< 2 Chronicles 8 >

1 Lẹ́yìn ogún ọdún lásìkò ìgbà tí Solomoni kọ́ ilé Olúwa àti ilé òun fúnra rẹ̀.
Au bout de vingt ans, pendant lesquels Salomon avait bâti la maison de l'Éternel et sa propre maison,
2 Solomoni tún ìlú tí Hiramu ti fi fún un kọ́, ó sì kó àwọn ọmọ Israẹli jọ níbẹ̀ kí wọn kí ó lè máa gbé nínú ibẹ̀.
Salomon bâtit les villes que Huram avait données à Salomon, et il y fit habiter les enfants d'Israël.
3 Nígbà náà Solomoni lọ sí Hamati-Ṣoba ó sì borí rẹ̀.
Salomon alla à Hamath-Zobach, et l'emporta sur elle.
4 Ó sì tún kọ́ Tadmori ní aginjù àti gbogbo ìlú ìṣúra tí ó ti kọ́ ní Hamati.
Il bâtit Tadmor dans le désert, et toutes les villes de stockage qu'il bâtit à Hamath.
5 Ó sì tún kọ́ òkè Beti-Horoni àti ìsàlẹ̀ Beti-Horoni gẹ́gẹ́ bí ìlú olódi, pẹ̀lú ògiri àti pẹ̀lú ìlẹ̀kùn àti ọ̀pá ìdábùú.
Il bâtit aussi Beth Horon la haute et Beth Horon la basse, villes fortifiées avec des murs, des portes et des barres,
6 Àti gẹ́gẹ́ bí Baalati àti gbogbo ìlú ìṣúra tí Solomoni ní, àti gbogbo ìlú fún kẹ̀kẹ́ rẹ̀ àti fún àwọn ẹṣin rẹ̀ ohunkóhun tí ó bá yẹ ní kókó ní Jerusalẹmu, ní Lebanoni àti ní gbogbo àyíká agbègbè tí ó ń darí.
Baalath, et toutes les villes de dépôt que Salomon avait, toutes les villes pour ses chars, les villes pour ses cavaliers, et tout ce que Salomon voulut bâtir pour son plaisir à Jérusalem, au Liban et dans tout le pays de sa domination.
7 Gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kúrò láti ara àwọn ará Hiti, ará Amori, ará Peresi, ará Hifi àti ará Jebusi àwọn ènìyàn wọ̀nyí wọn kì í ṣe àwọn ará Israẹli,
Quant à tout le peuple qui restait des Héthiens, des Amoréens, des Phéréziens, des Héviens et des Jébusiens, et qui n'était pas d'Israël,
8 èyí ni wí pé, àwọn ọmọ wọn tí ó kù sílé ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Israẹli kò parun àwọn ni Solomoni bu iṣẹ́ ìrú fún títí di òní yìí.
quant à leurs enfants restés après eux dans le pays et que les enfants d'Israël n'ont pas consommés, Salomon les fit travailler de force jusqu'à ce jour.
9 Ṣùgbọ́n Solomoni kò mú ọmọ ọ̀dọ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, wọn jẹ́ ọ̀gágun rẹ̀, olùdarí àwọn oníkẹ̀kẹ́ àti olùdarí kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
Mais Salomon n'avait pas fait des enfants d'Israël des serviteurs pour son travail, mais des hommes de guerre, chefs de ses capitaines, chefs de ses chars et de ses cavaliers.
10 Wọ́n sì tún jẹ́ olórí aláṣẹ fún ọba Solomoni, àádọ́ta ó lé nígba àwọn alákòóso lórí àwọn ènìyàn.
Tels étaient les principaux officiers du roi Salomon, au nombre de deux cent cinquante, qui dirigeaient le peuple.
11 Solomoni gbé ọmọbìnrin Farao sókè láti ìlú Dafidi lọ sí ibi tí ó ti kọ́ fún un, nítorí ó wí pé, “Aya mi kò gbọdọ̀ gbé nínú ilé Dafidi ọba Israẹli nítorí ibi tí àpótí ẹ̀rí Olúwa bá tí wọ̀, ibi mímọ́ ni.”
