< 2 Chronicles 8 >

1 Lẹ́yìn ogún ọdún lásìkò ìgbà tí Solomoni kọ́ ilé Olúwa àti ilé òun fúnra rẹ̀.
Solomon’s [workers] worked for 20 years to build the temple and the king’s palace.
2 Solomoni tún ìlú tí Hiramu ti fi fún un kọ́, ó sì kó àwọn ọmọ Israẹli jọ níbẹ̀ kí wọn kí ó lè máa gbé nínú ibẹ̀.
Then his [workers] rebuilt the cities that [King] Hiram had given back to Solomon, and Solomon sent Israelis to live in those cities.
3 Nígbà náà Solomoni lọ sí Hamati-Ṣoba ó sì borí rẹ̀.
Solomon’s [army] then went to Hamath-Zobah [town] and captured it.
4 Ó sì tún kọ́ Tadmori ní aginjù àti gbogbo ìlú ìṣúra tí ó ti kọ́ ní Hamati.
His workers also rebuilt walls around Tadmor [town] in the desert, and in [the] Hamath [region] in all the towns where they kept supplies.
5 Ó sì tún kọ́ òkè Beti-Horoni àti ìsàlẹ̀ Beti-Horoni gẹ́gẹ́ bí ìlú olódi, pẹ̀lú ògiri àti pẹ̀lú ìlẹ̀kùn àti ọ̀pá ìdábùú.
They rebuilt Upper Beth-Horon [town] and Lower Beth-Horon [city], and built walls around them with gates [in the walls] and bars [to fasten the gates].
6 Àti gẹ́gẹ́ bí Baalati àti gbogbo ìlú ìṣúra tí Solomoni ní, àti gbogbo ìlú fún kẹ̀kẹ́ rẹ̀ àti fún àwọn ẹṣin rẹ̀ ohunkóhun tí ó bá yẹ ní kókó ní Jerusalẹmu, ní Lebanoni àti ní gbogbo àyíká agbègbè tí ó ń darí.
They also rebuilt Baalath [town] and all the cities where supplies were kept and the cities where Solomon’s chariots and horses were kept. Solomon’s [workers] built whatever he wanted them to build, in Jerusalem and in Lebanon, and in other places in the area that he ruled.
7 Gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kúrò láti ara àwọn ará Hiti, ará Amori, ará Peresi, ará Hifi àti ará Jebusi àwọn ènìyàn wọ̀nyí wọn kì í ṣe àwọn ará Israẹli,
Solomon forced people from many other groups who were not Israelis to work for him like slaves. They were people from the Heth, Amor, Periz, Hiv, and Jebus people-groups.
8 èyí ni wí pé, àwọn ọmọ wọn tí ó kù sílé ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Israẹli kò parun àwọn ni Solomoni bu iṣẹ́ ìrú fún títí di òní yìí.
They were descendants of groups whom the Israelis had not completely destroyed. Solomon forced them to become his slaves, and they are still slaves.
9 Ṣùgbọ́n Solomoni kò mú ọmọ ọ̀dọ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, wọn jẹ́ ọ̀gágun rẹ̀, olùdarí àwọn oníkẹ̀kẹ́ àti olùdarí kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
But Solomon did not force Israelis to work for him. Israelis became his soldiers and commanders of his chariots and his chariot-drivers.
10 Wọ́n sì tún jẹ́ olórí aláṣẹ fún ọba Solomoni, àádọ́ta ó lé nígba àwọn alákòóso lórí àwọn ènìyàn.
They were also King Solomon’s chief officials. There were 250 of them, and they supervised the workers.
11 Solomoni gbé ọmọbìnrin Farao sókè láti ìlú Dafidi lọ sí ibi tí ó ti kọ́ fún un, nítorí ó wí pé, “Aya mi kò gbọdọ̀ gbé nínú ilé Dafidi ọba Israẹli nítorí ibi tí àpótí ẹ̀rí Olúwa bá tí wọ̀, ibi mímọ́ ni.”
