< 2 Corinthians 3 >

1 Àwa ha tún bẹ̀rẹ̀ láti máa yín ara wá bí? Tàbí àwa ha ń fẹ́ ìwé ìyìn sọ́dọ̀ yín, tàbí láti ọ̀dọ̀ yín gẹ́gẹ́ bí ẹlòmíràn tí ń ṣe?
Do you say that this is self-recommendation once more? Or do we need, as some do, letters of recommendation to you or from you?
2 Ẹ̀yin fúnra yín ni ìwé ìyìn wa, tí a ti kọ sí yín ní ọkàn, ti gbogbo ènìyàn mọ̀, tí wọ́n sì ń kà.
Our letter of recommendation is yourselves--a letter written on our hearts and everywhere known and read.
3 Ẹ̀yin sì ń fihàn pé ìwé tí a gbà sílẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Kristi ni yín, kì í ṣe èyí tí a sì fi jẹ́lú kọ, bí kò sẹ Ẹ̀mí Ọlọ́run alààyè, kì í ṣe nínú wàláà òkúta bí kò ṣe nínú wàláà ọkàn ẹran.
For all can see that you are a letter of Christ entrusted to our care, and written not with ink, but with the Spirit of the ever-living God--and not on tablets of stone, but on human hearts as tablets.
4 Irú ìgbẹ́kẹ̀lé yìí ni àwa ní nípasẹ̀ Kristi sọ́dọ̀ Ọlọ́run,
Such is the confidence which we have through Christ in the presence of God;
5 kì í ṣe pé àwa tó fún ara wa láti ṣírò ohunkóhun bí ẹni pé láti ọ̀dọ̀ àwa tìkára wa; ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní tító wà,
not that of ourselves we are competent to decide anything by our own reasonings, but our competency comes from God.
6 Ẹni tí ó mú wa yẹ bí ìránṣẹ́ májẹ̀mú tuntun; kì í ṣe ní ti ìwé àkọsílẹ̀ ṣùgbọ́n ní ti ẹ̀mí, nítorí ìwé a máa pa ni, ṣùgbọ́n ẹ̀mí a máa sọ ní di ààyè.
It is He also who has made us competent to serve Him in connexion with a new Covenant, which is not a written code but a Spirit; for the written code inflicts death, but the Spirit gives Life.
7 Ṣùgbọ́n bí iṣẹ́ ìránṣẹ́ tí ikú, tí a tí kọ tí a sì ti gbẹ́ sí ara òkúta bá jẹ́ ológo tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ọmọ Israẹli kò lè tẹjúmọ́ wíwo ojú Mose nítorí ògo ojú rẹ̀ (ògo ti ń kọjá lọ);
If, however, the service that proclaims death--its code being engraved in writing upon stones--came with glory, so that the children of Israel could not look steadily on the face of Moses because of the brightness of his face--a vanishing brightness;
8 yóò ha ti rí tí iṣẹ́ ìránṣẹ́ ti ẹ̀mí kì yóò kúkú jẹ́ ògo jù?
will not the service of the Spirit be far more glorious?
9 Nítorí pé bi iṣẹ́ ìránṣẹ́ ìdálẹ́bi bá jẹ́ ológo, mélòó mélòó ni iṣẹ́ ìránṣẹ́ òdodo yóò tayọ jù ú ní ògo.
For if the service which pronounces doom had glory, far more glorious still is the service which tells of righteousness.
10 Nítorí, èyí tí a tí ṣe lógo rí, kó lógo mọ́ báyìí, nítorí ògo tí ó tayọ.
For, in fact, that which was once resplendent in glory has no glory at all in this respect, that it pales before the glory which surpasses it.
11 Nítorí pé bí èyí ti ń kọjá lọ bá lógo, mélòó mélòó ni èyí tí ó dúró kí yóò ní ògo!
For if that which was to be abolished came with glory, much more is that which is permanent arrayed in glory.
12 Ǹjẹ́ nítorí náà bí a tí ní irú ìrètí bí èyí, àwa ń fi ìgboyà púpọ̀ sọ̀rọ̀.
Therefore, cherishing a hope like this, we speak without reserve, and we do not imitate Moses,
13 Kì í sì í ṣe bí Mose, ẹni tí ó fi ìbòjú bo ojú rẹ̀, ki àwọn ọmọ Israẹli má ba à lè tẹjúmọ́ wíwo òpin èyí tí ń kọjá lọ.
who used to throw a veil over his face to hide from the gaze of the children of Israel the passing away of what was but transitory.
14 Ṣùgbọ́n ojú inú wọn fọ́; nítorí pé títí fi di òní olónìí nípa kíka májẹ̀mú láéláé, ìbòjú kan náà ṣì wà láìká kúrò; nítorí pé nínú Kristi ni a tí lè mú ìbòjú náà kúrò.
Nay, their minds were made dull; for to this very day during the reading of the book of the ancient Covenant, the same veil remains unlifted, because it is only in Christ that it is to be abolished.
15 Ṣùgbọ́n títí di òní olónìí, nígbàkígbà ti a bá ń ka Mose, ìbòjú náà ń bẹ lọ́kàn wọn.
Yes, to this day, whenever Moses is read, a veil lies upon their hearts.
16 Ṣùgbọ́n nígbà ti òun bá yípadà sí Olúwa, a ó mú ìbòjú náà kúrò.
But whenever the heart of the nation shall have returned to the Lord, the veil will be withdrawn.
17 Ǹjẹ́ Olúwa ni Ẹ̀mí náà: níbi tí Ẹ̀mí Olúwa bá sì wà, níbẹ̀ ni òmìnira gbé wà.
Now by "the Lord" is meant the Spirit; and where the Spirit of the Lord is, freedom is enjoyed.
18 Ṣùgbọ́n gbogbo wa ń wo ògo Olúwa láìsí ìbòjú bí ẹni pé nínú àwòjìji, a sì ń pa wa dà sí àwòrán kan náà láti ògo dé ògo, àní bí láti ọ̀dọ̀ Olúwa tí í ṣe Ẹ̀mí.
And all of us, with unveiled faces, reflecting like bright mirrors the glory of the Lord, are being transformed into the same likeness, from one degree of radiant holiness to another, even as derived from the Lord the Spirit.

< 2 Corinthians 3 >