< 2 Chronicles 34 >

1 Josiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì dí ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
Jošíja je bil star osem let, ko je začel kraljevati in v Jeruzalemu je kraljeval enaintrideset let.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa, ó sì rìn ọ̀nà baba rẹ̀ Dafidi, kò sì yà sí ọwọ́ ọ̀tún tàbí òsì.
Delal je to, kar je bilo pravilno v Gospodovih očeh in hodil po poteh svojega očeta Davida in se ni nagnil niti k desni roki niti k levi.
3 Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀, nígbà tí ó sì wà ní ọ̀dọ́mọdé, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wá ojú Ọlọ́run baba Dafidi. Ní ọdún kejìlá. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fọ Juda àti Jerusalẹmu mọ́ kúrò ní ibi gíga rẹ̀, ère òrìṣà Aṣerah, àti ère yíyá àti ère dídà.
Kajti v osmem letu svojega kraljevanja, ko je bil še mlad, je začel iskati Boga svojega očeta Davida in v dvanajstem letu je začel čistiti Juda in Jeruzalem pred visokimi kraji, ašerami, izrezljanimi podobami in ulitimi podobami.
4 Lábẹ́ àpẹẹrẹ àwọn pẹpẹ Baali ni a yí lulẹ̀, ó sì fọ́ àwọn ère sí wẹ́wẹ́, ó run àwọn pẹpẹ tí ó wà lórí rẹ̀, wọ́n sì fọ́ túútúú, àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Èyí tí ó fọ́ wọn sì lúúlúú, ó sì gbọ̀n wọ́n sí orí isà òkú àti àwọn tí ó ń rú ẹbọ sí wọn.
V njegovi prisotnosti so porušili Báalove oltarje in podobe, ki so bile visoko nad njimi, je posekal. Ašere, izrezljane podobe in ulite podobe je zdrobil na koščke in iz njih naredil prah in ga raztresel po grobovih tistih, ki so jim žrtvovali.
5 Ó sì sun àwọn egungun àwọn àlùfáà lórí pẹpẹ wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni ó sì wẹ Juda àti Jerusalẹmu mọ́.
Kosti duhovnikov je sežgal na njihovih oltarjih ter očistil Juda in Jeruzalem.
6 Ní ìlú Manase, Efraimu àti Simeoni, àní títí ó fi dé Naftali, àti nínú àwọn, ó tú ilé wọn yíkákiri.
Tako je storil v mestih Manáseja, Efrájima in Simeona, celo do Neftálija, z njihovimi motikami naokoli.
7 Ó sì wó pẹpẹ àti ère Aṣerah lulẹ̀ àti àwọn ère yíyá àti àwọn òrìṣà, ó sì gùn ó sì ti ké gbogbo àwọn ère orí pẹpẹ lulẹ̀ ní gbogbo àyíká Israẹli. Lẹ́yìn náà ó padà sí Jerusalẹmu.
Ko je porušil oltarje in ašere in je rezane podobe poteptal v prah in posekal vse malike po vsej izraelski deželi, se je vrnil v Jeruzalem.
8 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Josiah ni a ti wẹ ilẹ̀ náà mọ́ àti ilé Olúwa, ó sì rán Ṣafani ọmọ Asalia àti Maaseiah olórí ìlú náà, pẹ̀lú Joah, ọmọ Joahasi, akọ̀wé, láti tún ilé Olúwa Ọlọ́run ṣe.
Torej v osemnajstem letu njegovega kraljevanja, ko je očistil deželo in hišo, je poslal Acaljájevega sina Šafána, voditelja mesta Maasejája in Joaházovega sina letopisca Joáha, da popravi hišo Gospoda, svojega Boga.
9 Wọ́n sì lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, ó sì fún un ní owó náà tí ó mú wá sí inú ilé Ọlọ́run, ti àwọn ọmọ Lefi ẹni tí ó jẹ́ aṣọ́bodè ti gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn Manase Efraimu àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ìyókù Israẹli àti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn Juda àti Benjamini wọ́n sì padà sí Jerusalẹmu.
Ko so prišli k vélikemu duhovniku Hilkijáju so izročili denar, ki je bil prinesen v Božjo hišo, ki so ga zbrali Lévijevci, ki so varovali vrata, iz roke Manáseja, Efrájima in vsega Izraelovega preostanka in od vsega Juda in Benjamina in se vrnili v Jeruzalem.
10 Nígbà náà ni wọn sì fi le àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ilé lọ́wọ́, àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ ilé Olúwa. Àwọn ọkùnrin yìí sì san owó fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń túnṣe, tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ní ilé Olúwa.
Položili so ga v roko delavcev, ki so imeli nadzor nad Gospodovo hišo in ga izročili delavcem, ki so delali v Gospodovi hiši, da hišo popravijo in izboljšajo.
11 Wọ́n sì tún fi owó fún àwọn oníṣọ̀nà àti àwọn olùkọ́lé láti ra òkúta gbígbẹ́ àti ìtì igi fún ìsopọ̀ àti igi rírẹ́ fún ìkọ́lé tí ọba Juda ti gbà láti túnṣe.
