< 2 Chronicles 6 >
1 Nígbà náà ni Solomoni wí pé, “Olúwa ti sọ wí pé òun yóò máa gbé nínú òkùnkùn tí ó ṣú biribiri;
Ngalesosikhathi uSolomoni wathi: UJehova wathi uzahlala emnyameni onzima.
2 ṣùgbọ́n èmi ti kọ́ tẹmpili dáradára fún ọ ibi tí ìwọ yóò máa gbé títí láé.”
Kodwa mina ngikwakhele indlu yokuhlala, lendawo yokuhlala kwakho kuze kube nini lanini.
3 Ní ìgbà tí gbogbo ìjọ Israẹli dúró níbẹ̀, ọba yíjú padà ó sì fi ìbùkún fún gbogbo wọn.
Inkosi yasiphendula ubuso bayo, yabusisa ibandla lonke lakoIsrayeli; ibandla lonke-ke lakoIsrayeli lalimi.
4 Nígbà náà ni ó sì wí pé: “Ògo ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ mú ohun tí ó fi ẹnu rẹ̀ sọ fún Dafidi baba mi ṣẹ. Nítorí tí ó wí pé,
Yasisithi: Kayibusiswe iNkosi, uNkulunkulu kaIsrayeli, eyakhuluma ngomlomo wayo kuDavida ubaba yakugcwalisa ngezandla zayo, isithi:
5 ‘Láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ènìyàn mi jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, èmi kò yan ìlú kan nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli, láti kọ́ ilé, kí orúkọ mi kí ó lè wà níbẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò yan ẹnikẹ́ni láti jẹ́ olórí lórí Israẹli ènìyàn mi.
Kusukela ngosuku engakhupha ngalo abantu bami elizweni leGibhithe kangikhethanga muzi ezizweni zonke zakoIsrayeli ukwakha indlu, ukuthi ibizo lami libe lapho, kangikhethanga muntu ukuba ngumkhokheli phezu kwabantu bami uIsrayeli.
6 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí èmi ti yan Jerusalẹmu, kí orúkọ mi le è wà níbẹ̀, èmi sì ti yan Dafidi láti jẹ ọba lórí Israẹli ènìyàn mi.’
Kodwa ngakhetha iJerusalema ukuthi ibizo lami libe lapho, ngakhetha uDavida ukuthi abe phezu kwabantu bami uIsrayeli.
7 “Baba mi Dafidi ti ní-in lọ́kàn láti kọ́ tẹmpili fún orúkọ Olúwa, àní Ọlọ́run Israẹli.
Njalo kwakusenhliziyweni kaDavida ubaba ukwakhela ibizo leNkosi, uNkulunkulu kaIsrayeli, indlu.
8 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Dafidi baba mi pé, ‘Nítorí tí ó wà ní ọkàn rẹ láti kọ́ tẹmpili yìí fún orúkọ mi, ìwọ ṣe ohun dáradára láti ní èyí ní ọkàn rẹ̀.
Kodwa iNkosi yathi kuDavida ubaba: Njengoba kwakusenhliziyweni yakho ukwakhela ibizo lami indlu, wenze kuhle ngokuthi kwakusenhliziyweni yakho.
9 Ṣùgbọ́n síbẹ̀, ìwọ kọ́ ni yóò kọ́ tẹmpili náà, bí kò ṣe ọmọ rẹ, ẹni tí o jẹ́ ẹran-ara àti ẹ̀jẹ̀ rẹ: òun ni yóò kọ́ tẹmpili fún orúkọ mi.’
Lanxa kunjalo kawuyikuyakha indlu wena, kodwa indodana yakho ezaphuma ekhalweni lwakho, yiyo ezakwakhela ibizo lami indlu.
10 “Olúwa sì ti mú ìlérí rẹ̀ ṣẹ. Èmi ti dìde ní ipò Dafidi baba mi, a sì gbé mi ka ìtẹ́ Israẹli, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣe ìlérí, èmi sì ti kọ́ tẹmpili fún orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
INkosi isiqinisile ilizwi layo eyalikhulumayo, ngoba ngivelile esikhundleni sikaDavida ubaba, ngihlezi esihlalweni sobukhosi sikaIsrayeli, njengokukhuluma kweNkosi; sengilakhele ibizo leNkosi, uNkulunkulu kaIsrayeli, indlu.
