< 2 Corinthians 5 >
1 Nítorí àwa mọ̀ pé, bi ilé àgọ́ wa ti ayé ba wó, àwa ní ilé kan láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run, ilé tí a kò fi ọwọ́ kọ́, ti ayérayé nínú àwọn ọ̀run. (aiōnios )
For we know that if this poor tent, our earthly house, is taken down, we have in Heaven a building which God has provided, a house not built by human hands, but eternal. (aiōnios )
2 Nítorí nítòótọ́ àwa ń kérora nínú èyí, àwa sì ń fẹ́ gidigidi láti fi ilé wa ti ọ̀run wọ̀ wá.
For in this one we sigh, because we long to put on over it our dwelling which comes from Heaven--
3 Bí ó bá ṣe pé a ti fi wọ̀ wá, a kì yóò bá wa ní ìhòhò.
if indeed having really put on a robe we shall not be found to be unclothed.
4 Nítorí àwa tí a ń bẹ nínú àgọ́ yìí ń kérora nítòótọ́, kì í ṣe nítorí tí àwa fẹ́ jẹ́ aláìwọṣọ, ṣùgbọ́n pé a ó wọ̀ wá ní aṣọ sí i, kí ìyè ba à lè gbé ara kíkú mì.
Yes, we who are in this tent certainly do sigh under our burdens, for we do not wish to lay aside that with which we are now clothed, but to put on more, so that our mortality may be absorbed in Life.
5 Ǹjẹ́ ẹni tí ó ti pèsè wa fún nǹkan yìí ni Ọlọ́run, ẹni tí o sì ti fi Ẹ̀mí fún wa pẹ̀lú ni ẹ̀rí ìdánilójú ohun tí ń bọ̀.
And He who formed us with this very end in view is God, who has given us His Spirit as a pledge and foretaste of that bliss.
6 Nítorí náà àwa ní ìgboyà nígbà gbogbo, àwa sì mọ̀ pé, nígbà tí àwa ń bẹ ní ilé nínú ara, àwa kò sí lọ́dọ̀ Olúwa.
We have therefore a cheerful confidence. We know that while we are at home in the body we are banished from the Lord;
7 Àwa ń gbé nípa ìgbàgbọ́, kì í ṣe nípa rí rí.
for we are living a life of faith, and not one of sight.
8 Mo ní, àwa ní ìgboyà, àwa sì ń fẹ́ kí a kúkú ti inú ara kúrò, kí a sì lè wà ní ilé lọ́dọ̀ Olúwa.
So we have a cheerful confidence, and we anticipate with greater delight being banished from the body and going home to the Lord.
9 Nítorí náà àwa ń ṣakitiyan, pé, bí àwa bá wà ní ilé tàbí bí a kò sí, kí àwa lè jẹ́ ẹni ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ rẹ̀.
And for this reason also we make it our ambition, whether at home or in exile, to please Him perfectly.
10 Nítorí pé gbogbo wa ni ó gbọdọ̀ fi ara hàn níwájú ìtẹ́ ìdájọ́ Kristi; kí olúkúlùkù lè gbà èyí tí ó ṣe gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó tọ́ sí i nígbà tí ó wà nínú ara ìbá à ṣe rere tàbí búburú.
For we must all of us appear before Christ's judgement-seat in our true characters, in order that each may then receive an award for his actions in this life, in accordance with what he has done, whether it be good or whether it be worthless.
11 Nítorí náà bí àwa ti mọ ẹ̀rù Olúwa, àwa ń yí ènìyàn lọ́kàn padà; ṣùgbọ́n a ń fi wá hàn fún Ọlọ́run; mo sì gbàgbọ́ pé, a sì ti fì wá hàn ní ọkàn yín pẹ̀lú.
Therefore, because we realize how greatly the Lord is to be feared, we are endeavouring to win men over, and God recognizes what our motives are, and I hope that you, in your hearts, recognize them too.
