< 2 Chronicles 8 >
1 Lẹ́yìn ogún ọdún lásìkò ìgbà tí Solomoni kọ́ ilé Olúwa àti ilé òun fúnra rẹ̀.
Or, au bout des vingt ans employés par Salomon à construire la maison du Seigneur et son propre palais,
2 Solomoni tún ìlú tí Hiramu ti fi fún un kọ́, ó sì kó àwọn ọmọ Israẹli jọ níbẹ̀ kí wọn kí ó lè máa gbé nínú ibẹ̀.
Salomon fortifia les villes que lui avait cédées Houram, roi de Tyr, et les peupla d’Israélites.
3 Nígbà náà Solomoni lọ sí Hamati-Ṣoba ó sì borí rẹ̀.
Puis, Salomon marcha contre Hamat-Çoba et s’en rendit maître.
4 Ó sì tún kọ́ Tadmori ní aginjù àti gbogbo ìlú ìṣúra tí ó ti kọ́ ní Hamati.
Il bâtit le Tadmor du désert ainsi que toutes les villes d’approvisionnement qu’il éleva dans le pays de Hamat.
5 Ó sì tún kọ́ òkè Beti-Horoni àti ìsàlẹ̀ Beti-Horoni gẹ́gẹ́ bí ìlú olódi, pẹ̀lú ògiri àti pẹ̀lú ìlẹ̀kùn àti ọ̀pá ìdábùú.
Il bâtit le Beth-Horôn supérieur et le Beth-Horôn inférieur, villes fortes munies de murailles, de portes et de verrous,
6 Àti gẹ́gẹ́ bí Baalati àti gbogbo ìlú ìṣúra tí Solomoni ní, àti gbogbo ìlú fún kẹ̀kẹ́ rẹ̀ àti fún àwọn ẹṣin rẹ̀ ohunkóhun tí ó bá yẹ ní kókó ní Jerusalẹmu, ní Lebanoni àti ní gbogbo àyíká agbègbè tí ó ń darí.
de même Baalat et toutes les autres villes d’approvisionnement de Salomon, toutes les villes de chariots, celles des cavaliers, bref, tout ce qu’il plaisait à Salomon de construire à Jérusalem, au Liban et dans tout le pays soumis à sa domination.
7 Gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kúrò láti ara àwọn ará Hiti, ará Amori, ará Peresi, ará Hifi àti ará Jebusi àwọn ènìyàn wọ̀nyí wọn kì í ṣe àwọn ará Israẹli,
Toute la population survivante des Héthéens, des Amorréens, des Phérézéens, des Hévéens et des Jébuséens, lesquels ne font point partie des enfants d’Israël,
8 èyí ni wí pé, àwọn ọmọ wọn tí ó kù sílé ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Israẹli kò parun àwọn ni Solomoni bu iṣẹ́ ìrú fún títí di òní yìí.
leurs descendants qui étaient restés après eux dans le pays et que les enfants d’Israël n’avaient pas exterminés, Salomon les obligea à payer tribut; ce qu’ils font encore aujourd’hui.
9 Ṣùgbọ́n Solomoni kò mú ọmọ ọ̀dọ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, wọn jẹ́ ọ̀gágun rẹ̀, olùdarí àwọn oníkẹ̀kẹ́ àti olùdarí kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
Pour les enfants d’Israël, Salomon n’en employa point comme esclaves pour ses travaux; ils étaient seulement ses hommes de guerre, ses fonctionnaires, capitaines, commandants de ses chars et de sa cavalerie.
10 Wọ́n sì tún jẹ́ olórí aláṣẹ fún ọba Solomoni, àádọ́ta ó lé nígba àwọn alákòóso lórí àwọn ènìyàn.
Les surveillants en chef du roi Salomon étaient au nombre de deux cent cinquante, chargés de diriger le peuple.
11 Solomoni gbé ọmọbìnrin Farao sókè láti ìlú Dafidi lọ sí ibi tí ó ti kọ́ fún un, nítorí ó wí pé, “Aya mi kò gbọdọ̀ gbé nínú ilé Dafidi ọba Israẹli nítorí ibi tí àpótí ẹ̀rí Olúwa bá tí wọ̀, ibi mímọ́ ni.”
