< 2 Chronicles 34 >

1 Josiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì dí ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
Iosia era în vârstă de opt ani când a început să domnească și a domnit în Ierusalim treizeci și unu de ani.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa, ó sì rìn ọ̀nà baba rẹ̀ Dafidi, kò sì yà sí ọwọ́ ọ̀tún tàbí òsì.
Și a făcut ceea ce era drept înaintea ochilor DOMNULUI și a umblat în căile tatălui său, David, și nu s-a abătut nici l-a dreapta, nici la stânga.
3 Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀, nígbà tí ó sì wà ní ọ̀dọ́mọdé, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wá ojú Ọlọ́run baba Dafidi. Ní ọdún kejìlá. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fọ Juda àti Jerusalẹmu mọ́ kúrò ní ibi gíga rẹ̀, ère òrìṣà Aṣerah, àti ère yíyá àti ère dídà.
Fiindcă în al optulea an al domniei lui, în timp ce era încă tânăr, a început să caute pe Dumnezeul tatălui său, David; și în al doisprezecelea an a început să curețe Iuda și Ierusalimul de înălțimi și de dumbrăvi și de chipuri cioplite și de chipuri turnate.
4 Lábẹ́ àpẹẹrẹ àwọn pẹpẹ Baali ni a yí lulẹ̀, ó sì fọ́ àwọn ère sí wẹ́wẹ́, ó run àwọn pẹpẹ tí ó wà lórí rẹ̀, wọ́n sì fọ́ túútúú, àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Èyí tí ó fọ́ wọn sì lúúlúú, ó sì gbọ̀n wọ́n sí orí isà òkú àti àwọn tí ó ń rú ẹbọ sí wọn.
Și au dărâmat altarele Baalilor în prezența sa, și le-a retezat chipurile care erau deasupra lor; și dumbrăvile și chipurile cioplite și chipurile turnate le-a spart în bucăți și le-a făcut praf și le-a împrăștiat pe mormintele celor care le sacrificaseră lor.
5 Ó sì sun àwọn egungun àwọn àlùfáà lórí pẹpẹ wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni ó sì wẹ Juda àti Jerusalẹmu mọ́.
Și a ars oasele preoților pe altarele lor și a curățat Iuda și Ierusalimul.
6 Ní ìlú Manase, Efraimu àti Simeoni, àní títí ó fi dé Naftali, àti nínú àwọn, ó tú ilé wọn yíkákiri.
Și astfel a făcut în cetățile lui Manase și Efraim și Simeon, chiar până la Neftali, cu armele lor de jur împrejur.
7 Ó sì wó pẹpẹ àti ère Aṣerah lulẹ̀ àti àwọn ère yíyá àti àwọn òrìṣà, ó sì gùn ó sì ti ké gbogbo àwọn ère orí pẹpẹ lulẹ̀ ní gbogbo àyíká Israẹli. Lẹ́yìn náà ó padà sí Jerusalẹmu.
Și după ce a dărâmat altarele și dumbrăvile și a prefăcut chipurile cioplite în praf și a retezat toți idolii din toată țara lui Israel, s-a întors în Ierusalim.
8 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Josiah ni a ti wẹ ilẹ̀ náà mọ́ àti ilé Olúwa, ó sì rán Ṣafani ọmọ Asalia àti Maaseiah olórí ìlú náà, pẹ̀lú Joah, ọmọ Joahasi, akọ̀wé, láti tún ilé Olúwa Ọlọ́run ṣe.
Și, în al optsprezecelea an al domniei lui, după ce a curățat țara și casa, a trimis pe Șafan, fiul lui Ațalia, și pe Maaseia, guvernatorul cetății, și pe Ioah, fiul lui Ioahaz, cronicarul, să repare casa DOMNULUI Dumnezeul său.
9 Wọ́n sì lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, ó sì fún un ní owó náà tí ó mú wá sí inú ilé Ọlọ́run, ti àwọn ọmọ Lefi ẹni tí ó jẹ́ aṣọ́bodè ti gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn Manase Efraimu àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ìyókù Israẹli àti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn Juda àti Benjamini wọ́n sì padà sí Jerusalẹmu.
Și când au venit la Hilchia, marele preot, au dat banii care au fost aduși în casa lui Dumnezeu, banii pe care leviții, care păzeau ușile, i-au adunat din mâna lui Manase și Efraim și din toată rămășița lui Israel și din tot Iuda și Beniamin; și s-au întors la Ierusalim.
10 Nígbà náà ni wọn sì fi le àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ilé lọ́wọ́, àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ ilé Olúwa. Àwọn ọkùnrin yìí sì san owó fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń túnṣe, tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ní ilé Olúwa.
Și i-au pus în mâna lucrătorilor care aveau supravegherea casei DOMNULUI și i-au dat lucrătorilor care lucrau în casa DOMNULUI, să întărească și să repare casa;
11 Wọ́n sì tún fi owó fún àwọn oníṣọ̀nà àti àwọn olùkọ́lé láti ra òkúta gbígbẹ́ àti ìtì igi fún ìsopọ̀ àti igi rírẹ́ fún ìkọ́lé tí ọba Juda ti gbà láti túnṣe.