Izročila sta ga celo rokodelcem in graditeljem, da kupijo klesan kamen, les za vezi in da tlakujejo hiše, ki so jih Judovi kralji uničili.
12 Àwọn ọkùnrin náà ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú òtítọ́, láti darí wọn ní Jahati àti Obadiah, àwọn ọmọ Lefi láti Merari, àti Sekariah àti Meṣullamu, sọ̀kalẹ̀ láti Kohati àwọn ọmọ Lefi gbogbo tí ó ní ọgbọ̀n ohun èlò orin.
Možje so zvesto opravljali delo in njihovi nadzorniki so bili Jahat in Obadjá, Lévijevca izmed Meraríjevih sinov; Zeharjá in Mešulám izmed Kehátovih sinov, da bi ga nadzirali in drugi izmed Lévijevcev, vsi, ki so vešči glasbenih instrumentov.
13 Wọ́n sì ní olórí àwọn aláàárù àti àwọn alábojútó gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ láti ibi iṣẹ́ sí ibi iṣẹ́, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Lefi sì ní akọ̀wé, olùtọ́jú àti olùṣọ́nà.
Bili so tudi nad nosilci bremen in bili so nadzorniki vseh teh, ki so na kakršen koli način opravljali delo. Izmed Lévijevcev so bili pisarji, častniki in vratarji.
14 Nígbà tí wọ́n mú owó náà tí wọ́n mú wá sí ilé Olúwa, Hilkiah àlùfáà sì rí ìwé òfin Olúwa tí a ti fi fún un láti ọwọ́ Mose.
Ko so jemali ven denar, ki je bil prinesen v Gospodovo hišo, je duhovnik Hilkijá našel knjigo Gospodove postave, ki je bila dana po Mojzesu.
15 Hilkiah sì wí fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi ti rí ìwé òfin nínú ilé Olúwa.” Ó sì fi fún Ṣafani.
Hilkijá je odgovoril in pisarju Šafánu rekel: »V Gospodovi hiši sem našel knjigo postave.« In Hilkijá je knjigo izročil Šafánu.
16 Nígbà náà Ṣafani sì mú ìwé náà lọ sí ọ̀dọ̀ ọba ó sì ròyìn fún un. “Àwọn ìjòyè rẹ̀ ń ṣe gbogbo nǹkan tí a ti fi lé wọn lọ́wọ́.
Šafán je knjigo odnesel h kralju in [poleg tega] kralju prinesel besedo, rekoč: »Vse, kar je bilo poverjeno tvojim služabnikom, so to storili.«
17 Wọ́n ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa wọ́n sì ti fi lé àwọn alábojútó lọ́wọ́ àti àwọn òṣìṣẹ́.”
Skupaj so zbrali denar, ki je bil najden v Gospodovi hiši ter ga izročili v roko nadzornikov in delavcev.
18 Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sì sọ fún ọba, “Hilkiah àlùfáà ti fún mi ní ìwé.” Ṣafani sì kà níwájú ọba.
Potem je pisar Šafán povedal kralju, rekoč: »Duhovnik Hilkijá mi je izročil knjigo.« In Šafán jo je bral pred kraljem.
19 Nígbà tí ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
Zgodilo se je, ko je kralj slišal besede postave, da je pretrgal svoja oblačila.
20 Ó sì pa àṣẹ yìí fún Hilkiah, Ahikamu ọmọ Ṣafani, Abdoni ọmọ Mika, Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
Kralj je ukazal Hilkijáju, Šafánovemu sinu Ahikámu, Mihajájevemu sinu Abdónu, pisarju Šafánu in kraljevemu služabniku Asajáju, rekoč:
21 “Ẹ lọ kí ẹ lọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi nípa àwọn ìyókù Israẹli àti Juda nípa ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ti jáde sí orí wa nítorí àwọn baba wa kò ti pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́, wọn kò sì tí ì ṣe gẹ́gẹ́ bí i gbogbo èyí tí a kọ sínú ìwé yìí.”
»Pojdite, vprašajte Gospoda zame in za tiste, ki so preostali v Izraelu in Judu, glede besed knjige, ki se je našla, kajti velik je Gospodov bes, ki je izlit na nas, ker se naši očetje niso držali Gospodove besede, da bi delali po vsem, kar je napisano v tej knjigi.«
22 Hilkiah àti àwọn ènìyàn tí ọba yàn tọ Hulda wòlíì obìnrin láti ba sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tokhati tí a tún ń pè ní Tikfa, ọmọ Harhasi, olùtọ́jú ibi ìkáṣọsí. Ó sì ń gbé ní Jerusalẹmu, ní ìhà kejì.
Hilkijá in tisti, ki jih je kralj določil, so odšli k prerokinji Huldi, ženi Šalúma, Tikvájevega sina, Hasrájevega sina, varuha garderobe (torej prebivala je v Jeruzalemu, v drugem okraju) in ji prav tako govorili.