Quant à la fille de Pharaon, Salomon lui fit quitter la Cité de David pour l’installer dans la demeure qu’il lui avait construite, "car, disait-il, je ne dois pas laisser résider une femme dans les demeures de David, roi d’Israël, devenues sacrées depuis que l’arche du Seigneur y a été transférée".
12 Lórí pẹpẹ Olúwa tí ó ti kọ́ níwájú ìloro náà, Solomoni sì rú ẹbọ sísun sí Olúwa,
Dès lors, Salomon offrait des holocaustes au Seigneur, sur l’autel qu’il lui avait élevé devant le portique;
13 nípa ìlànà ojoojúmọ́ fún ẹbọ rírú tí a pàṣẹ láti ọ̀dọ̀ Mose wá fún ọjọ́ ìsinmi, oṣù tuntun àti lẹ́rìn mẹ́ta lọ́dún, ní àjọ àìwúkàrà, ní àjọ ọ̀sẹ̀ méje àti àjọ àgọ́.
en se conformant au rite de chaque jour, il les offrait, selon les prescriptions de Moïse, les jours du Sabbat et des néoménies et aux fêtes qui se suivent trois fois par an, à la fête des Azymes, à la fête des Semaines et à la fête des Tabernacles.
14 Ní pípamọ́ pẹ̀lú ìlànà baba rẹ̀ Dafidi, ó sì yan ipa àwọn àlùfáà fún iṣẹ́ wọn àti àwọn ọmọ Lefi láti jẹ́ adarí láti máa yin àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ àwọn àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìlànà ojoojúmọ́. Ó sì tún yàn àwọn olùṣọ́nà nípa pípín sí olúkúlùkù ẹnu-ọ̀nà, nítorí èyí ni Dafidi ènìyàn Ọlọ́run ti paláṣẹ.
En vertu de la réglementation de son père David, il installa les sections de prêtres dans leur service et les Lévites dans leurs charges, consistant à réciter les cantiques et à faire le service concurremment avec les prêtres, selon le rite de chaque jour; il posta aussi les portiers par escouades à chacune des portes, comme l’avait ordonné David, l’homme de Dieu.
15 Wọn kò sì yà kúrò nínú àṣẹ ọba sí àwọn àlùfáà tàbí sí àwọn ọmọ Lefi, nínú ohunkóhun, àti pẹ̀lú ti ìṣúra.
On ne s’écarta en rien des prescriptions du roi David, concernant les prêtres et les Lévites, et notamment les trésors.
16 Gbogbo iṣẹ́ Solomoni ni a gbé jáde láti ọjọ́ ìfi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀ títí ó fi di ọjọ́ ìparí. Bẹ́ẹ̀ ni ilé Olúwa sì parí.
l’œuvre entière de Salomon fut accomplie à ce jour: la fondation de la maison du Seigneur jusqu’à son achèvement. La maison du Seigneur se trouva complète.
17 Nígbà náà ni Solomoni lọ sí Esioni-Geberi àti Elati ní Edomu létí òkun.
Alors Salomon se rendit à Ecion-Ghéber et à Elot, au bord de la mer dans le pays d’Edom.
18 Hiramu sì fi ọ̀kọ̀ ránṣẹ́ sì i nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọkùnrin tí ó mòye Òkun. Èyí pẹ̀lú àwọn ènìyàn Solomoni, lọ sí Ofiri wọ́n sì gbé àádọ́ta lé ní irinwó tálẹ́ǹtì wúrà wá, padà èyí tí wọ́n sì mú tọ ọba Solomoni wá.
Houram lui expédia, par ses serviteurs, des vaisseaux et des matelots experts dans la marine, qui se rendirent avec les serviteurs de Salomon à Ophir, d’où ils emportèrent quatre cent cinquante kikkar d’or, qu’ils remirent au roi Salomon.