< 2 Chronicles 5 >
1 Nígbà tí gbogbo iṣẹ́ tí Solomoni ti ṣe fún tẹmpili Olúwa ti parí, ó kó gbogbo àwọn nǹkan tí Dafidi baba rẹ̀ ti yà sọ́tọ̀: wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò ọ̀ṣọ́, ó sì fi wọ́n sínú ìṣúra ilé Ọlọ́run.
Enfin, tous les travaux qu'avait commandés Salomon pour le temple du Seigneur, furent achevés. Et Salomon transporta dans le trésor du temple les choses saintes de David son père, et l'argent et l'or, et les vaisseaux.
2 Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli jọ sí Jerusalẹmu, gbogbo àwọn olórí ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan àti àwọn olóyè àwọn ìdílé Israẹli, kí wọn kí ó gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá láti Sioni ìlú Dafidi.
Alors, Salomon assembla dans Jérusalem tous les anciens du peuple, tous les princes des tribus, les princes des familles paternelles d'Israël, pour transférer de Sion (la même que la ville de David) l'arche de l'alliance du Seigneur.
3 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli péjọ sí ọ̀dọ̀ ọba ní àkókò àjọ àgọ́.
Et tout Israël fut assemblé devant le roi Salomon, pendant la fête, le septième mois.
4 Gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli sì wá, àwọn ọmọ Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
Tous les anciens d'Israël y étaient venus; les lévites prirent l'arche,
5 Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí náà gòkè àti àgọ́ ìpàdé àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ni ó mú wọn gòkè wá.
Le tabernacle du témoignage, et toutes les choses saintes que contenait le tabernacle; puis, les prêtres et les lévites le transportèrent.
6 Nígbà náà ni ọba Solomoni àti gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, wà níwájú àpótí ẹ̀rí náà wọ́n sì fi àgùntàn àti màlúù tí a kò le è kà tán rú ẹbọ, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è mọ iye wọn tán nítorí bí wọ́n ti pọ̀ tó.
Or, le roi Salomon, toute la synagogue d'Israël, les hommes craignant Dieu, tous ceux d'entre eux qui étaient là rassemblés devant l'arche, sacrifiaient des bœufs et des brebis en quantité innombrable.
7 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
Et les prêtres introduisirent l'arche de l'alliance du Seigneur au lieu qui lui était destiné dans l'oracle du temple, dans le Saint des saints, sous les ailes des chérubins.
8 Àwọn Kérúbù na ìyẹ́ wọn bo ibi àpótí ẹ̀rí náà àti àwọn ọ̀pá tí ó gbé e ró.
Et les chérubins avaient les ailes déployées au-dessus du lieu où on mit l'arche, et les chérubins couvraient l'arche et les leviers.
9 Àwọn ọ̀pá rẹ̀ náà gùn tó bẹ́ẹ̀ tí a fi rí orí àwọn ọ̀pá náà láti ibi àpótí ẹ̀rí náà níwájú Ibi Mímọ́ náà, ṣùgbọ́n a kò rí wọn lóde. Níbẹ̀ ni ó sì wà títí di òní yìí.
Mais les leviers faisaient saillie; et, de l'intérieur du Saint des saints, on en voyait la tête en s'adossant à la façade de l'oracle; du dehors on ne les voyait pas: et ils sont restés là jusqu'à nos jours.
10 Kò sí ohun kan nínú àpótí ẹ̀rí náà bí kò ṣe wàláà méjì tí Mose fi sínú rẹ̀ ní Horebu, ní ìgbà tí Olúwa fi bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti.
Il n'y avait rien dans l'arche, sinon les deux tables que Moïse y avait déposées en Horeb; témoignage de l'alliance du Seigneur avec les fils d'Israël, quand il les eut fait sortir de l'Égypte.
11 Lẹ́yìn náà ni àwọn àlùfáà jáde wá láti Ibi Mímọ́. Gbogbo àwọn àlùfáà tí ó wà níbẹ̀ ni ó ya ara wọn sí mímọ́ láìbìkítà fún ìpín wọn.
Et, au moment où les prêtres sortirent du sanctuaire (car tous avaient été consacrés, et ils n'étaient point divisés encore par ordre journalier de service),
12 Gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ akọrin: Asafu, Hemani, Jedutuni àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ẹbí wọn, wọ́n dúró ní igun ìlà-oòrùn pẹpẹ náà wọ́n wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ tuntun wọ́n ń lo kimbali, dùùrù àti ohun èlò orin olókùn. Ìwọ̀n ọgọ́fà àwọn àlùfáà tí wọ́n ń fun ìpè ni wọ́n tẹ̀lé wọn.
Et, avec eux, les lévites, chanteurs de psaumes, tous subordonnés à Asaph, à Hêman, à Idithun, à leurs fils et à leurs frères, revêtus de robes de lin, portant des cymbales, des lyres, des harpes, se tenant en face de l'autel, et, avec eux, cent vingt prêtres sonnant de la trompette,
13 Àwọn afùnpè àti àwọn akọrin pa ohùn wọn pọ̀ sí ọ̀kan ṣoṣo, láti fi ìyìn àti ọpẹ́ fun Olúwa. Wọ́n fi ìpè, kimbali àti àwọn ohun èlò orin mìíràn mọ́ ọn, wọ́n gbé ohùn wọn sókè láti fi yin Olúwa, wọ́n ń kọrin pé, “Ó dára; ìfẹ́ rẹ̀ wà títí láéláé.” Nígbà náà ni ìkùùkuu ojú ọ̀run kún inú tẹmpili Olúwa,
Les trompettes, les harpes et les chants se réunirent en une seule harmonie pour louer d'une seule voix et célébrer le Seigneur. Et les voix s'élevaient accompagnées des trompettes, des cymbales et des instruments des chanteurs, et elles disaient: Rendez hommage à Dieu, parce qu'il est bon, et que sa miséricorde est éternelle. Alors, le temple fut rempli d'une nuée de gloire du Seigneur.
14 tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn àlùfáà kò le è ṣiṣẹ́ ìsìn wọn nítorí ìkùùkuu náà, nítorí ògo Olúwa kún inú tẹmpili Ọlọ́run.
Et les prêtres ne purent y demeurer ni faire le service divin, à cause de la nuée; car la gloire du Seigneur avait rempli le temple de Dieu.