< 2 Chronicles 34 >

1 Josiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì dí ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
Йосі́я був віку восьми́ літ, коли він зацарював, і царював в Єрусалимі тридцять і один рік.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa, ó sì rìn ọ̀nà baba rẹ̀ Dafidi, kò sì yà sí ọwọ́ ọ̀tún tàbí òsì.
І робив він угодне в Господніх оча́х, і ходив дорогами свого батька Давида, і не вступався ані право́руч, ані ліво́руч.
3 Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀, nígbà tí ó sì wà ní ọ̀dọ́mọdé, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wá ojú Ọlọ́run baba Dafidi. Ní ọdún kejìlá. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fọ Juda àti Jerusalẹmu mọ́ kúrò ní ibi gíga rẹ̀, ère òrìṣà Aṣerah, àti ère yíyá àti ère dídà.
І восьмого року царюва́ння свого, бувши ще юнако́м, розпоча́в він зверта́тися до Бога батька свого Давида, а дванадцятого року розпочав очищати Юду та Єрусалим від па́гірків, і Аста́рт, і бовва́нів рі́заних та литих.
4 Lábẹ́ àpẹẹrẹ àwọn pẹpẹ Baali ni a yí lulẹ̀, ó sì fọ́ àwọn ère sí wẹ́wẹ́, ó run àwọn pẹpẹ tí ó wà lórí rẹ̀, wọ́n sì fọ́ túútúú, àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Èyí tí ó fọ́ wọn sì lúúlúú, ó sì gbọ̀n wọ́n sí orí isà òkú àti àwọn tí ó ń rú ẹbọ sí wọn.
І порозбивали перед ним Ваалові же́ртівники, а стовпи́ сонця, що були на них, він повиру́бував, а Астарти, і бовва́ни різані та литі полама́в і розтер, і розкидав на гроби́ тих, хто прино́сив їм жертви.
5 Ó sì sun àwọn egungun àwọn àlùfáà lórí pẹpẹ wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni ó sì wẹ Juda àti Jerusalẹmu mọ́.
А кості жерців попалив на їхніх же́ртівниках, і очи́стив Юдею та Єрусалим.
6 Ní ìlú Manase, Efraimu àti Simeoni, àní títí ó fi dé Naftali, àti nínú àwọn, ó tú ilé wọn yíkákiri.
А по містах Манасії, і Єфрема, і Симеона, і аж до Нефталима по їхніх руїнах навко́ло
7 Ó sì wó pẹpẹ àti ère Aṣerah lulẹ̀ àti àwọn ère yíyá àti àwọn òrìṣà, ó sì gùn ó sì ti ké gbogbo àwọn ère orí pẹpẹ lulẹ̀ ní gbogbo àyíká Israẹli. Lẹ́yìn náà ó padà sí Jerusalẹmu.
порозбива́в же́ртівники та Аста́рти, і потовк бовва́ни на порох, а всі ідоли сонця повиру́бував в усьому Ізраїлевому кра́ї, і вернувся до Єрусалиму.
8 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Josiah ni a ti wẹ ilẹ̀ náà mọ́ àti ilé Olúwa, ó sì rán Ṣafani ọmọ Asalia àti Maaseiah olórí ìlú náà, pẹ̀lú Joah, ọmọ Joahasi, akọ̀wé, láti tún ilé Olúwa Ọlọ́run ṣe.
А вісімнадцятого року царюва́ння його́, по очи́щенні Кра́ю та Божого дому, послав він Шафана, сина Ацалії, і Маасею, зверхника міста, та Йоаха, та ка́нцлера Йоаха, сина Йохазового, щоб напра́вити дім Господа, Бога його.
9 Wọ́n sì lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, ó sì fún un ní owó náà tí ó mú wá sí inú ilé Ọlọ́run, ti àwọn ọmọ Lefi ẹni tí ó jẹ́ aṣọ́bodè ti gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn Manase Efraimu àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ìyókù Israẹli àti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn Juda àti Benjamini wọ́n sì padà sí Jerusalẹmu.
І прийшли вони до первосвященика Хілкійї, і дали срібло, що було зне́сене до Господнього дому, яке зібрали Левити, що стерегли́ поро́га, з руки Манасії й Єфрема, та з усієї решти Ізраїля, і з усього Юди й Веніямина та ме́шканців Єрусалиму.
10 Nígbà náà ni wọn sì fi le àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ilé lọ́wọ́, àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ ilé Olúwa. Àwọn ọkùnrin yìí sì san owó fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń túnṣe, tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ní ilé Olúwa.
I дали́ на руку робітникі́в праці, приста́влених до Господнього дому, а робітники тієї праці, що робили в Господньому домі, віддали́ на відбудову та на направу Божого дому.
