< 2 Chronicles 5 >

1 Nígbà tí gbogbo iṣẹ́ tí Solomoni ti ṣe fún tẹmpili Olúwa ti parí, ó kó gbogbo àwọn nǹkan tí Dafidi baba rẹ̀ ti yà sọ́tọ̀: wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò ọ̀ṣọ́, ó sì fi wọ́n sínú ìṣúra ilé Ọlọ́run.
Na kua oti katoa te mahi i mahia e Horomona mo te whare o Ihowa. A ka kawea mai e Horomona nga mea i whakatapua e tona papa, e Rawiri: te hiriwa, te koura, nga oko katoa, hoatu ana e ia ki roto ki nga taonga o te whare o te Atua.
2 Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli jọ sí Jerusalẹmu, gbogbo àwọn olórí ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan àti àwọn olóyè àwọn ìdílé Israẹli, kí wọn kí ó gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá láti Sioni ìlú Dafidi.
Katahi ka huihuia e Horomona nga kaumatua o Iharaira, me nga upoko katoa o nga iwi, nga rangatira o nga whare o nga matua o nga tama a Iharaira, ki Hiruharama, ki te mau ake i te aaka o te kawenata a Ihowa i roto i te pa o Rawiri, ara i Hiona.
3 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli péjọ sí ọ̀dọ̀ ọba ní àkókò àjọ àgọ́.
Na ka huihuia ki te kingi nga tangata katoa o Iharaira, ki te hakari, i te whitu o nga marama.
4 Gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli sì wá, àwọn ọmọ Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
Na ka haere mai nga kaumatua katoa o Iharaira, a ka hapainga ake te aaka e nga Riwaiti.
5 Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí náà gòkè àti àgọ́ ìpàdé àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ni ó mú wọn gòkè wá.
Kawea ana e ratou te aaka, me te tapenakara o te whakaminenga, me nga oko tapu katoa i roto i te tapenakara; kawea ana e nga tohunga, e nga Riwaiti.
6 Nígbà náà ni ọba Solomoni àti gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, wà níwájú àpótí ẹ̀rí náà wọ́n sì fi àgùntàn àti màlúù tí a kò le è kà tán rú ẹbọ, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è mọ iye wọn tán nítorí bí wọ́n ti pọ̀ tó.
Katahi a Kingi Horomona me te huihui katoa o Iharaira i huihui mai nei ki a ia ki mua i te aaka, ka patu i te hipi, i te kau, e kore nei e taea te korero, te tatau ranei, i te tini.
7 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
Na nga tohunga hoki i mau te aaka o te kawenata a Ihowa ki tona wahi, ki te ahurewa o te whare, ki te wahi tino tapu, ki raro i nga parirau o nga kerupima.
8 Àwọn Kérúbù na ìyẹ́ wọn bo ibi àpótí ẹ̀rí náà àti àwọn ọ̀pá tí ó gbé e ró.
I roha tonu hoki nga parirau o nga kerupima ki runga i te wahi i te aaka, a hipokina iho ana a runga o te aaka, me ona amo, e nga kerupima.
9 Àwọn ọ̀pá rẹ̀ náà gùn tó bẹ́ẹ̀ tí a fi rí orí àwọn ọ̀pá náà láti ibi àpótí ẹ̀rí náà níwájú Ibi Mímọ́ náà, ṣùgbọ́n a kò rí wọn lóde. Níbẹ̀ ni ó sì wà títí di òní yìí.
Na, i te roroa o nga amo, kitea ai nga pito o nga amo i te aaka, i te ritenga atu o te ahurewa; otiia kihai i kitea ki waho; na kei reira tonu a tae noa ki tenei ra.
10 Kò sí ohun kan nínú àpótí ẹ̀rí náà bí kò ṣe wàláà méjì tí Mose fi sínú rẹ̀ ní Horebu, ní ìgbà tí Olúwa fi bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti.
Kahore he mea i roto i te aaka, ko nga papa e rua anake i whaowhina nei ki reira e Mohi i Horepa i ta Ihowa whakaritenga kawenata ki nga tama a Iharaira i to ratou putanga mai i Ihipa.
11 Lẹ́yìn náà ni àwọn àlùfáà jáde wá láti Ibi Mímọ́. Gbogbo àwọn àlùfáà tí ó wà níbẹ̀ ni ó ya ara wọn sí mímọ́ láìbìkítà fún ìpín wọn.
A, i te putanga o nga tohunga i te wahi tapu; i whakatapua hoki nga tohunga katoa i kitea ki reira; kihai hoki nga tikanga mo nga wehenga i mau i taua ra;
12 Gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ akọrin: Asafu, Hemani, Jedutuni àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ẹbí wọn, wọ́n dúró ní igun ìlà-oòrùn pẹpẹ náà wọ́n wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ tuntun wọ́n ń lo kimbali, dùùrù àti ohun èlò orin olókùn. Ìwọ̀n ọgọ́fà àwọn àlùfáà tí wọ́n ń fun ìpè ni wọ́n tẹ̀lé wọn.
Ko nga Riwaiti hoki, ko nga kaiwaiata, ko ratou katoa, ara ko Ahapa, ko Hemana, ko Ierutunu, me a ratou tama, me o ratou teina, he rinena ma o ratou kakahu; he himipora ano a ratou, he hatere, he hapa; tu ana ratou ki te taha ki te rawhiti o te aata, me nga tohunga kotahi rau e rua tekau e whakatangi ana i nga tetere:
13 Àwọn afùnpè àti àwọn akọrin pa ohùn wọn pọ̀ sí ọ̀kan ṣoṣo, láti fi ìyìn àti ọpẹ́ fun Olúwa. Wọ́n fi ìpè, kimbali àti àwọn ohun èlò orin mìíràn mọ́ ọn, wọ́n gbé ohùn wọn sókè láti fi yin Olúwa, wọ́n ń kọrin pé, “Ó dára; ìfẹ́ rẹ̀ wà títí láéláé.” Nígbà náà ni ìkùùkuu ojú ọ̀run kún inú tẹmpili Olúwa,
Na reira, kia hui nga kaiwhakatangi tetere me nga kaiwaiata, kia kotahi tonu te reo i rangona, hei whakamoemiti; hei whakawhetai ki a Ihowa; kia whakarewa tahi ratou i o ratou reo me to nga tetere, me to nga himipora, me to nga mea rangi waiata, he whakamoemiti ki a Ihowa, me te mea, No te mea he pai ia: mau tonu hoki tana mahi tohu ake ake: hei reira kua ki te whare i te kapua, ara te whare o Ihowa,
14 tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn àlùfáà kò le è ṣiṣẹ́ ìsìn wọn nítorí ìkùùkuu náà, nítorí ògo Olúwa kún inú tẹmpili Ọlọ́run.
Na kihai nga tohunga i ahei te tu ki te minita, i te kapua hoki; kua ki hoki te whare o te Atua i te kororia o Ihowa.

< 2 Chronicles 5 >