< 2 Corinthians 2 >

1 Nítorí náà mo tí pinnu nínú ara mí pé, èmi kì yóò tún fi ìbànújẹ́ tọ̀ yin wá.
ⲁ̅ⲫⲁⲓ ⲅⲁⲣ ⲁⲓϯϩⲁⲡ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧ ⳿ⲉ⳿ϣⲧⲉⲙ⳿ⲑⲣⲓ⳿ⲓ ϩⲁⲣⲱⲧⲉⲛ ⲟⲛ ϧⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲙⲕⲁϩ ⳿ⲛϩⲏⲧ.
2 Nítorí pé bí èmi bá mú inú yín bàjẹ́, ǹjẹ́ ta ni ẹni ti ìbá mú inú mí dùn ní àkókò tí inú mi bá bàjẹ́ bí kò ṣe ẹni tí mo ti ba nínú jẹ́?
ⲃ̅ⲓⲥϫⲉ ⲅⲁⲣ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲉⲧϯⲉⲙⲕⲁϩ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲓⲉ ⲛⲓⲙ ⲉⲧ⳿ⲑⲣⲟ ⳿ⲙⲙⲟⲓ ⳿ⲉⲟⲩⲛⲟϥ ⳿ⲉⲃⲏⲗ ⳿ⲉⲫⲏ ⲉⲑⲙⲟⲕϩ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲟⲓ.
3 Èmi sì kọ̀wé bí mo tí kọ sí yín pé, nígbà tí mo bá sì de, kí èmi má ṣe ni ìbànújẹ́ lọ́dọ̀ àwọn ti ìbá mú mi ní ayọ̀, nítorí tí mo ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú gbogbo yín, wí pé ẹ̀yin yóò jẹ́ alábápín ayọ̀ mi.
ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲫⲁⲓ ⲁⲓ⳿ⲥϧⲏⲧϥ ϩⲓⲛⲁ ⲁⲓϣⲁⲛ⳿ⲓ ϩⲁⲣⲱⲧⲉⲛ ⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲁ⳿ϣⲧⲉⲙϭⲓ⳿ⲙⲕⲁϩ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲏ ⲉⲧⲉⲥ⳿ⲙ⳿ⲡϣⲁ ⲛⲏⲓ ⳿ⲛⲧⲁⲣⲁϣⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲉⲣⲉ ⲡⲁϩⲏⲧ ⲑⲏⲧ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲧⲏⲣⲟⲩ ϫⲉ ⲡⲁⲣⲁϣⲓ ⲫⲱⲧⲉⲛ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲡⲉ.
4 Nítorí pé nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàhálà àti ìrora ọkàn mí ni mo ti fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ omijé kọ̀wé sí yín; kì í ṣe nítorí kí a lè bà yín nínú jẹ́, ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin bá a lè mọ bí ìfẹ́ tí mo ní sí yín ṣe jinlẹ̀ tó.
ⲇ̅⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲅⲁⲣ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲛⲓϣϯ ⳿ⲛϩⲟϫϩⲉϫ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲉⲙⲕⲁϩ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲁⲓ⳿ⲥϧⲁⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛⲉⲣⲙⲏ ϫⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛϩⲏ⳿ⲙⲕⲁϩ ⲁⲛ ⲁⲗⲗⲁ ϫⲉⲭⲁⲥ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉϯ ⲁⲅⲁⲡⲏ ⲉⲧⲉⲣϩⲟⲩ⳿ⲟ ⳿ⲛϧⲏⲧ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ.
5 Bí ẹnikẹ́ni bá fa ohun ìbànújẹ́ kì í ṣe èmi ni ó bà nínú jẹ́, bí kò ṣe ẹ̀yin fúnra yín, níwọ̀n ìyówù kí ó jẹ́; n kò fẹ́ sọ ọ́ lọ́nà líle jù.
ⲉ̅ⲓⲥϫⲉ ⲇⲉ ⲁ ⲟⲩⲁⲓ ϯ ⳿ⲙⲕⲁϩ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲛⲉⲧⲁϥϯ ⳿ⲙⲕⲁϩ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲛⲏⲓ ⲁⲛ ⲁⲗⲗⲁ ⲁⲡⲟⲙⲉⲣⲟⲥ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲁ⳿ϣⲧⲉⲙⲟⲩⲁϩⲃⲁⲣⲟⲥ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲧⲏⲣⲟⲩ.
6 Ìyà náà tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ti fi jẹ́ irú ènìyàn bẹ́ẹ̀ tó fún un.
ⲋ̅ⲕⲏⲛ ⳿ⲉⲫⲁⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⳿ ⲉⲧⲁⲓ ⳿ ⲉⲡⲓⲧⲓⲙⲓⲁ ⲑⲁⲓ ⲉⲧⲁⲥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲓⲧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲏϣ.
7 Kàkà bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin ìbá kúkú dáríjì í, kí ẹ sí tù ú nínú ní gbogbo ọ̀nà, kí ìbànújẹ́ má bà á bo irú ènìyàn bẹ́ẹ̀ mọ́lẹ̀.
ⲍ̅ϩⲱⲥⲧⲉ ⲡⲉⲧⲟⲩⲃⲏϥ ⲙⲁⲗⲗⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛⲉⲣ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛϯⲛⲟⲙϯ ⲛⲁϥ ⲙⲏⲡⲱⲥ ϧⲉⲛ ⲡⲓϩⲟⲩ⳿ⲟ ⳿ⲛⲉⲙⲕⲁϩⲛϩⲏⲧ ⳿ⲛⲥⲉⲱⲙⲕ ⳿ⲙⲫⲁⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ.
8 Nítorí náà mo bẹ̀ yín, ẹ fi ìdánilójú ìfẹ́ yín hàn sí irú ẹni náà.
ⲏ̅ⲉⲑⲃⲉⲫⲁⲓ ϯϯϩⲟ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲧⲁϫⲣⲉ ⲟⲩ⳿ⲁⲅⲁⲡⲏ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲣⲟϥ.
9 Ìdí tí mo ṣe kọ̀wé ni kí èmi ba à lè rí ẹ̀rí dìímú nípa ìgbọ́ràn yín nínú ohun gbogbo.
ⲑ̅ⲉⲑⲃⲉⲫⲁⲓ ⲅⲁⲣ ⲁⲓ⳿ⲥϧⲁⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲁ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲇⲟⲕⲓⲙⲏ ⲓⲥϫⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲟⲓ ⳿ⲛⲣⲉϥⲥⲱⲧⲉⲙ ϧⲉⲛ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
10 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá dáríjì ẹnikẹ́ni, èmi pẹ̀lú dáríjì í. Ohun tí èmi pẹ̀lú bá fi jì, nítorí tiyín ní mo fi jì níwájú Kristi.
ⲓ̅ⲫⲏ ⲇⲉ ⳿ⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲉⲣ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲛⲁϥ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ϩⲱ ϯ⳿ⲓⲣⲓ ⲛⲁϥ ⲕⲉ ⲅⲁⲣ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⳿ⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲉⲧⲁⲓⲁⲓϥ ⲫⲏ ⳿ⲉⲧⲁⲓⲁⲓϥ ⳿ⲛ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲁⲓⲁⲓϥ ⲉⲑⲃⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϧⲉⲛ ⳿ⲡϩⲟ ⳿ⲛⲒⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ.̅.
11 Kí Satani má ba à rẹ́ wa jẹ. Nítorí àwa kò ṣe aláìmọ́ àrékérekè rẹ̀.
ⲓ̅ⲁ̅ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉ⳿ϣⲧⲉⲙ ⳿ⲡⲥⲁⲧⲁⲛⲁⲥ ϭⲓⲧⲧⲉⲛ⳿ⲛϫⲟⲛⲥ ⳿ⲛⲧⲉⲛⲟⲃϣ ⲅⲁⲣ ⲁⲛ ⳿ⲛⲛⲉϥⲙⲉⲩ⳿.Ⲓ.
12 Ṣùgbọ́n nígbà ti mo dé Troasi láti wàásù ìyìnrere Kristi, tí mo sì rí i wí pé Olúwa ti ṣí ìlẹ̀kùn fún mi,
ⲓ̅ⲃ̅⳿ⲉⲧⲁⲓ⳿ⲓ ⲇⲉ ⳿ⲉ⳿ⲧⲣⲱⲁⲥ ⳿ⲉⲡⲓⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁ ⲟⲩⲣⲟ ⲟⲩⲱⲛ ⲛⲏⲓ ϧⲉⲛ Ⲡ⳪.
