< 2 Chronicles 34 >

1 Josiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì dí ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
E waru nga tau o Hohia i tona kingitanga, a e toru tekau ma tahi nga tau i kingi ai ia ki Hiruharama.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa, ó sì rìn ọ̀nà baba rẹ̀ Dafidi, kò sì yà sí ọwọ́ ọ̀tún tàbí òsì.
A tika tonu tana mahi ki te titiro a Ihowa: i haere hoki ia i runga i nga ara o tona tupuna, o Rawiri; kihai hoki i peka ki matau, ki maui.
3 Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀, nígbà tí ó sì wà ní ọ̀dọ́mọdé, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wá ojú Ọlọ́run baba Dafidi. Ní ọdún kejìlá. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fọ Juda àti Jerusalẹmu mọ́ kúrò ní ibi gíga rẹ̀, ère òrìṣà Aṣerah, àti ère yíyá àti ère dídà.
I te waru hoki o nga tau o tona kingitanga, i te mea he taitamariki ano ia, ka timata ia te rapu i te Atua o tona tupuna, o Rawiri; a i te tekau ma rua o nga tau ka timata ia te tahi i te poke o Hura, o Hiruharama, ara i nga wahi tiketike, i nga Aherimi, i nga whakapakoko whaowhao, i nga whakapakoko whakarewa.
4 Lábẹ́ àpẹẹrẹ àwọn pẹpẹ Baali ni a yí lulẹ̀, ó sì fọ́ àwọn ère sí wẹ́wẹ́, ó run àwọn pẹpẹ tí ó wà lórí rẹ̀, wọ́n sì fọ́ túútúú, àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Èyí tí ó fọ́ wọn sì lúúlúú, ó sì gbọ̀n wọ́n sí orí isà òkú àti àwọn tí ó ń rú ẹbọ sí wọn.
I wahia ano e ratou nga aata a nga Paara i tona aroaro; tapahia ana e ia nga whakapakoko ra i runga ake o aua aata, mongamonga noa i a ia nga Aherimi, nga whakapakoko whaowhao, me nga whakapakoko whakarewa, tukia ana e ia kia puehu, ruia atu ana ki runga ki nga urupa o te hunga i patu whakahere ki a ratou.
5 Ó sì sun àwọn egungun àwọn àlùfáà lórí pẹpẹ wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni ó sì wẹ Juda àti Jerusalẹmu mọ́.
I tahuna ano e ia nga whenua o nga tohunga ki runga ki a ratou aata, a tahia ana e ia te poke o Hura, o Hiruharama.
6 Ní ìlú Manase, Efraimu àti Simeoni, àní títí ó fi dé Naftali, àti nínú àwọn, ó tú ilé wọn yíkákiri.
Pera ana ano ia i nga pa o Manahi, o Eparaima, o Himiona, a tae noa ki Napatari, i roto i to ratou ururua, a puta noa, puta noa.
7 Ó sì wó pẹpẹ àti ère Aṣerah lulẹ̀ àti àwọn ère yíyá àti àwọn òrìṣà, ó sì gùn ó sì ti ké gbogbo àwọn ère orí pẹpẹ lulẹ̀ ní gbogbo àyíká Israẹli. Lẹ́yìn náà ó padà sí Jerusalẹmu.
Na ka wahia iho e ia nga aata, a ka tukia nga Aherimi me nga whakapakoko kia puehu, a poto noa i a ia te tapatapahi nga whakapakoko ra puta noa i te whenua o Iharaira: na hoki ana ia ki Hiruharama.
8 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Josiah ni a ti wẹ ilẹ̀ náà mọ́ àti ilé Olúwa, ó sì rán Ṣafani ọmọ Asalia àti Maaseiah olórí ìlú náà, pẹ̀lú Joah, ọmọ Joahasi, akọ̀wé, láti tún ilé Olúwa Ọlọ́run ṣe.