11 Níbẹ̀ ni èmi sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa sí, nínú èyí ti májẹ̀mú ti Olúwa bá àwọn Israẹli ènìyàn mi dá wà.”
Ngiwubeke khona umtshokotsho lapho okulesivumelwano seNkosi khona eyasenza labantwana bakoIsrayeli.
12 Nígbà náà ni Solomoni dúró níwájú pẹpẹ Olúwa, ní iwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, ó sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì.
Wasesima phambi kwelathi leNkosi maqondana lebandla lonke lakoIsrayeli, welula izandla zakhe.
13 Solomoni ṣe àga idẹ kan tí ó jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún ní gígùn àti ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún fífẹ̀ àti ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ta ní gíga, a gbé e sí àárín àgbàlá ti òde. Ó sì dúró ní orí rẹ̀, àti pé ó kúnlẹ̀ lórí eékún rẹ̀ níwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, ó sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sí òkè ọ̀run.
Ngoba uSolomoni wayenze isitubhu sethusi, ubude baso buzingalo ezinhlanu, lobubanzi baso buzingalo ezinhlanu, lokuphakama kwaso kuzingalo ezintathu, wasimisa phakathi laphakathi kweguma. Wema phezu kwaso, waguqa ngamadolo akhe phambi kwebandla lonke lakoIsrayeli, welulela izandla zakhe emazulwini,
14 Ó wí pé: “Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, kò sí Ọlọ́run tí ó dàbí rẹ ní ọ̀run àti ní ayé: ìwọ tí o pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí ń fi tọkàntọkàn wọn rìn ní ọ̀nà rẹ.
wathi: Nkosi, Nkulunkulu kaIsrayeli, kakho uNkulunkulu onjengawe emazulwini lemhlabeni, ogcina isivumelwano lomusa ezincekwini zakho ezihamba phambi kwakho ngayo yonke inhliziyo yazo,
15 Ìwọ tí o pa ìlérí tí o ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ Dafidi baba mi mọ́; nítorí ìwọ ti fi ẹnu rẹ ṣe ìlérí àti pé ìwọ ti fi ọwọ́ rẹ mú un ṣẹ; bí ó ti rí lónìí yìí.
ogcinele inceku yakho uDavida ubaba lokho owakutsho kuyo; ngoba wakhuluma ngomlomo wakho usukugcwalisile ngesandla sakho njengalamuhla.
16 “Nísinsin yìí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, pa ìlérí tí ó ti ṣe mọ́ fún ìránṣẹ́ rẹ Dafidi baba mi nígbà tí o wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ kù láti ní ọkùnrin láti jókòó níwájú mi lórí ìtẹ́ Israẹli, kìkì bí àwọn ọmọ rẹ tí wọ́n bá kíyèsi ara nínú gbogbo ohun tí wọ́n ṣe láti rìn níwájú mi gẹ́gẹ́ bí òfin mi gẹ́gẹ́ bí o sì ti ṣe.’
Ngakho-ke, Nkosi, Nkulunkulu kaIsrayeli, gcinela inceku yakho uDavida ubaba lokho owakutsho kuyo usithi: Kakuyikusweleka umuntu kuwe phambi kobuso bami ozahlala esihlalweni sobukhosi sikaIsrayeli; kuphela uba abantwana bakho beqaphela indlela yabo phambi kwami, ukuthi bahambe ngomlayo wami, njengalokho uhambile phambi kwami.
17 Nísinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run Israẹli, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ tí o ti ṣèlérí fún ìránṣẹ́ rẹ Dafidi kí ó wá sí ìmúṣẹ.
Ngakho-ke, Nkosi, Nkulunkulu kaIsrayeli, kaliqiniseke ilizwi lakho owalikhuluma encekwini yakho, kuDavida.
18 “Ṣùgbọ́n ṣé Ọlọ́run nítòótọ́ yóò máa bá àwọn ènìyàn gbé lórí ilẹ̀ ayé bí? Ọ̀run àti ọ̀run gíga kò le gbà ọ́. Báwo ni ó ṣe kéré tó, ilé Olúwa tí mo ti kọ́!
Kambe ngeqiniso uNkulunkulu angahlala labantu emhlabeni? Khangela, amazulu, yebo, amazulu amazulu angekwanele; kangakanani-ke lindlu engiyakhileyo?