Salomon fit monter la fille de Pharaon de la cité de David dans la maison qu'il lui avait construite, car il avait dit: « Ma femme n'habitera pas dans la maison de David, roi d'Israël, car les lieux où est venue l'arche de Yahvé sont saints. »
12 Lórí pẹpẹ Olúwa tí ó ti kọ́ níwájú ìloro náà, Solomoni sì rú ẹbọ sísun sí Olúwa,
Salomon offrit des holocaustes à l'Éternel sur l'autel de l'Éternel qu'il avait construit devant le portique,
13 nípa ìlànà ojoojúmọ́ fún ẹbọ rírú tí a pàṣẹ láti ọ̀dọ̀ Mose wá fún ọjọ́ ìsinmi, oṣù tuntun àti lẹ́rìn mẹ́ta lọ́dún, ní àjọ àìwúkàrà, ní àjọ ọ̀sẹ̀ méje àti àjọ àgọ́.
selon les prescriptions de chaque jour, en faisant des offrandes selon le commandement de Moïse, aux sabbats, aux nouvelles lunes et aux fêtes fixes, trois fois par an, à la fête des pains sans levain, à la fête des semaines et à la fête des tentes.
14 Ní pípamọ́ pẹ̀lú ìlànà baba rẹ̀ Dafidi, ó sì yan ipa àwọn àlùfáà fún iṣẹ́ wọn àti àwọn ọmọ Lefi láti jẹ́ adarí láti máa yin àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ àwọn àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìlànà ojoojúmọ́. Ó sì tún yàn àwọn olùṣọ́nà nípa pípín sí olúkúlùkù ẹnu-ọ̀nà, nítorí èyí ni Dafidi ènìyàn Ọlọ́run ti paláṣẹ.
Il établit, selon l'ordonnance de David, son père, les divisions des sacrificateurs à leur service, et les Lévites à leurs fonctions, pour louer et servir devant les sacrificateurs, selon ce que le devoir de chaque jour exigeait, les portiers aussi par leurs divisions à chaque porte, car David, homme de Dieu, l'avait ordonné.
15 Wọn kò sì yà kúrò nínú àṣẹ ọba sí àwọn àlùfáà tàbí sí àwọn ọmọ Lefi, nínú ohunkóhun, àti pẹ̀lú ti ìṣúra.
Ils ne s'écartèrent pas de l'ordre donné par le roi aux prêtres et aux lévites, pour tout ce qui concerne les affaires et les trésors.
16 Gbogbo iṣẹ́ Solomoni ni a gbé jáde láti ọjọ́ ìfi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀ títí ó fi di ọjọ́ ìparí. Bẹ́ẹ̀ ni ilé Olúwa sì parí.
Or toute l'œuvre de Salomon s'est accomplie depuis le jour de la fondation de la maison de l'Éternel jusqu'à son achèvement. Ainsi la maison de Yahvé fut achevée.
17 Nígbà náà ni Solomoni lọ sí Esioni-Geberi àti Elati ní Edomu létí òkun.
Puis Salomon se rendit à Ezion Geber et à Eloth, au bord de la mer, dans le pays d'Edom.
18 Hiramu sì fi ọ̀kọ̀ ránṣẹ́ sì i nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọkùnrin tí ó mòye Òkun. Èyí pẹ̀lú àwọn ènìyàn Solomoni, lọ sí Ofiri wọ́n sì gbé àádọ́ta lé ní irinwó tálẹ́ǹtì wúrà wá, padà èyí tí wọ́n sì mú tọ ọba Solomoni wá.
Huram lui envoya des navires et des serviteurs qui connaissaient la mer par les mains de ses serviteurs; ils vinrent avec les serviteurs de Salomon à Ophir, et ils rapportèrent de là quatre cent cinquante talents d'or, qu'ils apportèrent au roi Salomon.

< 2 Chronicles 8 >