< 2 Chronicles 6 >

1 Nígbà náà ni Solomoni wí pé, “Olúwa ti sọ wí pé òun yóò máa gbé nínú òkùnkùn tí ó ṣú biribiri;
Kalpasanna, kinuna ni Solomon, “Kinuna ni Yahweh nga agnaed isuna iti napuskol a kasipngetan,
2 ṣùgbọ́n èmi ti kọ́ tẹmpili dáradára fún ọ ibi tí ìwọ yóò máa gbé títí láé.”
ngem impatakderanka iti maysa a nadaeg a pagtaengam, maysa a disso a pagnaedam iti agnanayon.”
3 Ní ìgbà tí gbogbo ìjọ Israẹli dúró níbẹ̀, ọba yíjú padà ó sì fi ìbùkún fún gbogbo wọn.
Kalpasanna, timallikud ti ari ket binendisionanna amin a taripnong ti Israel, bayat nga agtaktakder amin a taripnong ti Israel.
4 Nígbà náà ni ó sì wí pé: “Ògo ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ mú ohun tí ó fi ẹnu rẹ̀ sọ fún Dafidi baba mi ṣẹ. Nítorí tí ó wí pé,
Kinunana, “Madaydayaw koma ni Yahweh a Dios ti Israel, a nagsao kenni David nga amak, ken nangtungpal iti daytoy babaen kadagiti bukodna nga ima, a kinunana,
5 ‘Láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ènìyàn mi jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, èmi kò yan ìlú kan nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli, láti kọ́ ilé, kí orúkọ mi kí ó lè wà níbẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò yan ẹnikẹ́ni láti jẹ́ olórí lórí Israẹli ènìyàn mi.
'Sipud pay iti aldaw nga inruarko dagiti tattaok iti daga ti Egipto, awan ti pinilik a siudad manipud kadagiti amin a tribu ti Israel a pangipatakderan iti maysa a balay, tapno adda sadiay ti naganko. Awan met ti siasinoman a pinilik nga agbalin a prinsipe dagiti tattaok nga Israel.
6 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí èmi ti yan Jerusalẹmu, kí orúkọ mi le è wà níbẹ̀, èmi sì ti yan Dafidi láti jẹ ọba lórí Israẹli ènìyàn mi.’
Nupay kasta, pinilik ti Jerusalem tapno adda sadiay ti naganko, ken pinilik ni David a mangituray kadagiti tattaok nga Israel.'
7 “Baba mi Dafidi ti ní-in lọ́kàn láti kọ́ tẹmpili fún orúkọ Olúwa, àní Ọlọ́run Israẹli.
Ita adda iti puso ni David nga amak, ti mangipatakder iti maysa a balay para iti nagan ni Yahweh a Dios ti Israel.
8 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Dafidi baba mi pé, ‘Nítorí tí ó wà ní ọkàn rẹ láti kọ́ tẹmpili yìí fún orúkọ mi, ìwọ ṣe ohun dáradára láti ní èyí ní ọkàn rẹ̀.
Ngem kuna ni Yahweh kenni David nga amak, 'Iti dayta nga adda iti pusom a mangipatakder iti maysa a balay para iti naganko, nasayaat ti inaramidmo nga adda iti pusom.
9 Ṣùgbọ́n síbẹ̀, ìwọ kọ́ ni yóò kọ́ tẹmpili náà, bí kò ṣe ọmọ rẹ, ẹni tí o jẹ́ ẹran-ara àti ẹ̀jẹ̀ rẹ: òun ni yóò kọ́ tẹmpili fún orúkọ mi.’
Nupay kasta, saanmo a rumbeng nga ipatakder ti balay; ngem ketdi, ti putotmo a lalaki, nga agtaudto kadagita lumom, ti mangipatakderto iti balay para iti naganko.'
10 “Olúwa sì ti mú ìlérí rẹ̀ ṣẹ. Èmi ti dìde ní ipò Dafidi baba mi, a sì gbé mi ka ìtẹ́ Israẹli, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣe ìlérí, èmi sì ti kọ́ tẹmpili fún orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
Tinungpal ni Yahweh ti sao a kinunana, ta timmakderak a kasukat ni David nga amak, ket nagtugawak iti trono ti Israel, a kas inkari ni Yahweh. Impatakderko ti balay para iti nagan ni Yahweh a Dios ti Israel.
11 Níbẹ̀ ni èmi sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa sí, nínú èyí ti májẹ̀mú ti Olúwa bá àwọn Israẹli ènìyàn mi dá wà.”