19 Síbẹ̀ ṣe àfiyèsí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ̀ fún àánú, Olúwa Ọlọ́run mi, gbọ́ ẹkún àti àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ń gbà níwájú rẹ.
Kodwa phendukela emkhulekweni wenceku yakho lekuncengeni kwayo, Nkosi Nkulunkulu wami, ukuzwa ukukhala lomkhuleko inceku yakho ekukhulekayo phambi kwakho.
20 Kí ojú rẹ kí ó lè ṣí sí ilé Olúwa ní ọ̀sán àti lóru, ní ibí yìí tí ìwọ ti wí pé ìwọ yóò fi orúkọ rẹ síbẹ̀. Kí ìwọ kí ó gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà lórí ibí yìí.
Ukuze amehlo akho avulekele lindlu emini lebusuku, endaweni owatsho ngayo ukuthi uzabeka ibizo lakho khona, ukuthi uwuzwe umkhuleko inceku yakho ewukhulekayo ikhangele kulindawo.
21 Gbọ́ ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ àti ti àwọn ènìyàn Israẹli nígbà tí wọ́n bá ń gbàdúrà lórí ibí yìí. Gbọ́ láti ọ̀run, ibùgbé rẹ, nígbà tí ìwọ bá sì gbọ́, dáríjì.
Ngakho zwana ukuncenga kwenceku yakho lokwabantu bakho uIsrayeli abazakukhuleka bekhangele kulindawo; yebo, uzwe wena, usendaweni yakho yokuhlala, usemazulwini; lapho usizwa, uthethelele.
22 “Nígbà tí ọkùnrin kan bá dẹ́ṣẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀, tí a sì mú búra, tí ó sì búra níwájú pẹpẹ rẹ nínú ilé yìí,
Uba umuntu esona kumakhelwane wakhe, amethese isifungo ukumenza afunge, njalo isifungo size phambi kwelathi lakho kulindlu,
23 nígbà náà, gbọ́ láti ọ̀run kí o sì dáhùn. Ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn ìránṣẹ́ rẹ, san padà fún ẹni tí ó jẹ̀bi nípa mímú padà wá sí orí òun tìkára rẹ̀ ohun tí ó ti ṣe. Ṣe ìdáláre fún olódodo, bẹ́ẹ̀ sì ni, fi fún un gẹ́gẹ́ bí òdodo rẹ̀.
zwana-ke wena usemazulwini, njalo yenza wahlulele inceku zakho, ngokuphindisela okhohlakeleyo, ngokunika indlela yakhe ekhanda lakhe, langokulungisisa olungileyo, ngokumnika njengokulunga kwakhe.
24 “Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ Israẹli bá ní ìjákulẹ̀ níwájú àwọn ọ̀tá nítorí wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ àti nígbà tí wọ́n bá sì yípadà, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n gbàdúrà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ nínú ilé Olúwa yìí,
Lalapho abantu bakho uIsrayeli betshaywa phambi kwesitha, ngoba bonile kuwe, uba bephenduka, balivume ibizo lakho, bakhuleke bencenga phambi kwakho kulindlu,
25 nígbà náà, ni kí o gbọ́ láti ọ̀run kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn Israẹli jì wọ́n kí o sì mú wọn padà wá sílé tí o ti fi fún wọn àti àwọn baba wọn.
zwana-ke wena usemazulwini, uthethelele isono sabantu bakho uIsrayeli, ubabuyisele elizweni owalinika bona laboyise.
26 “Nígbà tí a bá ti ọ̀run, tí kò sì sí òjò nítorí àwọn ènìyàn rẹ ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ, nígbà tí wọ́n bá sì gbàdúrà sí ibí yìí tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ tí wọ́n sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn nítorí ìwọ ti pọ́n wọn lójú,
Lapho amazulu evaliwe, njalo kungelazulu, ngoba bonile kuwe, uba bekhuleka bekhangele kulindawo belivuma ibizo lakho, baphenduke esonweni sabo, nxa ubahluphile,
27 nígbà náà gbọ́ láti ọ̀run kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli kọ́ wọn ní ọ̀nà tí ó tọ́ nínú èyí tí wọn ó máa rìn, kí o sì rọ òjò sórí ilẹ̀ tí o ti fi fún àwọn ènìyàn rẹ fún ìní.
zwana-ke wena usemazulwini, uthethelele isono senceku zakho lesabantu bakho uIsrayeli, usubafundise indlela enhle abazahamba ngayo; unise izulu elizweni lakho owalinika abantu bakho libe yilifa labo.
