< 2 Corinthians 8 >

1 Pẹ̀lúpẹ̀lú, ará, àwa ń sọ fún yín ní ti oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run tí a fífún àwọn ìjọ Makedonia.
Vi kunngjør eder, brødre, den nåde som Gud har gitt i Makedonias menigheter,
2 Bí ó ti jẹ́ pé a dán wọn wò nípa ìpọ́njú, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ayọ̀ àti àìlódiwọ̀n àìní wọn ti kún àkúnwọ́sílẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ ìlawọ́ wọn.
at enda de var hårdt prøvet med trengsel, så har dog deres overvettes glede og deres dype fattigdom i overstrømmende fylde virket hos dem en rikdom på opriktig kjærlighet.
3 Nítorí mo jẹ́rìí pé gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, àní ju agbára wọn, wọ́n ṣe é láti ìfẹ́ inú ara wọn.
For efter evne gav de, det vidner jeg, ja over evne, av egen drift;
4 Wọ́n ń fi ẹ̀bẹ̀ púpọ̀ rọ̀ wá ní ti ẹ̀bùn àtinúwá yìí, láti ba à lè ní ìpín nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn mímọ́.
de bad oss inntrengende om å få lov til å være med i hjelpen til de hellige;
5 Àti èyí, kì í ṣe bí àwa tí rò rí, ṣùgbọ́n wọ́n tètè kọ́ fi àwọn fúnra wọn fún Olúwa, àti fún wá, nípa ìfẹ́ Ọlọ́run.
og de gav ikke bare således som vi håpet, men de gav sig selv først til Herren og til oss ved Guds vilje,
6 Tó bẹ́ẹ̀ tí àwa fi gba Titu níyànjú pé, bí ó tí bẹ̀rẹ̀ náà, bẹ́ẹ̀ ni kí ó sì parí ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ yìí nínú yín pẹ̀lú.
så vi bad Titus at likesom han før hadde begynt, således skulde han fullende hos eder også dette kjærlighetsverk.
7 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin ti pọ̀ lóhùn gbogbo, ní ìgbàgbọ́, àti ọ̀rọ̀ àti ìmọ̀, àti nínú iṣẹ́ ìyìnrere gbogbo, àti ní ìfẹ́ yín sí wa, ẹ rí i wí pé ẹ̀yin pọ̀ sí i nínú ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ yìí pẹ̀lú.
Men likesom I er rike i alle måter, på tro og på tale og på kunnskap og på all iver og på kjærlighet som I har vakt hos oss, så bli nu og rike i dette kjærlighetsverk!
8 Kì í ṣe nípa àṣẹ ni mo fi ń sọ ọ́, ṣùgbọ́n kí a lè rí ìdí òtítọ́ ìfẹ́ yín pẹ̀lú, nípa iṣẹ́ ìyìnrere ẹlòmíràn.
Dette sier jeg ikke som et bud, men ved andres iver vil jeg også prøve ektheten av eders kjærlighet.
9 Nítorí ẹ̀yin mọ oore-ọ̀fẹ́ Olúwa wa Jesu Kristi, pé bí òun ti jẹ́ ọlọ́rọ̀ rí ṣùgbọ́n nítorí yín ó di tálákà kí a lè sọ yín di ọlọ́rọ̀ nípa àìní rẹ̀.
For I kjenner vår Herre Jesu Kristi nåde, at han for eders skyld blev fattig da han var rik, forat I ved hans fattigdom skulde bli rike.
10 Àti nínú èyí ni mo fi ìmọ̀ràn mi fún yín, nítorí èyí ṣe àǹfààní fún yín, ẹ̀yin tí ó kọ́kọ́ bẹ̀rẹ̀ níwọ̀n ọdún tí ó kọjá, kì í ṣe láti ṣe nǹkan, ṣùgbọ́n láti fẹ́ pẹ̀lú.
Og jeg sier min mening i denne sak; for dette er til gagn for eder, I som alt før, fra ifjor av, begynte ikke bare å virke, men og å ville.
11 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ parí ṣíṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú; kí ó ba à lè ṣe pé, bí ìpinnu fún ṣíṣe ti wà, bẹ́ẹ̀ ni kí ìparí sì wà láti inú agbára yín.
Men fullfør nu også verket, forat fullførelsen må svare til viljens redebonhet, efter eders evne!
12 Nítorí bí ìpinnu bá wà ṣáájú, ó jásí ìtẹ́wọ́gbà gẹ́gẹ́ bí ohun tí ènìyàn bá ní, kì í ṣe gẹ́gẹ́ bí ohun tí kò ní.
For er redebonheten forhånden, da er den velbehagelig efter det den har, og ikke efter det den ikke har.