Inkabilko ti lakasa ti tulag sadiay, nga ayan ti katulagan ni Yahweh, nga inaramidna kadagiti tattao ti Israel.”
12 Nígbà náà ni Solomoni dúró níwájú pẹpẹ Olúwa, ní iwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, ó sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì.
Timmakder ni Solomon iti sangoanan ti altar ni Yahweh iti imatang ti amin a taripnong ti Israel, ket intag-ayna dagiti imana.
13 Solomoni ṣe àga idẹ kan tí ó jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún ní gígùn àti ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún fífẹ̀ àti ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ta ní gíga, a gbé e sí àárín àgbàlá ti òde. Ó sì dúró ní orí rẹ̀, àti pé ó kúnlẹ̀ lórí eékún rẹ̀ níwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, ó sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sí òkè ọ̀run.
Ta nangaramid isuna iti plataporma a bronse, lima a kubit ti kaatiddogna, lima a kubit ti kalawa ken tallo a kubit ti kangatona. Ingkabilna daytoy iti tengnga ti paraangan. Nagtakder iti rabaw daytoy ken nagparintumeng iti sangoanan ti amin a taripnong ti Israel ket intag-ayna dagiti imana.
14 Ó wí pé: “Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, kò sí Ọlọ́run tí ó dàbí rẹ ní ọ̀run àti ní ayé: ìwọ tí o pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí ń fi tọkàntọkàn wọn rìn ní ọ̀nà rẹ.
Kinunana, “O Yahweh a Dios ti Israel, awan ti Dios a kas kenka kadagiti langit wenno ditoy rabaw ti daga, a mangsalsalimetmet kadagiti tulag ken kinapudno iti tulag kadagiti adipenmo nga agtultulnog iti amin a pusoda;
15 Ìwọ tí o pa ìlérí tí o ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ Dafidi baba mi mọ́; nítorí ìwọ ti fi ẹnu rẹ ṣe ìlérí àti pé ìwọ ti fi ọwọ́ rẹ mú un ṣẹ; bí ó ti rí lónìí yìí.
sika a nangtungpal iti inkarim iti adipenmo a ni David, nga amak. Wen, nagsaoka kadagiti ngiwatmo ket tinungpalmo daytoy babaen iti imam, a kas iti daytoy nga aldaw.
16 “Nísinsin yìí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, pa ìlérí tí ó ti ṣe mọ́ fún ìránṣẹ́ rẹ Dafidi baba mi nígbà tí o wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ kù láti ní ọkùnrin láti jókòó níwájú mi lórí ìtẹ́ Israẹli, kìkì bí àwọn ọmọ rẹ tí wọ́n bá kíyèsi ara nínú gbogbo ohun tí wọ́n ṣe láti rìn níwájú mi gẹ́gẹ́ bí òfin mi gẹ́gẹ́ bí o sì ti ṣe.’
Ket ita O Yahweh, a Dios ti Israel, tungpalem ti inkarim iti adipenmo a ni David nga amak, idi kinunana, 'Agtultuloy nga adda maysa a tao iti imatangko ti agtugaw iti trono ti Israel, no laketdi ta agtulnog a sipapasnek dagiti kaputotam kadagiti lintegko, a kas iti panagtulnogmo iti sangoanak.'
17 Nísinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run Israẹli, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ tí o ti ṣèlérí fún ìránṣẹ́ rẹ Dafidi kí ó wá sí ìmúṣẹ.
Ita ngarud, O Dios ti Israel, ikararagko a matungpal koma ti inkarim iti adipenmo a ni David.
18 “Ṣùgbọ́n ṣé Ọlọ́run nítòótọ́ yóò máa bá àwọn ènìyàn gbé lórí ilẹ̀ ayé bí? Ọ̀run àti ọ̀run gíga kò le gbà ọ́. Báwo ni ó ṣe kéré tó, ilé Olúwa tí mo ti kọ́!
Ngem pudno kadi a makipagnaedto ti Dios kadagiti tattao ditoy daga? Kitaem, ti entero a sangalubongan ken ti langit a mismo ket saandaka a malaon—ad-adda a basbassit daytoy a templo nga impatakderko!
19 Síbẹ̀ ṣe àfiyèsí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ̀ fún àánú, Olúwa Ọlọ́run mi, gbọ́ ẹkún àti àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ń gbà níwájú rẹ.
Ngem pangaasim ta patgam koma daytoy a kararag ken dawat ti adipenmo, O Yahweh a Diosko; denggem ti asug ken kararag nga ikarkararag dagiti adipenmo iti sangoanam.