Na i te tekau ma waru o nga tau o tona kingitanga, i te mea ka oti nei te poke o te whenua, o te whare, te tahi, ka unga e ia a Hapana tama a Ataria ratou ko maaheia kawana o te pa, ko te kaiwhakamahara, ko Ioaha tama a Iehoahata, ki te hanga i t e whare o Ihowa, o tona Atua, kia pai.
9 Wọ́n sì lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, ó sì fún un ní owó náà tí ó mú wá sí inú ilé Ọlọ́run, ti àwọn ọmọ Lefi ẹni tí ó jẹ́ aṣọ́bodè ti gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn Manase Efraimu àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ìyókù Israẹli àti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn Juda àti Benjamini wọ́n sì padà sí Jerusalẹmu.
Na haere ana ratou ki a Hirikia tohunga nui, a hoatu ana e ratou te moni i kawea ki te whare o te Atua, ta nga Riwaiti, ta nga kaitiaki o nga tatau i kohikohi ai i te ringa o Manahi, o Eparaima, i nga morehu katoa o Iharaira, i a Hura katoa, i a Pineamine, i nga tangata ano o Hiruharama.
10 Nígbà náà ni wọn sì fi le àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ilé lọ́wọ́, àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ ilé Olúwa. Àwọn ọkùnrin yìí sì san owó fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń túnṣe, tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ní ilé Olúwa.
A na ratou i hoatu ki te ringa o nga kaimahi i tohutohu nei i te whare o Ihowa; a hoatu ana e enei ki nga kaimahi i mahi nei i te whare o Ihowa hei hanga i nga pakaru, hei whakapai i te whare.
11 Wọ́n sì tún fi owó fún àwọn oníṣọ̀nà àti àwọn olùkọ́lé láti ra òkúta gbígbẹ́ àti ìtì igi fún ìsopọ̀ àti igi rírẹ́ fún ìkọ́lé tí ọba Juda ti gbà láti túnṣe.
Ara i hoatu e ratou ki nga kamura, ki nga kaihanga, hei hoko i nga kohatu tarai, i nga rakau mo nga hononga, hei whakanoho rakau ano ki nga whare i kore nei i nga kingi o Hura.
12 Àwọn ọkùnrin náà ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú òtítọ́, láti darí wọn ní Jahati àti Obadiah, àwọn ọmọ Lefi láti Merari, àti Sekariah àti Meṣullamu, sọ̀kalẹ̀ láti Kohati àwọn ọmọ Lefi gbogbo tí ó ní ọgbọ̀n ohun èlò orin.
A pono tonu te mahinga a aua tangata i te mahi; na, ko nga kaitohutohu i a ratou, ko Iahata, ko Oparia, he Riwaiti, no nga tama a Merari; ko Hakaraia, ko Mehurama, no nga tama a nga Kohati, hei whakahohoro; me etahi atu ano o nga Riwaiti katoa i mohio ki nga mea whakatangi.
13 Wọ́n sì ní olórí àwọn aláàárù àti àwọn alábojútó gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ láti ibi iṣẹ́ sí ibi iṣẹ́, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Lefi sì ní akọ̀wé, olùtọ́jú àti olùṣọ́nà.
Ko ratou ano hei rangatira mo nga kaipikau, hei kaitirotiro ano mo te hunga katoa e mahi ana i tenei mahi ranei, i tera mahi ranei; ko etahi ano o nga Riwaiti hei karaipi, hei kaitohutohu, hei kaitiaki kuwaha.
14 Nígbà tí wọ́n mú owó náà tí wọ́n mú wá sí ilé Olúwa, Hilkiah àlùfáà sì rí ìwé òfin Olúwa tí a ti fi fún un láti ọwọ́ Mose.
Na, i ta ratou maunga atu i te moni i kawea nei ki te whare o Ihowa, ka kitea e te tohunga, e Hirikia te pukapuka o te ture a Ihowa i homai nei e Mohi.
