< 2 Chronicles 34 >

1 Josiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì dí ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
Josia var åtta år gammal, när han blev konung, och han regerade trettioett år i Jerusalem.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa, ó sì rìn ọ̀nà baba rẹ̀ Dafidi, kò sì yà sí ọwọ́ ọ̀tún tàbí òsì.
Han gjorde vad rätt var i HERRENS ögon och vandrade på sin fader Davids vägar och vek icke av vare sig till höger eller till vänster.
3 Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀, nígbà tí ó sì wà ní ọ̀dọ́mọdé, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wá ojú Ọlọ́run baba Dafidi. Ní ọdún kejìlá. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fọ Juda àti Jerusalẹmu mọ́ kúrò ní ibi gíga rẹ̀, ère òrìṣà Aṣerah, àti ère yíyá àti ère dídà.
I sitt åttonde regeringsår, medan han ännu var en yngling, begynte han att söka sin fader Davids Gud; och i det tolfte året begynte han att rena Juda och Jerusalem från offerhöjderna och Aserorna och från de skurna och gjutna belätena.
4 Lábẹ́ àpẹẹrẹ àwọn pẹpẹ Baali ni a yí lulẹ̀, ó sì fọ́ àwọn ère sí wẹ́wẹ́, ó run àwọn pẹpẹ tí ó wà lórí rẹ̀, wọ́n sì fọ́ túútúú, àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Èyí tí ó fọ́ wọn sì lúúlúú, ó sì gbọ̀n wọ́n sí orí isà òkú àti àwọn tí ó ń rú ẹbọ sí wọn.
Men Baalsaltarna brötos ned i hans åsyn, och solstoderna som voro uppställda på dem högg han ned, och Aserorna och de skurna och gjutna belätena slog han sönder och krossade dem till stoft och strödde ut stoftet på de mäns gravar, som hade offrat åt dem.
5 Ó sì sun àwọn egungun àwọn àlùfáà lórí pẹpẹ wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni ó sì wẹ Juda àti Jerusalẹmu mọ́.
Och prästernas ben brände han upp på deras altaren. Så renade han Juda och Jerusalem.
6 Ní ìlú Manase, Efraimu àti Simeoni, àní títí ó fi dé Naftali, àti nínú àwọn, ó tú ilé wọn yíkákiri.
Och i Manasses, Efraims och Simeons städer ända till Naftali genomsökte han överallt husen.
7 Ó sì wó pẹpẹ àti ère Aṣerah lulẹ̀ àti àwọn ère yíyá àti àwọn òrìṣà, ó sì gùn ó sì ti ké gbogbo àwọn ère orí pẹpẹ lulẹ̀ ní gbogbo àyíká Israẹli. Lẹ́yìn náà ó padà sí Jerusalẹmu.
Och sedan han hade brutit ned altarna och krossat Aserorna och belätena sönder till stoft och huggit ned alla solstoder i hela Israels land, vände han tillbaka till Jerusalem.
8 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Josiah ni a ti wẹ ilẹ̀ náà mọ́ àti ilé Olúwa, ó sì rán Ṣafani ọmọ Asalia àti Maaseiah olórí ìlú náà, pẹ̀lú Joah, ọmọ Joahasi, akọ̀wé, láti tún ilé Olúwa Ọlọ́run ṣe.
Och i sitt adertonde regeringsår, medan han höll på med att rena landet och templet, sände han Safan, Asaljas son, och Maaseja, hövitsmannen i staden, och kansleren Joa, Joahas' son, för att sätta HERRENS, sin Guds, hus i stånd.
9 Wọ́n sì lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, ó sì fún un ní owó náà tí ó mú wá sí inú ilé Ọlọ́run, ti àwọn ọmọ Lefi ẹni tí ó jẹ́ aṣọ́bodè ti gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn Manase Efraimu àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ìyókù Israẹli àti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn Juda àti Benjamini wọ́n sì padà sí Jerusalẹmu.
Och de gingo till översteprästen Hilkia och avlämnade de penningar som hade influtit till Guds hus, sedan de av de leviter som höllo vakt vid tröskeln hade blivit insamlade från Manasse, Efraim och hela det övriga Israel, så ock från hela Juda och Benjamin och från Jerusalems invånare;
10 Nígbà náà ni wọn sì fi le àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ilé lọ́wọ́, àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ ilé Olúwa. Àwọn ọkùnrin yìí sì san owó fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń túnṣe, tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ní ilé Olúwa.
de överlämnade dem åt de män som förrättade arbete såsom tillsyningsmän vid HERRENS hus. Sedan gåvos penningarna av dessa män, som förrättade arbete och hade befattning vid HERRENS hus med att laga huset och sätta det i stånd,
11 Wọ́n sì tún fi owó fún àwọn oníṣọ̀nà àti àwọn olùkọ́lé láti ra òkúta gbígbẹ́ àti ìtì igi fún ìsopọ̀ àti igi rírẹ́ fún ìkọ́lé tí ọba Juda ti gbà láti túnṣe.
de gåvos åt timmermännen och byggningsmännen, till att inköpa huggen sten och trävirke till stockar, för att man därmed skulle timra upp de hus som Juda konungar hade förstört.