12 Nítorí àwa kò sì ní máa tún yin ara wá sí i yín mọ́, ṣùgbọ́n àwa fi ààyè fún yín láti máa ṣògo nítorí wa, kí ẹ lè ní ohun tí ẹ̀yin yóò fi dá wọn lóhùn, àwọn ti ń ṣògo lóde ara kì í ṣe ní ọkàn.
We are not again commending ourselves to your favour, but are furnishing you with a ground of boasting on our behalf, so that you may have a reply ready for those with whom superficial appearances are everything and sincerity of heart counts for nothing.
13 Nítorí náà bí àwa bá ń sínwín, fún Ọlọ́run ni tàbí bí iyè wá bá ṣí pépé, fún yín ni.
For if we have been beside ourselves, it has been for God's glory; or if we are now in our right senses, it is in order to be of service to you.
14 Nítorí ìfẹ́ Kristi ń rọ̀ wá, nítorí àwa mọ̀ báyìí pé, bí ẹnìkan bá kú fún gbogbo ènìyàn, ǹjẹ́ nígbà náà, gbogbo wọ́n ni ó ti kú.
For the love of Christ overmasters us, the conclusion at which we have arrived being this--that One having died for all, His death was their death,
15 Ó sì ti kú fún gbogbo wọn, pé kí àwọn tí ó wà láààyè má sì ṣe wà láààyè fún ara wọn mọ́, bí kò ṣe fún ẹni tí ó kú nítorí wọn, tí ó sì ti jíǹde.
and that He died for all in order that the living may no longer live to themselves, but to Him who died for them and rose again.
16 Nítorí náà láti ìsinsin yìí lọ, àwa kò mọ ẹnìkan nípa ti ara mọ́; bí àwa tilẹ̀ ti mọ Kristi nípa ti ara, ṣùgbọ́n nísinsin yìí àwa kò mọ̀ ọ́n bẹ́ẹ̀ mọ́.
Therefore for the future we know no one simply as a man. Even if we have known Christ as a man, yet now we do so no longer.
17 Nítorí náà bí ẹnìkan bá wà nínú Kristi, ó di ẹ̀dá tuntun: ohun àtijọ́ ti kọjá lọ; kíyèsi i, ohun tuntun ti dé.
So that if any one is in Christ, he is a new creature: the old state of things has passed away; a new state of things has come into existence.
18 Ohun gbogbo sì ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, ẹni tí ó sì tipasẹ̀ Jesu Kristi bá wa làjà sọ́dọ̀ ara rẹ̀, tí ó sì ti fi iṣẹ́ ìránṣẹ́ ìlàjà fún wa.
And all this is from God, who has reconciled us to Himself through Christ, and has appointed us to serve in the ministry of reconciliation.
19 Èyí ni pé, Ọlọ́run wà nínú Kristi, ó ń bá aráyé làjà sọ́dọ̀ ara rẹ̀, kò sí ka ìrékọjá wọn sí wọn lọ́rùn; ó sì ti fi ọ̀rọ̀ ìlàjà lé wa lọ́wọ́.
We are to tell how God was in Christ reconciling the world to Himself, not charging men's transgressions to their account, and that He has entrusted to us the Message of this reconciliation.
20 Nítorí náà àwa ni ikọ̀ fún Kristi, bí ẹni pé Ọlọ́run ń ti ọ̀dọ̀ wa ṣìpẹ̀ fún yín: àwa ń bẹ̀ yín ní ipò Kristi, “Ẹ bá Ọlọ́run làjà.”
On Christ's behalf therefore we come as ambassadors, God, as it were, making entreaty through our lips: we, on Christ's behalf, beseech men to be reconciled to God.
21 Nítorí ó tí fi í ṣe ẹ̀ṣẹ̀ nítorí wa, ẹni tí kò mọ ẹ̀ṣẹ̀kẹ́ṣẹ̀ rí, kí àwa lè di òdodo Ọlọ́run nínú rẹ̀.
He has made Him who knew nothing of sin to be sin for us, in order that in Him we may become the righteousness of God.