Solomon moved his wife, who was the daughter of the king of Egypt, from [the place outside Jerusalem called] ‘The City of David’ to the place that his workers had built for her. He said, “I do not want my wife to live in the palace that [my father] King David’s workers built, because the Sacred Chest [was in that palace for a while], and any place where the Sacred Chest has been is holy.”
12 Lórí pẹpẹ Olúwa tí ó ti kọ́ níwájú ìloro náà, Solomoni sì rú ẹbọ sísun sí Olúwa,
On the altar that Solomon’s [workers] had built in front of the entrance [to the temple], Solomon sacrificed many offerings that were to be completely burned.
13 nípa ìlànà ojoojúmọ́ fún ẹbọ rírú tí a pàṣẹ láti ọ̀dọ̀ Mose wá fún ọjọ́ ìsinmi, oṣù tuntun àti lẹ́rìn mẹ́ta lọ́dún, ní àjọ àìwúkàrà, ní àjọ ọ̀sẹ̀ méje àti àjọ àgọ́.
He did that to obey the rules about what sacrifices Moses had declared should be made. These included sacrifices for every day and for the Sabbath days and to celebrate each day on which there was a new moon and for the three other festivals that were celebrated each year. Those festivals were the Festival of Eating Unleavened Bread, the Harvest Festival, and the Festival of Living in Temporary Shelters.
14 Ní pípamọ́ pẹ̀lú ìlànà baba rẹ̀ Dafidi, ó sì yan ipa àwọn àlùfáà fún iṣẹ́ wọn àti àwọn ọmọ Lefi láti jẹ́ adarí láti máa yin àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ àwọn àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìlànà ojoojúmọ́. Ó sì tún yàn àwọn olùṣọ́nà nípa pípín sí olúkúlùkù ẹnu-ọ̀nà, nítorí èyí ni Dafidi ènìyàn Ọlọ́run ti paláṣẹ.
Obeying what his father David had commanded, he appointed the groups of priests for their work, and he appointed the descendants of Levi to lead the people while they sang to praise Yahweh and while they assisted the priests in their daily work. He also appointed groups of them to guard all the gates, because that was also what David, the man who pleased God [very well], had commanded.
15 Wọn kò sì yà kúrò nínú àṣẹ ọba sí àwọn àlùfáà tàbí sí àwọn ọmọ Lefi, nínú ohunkóhun, àti pẹ̀lú ti ìṣúra.
The priests and other descendants of Levi obeyed completely everything that the king commanded, including [taking care of] the storerooms.
16 Gbogbo iṣẹ́ Solomoni ni a gbé jáde láti ọjọ́ ìfi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀ títí ó fi di ọjọ́ ìparí. Bẹ́ẹ̀ ni ilé Olúwa sì parí.
They did all the work [of building the temple] that Solomon told them to do, until it was all completed. So they finishing building the temple.
17 Nígbà náà ni Solomoni lọ sí Esioni-Geberi àti Elati ní Edomu létí òkun.
Then some of Solomon’s men went to Ezion-Geber and Elath [cities] on the coast of the Red Sea, an area that belonged to the Edom people-group.
18 Hiramu sì fi ọ̀kọ̀ ránṣẹ́ sì i nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọkùnrin tí ó mòye Òkun. Èyí pẹ̀lú àwọn ènìyàn Solomoni, lọ sí Ofiri wọ́n sì gbé àádọ́ta lé ní irinwó tálẹ́ǹtì wúrà wá, padà èyí tí wọ́n sì mú tọ ọba Solomoni wá.
King Hiram sent to Solomon from [Tyre city] some ships that were commanded by his officers. They were men who were experienced sailors. These men went in the ships with Solomon’s men to [the] Ophir [region] and brought back about 17 tons of gold, which they delivered to King Solomon.

< 2 Chronicles 8 >