12 Àwọn ọkùnrin náà ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú òtítọ́, láti darí wọn ní Jahati àti Obadiah, àwọn ọmọ Lefi láti Merari, àti Sekariah àti Meṣullamu, sọ̀kalẹ̀ láti Kohati àwọn ọmọ Lefi gbogbo tí ó ní ọgbọ̀n ohun èlò orin.
Och männen fingo vid sitt arbete handla på heder och tro; och tillsyningsmän över dem och föreståndare för arbetet voro Jahat och Obadja, leviter av Meraris barn, och Sakarja och Mesullam, av kehatiternas barn, så ock alla de leviter som voro kunniga på musikinstrumenter.
13 Wọ́n sì ní olórí àwọn aláàárù àti àwọn alábojútó gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ láti ibi iṣẹ́ sí ibi iṣẹ́, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Lefi sì ní akọ̀wé, olùtọ́jú àti olùṣọ́nà.
De hade ock tillsynen över bärarna, så att föreståndare funnos för alla arbetarna vid de särskilda göromålen. Av leviterna togos ock skrivare, uppsyningsmän och dörrvaktare.
14 Nígbà tí wọ́n mú owó náà tí wọ́n mú wá sí ilé Olúwa, Hilkiah àlùfáà sì rí ìwé òfin Olúwa tí a ti fi fún un láti ọwọ́ Mose.
När de nu togo ut penningarna som hade influtit till HERRENS hus, fann prästen Hilkia HERRENS lagbok, den som hade blivit given genom Mose
15 Hilkiah sì wí fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi ti rí ìwé òfin nínú ilé Olúwa.” Ó sì fi fún Ṣafani.
Då tog Hilkia till orda och sade till sekreteraren Safan: "Jag har funnit lagboken i HERRENS hus." Och Hilkia gav boken åt Safan.
16 Nígbà náà Ṣafani sì mú ìwé náà lọ sí ọ̀dọ̀ ọba ó sì ròyìn fún un. “Àwọn ìjòyè rẹ̀ ń ṣe gbogbo nǹkan tí a ti fi lé wọn lọ́wọ́.
Och Safan bar boken till konungen och avgav därjämte sin berättelse inför konungen och sade: "Allt vad dina tjänare hava fått i uppdrag att göra, det göra de.
17 Wọ́n ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa wọ́n sì ti fi lé àwọn alábojútó lọ́wọ́ àti àwọn òṣìṣẹ́.”
Och de hava tömt ut de penningar som funnos i HERRENS hus, och hava överlämnat dem åt tillsyningsmännen och åt arbetarna."
18 Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sì sọ fún ọba, “Hilkiah àlùfáà ti fún mi ní ìwé.” Ṣafani sì kà níwájú ọba.
Vidare berättade sekreteraren Safan för konungen och sade: "Prästen Hilkia har givit mig en bok." Och Safan föreläste därur för konungen
19 Nígbà tí ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
När konungen nu hörde lagens ord, rev han sönder sina kläder.
20 Ó sì pa àṣẹ yìí fún Hilkiah, Ahikamu ọmọ Ṣafani, Abdoni ọmọ Mika, Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
Och konungen bjöd Hilkia och Ahikam, Safans son, och Abdon, Mikas son, och sekreteraren Safan och Asaja, konungens tjänare, och sade:
21 “Ẹ lọ kí ẹ lọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi nípa àwọn ìyókù Israẹli àti Juda nípa ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ti jáde sí orí wa nítorí àwọn baba wa kò ti pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́, wọn kò sì tí ì ṣe gẹ́gẹ́ bí i gbogbo èyí tí a kọ sínú ìwé yìí.”
"Gån och frågen HERREN för mig och för dem som äro kvar av Israel och Juda, angående det som står i den bok som nu har blivit funnen. Ty stor är HERRENS vrede, den som är utgjuten över oss, därför att våra fäder icke hava hållit HERRENS ord och icke hava gjort allt som är föreskrivet i denna bok."
22 Hilkiah àti àwọn ènìyàn tí ọba yàn tọ Hulda wòlíì obìnrin láti ba sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tokhati tí a tún ń pè ní Tikfa, ọmọ Harhasi, olùtọ́jú ibi ìkáṣọsí. Ó sì ń gbé ní Jerusalẹmu, ní ìhà kejì.
Då gick Hilkia, tillika med andra som konungen sände åstad, till profetissan Hulda, hustru åt Sallum, klädkammarvaktaren, som var son till Tokehat, Hasras son; hon bodde i Jerusalem, i Nya staden. Och de talade med henne såsom dem bjudet var.