28 “Nígbà tí ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn bá wá sí ilẹ̀ náà, ìrẹ̀dànù tàbí ìmúwòdù, eṣú tàbí ẹlẹ́ǹgà, tàbí nígbà tí àwọn ọ̀tá wọn bá yọ wọ́n lẹ́nu nínú ọ̀kan lára àwọn ìlú wọn, ohunkóhun, ìpọ́njú tàbí ààrùn lè wá.
Uba kulendlala elizweni, uba kulomatshayabhuqe wesifo, uba kulokutshisa, lengumane, isikhonyane, lemihogoyi; uba izitha zabo zibavimbezela elizweni lesango labo, loba yiyiphi inhlupheko laloba yiwuphi umkhuhlane;
29 Nígbà tí àdúrà tàbí ẹ̀bẹ̀ bá sì wá láti ọ̀dọ̀ ẹnikẹ́ni àwọn ènìyàn rẹ Israẹli olúkúlùkù mọ̀ nípa ìpọ́njú rẹ̀ àti ìbànújẹ́, tí ó sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sí ìhà ilé Olúwa yìí.
lawuphi umkhuleko, lakuphi ukuncenga, okuzakwenziwa languwuphi umuntu, kumbe yibo bonke abantu bakho uIsrayeli, lapho besazi, ngulowo lalowo inhlupheko yakhe losizi lwakhe, eselulela izandla zakhe kulindlu;
30 Nígbà náà gbọ́ láti ọ̀run ibùgbé rẹ dáríjì, kí o sì pín fún olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí i gbogbo ohun tí ó ṣe, nígbà tí ìwọ ti mọ ọkàn rẹ̀ (nítorí ìwọ nìkan ni ó mọ ọkàn ènìyàn.)
zwana-ke wena usemazulwini, indawo yakho yokuhlala, uthethelele, uphe ngulowo lalowo ngokwezindlela zakhe zonke, onhliziyo yakhe uyayazi, ngoba nguwe wedwa owazi inhliziyo yabantwana babantu,
31 Bẹ́ẹ̀ ni kí wọn kí ó lè bẹ̀rù rẹ kí wọn kí ó sì rìn ní ọ̀nà rẹ ní gbogbo ìgbà tí wọ́n ń gbé nínú ilé tí o ti fi fún àwọn baba wa.
ukuze bakwesabe bahambe endleleni zakho insuku zonke abaziphila ebusweni bomhlaba owawupha obaba.
32 “Ní ti àwọn àlejò tí wọn kò sí lára àwọn ènìyàn rẹ Israẹli ṣùgbọ́n tí wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn nítorí orúkọ ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára rẹ àti nínà apá rẹ, nígbà tí ó bá wá tí ó sì gbàdúrà pẹ̀lú kíkojú si ilé Olúwa yìí.
Njalo mayelana lowezizweni ongesuye owabantu bakho uIsrayeli, kodwa evela elizweni elikhatshana ngenxa yebizo lakho elikhulu lesandla sakho esilamandla lengalo yakho eyeluliweyo; lapho besizakhuleka kulindlu,
33 Nígbà náà, gbọ́ láti ọ̀run àní láti ibi ibùgbé rẹ, kí o sì ṣe ohun tí àwọn àlejò béèrè lọ́wọ́ rẹ. Bẹ́ẹ̀ ni kí gbogbo àwọn ènìyàn ayé kí wọn lè mọ orúkọ rẹ kí wọn sì bẹ̀rù rẹ, gẹ́gẹ́ bí Israẹli ènìyàn rẹ ti ṣe, kí wọn kí ó sì lè mọ̀ wí pé ilé yìí tí èmi ti kọ, orúkọ rẹ ni ó ń jẹ́.
zwana-ke wena usemazulwini, usendaweni yakho yokuhlala, wenze njengakho konke owezizweni akhala ngakho kuwe, ukuze bonke abantu bomhlaba bazi ibizo lakho, bakwesabe, njengabantu bakho uIsrayeli, lokuthi bazi ukuthi ibizo lakho liyabizwa phezu kwalindlu engiyakhileyo.
