< 2 Chronicles 7 >

1 Nígbà tí Solomoni sì ti parí àdúrà, iná sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run ó sì jó ẹbọ sísun àti ẹbọ, ògo Ọlọ́run sì kún ilé Olúwa.
Sulayman duasini tügitishigila, asmandin ot chüshüp köydürme qurbanliq hemde bashqa qurbanliqlarni qoymay köydürüwetti; Perwerdigarning shan-sheripi öyni toldurdi.
2 Àwọn àlùfáà kò sì le wo ilé Olúwa náà nítorí pé ògo Olúwa kún un.
Perwerdigarning shan-sheripi öyni tolduruwetkechke, kahinlar Perwerdigarning öyige kirelmidi.
3 Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli rí iná tí ó ń sọ̀kalẹ̀ àti ògo Olúwa lórí ilé Olúwa náà, wọ́n sì kúnlẹ̀ lórí eékún wọn pẹ̀lú ojú ni dídàbolẹ̀, wọ́n sì sin Olúwa, wọ́n sì fi ìyìn fún Olúwa wí pé, “Nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ sì dúró títí láéláé.”
Ot chüshkenlikini we Perwerdigarning shan-sheripi öyning üstide toxtighanliqini körüp, Israillarning hemmisi tash yatquzulghan meydanda yükünüp bash urup: «Perwerdigar méhribandur, Uning özgermes muhebbiti menggügiche turidu!» dep Perwerdigargha ibadet qilip teshekkür-medhiye oqushti.
4 Nígbà náà ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn sì rú ẹbọ níwájú Olúwa.
Padishah we pütkül xelq Perwerdigarning aldida qurbanliqlirini sundi.
5 Ọba Solomoni sì rú ẹbọ ti ẹgbẹ̀rún méjìlélógún, orí màlúù àti àgùntàn àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn àti ẹranko. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn ya ilé Ọlọ́run sí mímọ́.
Sulayman padishah yigirme ikki ming kala, bir yüz yigirme ming qoyni qurbanliq qilip sundi. Shundaq qilip padishah we pütkül xelq Xudaning öyini [Xudagha] béghishlidi.
6 Àwọn àlùfáà dúró ní ààyè wọn, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Lefi ti ṣe pẹ̀lú ohun èlò orin Olúwa, tí ọba Dafidi ti ṣe fún ìyìn Olúwa àti tí á lò nígbà tí ó dúpẹ́, wí pé, “Àánú rẹ̀ sì dúró láéláé,” níwájú àwọn ọmọ Lefi, àwọn àlùfáà sì fọn ìpè, gbogbo àwọn ọmọ Israẹli sì dúró.
Kahinlar we shundaqla Perwerdigargha atighan sazlarni tutqan Lawiylar öz orunlirida turatti (padishah Dawut bu sazlarni Perwerdigarning medhiyiside ishletkili yasighanidi, [u Perwerdigargha]: «Uning özgermes muhebbiti ebedgichidur» dep medhiye oqughinida ularni ishlitetti); kahinlar Lawiylarning udulida turup kanay chélishatti; Israillarning hemmisi shu yerde öre turushqanidi.
7 Solomoni sì yà àgbàlá níwájú ilé Olúwa sọ́tọ̀, níbẹ̀ sì ni ó ti ṣe ìrúbọ ẹbọ sísun àti ọ̀rá ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ó ti ṣe kò lè gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọ̀rá náà.
Sulayman Perwerdigarning öyining aldidiki hoylisining otturisini ayrip muqeddes qilip, u yerde köydürme qurbanliqlar we inaqliq qurbanliqilirining yaghlirini sundi; chünki Sulayman yasatqan mis qurban’gah köydürme qurbanliqlar, ash hediyiliri we qurbanliqlarning yaghlirini qobul qilishqa kichik keldi.
8 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àsè ní àkókò náà fún ọjọ́ méje àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ àti ìjọ ènìyàn ńlá, àwọn ènìyàn láti Lebo-Hamati títí dé odò Ejibiti.