I-au dat tâmplarilor și constructorilor, ca să cumpere piatră tăiată, și lemnărie pentru încheieturi și să pună podele caselor pe care împărații lui Iuda le-au distrus.
12 Àwọn ọkùnrin náà ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú òtítọ́, láti darí wọn ní Jahati àti Obadiah, àwọn ọmọ Lefi láti Merari, àti Sekariah àti Meṣullamu, sọ̀kalẹ̀ láti Kohati àwọn ọmọ Lefi gbogbo tí ó ní ọgbọ̀n ohun èlò orin.
Și bărbații au lucrat cu credincioșie, și supraveghetorii lor erau leviții Iahat și Obadia, fiii lui Merari; și Zaharia și Meșulam, dintre fiii chehatiților, pentru a înainta lucrul; și alții dintre leviți, toți care cunoșteau instrumentele de muzică.
13 Wọ́n sì ní olórí àwọn aláàárù àti àwọn alábojútó gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ láti ibi iṣẹ́ sí ibi iṣẹ́, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Lefi sì ní akọ̀wé, olùtọ́jú àti olùṣọ́nà.
De asemenea ei erau peste purtătorii de poveri și erau supraveghetori ai tuturor celor care făceau lucrarea oricărui serviciu; și dintre leviți erau scribi și administratori și portari.
14 Nígbà tí wọ́n mú owó náà tí wọ́n mú wá sí ilé Olúwa, Hilkiah àlùfáà sì rí ìwé òfin Olúwa tí a ti fi fún un láti ọwọ́ Mose.
Și când au adus banii care au fost aduși în casa DOMNULUI, preotul Hilchia a găsit o carte a legii DOMNULUI, dată de Moise.
15 Hilkiah sì wí fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi ti rí ìwé òfin nínú ilé Olúwa.” Ó sì fi fún Ṣafani.
Și Hilchia a răspuns și a zis lui Șafan, scribul: Am găsit cartea legii în casa DOMNULUI. Și Hilchia a dat cartea lui Șafan.
16 Nígbà náà Ṣafani sì mú ìwé náà lọ sí ọ̀dọ̀ ọba ó sì ròyìn fún un. “Àwọn ìjòyè rẹ̀ ń ṣe gbogbo nǹkan tí a ti fi lé wọn lọ́wọ́.
Și Șafan a dus împăratului cartea și a adus înapoi cuvântul împăratului, spunând: Tot ce a fost încredințat servitorilor tăi, să facă.
17 Wọ́n ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa wọ́n sì ti fi lé àwọn alábojútó lọ́wọ́ àti àwọn òṣìṣẹ́.”
Și au adunat banii care s-au găsit în casa DOMNULUI și i-au dat în mâna supraveghetorilor și în mâna lucrătorilor.
18 Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sì sọ fún ọba, “Hilkiah àlùfáà ti fún mi ní ìwé.” Ṣafani sì kà níwájú ọba.
Atunci Șafan, scribul, a spus împăratului, zicând: Preotul Hilchia mi-a dat o carte. Și Șafan a citit-o înaintea împăratului.
19 Nígbà tí ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
Și s-a întâmplat, când împăratul a auzit cuvintele legii, că și-a sfâșiat hainele.
20 Ó sì pa àṣẹ yìí fún Hilkiah, Ahikamu ọmọ Ṣafani, Abdoni ọmọ Mika, Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
Și împăratul a poruncit lui Hilchia și lui Ahicam, fiul lui Șafan; și lui Abdon, fiul lui Mica; și lui Șafan, scribul; și lui Asaia, un servitor al împăratului, spunând:
21 “Ẹ lọ kí ẹ lọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi nípa àwọn ìyókù Israẹli àti Juda nípa ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ti jáde sí orí wa nítorí àwọn baba wa kò ti pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́, wọn kò sì tí ì ṣe gẹ́gẹ́ bí i gbogbo èyí tí a kọ sínú ìwé yìí.”
Duceți-vă și cercetați de la DOMNUL pentru mine și pentru cei ce au rămas în Israel și în Iuda, referitor la cuvintele cărții care a fost găsită: fiindcă mare este furia DOMNULUI turnată asupra noastră, deoarece părinții noștri nu au ținut cuvântul DOMNULUI, să facă după tot ce este scris în această carte.
22 Hilkiah àti àwọn ènìyàn tí ọba yàn tọ Hulda wòlíì obìnrin láti ba sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tokhati tí a tún ń pè ní Tikfa, ọmọ Harhasi, olùtọ́jú ibi ìkáṣọsí. Ó sì ń gbé ní Jerusalẹmu, ní ìhà kejì.
Și Hilchia și cei pe care împăratul îi rânduise, au mers la profetesa Hulda, soția lui Șalum, fiul lui Ticva, fiul lui Hasra, păzitorul garderobei (acum ea locuia în Ierusalim în școala profeților); și i-au vorbit în felul acela.
