< 2 Chronicles 5 >

1 Nígbà tí gbogbo iṣẹ́ tí Solomoni ti ṣe fún tẹmpili Olúwa ti parí, ó kó gbogbo àwọn nǹkan tí Dafidi baba rẹ̀ ti yà sọ́tọ̀: wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò ọ̀ṣọ́, ó sì fi wọ́n sínú ìṣúra ilé Ọlọ́run.
Angraeng ih im hanah Solomon mah toksak pacoeng boih naah, ampa David mah paek ih hmuennawk boih to lak moe, sui, sumkanglung hoi kalah hmuennawk boih to, Sithaw ih hmuenmae pakuemhaih ahmuen ah a suek.
2 Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli jọ sí Jerusalẹmu, gbogbo àwọn olórí ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan àti àwọn olóyè àwọn ìdílé Israẹli, kí wọn kí ó gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá láti Sioni ìlú Dafidi.
Solomon mah David ih vangpui, Zion vangpui hoiah Angraeng lokkamhaih thingkhong to angzawn hanah, Israel zaehoikungnawk, acaeng lu koeknawk, Israel acaeng zaehoikungnawk to Jerusalem ah kawk boih.
3 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli péjọ sí ọ̀dọ̀ ọba ní àkókò àjọ àgọ́.
To pongah Israel kaminawk loe khrah sarihto naah sak ih poih niah, siangpahrang khaeah angzoh o boih.
4 Gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli sì wá, àwọn ọmọ Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
Israel kacoehtanawk angzoh o boih moe, Levi acaengnawk mah thingkhong to angzawn o.
5 Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí náà gòkè àti àgọ́ ìpàdé àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ni ó mú wọn gòkè wá.
Angraeng ih thingkhong, kaminawk amgkhuenghaih kahni im, kahni imthung ah kaom kaciim hmuennawk to angzawn o boih; qaimanawk hoi Levi acaengnawk mah angzawn o.
6 Nígbà náà ni ọba Solomoni àti gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, wà níwájú àpótí ẹ̀rí náà wọ́n sì fi àgùntàn àti màlúù tí a kò le è kà tán rú ẹbọ, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è mọ iye wọn tán nítorí bí wọ́n ti pọ̀ tó.
Solomon siangpahrang hoi Angraeng ih thingkhong hmaa ah amkhueng Israel kaminawk boih mah, kroek laek ai, paroeai kapop tuu hoi maitawtaenawk to angbawnhaih ah paek o.
7 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
Qaimanawk mah kaom tangcae lok baktih toengah, Angraeng lokkamhaih thingkhong to im thung ih hmuenciim, Kaciim Koek ahmuen, cherubimnawk ih pakhraeh tlim ah suek o.
8 Àwọn Kérúbù na ìyẹ́ wọn bo ibi àpótí ẹ̀rí náà àti àwọn ọ̀pá tí ó gbé e ró.
Thingkhong suekhaih ahmuen loe Cherubim ih pakhraeh mah khuk khoep; thingkhong hoi angzawnhaih cung doeh cherubim mah khuk hmoek.
9 Àwọn ọ̀pá rẹ̀ náà gùn tó bẹ́ẹ̀ tí a fi rí orí àwọn ọ̀pá náà láti ibi àpótí ẹ̀rí náà níwájú Ibi Mímọ́ náà, ṣùgbọ́n a kò rí wọn lóde. Níbẹ̀ ni ó sì wà títí di òní yìí.
Angzawnhaih cung loe sawk parai pongah, athung ih hmuenciim hma hoiah amtueng; toe tasa bang hoiah loe amtueng ai; vaihni ni khoek to to ahmuen ah oh vop.
10 Kò sí ohun kan nínú àpótí ẹ̀rí náà bí kò ṣe wàláà méjì tí Mose fi sínú rẹ̀ ní Horebu, ní ìgbà tí Olúwa fi bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti.
Israel caanawk Izip prae thung hoi tacawt o pacoengah, Angraeng mah nihcae hoi lokmaihaih to sak, to naah Mosi mah Horeb ah suek ih thlung kangphaek daek hnetto khue ai ah loe, thingkhong thungah tidoeh om ai.
11 Lẹ́yìn náà ni àwọn àlùfáà jáde wá láti Ibi Mímọ́. Gbogbo àwọn àlùfáà tí ó wà níbẹ̀ ni ó ya ara wọn sí mímọ́ láìbìkítà fún ìpín wọn.
To pacoeng ah qaimanawk loe hmuenciim hoiah amlaem o; naa bang ih qaima maw, kawbaktih qaima maw, tiah pathlaenghaih om ai ah, to ahmuen ah kaom qaimanawk boih loe ciimcai ah oh o.
12 Gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ akọrin: Asafu, Hemani, Jedutuni àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ẹbí wọn, wọ́n dúró ní igun ìlà-oòrùn pẹpẹ náà wọ́n wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ tuntun wọ́n ń lo kimbali, dùùrù àti ohun èlò orin olókùn. Ìwọ̀n ọgọ́fà àwọn àlùfáà tí wọ́n ń fun ìpè ni wọ́n tẹ̀lé wọn.
Laasah Levi acaengnawk, Asaph, Heman, Jeduthun hoi anih ih caanawk, angmah ih nawkamyanawk boih loe, puu ngan kahni kanglung to angkhuek o; hmaicam ni angyae bangah angdoet o moe, cingceng bohhaih hoiah congca katoengnawk to kruek o; cumvai pumphaeto mongkah ueng qaimanawk mah nihcae to angdoet o haih;
13 Àwọn afùnpè àti àwọn akọrin pa ohùn wọn pọ̀ sí ọ̀kan ṣoṣo, láti fi ìyìn àti ọpẹ́ fun Olúwa. Wọ́n fi ìpè, kimbali àti àwọn ohun èlò orin mìíràn mọ́ ọn, wọ́n gbé ohùn wọn sókè láti fi yin Olúwa, wọ́n ń kọrin pé, “Ó dára; ìfẹ́ rẹ̀ wà títí láéláé.” Nígbà náà ni ìkùùkuu ojú ọ̀run kún inú tẹmpili Olúwa,
mongkah ueng kaminawk hoi laasah kaminawk nawnto amhong o, lok maeto hoiah Angraeng to saphaw o moe, anghoehaih lok a thuih o; mongkahnawk, cingcengnawk hoi kalah congca tamoinawk to kruek o moe, tha hoi Angraeng to saphaw o; Anih loe hoih; Anih ih amlunghaih loe dungzan khoek to cak, tiah hang o naah, Angraeng ih im to tamai mah khuk khoep:
14 tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn àlùfáà kò le è ṣiṣẹ́ ìsìn wọn nítorí ìkùùkuu náà, nítorí ògo Olúwa kún inú tẹmpili Ọlọ́run.
tamai mah khuk hmoek pongah, qaimanawk doeh toksak han angdoe o thai ai boeh; to tiah im loe Angraeng lensawkhaih hoiah koi.

< 2 Chronicles 5 >