11 Wọ́n sì tún fi owó fún àwọn oníṣọ̀nà àti àwọn olùkọ́lé láti ra òkúta gbígbẹ́ àti ìtì igi fún ìsopọ̀ àti igi rírẹ́ fún ìkọ́lé tí ọba Juda ti gbà láti túnṣe.
І дали́ вони те́слям, і будівни́чим, щоб купувати те́сане камі́ння та дере́ва на зв'я́зування та на покриття́ домів, що їх понищили Юдині царі.
12 Àwọn ọkùnrin náà ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú òtítọ́, láti darí wọn ní Jahati àti Obadiah, àwọn ọmọ Lefi láti Merari, àti Sekariah àti Meṣullamu, sọ̀kalẹ̀ láti Kohati àwọn ọmọ Lefi gbogbo tí ó ní ọgbọ̀n ohun èlò orin.
А ті люди чесно вико́нували працю, а над ними були́ поста́влені Яхат та Овадія, Левити з синів Мерарієвих, і Захарій та Мешуллам із синів Кегатівців для керува́ння. А всі ті Левіти, що розумілися на музичних знаря́ддях,
13 Wọ́n sì ní olórí àwọn aláàárù àti àwọn alábojútó gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ láti ibi iṣẹ́ sí ibi iṣẹ́, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Lefi sì ní akọ̀wé, olùtọ́jú àti olùṣọ́nà.
були над носія́ми, і керували всіма́ робітника́ми на кожну роботу; а з Левитів були писарі́ й уря́дники та придве́рні.
14 Nígbà tí wọ́n mú owó náà tí wọ́n mú wá sí ilé Olúwa, Hilkiah àlùfáà sì rí ìwé òfin Olúwa tí a ti fi fún un láti ọwọ́ Mose.
А коли вони виймали срібло, прине́сене до Господнього дому, священик Хілкійя знайшов книгу Господнього Зако́ну, даного через Мойсея.
15 Hilkiah sì wí fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi ti rí ìwé òfin nínú ilé Olúwa.” Ó sì fi fún Ṣafani.
І відповів Хілкійя й сказав до пи́саря Шафана: „Я знайшов у Господньому домі книгу Зако́ну!“І дав Хілкійя ту книгу Діафанові.
16 Nígbà náà Ṣafani sì mú ìwé náà lọ sí ọ̀dọ̀ ọba ó sì ròyìn fún un. “Àwọn ìjòyè rẹ̀ ń ṣe gbogbo nǹkan tí a ti fi lé wọn lọ́wọ́.
І приніс Шафан ту книгу до царя, і приніс царе́ві ще відповідь, говорячи: „Усе, що да́но через твоїх рабів, вони роблять.
17 Wọ́n ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa wọ́n sì ti fi lé àwọn alábojútó lọ́wọ́ àti àwọn òṣìṣẹ́.”
І вони ви́сипали те срібло, що зна́йдене в Господньому домі, і дали його на руку приста́влених та на руку робітникі́в праці“.
18 Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sì sọ fún ọba, “Hilkiah àlùfáà ti fún mi ní ìwé.” Ṣafani sì kà níwájú ọba.
І доніс писар Шафан цареві, говорячи: „Священик Хілкійя дав мені книгу“. І Шафан перечитав з неї перед царем.
19 Nígbà tí ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
І сталося, як цар почув слова́ книги Зако́ну, то розде́р свої шати...
20 Ó sì pa àṣẹ yìí fún Hilkiah, Ahikamu ọmọ Ṣafani, Abdoni ọmọ Mika, Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
І наказав цар Хілкійї, і Ахікамові, Шафановому синові, і Авдонові, Міхиному синові, і писареві Шафанові, і Асаї, царевому рабові, говорячи:
21 “Ẹ lọ kí ẹ lọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi nípa àwọn ìyókù Israẹli àti Juda nípa ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ti jáde sí orí wa nítorí àwọn baba wa kò ti pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́, wọn kò sì tí ì ṣe gẹ́gẹ́ bí i gbogbo èyí tí a kọ sínú ìwé yìí.”
„Ідіть, зверніться до Господа про мене та про позосталих в Ізраїлі та в Юдеї, про слова́ цієї книги, що зна́йдена. Великий бо гнів Господній, що вилився на нас за те, що батьки наші не дотри́мували Господнього слова, щоб робити все, як написано в цій книзі“.
22 Hilkiah àti àwọn ènìyàn tí ọba yàn tọ Hulda wòlíì obìnrin láti ba sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tokhati tí a tún ń pè ní Tikfa, ọmọ Harhasi, olùtọ́jú ibi ìkáṣọsí. Ó sì ń gbé ní Jerusalẹmu, ní ìhà kejì.
І пішов Хілкійя та ті, кому́ звелів цар, до пророчиці Хулди, жінки Шаллума, сина Токегата, сина Хасриного, сто́рожа шат, а вона сиділа в Єрусалимі на Ново́му Місті, — і говорили до неї про це.
