< 2 Chronicles 7 >

1 Nígbà tí Solomoni sì ti parí àdúrà, iná sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run ó sì jó ẹbọ sísun àti ẹbọ, ògo Ọlọ́run sì kún ilé Olúwa.
Et sitôt que Salomon eut achevé de faire sa prière, le feu descendit des cieux, et consuma l'holocauste et les sacrifices, et la gloire de l'Eternel remplit le Temple.
2 Àwọn àlùfáà kò sì le wo ilé Olúwa náà nítorí pé ògo Olúwa kún un.
Et les Sacrificateurs ne pouvaient entrer dans la maison de l'Eternel, parce que la gloire de l'Eternel avait rempli sa maison.
3 Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli rí iná tí ó ń sọ̀kalẹ̀ àti ògo Olúwa lórí ilé Olúwa náà, wọ́n sì kúnlẹ̀ lórí eékún wọn pẹ̀lú ojú ni dídàbolẹ̀, wọ́n sì sin Olúwa, wọ́n sì fi ìyìn fún Olúwa wí pé, “Nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ sì dúró títí láéláé.”
Et tous les enfants d'Israël voyant comment le feu descendait, et comment la gloire de l'Eternel était sur la maison, se courbèrent le visage en terre sur le pavé, et se prosternèrent, et célébrèrent l'Eternel, [en disant]: Ô! qu'il est bon, parce que sa gratuité demeure éternellement.
4 Nígbà náà ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn sì rú ẹbọ níwájú Olúwa.
Or le Roi et tout le peuple sacrifiaient des sacrifices devant l'Eternel.
5 Ọba Solomoni sì rú ẹbọ ti ẹgbẹ̀rún méjìlélógún, orí màlúù àti àgùntàn àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn àti ẹranko. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn ya ilé Ọlọ́run sí mímọ́.
Et le Roi Salomon offrit un sacrifice de vingt et deux mille bœufs, et de six vingt mille brebis. Ainsi le Roi et tout le peuple dédièrent la maison de Dieu.
6 Àwọn àlùfáà dúró ní ààyè wọn, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Lefi ti ṣe pẹ̀lú ohun èlò orin Olúwa, tí ọba Dafidi ti ṣe fún ìyìn Olúwa àti tí á lò nígbà tí ó dúpẹ́, wí pé, “Àánú rẹ̀ sì dúró láéláé,” níwájú àwọn ọmọ Lefi, àwọn àlùfáà sì fọn ìpè, gbogbo àwọn ọmọ Israẹli sì dúró.
Et les Sacrificateurs se tenaient à leurs emplois, et les Lévites avec les instruments de musique de l'Eternel, que le Roi David avait faits pour célébrer l'Eternel, [en disant], que sa gratuité demeure éternellement; ayant les Psaumes de David entre leurs mains. Les Sacrificateurs aussi sonnaient des trompettes vis-à-vis d'eux, et tout Israël était debout.
7 Solomoni sì yà àgbàlá níwájú ilé Olúwa sọ́tọ̀, níbẹ̀ sì ni ó ti ṣe ìrúbọ ẹbọ sísun àti ọ̀rá ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ó ti ṣe kò lè gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọ̀rá náà.
Et Salomon consacra le milieu du parvis qui était devant la maison de l'Eternel; car il offrit là les holocaustes, et les graisses des sacrifices de prospérités, parce que l'autel d'airain, qu'il avait fait, ne pouvait contenir les holocaustes, et les gâteaux, et les graisses.
8 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àsè ní àkókò náà fún ọjọ́ méje àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ àti ìjọ ènìyàn ńlá, àwọn ènìyàn láti Lebo-Hamati títí dé odò Ejibiti.
En ce temps-là donc Salomon célébra une fête solennelle, pendant sept jours, et avec lui, tout Israël, qui était une fort grande multitude de peuple, assemblé depuis Hamath, jusqu'au torrent d'Egypte.
9 Ní ọjọ́ kẹjọ, wọ́n sì pe ìjọ ènìyàn jọ nítorí tí wọ́n pe àpèjẹ ìyàsímímọ́ ti orí pẹpẹ fún ọjọ́ méje àti àsè náà fún ọjọ́ méje sí i.
Et au huitième jour ils firent une assemblée solennelle, car ils célébrèrent la dédicace de l'autel pendant sept jours, et la fête solennelle, pendant sept autres jours.
10 Ní ọjọ́ kẹtàlélógún tí oṣù keje, ó sì rán àwọn ènìyàn padà sí ilé wọn, pẹ̀lú ayọ̀ àti ìdùnnú nínú wọn fún ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi àti Solomoni, àti fún àwọn ènìyàn Israẹli.
Et au vingt et troisième jour du septième mois il laissa aller le peuple en ses tentes, se réjouissant et ayant le cœur plein de joie, à cause du bien que l'Eternel avait fait à David, et à Salomon, et à Israël son peuple.
11 Nígbà tí Solomoni ti parí ilé Olúwa àti ibi ilé ọba, nígbà tí ó sì ti ṣe àṣeyọrí láti gbé jáde gbogbo ohun tí ó ní lọ́kàn láti ṣe nínú ilé Olúwa àti nínú ilé òun tìkára rẹ̀,
Salomon donc acheva la maison de l'Eternel, et la maison Royale; et il réussit en tout ce qu'il avait eu dessein de faire dans la maison de l'Eternel, et dans sa maison.
