< 2 Corinthians 8 >

1 Pẹ̀lúpẹ̀lú, ará, àwa ń sọ fún yín ní ti oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run tí a fífún àwọn ìjọ Makedonia.
Na, he whakarite atu tenei na matou ki a koutou, e oku teina, i te aroha noa o te Atua kua homai nei ki nga hahi o Makeronia;
2 Bí ó ti jẹ́ pé a dán wọn wò nípa ìpọ́njú, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ayọ̀ àti àìlódiwọ̀n àìní wọn ti kún àkúnwọ́sílẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ ìlawọ́ wọn.
Ahakoa he nui te whakamatautauranga a nga mate, whakaputaina nuitia ana mai e te nui o to ratou koa, i roto i to ratou tino rawakoretanga, nga tahua o ta ratou manaaki.
3 Nítorí mo jẹ́rìí pé gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, àní ju agbára wọn, wọ́n ṣe é láti ìfẹ́ inú ara wọn.
Ko ahau hei kaiwhakaatu, hihiko tonu ratou ki te tapae i nga mea i taea e ratou, ae ra, i nga mea ano kihai i taea e ratou;
4 Wọ́n ń fi ẹ̀bẹ̀ púpọ̀ rọ̀ wá ní ti ẹ̀bùn àtinúwá yìí, láti ba à lè ní ìpín nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn mímọ́.
Me te nui o ta ratou tohe ki a matou, kia manako matou ki tenei aroha noa, kia uru tahi hoki ki te mahi ki te hunga tapu:
5 Àti èyí, kì í ṣe bí àwa tí rò rí, ṣùgbọ́n wọ́n tètè kọ́ fi àwọn fúnra wọn fún Olúwa, àti fún wá, nípa ìfẹ́ Ọlọ́run.
Kihai hoki ratou i pera me ta matou i whakaaro ai, engari i te tuatahi tuku ana ratou i a ratou ano ki te Ariki, ki a matou hoki i runga i ta te Atua i pai ai.
6 Tó bẹ́ẹ̀ tí àwa fi gba Titu níyànjú pé, bí ó tí bẹ̀rẹ̀ náà, bẹ́ẹ̀ ni kí ó sì parí ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ yìí nínú yín pẹ̀lú.
Koia matou i whakahau ai i a Taituha, nana hoki tena mahi i timata, mana ano e whakaoti tenei aroha noa hoki i roto i a koutou.
7 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin ti pọ̀ lóhùn gbogbo, ní ìgbàgbọ́, àti ọ̀rọ̀ àti ìmọ̀, àti nínú iṣẹ́ ìyìnrere gbogbo, àti ní ìfẹ́ yín sí wa, ẹ rí i wí pé ẹ̀yin pọ̀ sí i nínú ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ yìí pẹ̀lú.
Na, e hua na i a koutou nga mea katoa, te whakapono, te whai kupu, te matauranga, te whakaaro hohonu, me to koutou aroha ano ki a matou, kia hua ano hoki tenei mahi aroha noa a koutou.
8 Kì í ṣe nípa àṣẹ ni mo fi ń sọ ọ́, ṣùgbọ́n kí a lè rí ìdí òtítọ́ ìfẹ́ yín pẹ̀lú, nípa iṣẹ́ ìyìnrere ẹlòmíràn.
Ehara taku i te korero a ture, engari he mea i te kakama o era atu, hei whakamatautau ano i te pono o to koutou aroha.
9 Nítorí ẹ̀yin mọ oore-ọ̀fẹ́ Olúwa wa Jesu Kristi, pé bí òun ti jẹ́ ọlọ́rọ̀ rí ṣùgbọ́n nítorí yín ó di tálákà kí a lè sọ yín di ọlọ́rọ̀ nípa àìní rẹ̀.
E matau ana hoki koutou ki te aroha noa o to tatou Ariki, o Ihu Karaiti, ara i a ia e whai taonga ana, whakarawakoretia iho ana ia, he whakaaro ki a koutou, kia whai taonga ai koutou i tona rawakoretanga.
10 Àti nínú èyí ni mo fi ìmọ̀ràn mi fún yín, nítorí èyí ṣe àǹfààní fún yín, ẹ̀yin tí ó kọ́kọ́ bẹ̀rẹ̀ níwọ̀n ọdún tí ó kọjá, kì í ṣe láti ṣe nǹkan, ṣùgbọ́n láti fẹ́ pẹ̀lú.
A ka hoatu nei ahau i toku whakaaro mo tenei: he mea pai hoki tenei mo koutou, ko koutou na te tuatahi ki te timata i tera tau, ehara i te mea ko te mahi anake, engari ko te hiahia ano hoki.
11 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ parí ṣíṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú; kí ó ba à lè ṣe pé, bí ìpinnu fún ṣíṣe ti wà, bẹ́ẹ̀ ni kí ìparí sì wà láti inú agbára yín.
Na inaianei whakaotia hoki te mahi; i hihiko na te whakaaro i mua, kia whai otinga hoki i roto i to koutou kaha.
12 Nítorí bí ìpinnu bá wà ṣáájú, ó jásí ìtẹ́wọ́gbà gẹ́gẹ́ bí ohun tí ènìyàn bá ní, kì í ṣe gẹ́gẹ́ bí ohun tí kò ní.
Ki te mea hoki kei kona te ngakau hihiko, ka whakaaroa ko nga mea i te tangata, haunga nga mea kahore i a ia.
