< 2 Corinthians 10 >

1 Ṣùgbọ́n èmi Paulu fúnra mi fi inú tútù àti ìwà pẹ̀lẹ́ Kristi bẹ̀ yín, èmi ẹni ìrẹ̀lẹ̀ lójú yín nígbà tí mo wà láàrín yín, ṣùgbọ́n nígbà tí èmi kò sí, mo di ẹni ìgboyà sí yín.
Une ne Paulo, nene ebalabha huu nyenyekevu na uhugowe uwa Kristi. Nane endihogowe wakati nkendi hwitagalila lwenyu, Nina umalidada hwilimwe wakati nendi uhutali namwe.
2 Ṣùgbọ́n èmi bẹ̀ yín pé nígbà tí mo wà láàrín yín, kí èmi ba à lè lo ìgboyà pẹ̀lú ìgbẹ́kẹ̀lé náà, eléyìí tí mo ti fọkàn sí láti fi dojúkọ àwọn kan, ti ń funra sí wa bí ẹni tí ń rìn nípa ìlànà ti ayé yìí.
Embalabha amwe aje wakati nehwendi pandwemo namwe, sewanza abhe malidadi na hwiyamini hwilini nene. Lelo esebha ehwanza abhe malidadi wakati embakhoma bhala bhabhasebha aje tikhala jinsi eshebele.
3 Nítorí pé, bí àwa tilẹ̀ n gbé nínú ayé, ṣùgbọ́n àwa kò jagun nípa ti ara.
Antele nkashile tijenda katika belesetikhomana ibho kwa jinsi eyebele.
4 Nítorí ohun ìjà wa kì í ṣe ti ara, ṣùgbọ́n ó lágbára nínú Ọlọ́run láti wó ibi gíga palẹ̀.
Antele endoso zwatilumila akhomani se zwebele. Antele zilina maha ageshi Ngolobhe anankanya engome zwa zihwefwa tee mijadara yetezwa.
5 Àwa ń sọ gbogbo èrò àti gbogbo ohun gíga ti ń gbe ara rẹ̀ ga sí ìmọ̀ Ọlọ́run kalẹ̀, àwa sì ń di gbogbo èrò ní ìgbèkùn wá sí ìtẹríba fún Kristi.
Antele tinankanya kila chenye mamlaka gagahwinula ashile amataifa aga Ngolobhe. Tibhomba atekaye shila sebho eyogope hwa Kristi.
6 Àwa sì ti murá tan láti jẹ gbogbo àìgbọ́ràn ní yà, nígbà tí ìgbọ́ràn yín bá pé.
Tipewewe utayari uwa kuadhibu kilo matendo lyasa lihopa mara tu utii abha kamili.
7 Ẹ̀yin sì ń wo nǹkan gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti fihàn lóde. Bí ẹnikẹ́ni bá ní ìgboyà nínú ara rẹ̀, ti Kristi ni òun, kí ó tún rò lẹ́ẹ̀kan si pé, bí òun ti jẹ́ ti Kristi, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni àwa pẹ̀lú jẹ́ ti Kristi.
Enya shila shashiliwazi hwitagalila lwenyu. Nkashile yoyonti yasohwa aje umwahale wa Kristi, na hebu ahwikumbuzwe yoyo mwenyewe aje tu shahweli wa Kristi, esho shatili ate antele tili shesho.
8 Nítorí bí mo tilẹ̀ ń ṣògo bí ó ti wù mi nítorí agbára, tí Olúwa ti fi fún wá fún ìdàgbàsókè, dípò fífà yín ṣubú, ojú kí yóò tì mí.
Afwanaje hata nkembahwilole hashe tee ahusu mamlaka Ugosi agafumizwe kwajili eyahwiliti abhazenje amwe na sio abhana nkanye sembalole esoni.
9 Kí ó má ṣe dàbí ẹni pé èmi ń fi ìwé kíkọ dẹ́rùbà yín.
Sehwanza eli libhone aje embogofwe amwe hwu nkalata zwane.