34 “Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ bá lọ sójú ogun lórí àwọn ọ̀tá wọn, nígbàkígbà tí o bá rán wọn, tí wọ́n sì gbàdúrà sí ọ si ìhà ìlú yìí tí ìwọ ti yàn àti ilé Olúwa tí èmi ti kọ́ fún orúkọ rẹ.
Uba abantu bakho bephuma ukuyakulwa bemelene lezitha zabo ngendlela obathume ngayo, bakhuleke kuwe endleleni yomuzi owukhethileyo lendlu engiyakhele ibizo lakho,
35 Nígbà náà gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn láti ọ̀run, kí o sì mú ọ̀rọ̀ wọn dúró.
zwana-ke usemazulwini umkhuleko wabo lokuncenga kwabo, wenze ilungelo labo.
36 “Nígbà tí wọ́n bá sì dẹ́ṣẹ̀ sí ọ—nítorí kò sí ènìyàn kan tí kì í dẹ́ṣẹ̀—bí o bá sì bínú sí wọn tí o bá sì fi wọ́n fún àwọn ọ̀tá, tí wọ́n kó wọn ní ìgbèkùn sí ilẹ̀ tí ó jìnnà réré tàbí nítòsí,
Uba besona kuwe, ngoba kakulamuntu ongoniyo, ubusubathukuthelela, ubanikele phambi kwesitha, ukuze ababathumbileyo babathumbele elizweni elikhatshana kumbe eliseduze,
37 ṣùgbọ́n, nígbà tí wọ́n bá sì yí ọkàn wọn padà ní ilẹ̀ tí wọ́n ti mú wọn ní ìgbèkùn, tí wọ́n sì ronúpìwàdà tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ pẹ̀lú rẹ ní ilẹ̀ ìgbèkùn, wọn ó sì wí pé, ‘Àwa ti dẹ́ṣẹ̀, àwa sì ti ṣe ohun tí kò dára, a sì ti ṣe búburú’;
uba benakana ngakho enhliziyweni yabo elizweni abathunjelwe kilo, baphenduke bancenge kuwe elizweni lokuthunjwa kwabo bathi: Sonile, senze okubi, senza ngenkohlakalo;
38 tí wọn bá sì yípadà sí ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn àti ẹ̀mí ní ilẹ̀ ìgbèkùn wọn níbi tí wọ́n ti mú wọn, tí wọ́n sì gbàdúrà wọn, kojú si ìlú tí ìwọ ti yàn àti lórí ilé Olúwa tí mo ti kọ́ fún orúkọ rẹ;
uba bephendukela kuwe ngayo yonke inhliziyo yabo langawo wonke umphefumulo wabo elizweni lokuthunjwa kwabo, lapho ababathumbele khona, bakhuleke ngasendleleni yelizwe labo owalinika oyise, lomuzi owukhethileyo, langasendlini engiyakhele ibizo lakho,
39 nígbà náà, láti ọ̀run, ibi ibùgbé rẹ, gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn, kí o sì mú ọ̀ràn wọn dúró, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn jì wọn, tí wọn ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ.
zwana-ke usemazulwini, usendaweni yakho yokuhlala, umkhuleko wabo lokuncenga kwabo, wenze ilungelo labo, uthethelele abantu bakho abakonileyo.
40 “Nísinsin yìí, Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ojú rẹ kí ó ṣí kí o sì tẹ́ etí rẹ sílẹ̀ fún àdúrà sí ibí yìí.
Ngakho, Nkulunkulu wami, ake amehlo akho avuleke lendlebe zakho zilalele umkhuleko walindawo.
41 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí dìde, Olúwa Ọlọ́run mi, sí ibi ìsinmi rẹ,
Khathesi-ke, sukuma, Nkosi Nkulunkulu, uze endaweni yakho yokuphumula, wena lomtshokotsho wamandla akho. Abapristi bakho, Nkosi Nkulunkulu, kabembathe usindiso, labangcwele bakho bathokoze ngokuhle.
42 Olúwa Ọlọ́run mi, má ṣe kọ̀ ẹni àmì òróró rẹ.
Nkosi Nkulunkulu, ungafulathelisi ubuso bogcotshiweyo wakho. Khumbula izisa zikaDavida inceku yakho.