< 2 Chronicles 8 >

1 Lẹ́yìn ogún ọdún lásìkò ìgbà tí Solomoni kọ́ ilé Olúwa àti ilé òun fúnra rẹ̀.
And it came to pass at the end of twenty years, when Solomon had built the house of the Lord, and his own house,
2 Solomoni tún ìlú tí Hiramu ti fi fún un kọ́, ó sì kó àwọn ọmọ Israẹli jọ níbẹ̀ kí wọn kí ó lè máa gbé nínú ibẹ̀.
That [as regardeth] the cities which Churam had restored to Solomon, Solomon built them, and caused the children of Israel to dwell there.
3 Nígbà náà Solomoni lọ sí Hamati-Ṣoba ó sì borí rẹ̀.
And Solomon went to Chamath-zobah, and prevailed against it.
4 Ó sì tún kọ́ Tadmori ní aginjù àti gbogbo ìlú ìṣúra tí ó ti kọ́ ní Hamati.
And he built Thadmor in the wilderness, and all the treasure-cities, which he built in Chamath.
5 Ó sì tún kọ́ òkè Beti-Horoni àti ìsàlẹ̀ Beti-Horoni gẹ́gẹ́ bí ìlú olódi, pẹ̀lú ògiri àti pẹ̀lú ìlẹ̀kùn àti ọ̀pá ìdábùú.
And he built the upper Beth-choron, and the lower Beth-choron, fortified cities, with walls, gates, and bars;
6 Àti gẹ́gẹ́ bí Baalati àti gbogbo ìlú ìṣúra tí Solomoni ní, àti gbogbo ìlú fún kẹ̀kẹ́ rẹ̀ àti fún àwọn ẹṣin rẹ̀ ohunkóhun tí ó bá yẹ ní kókó ní Jerusalẹmu, ní Lebanoni àti ní gbogbo àyíká agbègbè tí ó ń darí.
And Ba'alath, and all the treasure-cities that Solomon had, and all the cities for chariots, and the cities for horsemen, and all the [other] desire of Solomon which he desired to build in Jerusalem, and in the Lebanon, and throughout all the land of his dominion.
7 Gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kúrò láti ara àwọn ará Hiti, ará Amori, ará Peresi, ará Hifi àti ará Jebusi àwọn ènìyàn wọ̀nyí wọn kì í ṣe àwọn ará Israẹli,
All the people that were left of the Hittites, and the Emorites, and the Perizzites, and the Hivites, and the Jebusites, who were not of Israel,
8 èyí ni wí pé, àwọn ọmọ wọn tí ó kù sílé ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Israẹli kò parun àwọn ni Solomoni bu iṣẹ́ ìrú fún títí di òní yìí.
Out of their children, who were left after them in the land, whom the children of Israel had not destroyed—these did Solomon levy as tributary [laborers] until this day.
9 Ṣùgbọ́n Solomoni kò mú ọmọ ọ̀dọ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, wọn jẹ́ ọ̀gágun rẹ̀, olùdarí àwọn oníkẹ̀kẹ́ àti olùdarí kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
Yet of the children of Israel did Solomon make no bondmen for his work; but they were men of war, and chiefs of his captains; and officers of his chariots and of his horsemen.
10 Wọ́n sì tún jẹ́ olórí aláṣẹ fún ọba Solomoni, àádọ́ta ó lé nígba àwọn alákòóso lórí àwọn ènìyàn.
And these were the chiefs of the superintendents whom king Solomon had, [even] two hundred and fifty, who ruled over the people.
11 Solomoni gbé ọmọbìnrin Farao sókè láti ìlú Dafidi lọ sí ibi tí ó ti kọ́ fún un, nítorí ó wí pé, “Aya mi kò gbọdọ̀ gbé nínú ilé Dafidi ọba Israẹli nítorí ibi tí àpótí ẹ̀rí Olúwa bá tí wọ̀, ibi mímọ́ ni.”
And the daughter of Pharaoh did Solomon bring up out of the city of David unto the house that he had built for her; for he said, No wife of mine shall dwell in a house of David the king of Israel, because they are holy, because there came [once] unto them the ark of the Lord.
12 Lórí pẹpẹ Olúwa tí ó ti kọ́ níwájú ìloro náà, Solomoni sì rú ẹbọ sísun sí Olúwa,
Then did Solomon offer burnt-offerings unto the Lord on the altar of the Lord, which he had built before the porch,
13 nípa ìlànà ojoojúmọ́ fún ẹbọ rírú tí a pàṣẹ láti ọ̀dọ̀ Mose wá fún ọjọ́ ìsinmi, oṣù tuntun àti lẹ́rìn mẹ́ta lọ́dún, ní àjọ àìwúkàrà, ní àjọ ọ̀sẹ̀ méje àti àjọ àgọ́.
Even according to what was the due of [every] day on its day, offering according to the commandment of Moses, on the sabbaths, and on the new-moons, and on the stated festivals, three times in the year, on the feast of unleavened bread, and on the feast of weeks, and on the feast of tabernacles.
14 Ní pípamọ́ pẹ̀lú ìlànà baba rẹ̀ Dafidi, ó sì yan ipa àwọn àlùfáà fún iṣẹ́ wọn àti àwọn ọmọ Lefi láti jẹ́ adarí láti máa yin àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ àwọn àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìlànà ojoojúmọ́. Ó sì tún yàn àwọn olùṣọ́nà nípa pípín sí olúkúlùkù ẹnu-ọ̀nà, nítorí èyí ni Dafidi ènìyàn Ọlọ́run ti paláṣẹ.
And he stationed, according to the prescription of David his father, the divisions of the priests at their service, and the Levites at their stations, to praise and minister next to the priests, in the requirement of every day on its day, and the gate-keepers in their divisions at every gate; for so was the charge of David the man of God.
15 Wọn kò sì yà kúrò nínú àṣẹ ọba sí àwọn àlùfáà tàbí sí àwọn ọmọ Lefi, nínú ohunkóhun, àti pẹ̀lú ti ìṣúra.
And they departed not from the charge of the king concerning the priests and Levites respecting every matter, and respecting the treasuries.
16 Gbogbo iṣẹ́ Solomoni ni a gbé jáde láti ọjọ́ ìfi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀ títí ó fi di ọjọ́ ìparí. Bẹ́ẹ̀ ni ilé Olúwa sì parí.
And [so] was all the work of Solomon successful from the day of founding the house of the Lord, even until it was finished. [So] was perfected the house of the Lord.
17 Nígbà náà ni Solomoni lọ sí Esioni-Geberi àti Elati ní Edomu létí òkun.
Then went Solomon to 'Ezyon-geber, and to Eloth, at the sea-shore in the land of Edom.
18 Hiramu sì fi ọ̀kọ̀ ránṣẹ́ sì i nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọkùnrin tí ó mòye Òkun. Èyí pẹ̀lú àwọn ènìyàn Solomoni, lọ sí Ofiri wọ́n sì gbé àádọ́ta lé ní irinwó tálẹ́ǹtì wúrà wá, padà èyí tí wọ́n sì mú tọ ọba Solomoni wá.
And Churam sent him by means of his servants ships, and servants that had knowledge of the sea; and they went with the servants of Solomon to Ophir, and they fetched away thence four hundred and fifty talents of gold, and brought the same to king Solomon.

< 2 Chronicles 8 >