṣògo fún àwọn ará Makedonia nítorí yín, pé, àwọn ara Akaia ti múra tan níwọ̀n ọdún kan tí ó kọjá ìtara yín sì ti rú ọ̀pọ̀lọpọ̀ sókè.
ⲃ̅ϮⲤⲰⲞⲨⲚ ⲄⲀⲢ ⲘⲠⲈⲦⲈⲚⲢⲰⲞⲨⲦϤ ⲪⲀⲒ ⲈϮⲢⲀ ⲘⲘⲞϤ ⲚϢⲞⲨϢⲞⲨ ⲈϪⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ ϦⲀⲦⲞⲦⲞⲨ ⲚⲚⲀ ⲐⲘⲀⲔⲈⲆⲞⲚⲒⲀ ϪⲈ ⲀⲚⲀ ϮⲀⲬⲀⲒⲀ ⲤⲈⲂⲦⲞⲦⲞⲨ ⲒⲤϪⲈⲚ ⲤⲚⲞⲨϤ ⲀⲖⲖⲀ ⲠⲈⲦⲈⲚⲬ ⲞϨ ⲀϤϮⲬⲞϨ ⲘⲠⲞⲨϨⲞⲨⲞ.
3 Ṣùgbọ́n mo ti rán àwọn arákùnrin, kí ìṣògo wa nítorí yín má ṣe jásí asán ní ti ọ̀ràn yìí; pé gẹ́gẹ́ bí mó ti wí, kí ẹ̀yin lè múra tẹ́lẹ̀.
ⲅ̅ⲀⲚⲞⲨⲰⲢⲠ ⲆⲈ ⲚⲚⲒⲤⲚⲎⲞⲨ ϨⲀⲢⲰⲦⲈⲚ ϨⲒⲚⲀ ⲠⲈⲚϢⲞⲨϢⲞⲨ ⲈⲦⲈⲚⲢⲀ ⲘⲘⲞϤ ⲈϪⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲚⲦⲈϤϢⲦⲈⲘϢⲰⲠⲒ ⲈϤϢⲞⲨⲒⲦ ϦⲈⲚⲠⲀⲒⲘⲈⲢⲞⲤ ϨⲒⲚⲀ ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲈⲚⲀⲒϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚϢⲰⲠⲒ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲤⲈⲂⲦⲰⲦ.
4 Kí ó má ba à jẹ́ pé, bí àwọn nínú ara Makedonia bá bá mi wá, tí wọ́n sì bá yín ní àìmúra sílẹ̀, ojú a sì tì wá kì í ṣe ẹ̀yin, ní ti ìgbẹ́kẹ̀lé yìí.
ⲇ̅ⲘⲎⲠⲰⲤ ⲀⲨϢⲀⲚⲒ ⲚⲈⲘⲎⲒ ⲚϪⲈⲚⲀ ⲐⲘⲀⲔⲈⲆⲞⲚⲒⲀ ⲚⲤⲈϪⲈⲘ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚⲤⲈⲂⲦⲰⲦ ⲀⲚ ⲚⲦⲈⲚϢⲒⲠⲒ ⲀⲚⲞⲚ ϨⲒⲚⲀ ϪⲈ ⲚⲚⲈⲚϪⲞⲤ ϪⲈ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲚϨⲢⲎⲒ ϦⲈⲚⲠⲀⲒϢⲒ.
5 Nítorí náà ni mo ṣe rò pé ó yẹ láti gba àwọn arákùnrin níyànjú, kí wọn kọ́kọ́ tọ̀ yín wá, kí ẹ sì múra ẹ̀bùn yín, tí ẹ ti ṣe ìlérí tẹ́lẹ̀ sílẹ̀, kí ó lè ti wà ní lẹ́bi ẹ̀bùn gidi, kí ó má sì ṣe dàbí ohun ti a fi ìkùnsínú ṣe.
ⲉ̅ⲞⲨⲀⲚⲀⲄⲔⲈⲞⲚ ⲞⲨⲚ ⲀⲒⲘⲈⲨⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲈⲐⲈⲦ ⲚϨⲎⲦ ⲚⲚⲒⲤⲚⲎⲞⲨ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲤⲈⲈⲢϢⲞⲢⲠ ⲚⲒ ϨⲀⲢⲰⲦⲈⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲤⲈⲈⲢϢⲞⲢⲠ ⲚⲤⲈⲂⲦⲈ ⲠⲈⲦⲈⲚⲤⲘⲞⲨ ⲪⲎ ⲈⲦⲀⲢⲈⲦⲈⲚⲰϢ ⲘⲘⲞϤ ⲒⲤϪⲈⲚ ϢⲞⲢⲠ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϤϢⲰⲠⲒ ⲈϤⲤⲈⲂⲦⲰⲦ ⲠⲀⲒⲢⲎϮ ⲆⲈ ϨⲰⲤ ⲞⲨⲤⲘⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲞⲨⲘⲈⲦϬⲒⲚϪⲞⲚⲤ ⲀⲚ.