23 Ó sì wí fún wọn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ti sọ, sọ fún àwọn ọkùnrin tí ó rán ọ sí mi pé,
А вона сказала до них: „Так говорить Господь, Бог Ізраїлів: Скажіть чоловікові, що послав вас до мене:
24 ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi yóò sì mú ibi wá sí ìhín yìí àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gbogbo àní ègún tí a kọ sínú ìwé tí wọ́n ti kà níwájú ọba Juda.”
Так говорить Господь: Ось Я наведу́ лихо на оце місце та на ме́шканців його, усі ті прокля́ття, що написані в книзі, яку читали перед Юдиним царем,
25 Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀ wọ́n sì ti sun tùràrí sí ọlọ́run mìíràn wọ́n sì ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn ṣe, ìbínú yóò tú jáde wá sórí ibí yìí, a kì yóò sì paná rẹ̀.’
за те, що вони поки́нули Мене й кадили іншим бога́м, щоб гніви́ти Мене всіма́ ділами своїх рук. І вилився гнів Мій на це місце, — і він не погасне.
26 Sọ fún ọba Juda, ẹni tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa ti sọ, Ọlọ́run Israẹli, sọ nípa ọ̀rọ̀ wọ́n nì tí ìwọ gbọ́.
А Юдиному царе́ві, що послав вас звернутися до Господа, скажете йому так: Так говорить Господь, Бог Ізраїлів, — про ті слова́, які ти чув:
27 Nítorí ọkàn rẹ̀ dúró, ìwọ sì rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa nígbà tí ó gbọ́ ohun tí ó sọ lórí ibí yìí àti ènìyàn rẹ, nítorí ìwọ rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú mi tí o sì fa aṣọ rẹ ya, tí o sì lọ níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ ni Olúwa wí.
За те, що зм'якло твоє серце, і ти впокори́вся перед лицем Бога свого, коли ти почув слова́ Його на це місце та на ме́шканців його, і ти впокори́вся перед лицем Моїм, і розде́р свої шати та плакав перед Моїм лицем, то Я також почув, — говорить Господь.
28 Nísinsin yìí, Èmi ó kó ọ jọ pọ̀ sọ́dọ̀ àwọn baba rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kò sì ní rí gbogbo ibi tí èmi ó mú wá sórí ibí yìí àti lórí àwọn tí ń gbé ibẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú ìdáhùn rẹ̀ padà sí ọ̀dọ̀ ọba.
Ось Я прилучу́ тебе до батькі́в твоїх, і ти бу́деш прилу́чений до гробі́в своїх у споко́ї, і очі твої не побачать усього того лиха, що Я наведу́ на оце місце та на ме́шканців його!“І вони прине́сли відповідь цареві.
29 Nígbà náà ni ọba sì pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda jọ àti Jerusalẹmu.
А цар послав, і зібрав усіх старши́х Юдеї та Єрусалиму.
30 Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
І ввійшов до Господнього дому цар, і кожен муж Юдеї, і ме́шканці Єрусалиму, і священики, і Левити, і ввесь народ від великого й аж до мало́го, і він прочитав уго́лос слова́ книги Заповіту, зна́йденої в Господньому домі.
31 Ọba sì dúró ní ipò rẹ̀ ó sì tún májẹ̀mú dá níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti ẹ̀rí rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo àyà rẹ̀ àti láti pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé yìí.
І став цар на своєму місці, і склав заповіта перед Господнім лицем, щоб ходити за Господом та додержувати заповіді Його, і сві́дчення Його, і устави Його всім серцем своїм та всім життям своїм, щоб вико́нувати слова́ того заповіту, що написані в тій книзі.
32 Nígbà náà, ó sì mú kí gbogbo ènìyàn ní Jerusalẹmu àti Benjamini dúró nínú ẹ̀rí fún ara wọn, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ṣe èyí gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú Ọlọ́run, Ọlọ́run baba ńlá wọn.
І наставив він кожного, хто знахо́дився в Єрусалимі та в Веніямині, до того. І ме́шканці Єрусалиму робили за заповітом Бога, Бога своїх батьків.
33 Josiah sì kó gbogbo ohun ìríra kúrò nínú gbogbo ìlú tí ń ṣe ti àwọn tí ó wà ní Israẹli, ó sì mú kí gbogbo àwọn tí ó wà ní Israẹli sin Olúwa Ọlọ́run wọn gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà láyè wọn, kò yà kúrò láti máa tọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn lẹ́yìn.
І Йосі́я повикидав усі поганські гидо́ти з усіх країв, що в Ізраїлевих синів, і змусив кожного, хто знахо́дився в Ізраїлі, служити Господе́ві, їхньому Богові. За всіх днів його вони не відступали від Господа, Бога своїх батьків.

< 2 Chronicles 34 >