20 Kí ojú rẹ kí ó lè ṣí sí ilé Olúwa ní ọ̀sán àti lóru, ní ibí yìí tí ìwọ ti wí pé ìwọ yóò fi orúkọ rẹ síbẹ̀. Kí ìwọ kí ó gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà lórí ibí yìí.
Silulukat koma dagiti matam iti daytoy a templo iti aldaw ken rabii, iti lugar a kinunam nga adda koma sadiay ti naganmo tapno denggem dagiti kararag ti adipenmo nga agkararagto iti daytoy a disso.
21 Gbọ́ ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ àti ti àwọn ènìyàn Israẹli nígbà tí wọ́n bá ń gbàdúrà lórí ibí yìí. Gbọ́ láti ọ̀run, ibùgbé rẹ, nígbà tí ìwọ bá sì gbọ́, dáríjì.
Isu a denggem koma dagiti kiddaw ti adipenmo ken dagiti tattaom nga Israel inton agkararagkami a nakasango iti daytoy a disso. Wen, denggem manipud iti disso a pagnanaedam, manipud kadagiti langit; ket inton denggem, mamakawanka.
22 “Nígbà tí ọkùnrin kan bá dẹ́ṣẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀, tí a sì mú búra, tí ó sì búra níwájú pẹpẹ rẹ nínú ilé yìí,
No makabasol ti maysa a tao a maibusor iti kaarrubana ket masapul nga agsapata, ket no umay isuna ken agsapata iti sangoanan ti altarmo iti daytoy a balay,
23 nígbà náà, gbọ́ láti ọ̀run kí o sì dáhùn. Ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn ìránṣẹ́ rẹ, san padà fún ẹni tí ó jẹ̀bi nípa mímú padà wá sí orí òun tìkára rẹ̀ ohun tí ó ti ṣe. Ṣe ìdáláre fún olódodo, bẹ́ẹ̀ sì ni, fi fún un gẹ́gẹ́ bí òdodo rẹ̀.
denggem ngarud manipud kadagiti langit ket agtignay ken ukomem dagiti adipenmo, supapakam ti nadangkes, tapno agballatek kenkuana ti aramidna. Ket ipakaammom a nalinteg ti awan basolna, tapno maikkan isuna iti gunggona gapu iti kinalintegna.
24 “Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ Israẹli bá ní ìjákulẹ̀ níwájú àwọn ọ̀tá nítorí wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ àti nígbà tí wọ́n bá sì yípadà, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n gbàdúrà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ nínú ilé Olúwa yìí,
No dagiti tattaom nga Israel ket pinarmek ti kabusor gapu ta nagbasolda kenka, no agsublida kenka, raemenda ti naganmo, agkararag ken agkiddawda iti pammakawan iti sangoanam iti daytoy a templo—
25 nígbà náà, ni kí o gbọ́ láti ọ̀run kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn Israẹli jì wọ́n kí o sì mú wọn padà wá sílé tí o ti fi fún wọn àti àwọn baba wọn.
ket denggem koma manipud kadagiti langit ken pakawanem ti basol dagiti tattaom nga Israel; isublim ida iti daga nga intedmo kadakuada ken kadagiti kapuonanda.
26 “Nígbà tí a bá ti ọ̀run, tí kò sì sí òjò nítorí àwọn ènìyàn rẹ ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ, nígbà tí wọ́n bá sì gbàdúrà sí ibí yìí tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ tí wọ́n sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn nítorí ìwọ ti pọ́n wọn lójú,
No agrikep dagiti tangatang ket awan ti tudo gapu ta nagbasol dagiti tattao kenka—no agkararagda a nakasango iti daytoy a disso, raemenda ti naganmo, ket isardengda dagiti basolda inton parigatem ida—
27 nígbà náà gbọ́ láti ọ̀run kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli kọ́ wọn ní ọ̀nà tí ó tọ́ nínú èyí tí wọn ó máa rìn, kí o sì rọ òjò sórí ilẹ̀ tí o ti fi fún àwọn ènìyàn rẹ fún ìní.
ket denggem koma dita langit ken pakawanem ti basol dagiti adipenmo ken dagiti tattaom nga Israel, inton idalanmo ida iti nasayaat a dalan a rumbeng a pagnaanda. Pagtudoem iti dagam, nga intedmo kadagiti tattaom, a kas tawidda.
