< 2 Chronicles 8 >
1 Lẹ́yìn ogún ọdún lásìkò ìgbà tí Solomoni kọ́ ilé Olúwa àti ilé òun fúnra rẹ̀.
Et vingt ans s'étant écoulés depuis que Salomon eut bâti le Temple de l'Éternel et son palais,
2 Solomoni tún ìlú tí Hiramu ti fi fún un kọ́, ó sì kó àwọn ọmọ Israẹli jọ níbẹ̀ kí wọn kí ó lè máa gbé nínú ibẹ̀.
il fortifia les villes données par Huram à Salomon, et les peupla d'enfants d'Israël.
3 Nígbà náà Solomoni lọ sí Hamati-Ṣoba ó sì borí rẹ̀.
Et Salomon marcha contre Hamath en Tsoba et s'en empara.
4 Ó sì tún kọ́ Tadmori ní aginjù àti gbogbo ìlú ìṣúra tí ó ti kọ́ ní Hamati.
Et il bâtit Thadmor au Désert et toutes les villes des magasins qu'il construisit en Hamath.
5 Ó sì tún kọ́ òkè Beti-Horoni àti ìsàlẹ̀ Beti-Horoni gẹ́gẹ́ bí ìlú olódi, pẹ̀lú ògiri àti pẹ̀lú ìlẹ̀kùn àti ọ̀pá ìdábùú.
Et il fortifia Bethoron la haute et Bethoron la basse, places fortes, de murs, de portes et de verrous,
6 Àti gẹ́gẹ́ bí Baalati àti gbogbo ìlú ìṣúra tí Solomoni ní, àti gbogbo ìlú fún kẹ̀kẹ́ rẹ̀ àti fún àwọn ẹṣin rẹ̀ ohunkóhun tí ó bá yẹ ní kókó ní Jerusalẹmu, ní Lebanoni àti ní gbogbo àyíká agbègbè tí ó ń darí.
et Baalath et toutes les villes à magasins qu'avait Salomon, et toutes les villes aux chars et les villes à cavalerie et tous les lieux de plaisance qu'il plut à Salomon de construire à Jérusalem et au Liban et dans tout le pays de sa domination.
7 Gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kúrò láti ara àwọn ará Hiti, ará Amori, ará Peresi, ará Hifi àti ará Jebusi àwọn ènìyàn wọ̀nyí wọn kì í ṣe àwọn ará Israẹli,
Quant à toute la population restée des Héthiens et des Amorites et des Périziens et des Hévites et des Jébusites, qui n'étaient pas des enfants d'Israël,
8 èyí ni wí pé, àwọn ọmọ wọn tí ó kù sílé ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Israẹli kò parun àwọn ni Solomoni bu iṣẹ́ ìrú fún títí di òní yìí.
sur leurs fils qui étaient restés après eux dans le pays, et que les enfants d'Israël n'avaient pas détruits, Salomon en fit une levée pour la corvée, comme c'est aujourd'hui.
9 Ṣùgbọ́n Solomoni kò mú ọmọ ọ̀dọ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, wọn jẹ́ ọ̀gágun rẹ̀, olùdarí àwọn oníkẹ̀kẹ́ àti olùdarí kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
Mais des enfants d'Israël Salomon ne fit point de serfs pour ses travaux, car ils étaient les gens de guerre et les chefs de ses triaires et les chefs de ses chars et de sa cavalerie.
10 Wọ́n sì tún jẹ́ olórí aláṣẹ fún ọba Solomoni, àádọ́ta ó lé nígba àwọn alákòóso lórí àwọn ènìyàn.
Et les surintendants du roi Salomon étaient au nombre de deux cent cinquante régissant le peuple.
11 Solomoni gbé ọmọbìnrin Farao sókè láti ìlú Dafidi lọ sí ibi tí ó ti kọ́ fún un, nítorí ó wí pé, “Aya mi kò gbọdọ̀ gbé nínú ilé Dafidi ọba Israẹli nítorí ibi tí àpótí ẹ̀rí Olúwa bá tí wọ̀, ibi mímọ́ ni.”