13 Nítorí èmi kò fẹ́ kí àwọn ẹlòmíràn wà ní ìrọ̀rùn, kí ó sì jẹ́ ìpọ́njú fún yín, ṣùgbọ́n pé nípa mímú dọ́gba.
Ehara taku korero i tenei, kia mama ai etahi, a ko koutou kia taimaha;
14 Ní àkókò yìí, pé kí àníṣẹ́kù yín lè ṣe déédé àìní wọn, kí àníṣẹ́kù tiwọn pẹ̀lú ba à lè ṣe déédé àìní yín, kí ìmúdọ́gba ba à lè wà.
Engari kia taurite; ko nga mea a koutou i hira i tenei wa hei mea mo to ratou hapa, a ko nga mea a ratou e hira hei mea ma koutou ina hapa; kia rite ai:
15 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Ẹni tí ó kó púpọ̀ kò ní púpọ̀ jù, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó kó ìwọ̀nba kò ní kéré jù.”
Kia pera me te mea i tuhituhia, Ko te tangata i nui tana whakaemi kahore he tuhene; ko te tangata i nohinohi tana kihai i hapa.
16 Ṣùgbọ́n ọpẹ́ ní fún Ọlọ́run ẹni tí ó fi ìtara àníyàn kan náà yìí sí ọkàn Titu fún yín.
Otiia me whakawhetai atu ki te, Atua, nana nei i homai ki roto ki te ngakau o Taituha taua kakama mo koutou.
17 Nítorí kì í ṣe pé òun gba ọ̀rọ̀ ìyànjú wa nìkan ni; ṣùgbọ́n bí òun ti ní ìtara púpọ̀, òun tìkára rẹ̀ tọ̀ yín wá, fúnra rẹ̀.
I tahuri mai hoki ia ki ta matou whakahau; he nui no tona kakama i hihiko ai ia ki te haere atu ki a koutou.
18 Àwa ti rán arákùnrin náà pẹ̀lú rẹ̀, ìyìn ẹni tí ó wà nínú ìyìnrere yíká gbogbo ìjọ.
A na matou i tono tahi atu me ia te teina, ka paku nei ki nga hahi katoa te whakamoemiti ki a ia i roto i te rongopai;
19 Kì í sì í ṣe bẹ́ẹ̀ nìkan, ṣùgbọ́n ẹni tí a tí yàn wá pẹ̀lú láti ọ̀dọ̀ ìjọ láti máa bá wa rìn kiri nínú ọ̀rọ̀ oore-ọ̀fẹ́ yìí, tí àwa ń ṣe ìránṣẹ́ rẹ̀ fún ògo Olúwa àti ìmúra ìtara wa.
A ehara i te mea ko tera anake, engari i whiriwhiria ano hoki ia hei hoa haere mo matou, ki te kawe i tenei aroha noa e mahia nei e matou hei whakakororia mo te Ariki, hei whakakite hoki i to matou hihiko:
20 Àwa ń yẹra fún èyí, kí ẹnikẹ́ni má ba à rí wí sí wa ní ti ẹ̀bùn àtinúwá yìí tí àwa pín.
Me te tupato ano, kei whai kupu tetahi tangata ki a matou mo enei taonga maha e whakahaerea nei e matou:
21 Àwa ń gbèrò ohun rere, kì í ṣe níwájú Olúwa nìkan, ṣùgbọ́n níwájú ènìyàn pẹ̀lú.
E whakaaro ana hoki matou ki nga mea rangatira, ehara i te mea i te aroaro anake o te Ariki, engari i te aroaro ano o nga tangata.
22 Àwa sì ti rán arákùnrin wa pẹ̀lú wọn, ẹni tí àwa rí dájú nígbà púpọ̀ pé ó ní ìtara nínú ohun púpọ̀, ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí ni ìtara rẹ̀ túbọ̀ pọ̀ sí i nípa ìfọkàntán ńlá tí ó ní sí yín.
A kua tonoa atu ano e matou hei hoa mo raua to matou teina, kua maha nei o matou kitenga i tona uaua i nga mea maha, heoi nui ke atu tona uaua inaianei, na te nui o te u o tona whakaaro ki a koutou.
23 Bí ẹnikẹ́ni bá béèrè ẹni tí Titu jẹ́, ẹlẹgbẹ́ àti olùbáṣiṣẹ́ mi ni, nítorí yín; tàbí ní ti àwọn arákùnrin wa ni ẹnikẹ́ni ń béèrè, ìránṣẹ́ ìjọ ni wọ́n jẹ́, àti ògo Kristi.
Ki te ui tetahi mo Taituha, ko ia toku hoa, he hoa mahi noku ki a koutou: ki te ui ranei mo o matou teina, he karere ratou na nga hahi, he kororia no te Karaiti.
24 Nítorí náà ẹ fi ẹ̀rí ìfẹ́ yín hàn wọ́n níwájú ìjọ, àti ìṣògo wa nítorí yín.
Na, whakakitea e koutou ki a ratou i te aroaro o nga hahi te tohu o to koutou aroha, o ta matou whakamanamana hoki mo koutou.

< 2 Corinthians 8 >