15 Hilkiah sì wí fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi ti rí ìwé òfin nínú ilé Olúwa.” Ó sì fi fún Ṣafani.
Na ka oho a Hirikia, ka mea ki a Hapana karaipi, Kua kitea e ahau te pukapuka o te ture i roto i te whare o Ihowa. A homai ana te pukapuka e Hirikia ki a Hapana.
16 Nígbà náà Ṣafani sì mú ìwé náà lọ sí ọ̀dọ̀ ọba ó sì ròyìn fún un. “Àwọn ìjòyè rẹ̀ ń ṣe gbogbo nǹkan tí a ti fi lé wọn lọ́wọ́.
A na Hapana i kawe te pukapuka ki te kingi. I whakahokia ano e ia te korero ki te kingi; i mea ia, ko nga mea katoa i homai ki te ringa o au pononga, e meatia ana e ratou.
17 Wọ́n ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa wọ́n sì ti fi lé àwọn alábojútó lọ́wọ́ àti àwọn òṣìṣẹ́.”
Kua ringihia hoki e ratou te moni i kitea i roto i te whare o Ihowa, a hoatu ana ki te ringa ano o nga kaimahi.
18 Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sì sọ fún ọba, “Hilkiah àlùfáà ti fún mi ní ìwé.” Ṣafani sì kà níwájú ọba.
Na ka korero a Hapana karaipi ki te kingi ka mea, Kua homai he pukapuka ki ahau e Hirikia tohunga. A korerotia ana e Hapana i te aroaro o te kingi.
19 Nígbà tí ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
A, no te rongonga o te kingi i nga kupu o te ture, haea ana e ia ona kakahu.
20 Ó sì pa àṣẹ yìí fún Hilkiah, Ahikamu ọmọ Ṣafani, Abdoni ọmọ Mika, Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
Na ka whakahau te kingi ki a Hirikia, ki a Ahikama tama a Hapana, ki a Aparono tama a Mika, ki a Hapana karaipi, ki a Ahaia tangata a te kingi, ka mea,
21 “Ẹ lọ kí ẹ lọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi nípa àwọn ìyókù Israẹli àti Juda nípa ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ti jáde sí orí wa nítorí àwọn baba wa kò ti pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́, wọn kò sì tí ì ṣe gẹ́gẹ́ bí i gbogbo èyí tí a kọ sínú ìwé yìí.”
Haere, ui atu ki a Ihowa moku, mo nga morehu ano o Iharaira, o Hura, ara i te tikanga o nga kupu o te pukapuka kua kitea nei: he nui hoki te riri o Ihowa kua ringihia nei ki a tatou, no te mea kihai o tatou matua i pupuri i te kupu a Ihowa, kiha i i mahi i nga mea katoa i tuhituhia ki tenei pukapuka.
22 Hilkiah àti àwọn ènìyàn tí ọba yàn tọ Hulda wòlíì obìnrin láti ba sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tokhati tí a tún ń pè ní Tikfa, ọmọ Harhasi, olùtọ́jú ibi ìkáṣọsí. Ó sì ń gbé ní Jerusalẹmu, ní ìhà kejì.
Heoi haere ana a Hirikia ratou ko a te kingi i whakarite ai, ki a Hurura ki te wahine poropiti, he wahine ia na Harumu, tama a Tokohata, tama a Haharaha, kaitiaki kakahu; i Hiruharama hoki taua wahine e noho ana, i te wahi tuarua. Na korerotia a na enei mea e ratou ki a ia.
23 Ó sì wí fún wọn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ti sọ, sọ fún àwọn ọkùnrin tí ó rán ọ sí mi pé,
Na ka mea ia ki a ratou, Ko te korero tenei a Ihowa, a te Atua o Iharaira, Mea atu ki te tangata nana koutou i tono mai ki ahau,
24 ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi yóò sì mú ibi wá sí ìhín yìí àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gbogbo àní ègún tí a kọ sínú ìwé tí wọ́n ti kà níwájú ọba Juda.”