Et Salomon fit monter la fille de Pharaon de la Cité de David au palais qu'il lui avait bâti, car il disait: Je ne veux pas que femme habite de par moi le palais de David, roi d'Israël, car sacrés sont les lieux où est entrée l'Arche de l'Éternel.
12 Lórí pẹpẹ Olúwa tí ó ti kọ́ níwájú ìloro náà, Solomoni sì rú ẹbọ sísun sí Olúwa,
Alors Salomon offrit des holocaustes à l'Éternel sur l'autel de l'Éternel qu'il avait érigé devant le vestibule,
13 nípa ìlànà ojoojúmọ́ fún ẹbọ rírú tí a pàṣẹ láti ọ̀dọ̀ Mose wá fún ọjọ́ ìsinmi, oṣù tuntun àti lẹ́rìn mẹ́ta lọ́dún, ní àjọ àìwúkàrà, ní àjọ ọ̀sẹ̀ méje àti àjọ àgọ́.
et il offrait l'ordinaire quotidien selon l'ordre de Moïse pour les sabbats, les nouvelles lunes et les fêtes, trois fois l'année, à la fête des azymes, et à la fête des semaines et à la fête des huttes.
14 Ní pípamọ́ pẹ̀lú ìlànà baba rẹ̀ Dafidi, ó sì yan ipa àwọn àlùfáà fún iṣẹ́ wọn àti àwọn ọmọ Lefi láti jẹ́ adarí láti máa yin àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ àwọn àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìlànà ojoojúmọ́. Ó sì tún yàn àwọn olùṣọ́nà nípa pípín sí olúkúlùkù ẹnu-ọ̀nà, nítorí èyí ni Dafidi ènìyàn Ọlọ́run ti paláṣẹ.
Et il établit selon la règle de David, son père, les classes des Prêtres pour leur service, et les Lévites dans leurs fonctions pour rendre grâces et officier devant les Prêtres à l'ordinaire quotidien, et les portiers selon leurs classes à chaque porte, car tel était l'ordre de David, homme de Dieu.
15 Wọn kò sì yà kúrò nínú àṣẹ ọba sí àwọn àlùfáà tàbí sí àwọn ọmọ Lefi, nínú ohunkóhun, àti pẹ̀lú ti ìṣúra.
Et l'on ne s'écarta point de l'ordonnance du roi pour les Prêtres et les Lévites relativement à chaque point et relativement aux trésors.
16 Gbogbo iṣẹ́ Solomoni ni a gbé jáde láti ọjọ́ ìfi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀ títí ó fi di ọjọ́ ìparí. Bẹ́ẹ̀ ni ilé Olúwa sì parí.
Et ainsi fut organisée toute l'œuvre de Salomon jusqu'au jour de la fondation du Temple de l'Éternel et jusqu'à son achèvement, à la complète construction du Temple de l'Éternel.
17 Nígbà náà ni Solomoni lọ sí Esioni-Geberi àti Elati ní Edomu létí òkun.
Alors Salomon se rendit à Etsion-Géber et à Eloth sur le bord de la mer au pays d'Edom.
18 Hiramu sì fi ọ̀kọ̀ ránṣẹ́ sì i nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọkùnrin tí ó mòye Òkun. Èyí pẹ̀lú àwọn ènìyàn Solomoni, lọ sí Ofiri wọ́n sì gbé àádọ́ta lé ní irinwó tálẹ́ǹtì wúrà wá, padà èyí tí wọ́n sì mú tọ ọba Solomoni wá.
Et Huram lui envoya par ses serviteurs des navires et des serviteurs connaissant la mer, et ils vinrent avec les serviteurs de Salomon à Ophir d'où ils rapportèrent quatre cent cinquante talents d'or qu'ils présentèrent au roi Salomon.