6 Ṣùgbọ́n èyí ni mo wí pé, ẹni tí ó bá fúnrúgbìn kín ún, kín ún ni yóò ká; ẹni tí ó bá sì fúnrúgbìn púpọ̀, púpọ̀ ni yóò ká.
ⲋ̅ⲪⲀⲒ ⲆⲈ ⲠⲈ ϪⲈ ⲪⲎ ⲈⲦϮⲀⲤⲞ ⲈϤⲤⲒϮ ⲈϤⲈⲰⲤϦ ⲞⲚ ϦⲈⲚⲞⲨϮⲀⲤⲞ ⲞⲨⲞϨ ⲪⲎ ⲈⲦⲤⲒϮ ϦⲈⲚⲞⲨⲤⲘⲞⲨ ⲈϤⲈⲰⲤϦ ⲞⲚ ϦⲈⲚⲞⲨⲤⲘⲞⲨ
7 Kí olúkúlùkù ènìyàn ṣe gẹ́gẹ́ bí ó ti pinnu ní ọkàn rẹ̀; kì í ṣe àfi ìkùnsínú ṣe, tàbí ti àìgbọdọ̀ má ṣe; nítorí Ọlọ́run fẹ́ onínúdídùn ọlọ́rẹ.
ⲍ̅ⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲀϤⲤⲰⲦⲠ ⲚⲀϤ ϦⲈⲚⲠⲈϤϨⲎⲦ ⲚⲈⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲞⲨⲘⲔⲀϨ ⲚϨⲎⲦ ⲀⲚ ⲒⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲞⲨⲀⲚⲀⲄⲔⲎ ⲞⲨⲢⲈϤϮ ⲄⲀⲢ ⲈϤⲢⲀϢⲒ ⲈⲦⲈ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲘⲈⲒ ⲘⲘⲞϤ.
8 Ọlọ́run sì lè mú kí gbogbo oore-ọ̀fẹ́ máa bí sí i fún yín; kí ẹ̀yin tí ó ní ànító ohun gbogbo, nígbà gbogbo, lè máa pọ̀ sí i ní iṣẹ́ rere gbogbo.
ⲏ̅ⲞⲨⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲆⲈ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲐⲢⲈ ϨⲘⲞⲦ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲀϢⲀⲒ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϨⲒⲚⲀ ⲈⲢⲈ ⲪⲢⲰϢⲒ ϢⲞⲠ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϦⲈⲚϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲚⲤⲎⲞⲨ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚⲈⲢϨⲞⲨⲞ ϦⲈⲚϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲚⲀⲄⲀⲐⲞⲚ.
9 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ́ ọ pé: “Ó tí fọ́nká; ó ti fi fún àwọn tálákà, òdodo rẹ̀ dúró láéláé.” (aiōn )
ⲑ̅ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲤϦⲎⲞⲨⲦ ϪⲈ ⲀϤⲤⲰⲢ ⲈⲂⲞⲖ ⲀϤϮ ⲚⲚⲒϨⲎⲔⲒ ⲦⲈϤⲘⲈⲐⲘⲎⲒ ϢⲰⲠ ϢⲀ ⲈⲚⲈϨ. (aiōn )
10 Ǹjẹ́ ẹni tí ń fi irúgbìn fún afúnrúgbìn, àti àkàrà fún oúnjẹ, yóò fi irúgbìn fún un yín, yóò sì sọ ọ́ di púpọ̀, yóò sì mú èso òdodo yín bí sí i.
ⲓ̅ⲠⲈⲦⲤⲀϨⲚⲒ ⲆⲈ ⲘⲠⲒϪⲢⲞϪ ⲘⲠⲈⲦⲤⲒϮ ⲈϤⲈⲤⲈϨⲚⲈ ⲠⲒⲔⲈⲰⲒⲔ ⲚⲀϤ ⲞⲚ ⲈⲞⲨⲰⲘ ⲞⲨⲞϨ ⲈϤⲈⲐⲢⲈ ⲚⲈⲦⲈⲚϬⲞ ⲀϢⲀⲒ ⲈϤⲈⲐⲢⲞⲨⲀϢⲀⲒ ⲚϪⲈⲚⲒⲞⲨⲦⲀϨ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚⲘⲈⲐⲘⲎⲒ.