28 “Nígbà tí ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn bá wá sí ilẹ̀ náà, ìrẹ̀dànù tàbí ìmúwòdù, eṣú tàbí ẹlẹ́ǹgà, tàbí nígbà tí àwọn ọ̀tá wọn bá yọ wọ́n lẹ́nu nínú ọ̀kan lára àwọn ìlú wọn, ohunkóhun, ìpọ́njú tàbí ààrùn lè wá.
No kas pangarigan adda bisin iti dayta a daga, wenno kas pangarigan ta adda sakit, kebbet wenno buot, dagiti dudon wenno igges; wenno kas pangarigan ta rauten dagiti kabusor dagiti ruangan iti dagada, wenno adda didigra wenno sakit—
29 Nígbà tí àdúrà tàbí ẹ̀bẹ̀ bá sì wá láti ọ̀dọ̀ ẹnikẹ́ni àwọn ènìyàn rẹ Israẹli olúkúlùkù mọ̀ nípa ìpọ́njú rẹ̀ àti ìbànújẹ́, tí ó sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sí ìhà ilé Olúwa yìí.
ket kas pangarigan ta agkarkararag ken dumawdawat ti maysa a tao wenno dagiti amin a tattaom nga Israel—a bigbigen ti tunggal maysa ti didigra ken ladingit iti bukodna a puso bayat iti panangitag-ayna kadagiti imana a nakasango iti templo.
30 Nígbà náà gbọ́ láti ọ̀run ibùgbé rẹ dáríjì, kí o sì pín fún olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí i gbogbo ohun tí ó ṣe, nígbà tí ìwọ ti mọ ọkàn rẹ̀ (nítorí ìwọ nìkan ni ó mọ ọkàn ènìyàn.)
Ket denggem koma manipud langit, ti lugar a pagnanaedam; pakawanem ken gunggonaam ti tunggal tao segun kadagiti amin a wagasna; ammom ti pusona, gapu ta Sika ken Sika laeng ti makaammo kadagiti puso dagiti tattao.
31 Bẹ́ẹ̀ ni kí wọn kí ó lè bẹ̀rù rẹ kí wọn kí ó sì rìn ní ọ̀nà rẹ ní gbogbo ìgbà tí wọ́n ń gbé nínú ilé tí o ti fi fún àwọn baba wa.
Aramidem daytoy tapno agbutengda kenka, tapno agtulnogda kadagiti wagasmo iti amin nga aldaw iti panagbiagda iti rabaw ti daga nga intedmo kadagiti kapuonanmi.
32 “Ní ti àwọn àlejò tí wọn kò sí lára àwọn ènìyàn rẹ Israẹli ṣùgbọ́n tí wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn nítorí orúkọ ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára rẹ àti nínà apá rẹ, nígbà tí ó bá wá tí ó sì gbàdúrà pẹ̀lú kíkojú si ilé Olúwa yìí.
Maysa pay, maipapan kadagiti ganggannaet a saan a maibilang kadagiti tattaom nga Israel: no aggapu isuna iti adayo a pagilian gapu iti naindaklan a naganmo, ti nabileg nga imam, ken ti nakangato a takkiagmo; inton umayda ket agkararagda a nakasango iti daytoy a balay—
33 Nígbà náà, gbọ́ láti ọ̀run àní láti ibi ibùgbé rẹ, kí o sì ṣe ohun tí àwọn àlejò béèrè lọ́wọ́ rẹ. Bẹ́ẹ̀ ni kí gbogbo àwọn ènìyàn ayé kí wọn lè mọ orúkọ rẹ kí wọn sì bẹ̀rù rẹ, gẹ́gẹ́ bí Israẹli ènìyàn rẹ ti ṣe, kí wọn kí ó sì lè mọ̀ wí pé ilé yìí tí èmi ti kọ, orúkọ rẹ ni ó ń jẹ́.
denggem koma ngarud manipud kadagiti langit, a lugar a pagnanaedam, ket aramidem ti aniaman a kidkiddawen kenka ti ganggannaet, tapno maammoan dagiti amin a bunggoy dagiti tattao iti rabaw ti daga ti naganmo, tapno agbutengda kenka, a kas kadagiti tattaom nga Israel, ken tapno maammoanda daytoy a balay nga impatakderko a naawagan babaen iti naganmo.
34 “Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ bá lọ sójú ogun lórí àwọn ọ̀tá wọn, nígbàkígbà tí o bá rán wọn, tí wọ́n sì gbàdúrà sí ọ si ìhà ìlú yìí tí ìwọ ti yàn àti ilé Olúwa tí èmi ti kọ́ fún orúkọ rẹ.