13 Nítorí èmi kò fẹ́ kí àwọn ẹlòmíràn wà ní ìrọ̀rùn, kí ó sì jẹ́ ìpọ́njú fún yín, ṣùgbọ́n pé nípa mímú dọ́gba.
For dette sier jeg, ikke forat andre skal ha lettelse og I trengsel,
14 Ní àkókò yìí, pé kí àníṣẹ́kù yín lè ṣe déédé àìní wọn, kí àníṣẹ́kù tiwọn pẹ̀lú ba à lè ṣe déédé àìní yín, kí ìmúdọ́gba ba à lè wà.
men forat det skal være likelighet; i den nuværende tid kommer eders overflod deres trang til hjelp, forat også deres overflod må komme eders trang til hjelp, forat det må være likelighet,
15 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Ẹni tí ó kó púpọ̀ kò ní púpọ̀ jù, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó kó ìwọ̀nba kò ní kéré jù.”
som skrevet står: Den som sanket meget, hadde ikke overflod, og den som sanket lite, hadde ikke trang.
16 Ṣùgbọ́n ọpẹ́ ní fún Ọlọ́run ẹni tí ó fi ìtara àníyàn kan náà yìí sí ọkàn Titu fún yín.
Men Gud være takk, som har inngitt den samme iver for eder i Titus' hjerte!
17 Nítorí kì í ṣe pé òun gba ọ̀rọ̀ ìyànjú wa nìkan ni; ṣùgbọ́n bí òun ti ní ìtara púpọ̀, òun tìkára rẹ̀ tọ̀ yín wá, fúnra rẹ̀.
for han tok gjerne imot min tilskyndelse, ja, hans iver er så stor at han av egen drift drar ut til eder.
18 Àwa ti rán arákùnrin náà pẹ̀lú rẹ̀, ìyìn ẹni tí ó wà nínú ìyìnrere yíká gbogbo ìjọ.
Og med ham sender vi og den bror som ved sin virksomhet for evangeliet har vunnet ros i alle menigheter,
19 Kì í sì í ṣe bẹ́ẹ̀ nìkan, ṣùgbọ́n ẹni tí a tí yàn wá pẹ̀lú láti ọ̀dọ̀ ìjọ láti máa bá wa rìn kiri nínú ọ̀rọ̀ oore-ọ̀fẹ́ yìí, tí àwa ń ṣe ìránṣẹ́ rẹ̀ fún ògo Olúwa àti ìmúra ìtara wa.
Og ikke bare det, men som også er valgt av menighetene til å reise sammen med oss med denne kjærlighetsgave som kommer i stand ved vår tjeneste, for å fremme Herrens egen ære og vår redebonhet;
20 Àwa ń yẹra fún èyí, kí ẹnikẹ́ni má ba à rí wí sí wa ní ti ẹ̀bùn àtinúwá yìí tí àwa pín.
for derved undgår vi at nogen skal kunne laste oss for noget som vedkommer denne rike gave som kommer i stand ved vår tjeneste,
21 Àwa ń gbèrò ohun rere, kì í ṣe níwájú Olúwa nìkan, ṣùgbọ́n níwájú ènìyàn pẹ̀lú.
da vi legger vinn på det som er godt, ikke alene i Herrens, men og i menneskers øine.
22 Àwa sì ti rán arákùnrin wa pẹ̀lú wọn, ẹni tí àwa rí dájú nígbà púpọ̀ pé ó ní ìtara nínú ohun púpọ̀, ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí ni ìtara rẹ̀ túbọ̀ pọ̀ sí i nípa ìfọkàntán ńlá tí ó ní sí yín.
Og med dem sender vi vår bror, som vi ofte på mange måter har funnet ivrig, men nu meget ivrigere på grunn av den store tillit han har til eder.
23 Bí ẹnikẹ́ni bá béèrè ẹni tí Titu jẹ́, ẹlẹgbẹ́ àti olùbáṣiṣẹ́ mi ni, nítorí yín; tàbí ní ti àwọn arákùnrin wa ni ẹnikẹ́ni ń béèrè, ìránṣẹ́ ìjọ ni wọ́n jẹ́, àti ògo Kristi.
Hvad enten det da gjelder Titus, så er han min medbroder og medarbeider hos eder, eller det gjelder våre brødre, så er de menighetsutsendinger, Kristi ære.
24 Nítorí náà ẹ fi ẹ̀rí ìfẹ́ yín hàn wọ́n níwájú ìjọ, àti ìṣògo wa nítorí yín.
Så vis dem altså sannheten av eders kjærlighet og av den ros vi har gitt eder, for menighetenes åsyn!

< 2 Corinthians 8 >