12 Olúwa sì farahàn Solomoni ní òru ó sì wí pé: “Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti yàn ibí yìí fún ara mi gẹ́gẹ́ bí ilé fún ẹbọ.
L'Eternel s'apparut encore à Salomon de nuit, et lui dit: J'ai exaucé ta prière, et je me suis choisi ce lieu-ci pour une maison de sacrifice.
13 “Nígbà tí mo bá sé ọ̀run kí ó ma bá à sí òjò, tàbí láti pàṣẹ fún eṣú láti jẹ ilẹ̀ náà run tàbí rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí àárín àwọn ènìyàn mi,
Si je ferme les cieux, et qu'il n'y ait point de pluie; et si je commande aux sauterelles de consumer la terre; et si j'envoie la mortalité parmi mon peuple;
14 tí àwọn ènìyàn, tí a fi orúkọ mi pè, tí wọ́n bá rẹ ara wọn sílẹ̀, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì rí ojú mi, tí wọ́n sì yí kúrò nínú ọ̀nà búburú wọn, nígbà náà, èmi yóò gbọ́ láti ọ̀run, èmi yóò sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n èmi yóò sì wo ilẹ̀ wọn sàn.
Et que mon peuple, sur lequel mon Nom est réclamé, s'humilie, et fasse des prières, et recherche ma face, et se détourne de sa mauvaise voie, alors je l'exaucerai des cieux, et je pardonnerai leurs péchés, et je guérirai leur pays.
15 Nísinsin yìí, ojú mi yóò sì là etí mi yóò sì là, sí àdúrà ọrẹ níbí yìí.
Mes yeux seront désormais ouverts, et mes oreilles attentives à la prière qu'on fera dans ce lieu-ci.
16 Èmi sì ti yàn, èmi sì ti ya ilé yìí sí mímọ́ bẹ́ẹ̀ ni kí orúkọ mi kí ó le wà níbẹ̀ títí láéláé.
Car j'ai maintenant choisi et sanctifié cette maison, afin que mon Nom y soit à toujours; et mes yeux et mon cœur seront toujours-là.
17 “Ní ti bí ìwọ bá rìn níwájú mi gẹ́gẹ́ bí Dafidi baba rẹ ti ṣe, tí o sì ṣe gbogbo ohun tí mo paláṣẹ, tí ìwọ sì ṣe àkíyèsí àṣẹ mi láti ọ̀run,
Et quant à toi, si tu marches devant moi comme a marché David ton père, faisant tout ce que je t'ai commande, et [si] tu gardes mes statuts et mes ordonnances;
18 Èmi yóò fi ìdí ìtẹ́ ìjọba rẹ múlẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe pẹ̀lú Dafidi baba rẹ nígbà tí mo bá a dá májẹ̀mú wí pé, ìwọ kò ní fẹ́ ẹnìkan kù láti ṣe alákòóso lórí Israẹli.
Alors j'affermirai le trône de ton Royaume, comme je l'ai promis à David ton père, en disant: Il ne te sera point retranché de [successeur] pour régner en Israël.
19 “Ṣùgbọ́n tí ìwọ bá yípadà tí o sì kọ òfin mi sílẹ̀ àti àṣẹ tí mo ti fi fún yín tí ẹ sì lọ sókè láti lọ sin ọlọ́run mìíràn tí ẹ sì bọ wọ́n,
Mais si vous vous détournez, et si vous abandonnez mes statuts, et mes commandements que je vous ai proposés, et que vous vous en alliez et serviez d'autres dieux, et vous prosterniez devant eux;
20 nígbà náà ni èmi yóò fa Israẹli tu kúrò láti ilẹ̀ mi, èyí tí èmi ti fi fún wọn, èmi yóò sì kọ̀ ilé náà sílẹ̀ èyí tí èmi ti yà sọ́tọ̀ fún orúkọ mi, èmi yóò sì fi ṣe ọ̀rọ̀ òwe, n ó fi ṣe ẹlẹ́yà láàrín gbogbo ènìyàn,
Je les arracherai de dessus ma terre, que je leur ai donnée, et je rejetterai de devant moi cette maison, que j'ai consacrée à mon Nom, et je ferai qu'elle sera un sujet de raillerie parmi tous les peuples.
21 àti ní gbogbo àyíká ilé yìí nísinsin yìí, bẹ́ẹ̀ ni yóò di ohun ìtànjẹ; gbogbo àwọn tí ó bá sì kọjá níbẹ̀ ni yóò jáláyà, wọn yóò sì wí pé, ‘Kí ni ó dé tí Olúwa fì ṣe irú èyí sí ilẹ̀ yí àti sí ilé yìí?’
Et quiconque passera près de cette maison, qui aura été haut élevée, sera étonné, et on dira: Pourquoi l'Eternel a-t-il traité ainsi ce pays, et cette maison?
22 Àwọn ènìyàn yóò sì dáhùn wí pé, ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run baba wọn ẹni tí ó mú wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n sì ti fi ọwọ́ gba ọlọ́run mìíràn mọ́ra, wọ́n bọ wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń sìn wọ́n, ìdí nìyí tí ó fi mú gbogbo ìjàǹbá náà wá sórí wọn.’”
Et on répondra: Parce qu'ils ont abandonné l'Eternel le Dieu de leurs pères, qui les avait retirés du pays d'Egypte, et qu'ils se sont attachés à d'autres dieux, et se sont prosternés devant eux, et les ont servis, à cause de cela il a fait venir tout ce mal sur eux.

< 2 Chronicles 7 >