Shuning bilen u waqitta Sulayman we uning bilen bolghan pütün Israil, yeni Xamat rayonigha kirish éghizidin tartip Misir éqinighiche hemme yerlerdin kelgen zor bir jamaet héyt ötküzdi.
9 Ní ọjọ́ kẹjọ, wọ́n sì pe ìjọ ènìyàn jọ nítorí tí wọ́n pe àpèjẹ ìyàsímímọ́ ti orí pẹpẹ fún ọjọ́ méje àti àsè náà fún ọjọ́ méje sí i.
Sekkizinchi küni ular tentenilik bir ibadet yighilishi ötküzdi; ular yette kün qurban’gahni Xudagha atap béghishlighanidi andin ular yene yette kün héyt ötküzdi.
10 Ní ọjọ́ kẹtàlélógún tí oṣù keje, ó sì rán àwọn ènìyàn padà sí ilé wọn, pẹ̀lú ayọ̀ àti ìdùnnú nínú wọn fún ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi àti Solomoni, àti fún àwọn ènìyàn Israẹli.
Yettinchi ayning yigirme üchinchi küni padishah xelqni öz öy-chédirlirige qayturdi; ular Perwerdigarning Dawutqa, Sulayman’gha we Öz xelqi Israilgha qilghan yaxshiliqliri üchün qelbide shad-xuram bolup qaytip ketti.
11 Nígbà tí Solomoni ti parí ilé Olúwa àti ibi ilé ọba, nígbà tí ó sì ti ṣe àṣeyọrí láti gbé jáde gbogbo ohun tí ó ní lọ́kàn láti ṣe nínú ilé Olúwa àti nínú ilé òun tìkára rẹ̀,
Shundaq qilip Sulayman Perwerdigarning öyini we padishahning ordisini yasap püttürdi. Sulaymanning könglige Perwerdigarning öyide we özining ordisida néme qilish kelgen bolsa, shu ishlarning hemmisi ongushluq pütti.
12 Olúwa sì farahàn Solomoni ní òru ó sì wí pé: “Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti yàn ibí yìí fún ara mi gẹ́gẹ́ bí ilé fún ẹbọ.
Andin Perwerdigar kéchide Sulayman’gha ayan bolup uninggha: «Men séning duayingni anglidim we Özümgimu bu jayni «qurbanliq öyi» bolushqa tallidim.
13 “Nígbà tí mo bá sé ọ̀run kí ó ma bá à sí òjò, tàbí láti pàṣẹ fún eṣú láti jẹ ilẹ̀ náà run tàbí rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí àárín àwọn ènìyàn mi,
Eger Men asmanni yamghur yaghmaydighan qilip étiwetsem yaki chéketkilerge zémindiki mehsulatlarni yep tashlashni buyrusam we yaki xelqim arisigha waba tarqitiwetsem,
14 tí àwọn ènìyàn, tí a fi orúkọ mi pè, tí wọ́n bá rẹ ara wọn sílẹ̀, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì rí ojú mi, tí wọ́n sì yí kúrò nínú ọ̀nà búburú wọn, nígbà náà, èmi yóò gbọ́ láti ọ̀run, èmi yóò sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n èmi yóò sì wo ilẹ̀ wọn sàn.
[shu chaghda] namim bilen atalghan bu xelqim özini kemter tutup, dua qilip yüzümni izlep, rezil yolliridin yansa, Men asmanda turup anglap, ularning gunahini kechürimen we zéminini saqaytimen.
15 Nísinsin yìí, ojú mi yóò sì là etí mi yóò sì là, sí àdúrà ọrẹ níbí yìí.
Emdi bu yerde qilin’ghan dualargha Méning közlirim ochuq we qulaqlirim ding bolidu.
16 Èmi sì ti yàn, èmi sì ti ya ilé yìí sí mímọ́ bẹ́ẹ̀ ni kí orúkọ mi kí ó le wà níbẹ̀ títí láéláé.