11 Bẹ́ẹ̀ ni a ó sọ yín di ọlọ́rọ̀ nínú ohun gbogbo, fún ìlawọ́ yín gbogbo tí ń ṣiṣẹ́ ọpẹ́ sí Ọlọ́run nípa wa.
ⲓ̅ⲁ̅ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲞⲒ ⲚⲢⲀⲘⲀⲞ ϦⲈⲚϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ϦⲈⲚⲘⲈⲦϨⲀⲠⲖⲞⲨⲤ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲐⲀⲒ ⲈⲦⲈⲢϨⲰⲂ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦⲈⲚ ⲈⲨϢⲈⲠϨⲘⲞⲦ ⲚⲦⲈⲚ ⲪⲚⲞⲨϮ.
12 Nítorí iṣẹ́ ìránṣẹ́ ìsìn yìí kò kún ìwọ̀n àìní àwọn ènìyàn mímọ́ nìkan, ṣùgbọ́n ó túbọ̀ pọ̀ sí i nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọpẹ́ sí Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲃ̅ϪⲈ ⲦⲀⲒⲆⲒⲀⲔⲞⲚⲒⲀ ⲚⲦⲈⲦⲀⲒⲪⲀϢⲚⲒ ⲞⲨ ⲘⲞⲚⲞⲚ ⲈⲤϢⲞⲠ ⲈⲤϪⲰⲔ ⲚⲚⲒⲬⲢⲒⲀ ⲚⲦⲈⲚⲒⲀⲄⲒⲞⲤ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦⲞⲨ ⲀⲖⲖⲀ ⲤⲈⲢⲠⲔⲈⲞⲨⲀⲒ ⲚϨⲞⲨⲞ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲞⲨⲘⲎϢ ⲚϢⲈⲠϨⲘⲞⲦ ⲚⲦⲈⲚ ⲪⲚⲞⲨϮ.
13 Nítorí ìdúró yin lábẹ́ ìdánwò iṣẹ́ ìsìn yìí, wọn yóò yin Ọlọ́run lógo fún ìgbọ́ràn yín ní gbígba ìyìnrere Kristi àti nípa ìlawọ́ ìdáwó yín fún wọn àti fún gbogbo ènìyàn.
ⲓ̅ⲅ̅ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ϮⲆⲞⲔⲒⲘⲎ ⲚⲦⲈⲠⲀⲒϢⲈⲘϢⲒ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚϮⲰⲞⲨ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲒϬⲚⲈϪⲰϤ ⲚⲦⲈⲠⲈⲦⲈⲚⲞⲨⲰⲚϨ ⲈⲂⲞⲖ ⲈⲠⲒⲈⲨⲀⲄⲄⲈⲖⲒⲞⲚ ⲚⲦⲈⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲚⲈⲘ ϮⲘⲈⲦⲀⲠⲖⲞⲨⲤ ⲚⲦⲈϮⲘⲈⲦϢⲪⲎⲢ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ.
14 Àti nínú àdúrà fún un yín, ọkàn wọn ń ṣe àfẹ́rí yín nítorí ọ̀pọ̀ oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run ti ń bẹ nínú yín.
ⲓ̅ⲇ̅ⲚⲈⲘ ⲠⲞⲨⲦⲰⲂϨ ⲈⲦⲞⲨⲢⲀ ⲘⲘⲞϤ ⲈϨⲢⲎ ⲒⲈϪⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲈⲨϢⲞⲠ ϦⲈⲚⲞⲨⲘⲈⲒ ⲚϨⲎⲦ ⲈⲢⲰⲦⲈⲚ ⲈⲐⲂⲈ ⲠⲒϨⲘⲞⲦ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲦⲈⲢϨⲞⲨⲞ ϦⲈⲚⲐⲎⲚⲞⲨ.
15 Ọpẹ́ ni fún Ọlọ́run nítorí aláìlèfẹnusọ ẹ̀bùn rẹ̀!
ⲓ̅ⲉ̅ⲠϨⲘⲞⲦ ⲆⲈ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ϢⲎⲠ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲦⲈϤⲆⲰⲢⲈⲀ ⲚⲀⲦⲤⲀϪⲒ ⲘⲘⲞⲤ.