< 2 Chronicles 5 >

1 Nígbà tí gbogbo iṣẹ́ tí Solomoni ti ṣe fún tẹmpili Olúwa ti parí, ó kó gbogbo àwọn nǹkan tí Dafidi baba rẹ̀ ti yà sọ́tọ̀: wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò ọ̀ṣọ́, ó sì fi wọ́n sínú ìṣúra ilé Ọlọ́run.
PELA i paa ai na mea a pau a Solomona i hana'i no ka hale o Iehova; a hookomo o Solomona i na mea a Davida, a kona makua kane i hoolaa ai, i ke kala a me ke gula, a me na ipu a pau, a waiho iho la iloko o ka waihonawaiwai o ke Akua.
2 Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli jọ sí Jerusalẹmu, gbogbo àwọn olórí ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan àti àwọn olóyè àwọn ìdílé Israẹli, kí wọn kí ó gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá láti Sioni ìlú Dafidi.
Alaila, hoakoakoa o Solomona i na lunakahiko o ka Iseraela, a me ka poe koikoi o na ohana, i na kaukaualii, a me na makualii no na mamo a Iseraela, i Ierusalema, e lawe i ka pahu o ka berita o Iehova mai ke kulanakauhale o Davida, mai Ziona mai.
3 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli péjọ sí ọ̀dọ̀ ọba ní àkókò àjọ àgọ́.
A hoakoakoaia e ke alii na kanaka a pau loa o ka Iseraela i ka ahaaina i ka malama ehiku.
4 Gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli sì wá, àwọn ọmọ Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
A hiki mai la ka poe lunakahiko o ka Iseraela, a hapai ae la na Levi i ka pahu.
5 Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí náà gòkè àti àgọ́ ìpàdé àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ni ó mú wọn gòkè wá.
Lawe lakou i ka pahu, a me ka halelewa o ke anainakanaka, a me na ipu hoano a pau, aia no iloko o ka halelewa; na ka poe kahuna, na ka Levi i lawe.
6 Nígbà náà ni ọba Solomoni àti gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, wà níwájú àpótí ẹ̀rí náà wọ́n sì fi àgùntàn àti màlúù tí a kò le è kà tán rú ẹbọ, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è mọ iye wọn tán nítorí bí wọ́n ti pọ̀ tó.
A o ke alii, o Solomona a me ka ahakanaka a pau o ka Iseraela i hoakoakoaia io na la imua o ka pa hu berita, mohai aku lakou i na hi pa, a me na bipi i pau ole i ka heluia no ka nui loa.
7 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
Alaila, hookomo ka poe kahuna i ka pahu berita o Iehova i kona wahi, i kahi hoano o ka hale, kahi hoano loa malalo iho o na eheu o na kerubima.
8 Àwọn Kérúbù na ìyẹ́ wọn bo ibi àpótí ẹ̀rí náà àti àwọn ọ̀pá tí ó gbé e ró.
Ua hoholaia na eheu o na kerubima ma kahi o ka pahu, a ua uhi na kerubima i ka pahu, a me kona mau laau auamo maluna iho.
9 Àwọn ọ̀pá rẹ̀ náà gùn tó bẹ́ẹ̀ tí a fi rí orí àwọn ọ̀pá náà láti ibi àpótí ẹ̀rí náà níwájú Ibi Mímọ́ náà, ṣùgbọ́n a kò rí wọn lóde. Níbẹ̀ ni ó sì wà títí di òní yìí.
A huki mai lakou i na laau auamo, a ua ikea na poo o na laau auamo, mai ka pahu, a imua o kahi hoano, aole i ikeia mawaho. A aia no ia a hiki i neia la.
10 Kò sí ohun kan nínú àpótí ẹ̀rí náà bí kò ṣe wàláà méjì tí Mose fi sínú rẹ̀ ní Horebu, ní ìgbà tí Olúwa fi bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti.
Aohe mea e iloko o ka pahu, o na papa elua wale no a Mose i hookomo ai iloko ma Horeba, i ka manawa i hoohiki ai ke Akua me ka poe mamo a Iseraela i ko lakou hele ana mai Aigupita mai.
11 Lẹ́yìn náà ni àwọn àlùfáà jáde wá láti Ibi Mímọ́. Gbogbo àwọn àlùfáà tí ó wà níbẹ̀ ni ó ya ara wọn sí mímọ́ láìbìkítà fún ìpín wọn.
A puka mai ka poe kahuna mai kahi hoano mai, (no ka mea ua huikalaia na kahuna a pau loa, aole lakou i ku papa ia manawa:
12 Gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ akọrin: Asafu, Hemani, Jedutuni àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ẹbí wọn, wọ́n dúró ní igun ìlà-oòrùn pẹpẹ náà wọ́n wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ tuntun wọ́n ń lo kimbali, dùùrù àti ohun èlò orin olókùn. Ìwọ̀n ọgọ́fà àwọn àlùfáà tí wọ́n ń fun ìpè ni wọ́n tẹ̀lé wọn.
A o na Levi, ka poe himeni a pau na Asapa, na Hemana, na Iedutuna, a me ka lakou poe keiki, a me ko lakou poe hoahanau i aahuia i ka ie olona maikai me na kimebala, a me na pesaleteri, a me na lira, ku lakou imua o ke kuahu, a me lakou pu na kahuna he haneri a me ka iwakalua, e hookani ana i na pu.)
13 Àwọn afùnpè àti àwọn akọrin pa ohùn wọn pọ̀ sí ọ̀kan ṣoṣo, láti fi ìyìn àti ọpẹ́ fun Olúwa. Wọ́n fi ìpè, kimbali àti àwọn ohun èlò orin mìíràn mọ́ ọn, wọ́n gbé ohùn wọn sókè láti fi yin Olúwa, wọ́n ń kọrin pé, “Ó dára; ìfẹ́ rẹ̀ wà títí láéláé.” Nígbà náà ni ìkùùkuu ojú ọ̀run kún inú tẹmpili Olúwa,
A lokahi ka manao o ka poe hookani i ka pu, a me ka poe himeni me ka leo hookahi, e hoolea aku, a e hoomaikai aku ia Iehova, a hookiekie lakou i ka leo me na pu, a me na kimebala a me na mea kani e ae; a i ko lakou hoolea ana'ku ia Iehova. No ka mea, ua maikai no ia, ua mau loa kona aloha: aia hoi, na hoopihaia ka hale i ke ao, ka hale o Iehova.
14 tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn àlùfáà kò le è ṣiṣẹ́ ìsìn wọn nítorí ìkùùkuu náà, nítorí ògo Olúwa kún inú tẹmpili Ọlọ́run.
Aole i hiki i na kahuna ke ku a e lawelawe imua o ke ao; no ka mea, ua piha ka hale o ke Akua i ka nani o Iehova.

< 2 Chronicles 5 >