10 Nítorí wọ́n wí pé, “Ìwé rẹ wúwo, wọn sì lágbára; ṣùgbọ́n ní ti ara ìrísí rẹ̀ jẹ aláìlera, ọ̀rọ̀ rẹ kò níláárí.”
Shila bhamo abhantu bhayanga, “Enkalata zwane hali na zilinamaha, lelo eshebele umwahale zaifu. Enjengo zwakwe sezihwaziwa atejelezewe.”
11 Kí irú ènìyàn bẹ́ẹ̀ mọ̀ pé, irú ẹni tí àwa jẹ́ nínú ọ̀rọ̀ nípa ìwé kíkọ nígbà tí àwa kò sí, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni àwa sì jẹ́ nínú iṣẹ́ pẹ̀lú nígbà ti àwa bá wà.
Umba abhantu bhenamna enyo bhelewe aje shila shatiyanga unkalata wakati natili hutali, ni lyolilyoli tilishalipandwemo namwe pala.
12 Nítorí pé àwa kò dáṣà láti ka ara wa mọ́, tàbí láti fi ara wa wé àwọn mìíràn nínú wọn tí ń yin ara wọn; ṣùgbọ́n àwọn fúnra wọn jẹ́ aláìlóye bí wọn ti ń fi ara wọn díwọ̀n ara wọ́n, tí wọ́n sì ń fi ara wọn wé ara wọn.
Setibhale uhutali tee ahwibhonganye tete au ahwilangisye tete na bhala ambao bhuhwisifu bhebho. Lelo nabhahwipama bhebho nab shila muntu wao salinejele.
13 Ṣùgbọ́n àwa kò ṣògo rékọjá ààlà wa, ṣùgbọ́n nípa ààlà ìwọ̀n tí Ọlọ́run ti pín fún wa, èyí tí ó mú kí ó ṣe é ṣe láti dé ọ̀dọ̀ yín.
Ate hata shesho setibhalwivune, ashele empaho. Badala yakwe tibhabhombe shesho tu mhati eye mpaho ambayo Ungolobhe atipimie ate empaho yefiha utali uwenyu shauhweli.
14 Nítorí àwa kò nawọ́ wa rékọjá rárá, bí ẹni pé àwa kò dé ọ̀dọ̀ yín: nítorí àwa tilẹ̀ dé ọ̀dọ̀ yín pẹ̀lú nínú ìyìnrere Kristi.
Afwanaje setahwiyonjizwezwe. Tete natabhafishiye amwe tali bhahwande afishe uhutali neshe uwenyu ewilombelelo lya Kristi.
15 Àwa kò ṣògo rékọjá ààlà wa, èyí nì, lórí iṣẹ́ ẹlòmíràn, ṣùgbọ́n àwa ní ìrètí pé, bí ìgbàgbọ́ yín ti ń dàgbà sí i, gẹ́gẹ́ bí ààlà wa, àwa ó dí gbígbéga lọ́dọ̀ yín sí i lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Selihwivunile ashile ampaho ahusu embombo ezwa bhanje. Badala yakwe titegemela neshe ulyeteho lyenu shalukula aje ieneo lyenyu elye mbombo libhapanushe tee, antele bado ibhabhe muhati eye mpaho eye lyoli.
16 Kí a bá à lè wàásù ìyìnrere ní àwọn ìlú tí ń bẹ níwájú yín, kí a má sì ṣògo nínú ààlà ẹlòmíràn nípa ohun tí ó wà ní àrọ́wọ́tó.
Titegemela huveli aje tiwezwe alombele endombelelo hata hwenye mikoa zaidi yenyu. Setibhahwikune ahusu embombo yebhombeha katika sehemu ezwamwao.
17 “Ṣùgbọ́n jẹ́ kí ẹni tí ó bá ń ṣògo, kí ó máa ṣògo nínú Olúwa.”
“Antele yoyonti yahwilola katika Gosi.”
18 Nítorí kì í ṣe ẹni tí ń yin ara rẹ̀ ni ó ní ìtẹ́wọ́gbà, bí kò ṣe ẹni tí Olúwa bá yìn.
Hwa maana siyo yola yahwisibitisya yoyo asibitiziwa. Isipokuwa, yoyo ambaye Ugosi ahusibitizwa.

< 2 Corinthians 10 >