Men emdi namim menggü bu yerde ayan qilinsun dep bu öyni tallap, uni Özümge muqeddes qildim; közümmu, qelbimmu hemishe shu yerde bolidu.
17 “Ní ti bí ìwọ bá rìn níwájú mi gẹ́gẹ́ bí Dafidi baba rẹ ti ṣe, tí o sì ṣe gbogbo ohun tí mo paláṣẹ, tí ìwọ sì ṣe àkíyèsí àṣẹ mi láti ọ̀run,
Sen bolsang, atang Dawutning aldimda mangghinidek senmu sanga buyrughinimning hemmisige muwapiq emel qilish üchün belgilimilirim we hökümlirimni tutup aldimda mangsang,
18 Èmi yóò fi ìdí ìtẹ́ ìjọba rẹ múlẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe pẹ̀lú Dafidi baba rẹ nígbà tí mo bá a dá májẹ̀mú wí pé, ìwọ kò ní fẹ́ ẹnìkan kù láti ṣe alákòóso lórí Israẹli.
Men emdi atang Dawutqa: «Israilning textide sanga ewladingdin olturushqa bir zat kem bolmaydu» dep ehde qilghinimdek, Men séning padishahliq textingni Israilning üstide mehkem qilimen.
19 “Ṣùgbọ́n tí ìwọ bá yípadà tí o sì kọ òfin mi sílẹ̀ àti àṣẹ tí mo ti fi fún yín tí ẹ sì lọ sókè láti lọ sin ọlọ́run mìíràn tí ẹ sì bọ wọ́n,
Biraq eger siler Méningdin yüz örüp, Men silerning aldinglarda jakarlighan belgilimilirim we emrlirimni tashlap, bashqa ilahlarning qulluqigha kirip choqunsanglar,
20 nígbà náà ni èmi yóò fa Israẹli tu kúrò láti ilẹ̀ mi, èyí tí èmi ti fi fún wọn, èmi yóò sì kọ̀ ilé náà sílẹ̀ èyí tí èmi ti yà sọ́tọ̀ fún orúkọ mi, èmi yóò sì fi ṣe ọ̀rọ̀ òwe, n ó fi ṣe ẹlẹ́yà láàrín gbogbo ènìyàn,
shu chaghda Men Israilni ulargha teqdim qilghan zéminidin yulup tashlaymen; we Öz namimni körsitishke Özümge muqeddes qilghan bu öyni nezirimdin tashlaymen we Israilni hemme xelqler arisida söz-chöchek we tapa-tenining obyékti qilimen;
21 àti ní gbogbo àyíká ilé yìí nísinsin yìí, bẹ́ẹ̀ ni yóò di ohun ìtànjẹ; gbogbo àwọn tí ó bá sì kọjá níbẹ̀ ni yóò jáláyà, wọn yóò sì wí pé, ‘Kí ni ó dé tí Olúwa fì ṣe irú èyí sí ilẹ̀ yí àti sí ilé yìí?’
bu öy gerche hazir ulugh bolsimu, shu zamanda uningdin ötkenlerning hemmisi qattiq heyran qiliship: «Perwerdigar bu zémin’gha we bu öyge némishqa shundaq qilghandu?» dep soraydu.
22 Àwọn ènìyàn yóò sì dáhùn wí pé, ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run baba wọn ẹni tí ó mú wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n sì ti fi ọwọ́ gba ọlọ́run mìíràn mọ́ra, wọ́n bọ wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń sìn wọ́n, ìdí nìyí tí ó fi mú gbogbo ìjàǹbá náà wá sórí wọn.’”
Kishiler: — Chünki [zémindiki xelqler] ata-bowilirining Xudasi, yeni ularni Misir zéminidin chiqarghan Perwerdigarni tashlap, özlirini bashqa ilarhlargha baghlap, ulargha sejde qilip qulluqida bolghanliqi üchün, U bu pütkül külpetni ularning béshigha chüshürüptu, dep jawab béridu.

< 2 Chronicles 7 >