< 2 Chronicles 5 >

1 Nígbà tí gbogbo iṣẹ́ tí Solomoni ti ṣe fún tẹmpili Olúwa ti parí, ó kó gbogbo àwọn nǹkan tí Dafidi baba rẹ̀ ti yà sọ́tọ̀: wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò ọ̀ṣọ́, ó sì fi wọ́n sínú ìṣúra ilé Ọlọ́run.
Ainsi tout l'ouvrage que Salomon fit pour la maison de l'Eternel fut achevé. Puis Salomon fit apporter dedans ce que David son père avait consacré, savoir l'argent, et tous les vaisseaux, et il le mit dans les trésors de la maison de Dieu.
2 Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli jọ sí Jerusalẹmu, gbogbo àwọn olórí ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan àti àwọn olóyè àwọn ìdílé Israẹli, kí wọn kí ó gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá láti Sioni ìlú Dafidi.
Alors Salomon assembla à Jérusalem les Anciens d'Israël, et tous les Chefs des Tribus, les principaux des pères des enfants d'Israël, pour emporter l'Arche de l'alliance de l'Eternel, de la Cité de David, qui est Sion.
3 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli péjọ sí ọ̀dọ̀ ọba ní àkókò àjọ àgọ́.
Et tous ceux d'Israël furent assemblés vers le Roi, en la fête solennelle qui est au septième mois.
4 Gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli sì wá, àwọn ọmọ Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
Tous les Anciens donc d'Israël vinrent, et les Lévites portèrent l'Arche.
5 Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí náà gòkè àti àgọ́ ìpàdé àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ni ó mú wọn gòkè wá.
Ainsi on emporta l'Arche, et le Tabernacle d'assignation, et tous les saints vaisseaux qui étaient dans le Tabernacle; les Sacrificateurs, dis-je, [et] les Lévites les emportèrent.
6 Nígbà náà ni ọba Solomoni àti gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, wà níwájú àpótí ẹ̀rí náà wọ́n sì fi àgùntàn àti màlúù tí a kò le è kà tán rú ẹbọ, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è mọ iye wọn tán nítorí bí wọ́n ti pọ̀ tó.
Or le Roi Salomon, et toute l'assemblée d'Israël qui s'était rendue auprès de lui, étaient devant l'Arche, sacrifiant du gros et du menu bétail en si grand nombre, qu'on ne le pouvait nombrer ni compter.
7 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
Et les Sacrificateurs apportèrent l'Arche de l'alliance de l'Eternel en son lieu, dans l'Oracle de la maison, au lieu Très-saint, sous les ailes des Chérubins.
8 Àwọn Kérúbù na ìyẹ́ wọn bo ibi àpótí ẹ̀rí náà àti àwọn ọ̀pá tí ó gbé e ró.
Car les Chérubins étendaient les ailes sur l'endroit où devait être l'Arche; et les Chérubins couvraient l'Arche et ses barres.
9 Àwọn ọ̀pá rẹ̀ náà gùn tó bẹ́ẹ̀ tí a fi rí orí àwọn ọ̀pá náà láti ibi àpótí ẹ̀rí náà níwájú Ibi Mímọ́ náà, ṣùgbọ́n a kò rí wọn lóde. Níbẹ̀ ni ó sì wà títí di òní yìí.
Et ils retirèrent les barres en dedans; de sorte que les bouts des barres se voyaient hors de l'Arche sur le devant de l'Oracle, mais ils ne se voyaient point en dehors; et elles sont demeurées là jusqu'à aujourd'hui.
10 Kò sí ohun kan nínú àpótí ẹ̀rí náà bí kò ṣe wàláà méjì tí Mose fi sínú rẹ̀ ní Horebu, ní ìgbà tí Olúwa fi bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti.
Il n'y avait dans l'Arche que les deux Tables que Moïse y avait mises en Horeb, quand l'Eternel traita [alliance] avec les enfants d'Israël, après qu'ils furent sortis d'Egypte.
11 Lẹ́yìn náà ni àwọn àlùfáà jáde wá láti Ibi Mímọ́. Gbogbo àwọn àlùfáà tí ó wà níbẹ̀ ni ó ya ara wọn sí mímọ́ láìbìkítà fún ìpín wọn.
Or il arriva que comme les Sacrificateurs furent sortis du lieu Saint, (car tous les Sacrificateurs qui se trouvèrent là se sanctifièrent, sans observer les départements; )
12 Gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ akọrin: Asafu, Hemani, Jedutuni àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ẹbí wọn, wọ́n dúró ní igun ìlà-oòrùn pẹpẹ náà wọ́n wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ tuntun wọ́n ń lo kimbali, dùùrù àti ohun èlò orin olókùn. Ìwọ̀n ọgọ́fà àwọn àlùfáà tí wọ́n ń fun ìpè ni wọ́n tẹ̀lé wọn.
Et que les Lévites qui étaient chantres, selon tous leurs [départements], tant d'Asaph, que d'Héman, et de Jéduthun, et de leurs fils, et de leurs frères, vêtus de fin lin, avec des cymbales, des musettes, et des violons, se tenaient vers l'Orient de l'autel, et avec eux six vingts Sacrificateurs, qui sonnaient des trompettes;
13 Àwọn afùnpè àti àwọn akọrin pa ohùn wọn pọ̀ sí ọ̀kan ṣoṣo, láti fi ìyìn àti ọpẹ́ fun Olúwa. Wọ́n fi ìpè, kimbali àti àwọn ohun èlò orin mìíràn mọ́ ọn, wọ́n gbé ohùn wọn sókè láti fi yin Olúwa, wọ́n ń kọrin pé, “Ó dára; ìfẹ́ rẹ̀ wà títí láéláé.” Nígbà náà ni ìkùùkuu ojú ọ̀run kún inú tẹmpili Olúwa,
Il arriva, [dis-je], que tous ensemble sonnant des trompettes, et chantant, et faisant retentir tous d'un accord leur voix pour louer et célébrer l'Eternel, élevant donc leur voix avec des trompettes, des cymbales, et d'autres instruments de musique en louant l'Eternel de ce qu'il est bon, parce que sa miséricorde demeure à toujours, la maison de l'Eternel fut remplie d'une nuée;
14 tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn àlùfáà kò le è ṣiṣẹ́ ìsìn wọn nítorí ìkùùkuu náà, nítorí ògo Olúwa kún inú tẹmpili Ọlọ́run.
En sorte que les Sacrificateurs ne se pouvaient tenir debout pour faire le service, à cause de la nuée; car la gloire de l'Eternel avait rempli la maison de Dieu.

< 2 Chronicles 5 >