23 Ó sì wí fún wọn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ti sọ, sọ fún àwọn ọkùnrin tí ó rán ọ sí mi pé,
Și ea le-a răspuns: Astfel spune DOMNUL Dumnezeul lui Israel: Spuneți bărbatului care v-a trimis la mine:
24 ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi yóò sì mú ibi wá sí ìhín yìí àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gbogbo àní ègún tí a kọ sínú ìwé tí wọ́n ti kà níwájú ọba Juda.”
Astfel spune DOMNUL: Iată, voi aduce răul peste acest loc și peste locuitorii lui, toate blestemele care sunt scrise în cartea pe care au citit-o înaintea împăratului lui Iuda;
25 Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀ wọ́n sì ti sun tùràrí sí ọlọ́run mìíràn wọ́n sì ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn ṣe, ìbínú yóò tú jáde wá sórí ibí yìí, a kì yóò sì paná rẹ̀.’
Pentru că m-au părăsit și au ars tămâie altor dumnezei, ca să mă provoace la mânie cu toate lucrările mâinilor lor, de aceea furia mea va fi turnată peste acest loc și nu se va stinge.
26 Sọ fún ọba Juda, ẹni tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa ti sọ, Ọlọ́run Israẹli, sọ nípa ọ̀rọ̀ wọ́n nì tí ìwọ gbọ́.
Și cât despre împăratul lui Iuda, care a trimis să cerceteze de la DOMNUL, astfel să îi spuneți: Astfel spune DOMNUL Dumnezeul lui Israel referitor la cuvintele pe care le-ai auzit:
27 Nítorí ọkàn rẹ̀ dúró, ìwọ sì rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa nígbà tí ó gbọ́ ohun tí ó sọ lórí ibí yìí àti ènìyàn rẹ, nítorí ìwọ rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú mi tí o sì fa aṣọ rẹ ya, tí o sì lọ níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ ni Olúwa wí.
Pentru că inima ta s-a înmuiat și te-ai umilit înaintea lui Dumnezeu când ai auzit cuvintele lui împotriva acestui loc și împotriva locuitorilor lui și te-ai umilit înaintea mea și ți-ai sfâșiat hainele și ai plâns înaintea mea, chiar eu însumi te-am auzit, spune DOMNUL.
28 Nísinsin yìí, Èmi ó kó ọ jọ pọ̀ sọ́dọ̀ àwọn baba rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kò sì ní rí gbogbo ibi tí èmi ó mú wá sórí ibí yìí àti lórí àwọn tí ń gbé ibẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú ìdáhùn rẹ̀ padà sí ọ̀dọ̀ ọba.
Iată, te voi aduna la părinții tăi și vei fi adunat la mormântul tău în pace și nu vor vedea ochii tăi tot răul care îl voi aduce peste acest loc și peste locuitorii lui. Astfel ei au adus înapoi cuvânt împăratului.
29 Nígbà náà ni ọba sì pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda jọ àti Jerusalẹmu.
Atunci împăratul a trimis și a adunat pe toți bătrânii lui Iuda și ai Ierusalimului.
30 Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
Și împăratul a plâns în casa DOMNULUI, el și toți bărbații lui Iuda și locuitorii Ierusalimului și preoții și leviții și tot poporul, mari și mici; și el a citit în urechile lor toate cuvintele cărții legământului care s-a găsit în casa DOMNULUI.
31 Ọba sì dúró ní ipò rẹ̀ ó sì tún májẹ̀mú dá níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti ẹ̀rí rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo àyà rẹ̀ àti láti pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé yìí.
Și împăratul a stat în picioare în locul său și a făcut un legământ înaintea DOMNULUI, să umble după DOMNUL și să țină poruncile lui și mărturiile lui și statutele lui, cu toată inima lui și cu tot sufletul lui, să împlinească toate cuvintele legământului scrise în această carte.
32 Nígbà náà, ó sì mú kí gbogbo ènìyàn ní Jerusalẹmu àti Benjamini dúró nínú ẹ̀rí fún ara wọn, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ṣe èyí gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú Ọlọ́run, Ọlọ́run baba ńlá wọn.
Și a făcut ca toți cei care erau prezenți în Ierusalim și în Beniamin să stea în picioare la acesta. Și locuitorii Ierusalimului au făcut conform legământului lui Dumnezeu, Dumnezeul părinților lor.
33 Josiah sì kó gbogbo ohun ìríra kúrò nínú gbogbo ìlú tí ń ṣe ti àwọn tí ó wà ní Israẹli, ó sì mú kí gbogbo àwọn tí ó wà ní Israẹli sin Olúwa Ọlọ́run wọn gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà láyè wọn, kò yà kúrò láti máa tọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn lẹ́yìn.
Și Iosia a îndepărtat toate urâciunile din toate țările care aparțineau de copiii lui Israel și a făcut pe toți cei care erau prezenți în Israel să servească, să servească pe DOMNUL Dumnezeul lor. Și în toate zilele lui nu s-au depărtat de la a urma pe DOMNUL, Dumnezeul părinților lor.

< 2 Chronicles 34 >