< 2 Corinthians 6 >
1 Gẹ́gẹ́ bí alábáṣiṣẹ́pọ̀ nínú Ọlọ́run, ǹjẹ́, àwa ń rọ̀ yín kí ẹ má ṣe gba oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run lásán.
Puisque nous faisons l'oeuvre avec Dieu, nous vous exhortons à ne pas recevoir la grâce de Dieu en vain,
2 Nítorí o wí pé, “Ní àkókò ìtẹ́wọ́gbà mi, èmi tí gbọ́ ohùn rẹ, àti ọjọ́ ìgbàlà, èmi sì ti ràn ọ́ lọ́wọ́.” Èmi wí fún ọ, nísinsin yìí ní àkókò ìtẹ́wọ́gbà, nísinsin yìí ni ọjọ́ ìgbàlà.
car il dit: «Je t’ai exaucé au temps favorable; je t'ai porté secours au jour du salut.» Voici, c'est aujourd'hui «le temps particulièrement favorable; » voici, c'est aujourd'hui «le jour du salut.»
3 Àwa kò sì gbé ohun ìkọ̀sẹ̀ kankan si ọ̀nà ẹnikẹ́ni, ki iṣẹ́ ìránṣẹ́ wa má ṣe di ìsọ̀rọ̀-òdì sí.
Nous faisons cette oeuvre, en ne donnant aucun sujet de scandale en quoi que ce soit, afin que notre ministère ne soit l'objet d'aucun blâme.
4 Ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀, ni ọnà gbogbo, àwa ń fi ara wa hàn bí àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ sùúrù, nínú ìpọ́njú, nínú àìní, nínú wàhálà,
Nous nous rendons recommandables sous tous les rapports, comme le doivent des ministres de Dieu, par une grande patience dans les afflictions, dans les nécessités, dans les extrêmes misères,
5 nípa nínà, nínú túbú, nínú ìrúkèrúdò, nínú iṣẹ́ àṣekára, nínú àìsàn, nínú ìgbààwẹ̀.
sous les coups, dans les prisons, dans les troubles, dans les travaux, dans les veilles, dans les jeûnes,
6 Nínú ìwà mímọ́, nínú ìmọ̀, nínú ìpamọ́ra, nínú ìṣeun, nínú Ẹ̀mí Mímọ́, nínú ìfẹ́ àìṣẹ̀tàn.
par la pureté, par la science, par la longanimité, par la bonté, par un esprit saint, par une charité sincère,
7 Nínú ọ̀rọ̀ òtítọ́, nínú agbára Ọlọ́run, nínú ìhámọ́ra òdodo ní apá ọ̀tún àti ní apá òsì.
par la parole de vérité, par la puissance de Dieu; maniant de la droite et de la gauche les armes de la justice,
8 Nípa ọlá àti ẹ̀gàn, nípa ìyìn búburú àti ìyìnrere: bí ẹlẹ́tàn, ṣùgbọ́n a jásí olóòtítọ́,
tirant parti de la gloire et de l'ignominie, de la bonne et de la mauvaise réputation; tenus pour imposteurs, bien que véridiques;
9 bí ẹni tí a kò mọ̀, ṣùgbọ́n a mọ̀ wá dájúdájú; bí ẹni tí ń kú lọ, ṣùgbọ́n a ṣì wà láààyè; bí ẹni tí a nà, ṣùgbọ́n a kò sì pa wá,
pour inconnus, quoique bien connus; pour mourants, et voilà que nous vivons; pour châtiés, et pourtant nous ne sommes pas mis à mort;
10 bí ẹni tí ó kún fún ìbànújẹ́, ṣùgbọ́n àwa ń yọ̀ nígbà gbogbo; bí tálákà, ṣùgbọ́n àwa ń sọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ dí ọlọ́rọ̀; bí ẹni tí kò ní nǹkan, ṣùgbọ́n àwa ni ohun gbogbo.
pour tristes, nous qui sommes toujours joyeux; pour pauvres, nous qui en enrichissons bon nombre; pour n'ayant rien, nous qui avons tout.
11 Ẹ̀yin ará Kọrinti, a ti bá yín sọ òtítọ́ ọ̀rọ̀, a ṣí ọkàn wa páyà sí yín.
Notre bouche s'est ouverte pour vous, ô Corinthiens, notre coeur s'est élargi:
12 Àwa kò fa ìfẹ́ wa sẹ́yìn fún yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin fa ìfẹ́ yín sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ wa.
vous n'êtes point à l'étroit au dedans de nous, tandis que nous sommes à l'étroit dans votre affection.
13 Ní sísán padà, ní ọ̀nà tí ó dára, èmi ń sọ bí ẹni pé fún àwọn ọmọdé, ẹ̀yin náà ẹ ṣí ọkàn yín páyà pẹ̀lú.
Rendez-nous la pareille; je vous parle comme à mes enfants; vous aussi, élargissez vos coeurs.
14 Ẹ má ṣe fi àìdọ́gba dàpọ̀ pẹ̀lú àwọn aláìgbàgbọ́, nítorí ìdàpọ̀ kín ni òdodo ní pẹ̀lú àìṣòdodo? Ìdàpọ̀ kín ni ìmọ́lẹ̀ sì ní pẹ̀lú òkùnkùn?
Ne vous unissez point aux infidèles, car quelle parenté ya-t-il entre la justice et l'iniquité? ou, qu'a de commun la lumière avec les ténèbres?
15 Ìrẹ́pọ̀ kín ni Kristi ní pẹ̀lú Beliali? Tàbí ìpín wó ni ẹni tí ó gbàgbọ́ ní pẹ̀lú aláìgbàgbọ́?
Quel accord y a-t-il entre Christ et Bélial? ou, quel rapport y a-t-il entre le fidèle et l'infidèle?
16 Ìrẹ́pọ̀ kín ni tẹmpili Ọlọ́run ní pẹ̀lú òrìṣà? Nítorí ẹ̀yin ní tẹmpili Ọlọ́run alààyè; gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti wí pé: “Èmi á gbé inú wọn, èmi o sì máa rìn láàrín wọn, èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, wọn yóò sì jẹ́ ènìyàn mi.”
Quelle compatibilité y a-t-il entre le temple de Dieu et les idoles? car nous sommes le temple du Dieu vivant, comme Dieu l’a dit: «J'habiterai et je marcherai au milieu d'eux; je serai leur Dieu et ils seront mon peuple.
17 Nítorí náà, “Ẹ jáde kúrò láàrín wọn, kí ẹ sì yá ara yín si ọ̀tọ̀, ni Olúwa wí. Ki ẹ má ṣe fi ọwọ́ kan ohun àìmọ́; Èmi ó sì gbà yín.”
C'est pourquoi, sortez du milieu d'eux et séparez-vous d'eux, dit le Seigneur. Ne touchez point à ce qui est impur, et moi je vous adopterai:
18 Àti, “Èmi o sì jẹ́ Baba fún yín. Ẹ̀yin ó sì jẹ́ ọmọkùnrin mi àti ọmọbìnrin mi, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
je serai pour vous un père, et vous serez pour moi des fils et des filles, dit le Seigneur tout-puissant. »