13 síbẹ̀ èmi kò ní àlàáfíà lọ́kàn mi, nítorí tí èmi kò rí Titu arákùnrin mi níbẹ̀. Nítorí ìdí èyí ni mo ṣe dágbére fún wọn, mo si rékọjá lọ sí Makedonia.
ⲓ̅ⲅ̅⳿ⲙⲡⲉ ⲡⲁⲡⲛ̅ⲁ̅ ⲉⲙⲧⲟⲛ ⳿ⲉⲧⲉ ⳿ⲙⲡⲓϫⲓⲙⲓ ⳿ⲛⲧⲓⲧⲟⲥ ⲡⲁⲥⲟⲛ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁⲓⲉⲣⲁⲡⲟⲧⲁⲍⲉⲥⲑⲉ ⲛⲱⲟⲩ ⲁⲓ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲉ⳿ⲑⲙⲁⲕⲉⲇⲟⲛⲓⲁ.
14 Ṣùgbọ́n ọpẹ́ ni fún Ọlọ́run, ẹni tí ń yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí wá nígbà gbogbo nínú Kristi, tí a sì ń fi òórùn dídùn ìmọ̀ rẹ̀ hàn nípa wa níbi gbogbo.
ⲓ̅ⲇ̅⳿ⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲇⲉ ⳿ⲙⲫϯ ϣⲏⲡ ⲫⲁⲓ ⲉⲑⲟⲩⲱⲛϩ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲥⲏⲟⲩ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϧⲉⲛ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛ⳿ⲥⲑⲟⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉϥ⳿ⲉⲙⲓ ⲉϥⲟⲩⲱⲛϩ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ⲙⲁⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
15 Nítorí òórùn dídùn Kristi ni àwa jẹ́ fún Ọlọ́run, nínú àwọn tí a ń gbàlà àti nínú àwọn tí ó ń ṣègbé.
ⲓ̅ⲉ̅ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ⲟⲩ⳿ⲥⲑⲟⲓⲛⲟⲩϥⲓ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⳿ⲙⲫϯ ϧⲉⲛ ⲛⲏⲉⲑⲛⲁⲛⲟϩⲉⲙ ⲛⲉⲙ ϧⲉⲛ ⲛⲏⲉⲑⲛⲁⲧⲁⲕⲟ.
16 Fún àwọn kan, àwa jẹ́ òórùn sí ikú, àti fún àwọn mìíràn òórùn ìyè sí ìyè. Ta ni ó ha si tọ́ fún nǹkan wọ̀nyí?
ⲓ̅ⲋ̅⳿ⲛϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ ⲙⲉⲛ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ⲥⲑⲟⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲟⲩ ⲉⲩⲙⲟⲩ ⳿ⲛϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ ⲇⲉ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ⲥⲑⲟⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲱⲛϧ ⲉⲩⲱⲛϧ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲓⲙ ⲉⲧⲟⲓ ⳿ⲛϩⲓⲕⲁⲛⲟⲥ ⲟⲩⲃⲉ ⲛⲁⲓ.
17 Nítorí àwa kò dàbí àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀, tí ń fi ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ṣòwò jẹun; ṣùgbọ́n nínú òtítọ́ inú àwa ń sọ̀rọ̀ níwájú Ọlọ́run nínú Kristi gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a rán láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.
ⲓ̅ⲍ̅ⲁⲛⲟⲛ ⲅⲁⲣ ⲁⲛ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲏϣ ⲉⲩⲉⲣⲓⲉⲃϣⲱⲧ ⳿ⲙ⳿ⲡⲥⲁϫⲓ ⳿ⲙⲫϯ ⲁⲗⲗⲁ ϩⲱⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲟⲩⲧⲟⲩⲃⲟ ⲁⲗⲗⲁ ϩⲱⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲫϯ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲙⲫϯ ϧⲉⲛ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲧⲉⲛⲥⲁϫⲓ.

< 2 Corinthians 2 >