23 Ó sì wí fún wọn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ti sọ, sọ fún àwọn ọkùnrin tí ó rán ọ sí mi pé,
Då svarade hon dem: "Så säger HERREN, Israels Gud: Sägen till den man som har sänt eder till mig:
24 ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi yóò sì mú ibi wá sí ìhín yìí àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gbogbo àní ègún tí a kọ sínú ìwé tí wọ́n ti kà níwájú ọba Juda.”
Så säger HERREN: Se, över denna plats och över dess invånare skall jag låta olycka komma, alla de förbannelser som äro skrivna i den bok som man har föreläst för Juda konung --
25 Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀ wọ́n sì ti sun tùràrí sí ọlọ́run mìíràn wọ́n sì ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn ṣe, ìbínú yóò tú jáde wá sórí ibí yìí, a kì yóò sì paná rẹ̀.’
detta därför att de hava övergivit mig och tänt offereld åt andra gudar, och så hava förtörnat mig med alla sina händers verk. Min vrede skall utgjutas över denna plats och skall icke bliva utsläckt.
26 Sọ fún ọba Juda, ẹni tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa ti sọ, Ọlọ́run Israẹli, sọ nípa ọ̀rọ̀ wọ́n nì tí ìwọ gbọ́.
Men till Juda konung, som har sänt eder för att fråga HERREN, till honom skolen I säga så: Så säger HERREN, Israels Gud, angående de ord som du har hört:
27 Nítorí ọkàn rẹ̀ dúró, ìwọ sì rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa nígbà tí ó gbọ́ ohun tí ó sọ lórí ibí yìí àti ènìyàn rẹ, nítorí ìwọ rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú mi tí o sì fa aṣọ rẹ ya, tí o sì lọ níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ ni Olúwa wí.
Eftersom ditt hjärta blev bevekt och du ödmjukade dig inför Gud, när du hörde hans ord mot denna plats och mot dess invånare, ja, ödmjukade dig inför mig och rev sönder dina kläder och grät inför mig, fördenskull har jag ock hört dig, säger HERREN.
28 Nísinsin yìí, Èmi ó kó ọ jọ pọ̀ sọ́dọ̀ àwọn baba rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kò sì ní rí gbogbo ibi tí èmi ó mú wá sórí ibí yìí àti lórí àwọn tí ń gbé ibẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú ìdáhùn rẹ̀ padà sí ọ̀dọ̀ ọba.
Se, jag vill samla dig till dina fäder, så att du får samlas till dem i din grav med frid, och dina ögon skola slippa att se all den olycka som jag skall låta komma över denna plats och dess invånare." Och de vände tillbaka till konungen med detta svar.
29 Nígbà náà ni ọba sì pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda jọ àti Jerusalẹmu.
Då sände konungen åstad och lät församla alla de äldste i Juda och Jerusalem.
30 Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
Och konungen gick upp i HERRENS hus med alla Juda män och Jerusalems invånare, också prästerna och leviterna, ja, allt folket, ifrån den störste till den minste. Och han läste upp för dem allt vad som stod i förbundsboken, som hade blivit funnen i HERRENS hus.
31 Ọba sì dúró ní ipò rẹ̀ ó sì tún májẹ̀mú dá níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti ẹ̀rí rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo àyà rẹ̀ àti láti pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé yìí.
Och konungen trädde fram på sin plats och slöt inför HERRENS ansikte det förbundet, att de skulle följa efter HERREN och hålla hans bud, hans vittnesbörd och hans stadgar, av allt sitt hjärta och av all sin själ, och göra efter förbundets ord, dem som voro skrivna i denna bok.
32 Nígbà náà, ó sì mú kí gbogbo ènìyàn ní Jerusalẹmu àti Benjamini dúró nínú ẹ̀rí fún ara wọn, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ṣe èyí gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú Ọlọ́run, Ọlọ́run baba ńlá wọn.
Och han lät alla som funnos i Jerusalem och Benjamin träda in i förbundet Och Jerusalems invånare gjorde efter Guds, sina fäders Guds, förbund.
33 Josiah sì kó gbogbo ohun ìríra kúrò nínú gbogbo ìlú tí ń ṣe ti àwọn tí ó wà ní Israẹli, ó sì mú kí gbogbo àwọn tí ó wà ní Israẹli sin Olúwa Ọlọ́run wọn gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà láyè wọn, kò yà kúrò láti máa tọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn lẹ́yìn.
Och Josia skaffade bort alla styggelser ur Israels barns alla landområden, och tillhöll alla dem som funnos i Israel att tjäna HERREN, sin Gud. Så länge han levde, veko de icke av ifrån HERREN, sina fäders Gud.

< 2 Chronicles 34 >