No kas pangarigan ta mapan makigubat dagiti tattaom kadagiti kabusorda, babaen iti aniaman a wagas a panangibaonmo kadakuada, ket kas pangarigan ta agkararagda kenka a nakasango iti daytoy a siudad a pinilim, ken nakasango iti balay a binangonko para iti naganmo.
35 Nígbà náà gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn láti ọ̀run, kí o sì mú ọ̀rọ̀ wọn dúró.
Ket denggem koma manipud kadagiti langit dagiti kararagda, dagiti kiddawda, ket pagballigiem ida kadagiti dawatda.
36 “Nígbà tí wọ́n bá sì dẹ́ṣẹ̀ sí ọ—nítorí kò sí ènìyàn kan tí kì í dẹ́ṣẹ̀—bí o bá sì bínú sí wọn tí o bá sì fi wọ́n fún àwọn ọ̀tá, tí wọ́n kó wọn ní ìgbèkùn sí ilẹ̀ tí ó jìnnà réré tàbí nítòsí,
No kas pangarigan ta agbasolda kenka—agsipud ta awan ti tao a saan nga agbasol—ken no kas pangarigan ta makaungetka kadakuada ket iyawatmo ida kadagiti kabusorda, tapno iyadayo ida dagiti kabusorda ken italawda ida a kas balud iti dagada, iti adayo man wenno iti asideg.
37 ṣùgbọ́n, nígbà tí wọ́n bá sì yí ọkàn wọn padà ní ilẹ̀ tí wọ́n ti mú wọn ní ìgbèkùn, tí wọ́n sì ronúpìwàdà tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ pẹ̀lú rẹ ní ilẹ̀ ìgbèkùn, wọn ó sì wí pé, ‘Àwa ti dẹ́ṣẹ̀, àwa sì ti ṣe ohun tí kò dára, a sì ti ṣe búburú’;
Ket no kas pangarigan ta maamirisda nga addada iti daga a nakaitalawanda, ket kas pangarigan ta agbabawida ken dumawatda iti pabor manipud kenka iti daga a nakaibaludanda. No kas pangarigan ta ibagada, 'Nagaramidkami kadagiti dinadakes ken nagbasolkami. Dakes ti inar-aramidmi.'
38 tí wọn bá sì yípadà sí ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn àti ẹ̀mí ní ilẹ̀ ìgbèkùn wọn níbi tí wọ́n ti mú wọn, tí wọ́n sì gbàdúrà wọn, kojú si ìlú tí ìwọ ti yàn àti lórí ilé Olúwa tí mo ti kọ́ fún orúkọ rẹ;
No kas pangarigan ta agsublida kenka iti amin a pusoda ken iti amin a kararuada iti daga a nakaibaludanda, a nangipananda kadakuada a kas balud, ken no kas pangarigan ta agkararagda a nakasango iti dagada nga intedmo kadagiti kapuonanda, ken sumangoda iti dayta a siudad a pinilim, ken sumangoda iti balay nga impatakderko para iti naganmo.
39 nígbà náà, láti ọ̀run, ibi ibùgbé rẹ, gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn, kí o sì mú ọ̀ràn wọn dúró, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn jì wọn, tí wọn ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ.
Ket denggem koma manipud kadagiti langit, a lugar a pagnanaedam, dagiti kararag ken dagiti kiddawda, ken pagballigiem ida. Pakawanem dagiti tattaom, a nagbasol kenka.
40 “Nísinsin yìí, Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ojú rẹ kí ó ṣí kí o sì tẹ́ etí rẹ sílẹ̀ fún àdúrà sí ibí yìí.
Ita, O Diosko, ipakpakaasik kenka, imulagatmo koma dagiti matam, ket denggen koma dagiti lapayagmo dagiti maikararag iti daytoy a disso.
41 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí dìde, Olúwa Ọlọ́run mi, sí ibi ìsinmi rẹ,
Tumakderka ngarud ita, O Yahweh a Dios, iti pagin-inanaam a disso, sika ken ti lakasa ti pannakabalinmo. O Yahweh a Dios, makawesan koma iti pannakaisalakan dagiti papadim, ken agrag-o koma dagiti sasantom iti kinaimbagmo.
42 Olúwa Ọlọ́run mi, má ṣe kọ̀ ẹni àmì òróró rẹ.
O Yahweh a Dios, saanmo kadi a laksiden dagiti pinulotam. Laglagipem ti kinapudnom iti tulagmo kenni David nga adipenmo.”

< 2 Chronicles 6 >