23 Ó sì wí fún wọn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ti sọ, sọ fún àwọn ọkùnrin tí ó rán ọ sí mi pé,
Odgovorila jim je: »Tako govori Gospod, Izraelov Bog: ›Povejte človeku, ki vas je poslal k meni:
24 ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi yóò sì mú ibi wá sí ìhín yìí àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gbogbo àní ègún tí a kọ sínú ìwé tí wọ́n ti kà níwájú ọba Juda.”
›Tako govori Gospod: ›Glejte, zlo bom privedel nad ta kraj in nad njegove prebivalce, celó vsa prekletstva, ki so zapisana v knjigi, ki so jo brali pred Judovim kraljem,
25 Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀ wọ́n sì ti sun tùràrí sí ọlọ́run mìíràn wọ́n sì ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn ṣe, ìbínú yóò tú jáde wá sórí ibí yìí, a kì yóò sì paná rẹ̀.’
ker so me zapustili in zažigali kadilo drugim bogovom, da bi me lahko dražili do jeze z vsemi deli svojih rok, zato bo moj bes izlit na ta kraj in ne bo pogašen.
26 Sọ fún ọba Juda, ẹni tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa ti sọ, Ọlọ́run Israẹli, sọ nípa ọ̀rọ̀ wọ́n nì tí ìwọ gbọ́.
Kar se tiče Judovega kralja, ki vas je poslal, da poizveste od Gospoda, mu boste rekli takole: ›Tako govori Gospod, Izraelov Bog, glede besed, ki si jih slišal:
27 Nítorí ọkàn rẹ̀ dúró, ìwọ sì rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa nígbà tí ó gbọ́ ohun tí ó sọ lórí ibí yìí àti ènìyàn rẹ, nítorí ìwọ rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú mi tí o sì fa aṣọ rẹ ya, tí o sì lọ níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ ni Olúwa wí.
›Ker je bilo tvoje srce nežno in si se ponižal pred Bogom, ko si slišal njegove besede zoper to mesto in zoper njegove prebivalce in se ponižuješ pred menoj in si pretrgal svoja oblačila in jokal pred menoj; celo tudi jaz sem te slišal, ‹ govori Gospod.
28 Nísinsin yìí, Èmi ó kó ọ jọ pọ̀ sọ́dọ̀ àwọn baba rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kò sì ní rí gbogbo ibi tí èmi ó mú wá sórí ibí yìí àti lórí àwọn tí ń gbé ibẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú ìdáhùn rẹ̀ padà sí ọ̀dọ̀ ọba.
›Glej, zbral te bom k tvojim očetom in v miru boš zbran k svojemu grobu niti tvoje oči ne bodo videle vsega zla, ki ga bom privedel nad ta kraj in nad prebivalce istega.‹« Tako so kralju ponovno prinesli besedo.
29 Nígbà náà ni ọba sì pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda jọ àti Jerusalẹmu.
Potem je kralj poslal in zbral skupaj vse starešine iz Juda in Jeruzalema.
30 Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
Kraj je odšel gor v Gospodovo hišo in vsi Judovi možje, prebivalci Jeruzalema, duhovniki, Lévijevci in vse ljudstvo, veliki in mali, in na njihova ušesa je bral vse besede knjige zaveze, ki se je našla v Gospodovi hiši.
31 Ọba sì dúró ní ipò rẹ̀ ó sì tún májẹ̀mú dá níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti ẹ̀rí rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo àyà rẹ̀ àti láti pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé yìí.
Kralj je stal na svojem mestu in sklenil zavezo pred Gospodom, da hodi za Gospodom in da se drži njegovih zapovedi, njegovih pričevanj in njegovih zapovedi z vsem svojim srcem in z vso svojo dušo, da izpolni besede zaveze, ki so zapisane v tej knjigi.
32 Nígbà náà, ó sì mú kí gbogbo ènìyàn ní Jerusalẹmu àti Benjamini dúró nínú ẹ̀rí fún ara wọn, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ṣe èyí gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú Ọlọ́run, Ọlọ́run baba ńlá wọn.
Vsem, ki so bili prisotni v Jeruzalemu in Benjaminu, je velel, da pristopijo k temu. Prebivalci Jeruzalema so storili glede na zavezo Boga, Boga svojih očetov.
33 Josiah sì kó gbogbo ohun ìríra kúrò nínú gbogbo ìlú tí ń ṣe ti àwọn tí ó wà ní Israẹli, ó sì mú kí gbogbo àwọn tí ó wà ní Israẹli sin Olúwa Ọlọ́run wọn gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà láyè wọn, kò yà kúrò láti máa tọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn lẹ́yìn.
Jošíja je odvzel vse ogabnosti iz vseh dežel, ki so pripadale Izraelovim otrokom in pripravil vse, ki so bili prisotni v Izraelu, da služijo, torej da služijo Gospodu, svojemu Bogu. In vse svoje dni se niso odvrnili od sledenja Gospodu, Bogu svojih očetov.

< 2 Chronicles 34 >