Ko ta Ihowa kupu tenei, Tenei ahau te kawe nei i te kino mo tenei wahi, mo nga tangata ano o konei, ara nga kanga katoa kua oti te tuhituhi ki te pukapuka i korerotia ra i te aroaro o te kingi o Hura;
25 Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀ wọ́n sì ti sun tùràrí sí ọlọ́run mìíràn wọ́n sì ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn ṣe, ìbínú yóò tú jáde wá sórí ibí yìí, a kì yóò sì paná rẹ̀.’
Mo ratou i whakarere i ahau, i tahu whakakakara hoki ki nga atua ke, hei whakapataritari i ahau ki nga mahi katoa a o ratou ringa; koia toku riri ka ringihia ai ki tenei wahi; e kore ano e tineia.
26 Sọ fún ọba Juda, ẹni tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa ti sọ, Ọlọ́run Israẹli, sọ nípa ọ̀rọ̀ wọ́n nì tí ìwọ gbọ́.
Otiia kia penei ta koutou ki atu ki te kingi o Hura, nana nei koutou i tono mai ki te ui ki a Ihowa, Ko te kupu tenei a Ihowa, a te Atua o Iharaira, Na, nga kupu i rongo na koe,
27 Nítorí ọkàn rẹ̀ dúró, ìwọ sì rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa nígbà tí ó gbọ́ ohun tí ó sọ lórí ibí yìí àti ènìyàn rẹ, nítorí ìwọ rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú mi tí o sì fa aṣọ rẹ ya, tí o sì lọ níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ ni Olúwa wí.
Na, i te mea i ngawari tou ngakau, a kua whakaiti koe i a koe i te aroaro o te Atua, i tou rongonga ki ana kupu mo tenei wahi, mo ona tangata ano, a kua whakaiti koe i a koe ki toku aroaro, kua haehae i ou kakahu, a kua tangi ki toku aroaro; kua rongo ahau, e ai ta Ihowa,
28 Nísinsin yìí, Èmi ó kó ọ jọ pọ̀ sọ́dọ̀ àwọn baba rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kò sì ní rí gbogbo ibi tí èmi ó mú wá sórí ibí yìí àti lórí àwọn tí ń gbé ibẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú ìdáhùn rẹ̀ padà sí ọ̀dọ̀ ọba.
Nana, ka huihuia atu koe e ahau ki ou matua ka huihuia atu koe ki tou tanumanga i runga i te rangimarie; e kore ano ou kanohi e kite i nga kino katoa e kawea mai e ahau ki tenei wahi, ki nga tangata ano o konei. Na whakahokia ana e ratou te kore ro ki te kingi.
29 Nígbà náà ni ọba sì pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda jọ àti Jerusalẹmu.
Katahi te kingi ka tono tangata, a huihuia ana e ia nga kaumatua katoa o Hura, o Hiruharama.
30 Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
Na haere ana te kingi ki te whare o Ihowa, ratou ko nga tangata katoa o Hura, ko nga tangata o Hiruharama, ko nga tohunga, ko nga Riwaiti, ko te iwi katoa, te rahi, te iti. Na ka korerotia e ia ki o ratou taringa nga kupu katoa o te pukapuka o t e kawenata i kitea nei ki te whare o Ihowa.
31 Ọba sì dúró ní ipò rẹ̀ ó sì tún májẹ̀mú dá níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti ẹ̀rí rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo àyà rẹ̀ àti láti pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé yìí.
Na tu ana te kingi ki tona turanga, a whakaritea ana e ia he kawenata ki te aroaro o Ihowa, ara kia whakapaua tona ngakau, tona wairua ki te whai ki a Ihowa, ki te pupuri i ana whakahau, i ana whakaaturanga, i ana tikanga, ki te whakamana ano i nga kupu o te kawenata kua tuhituhia nei ki tenei pukapuka.
32 Nígbà náà, ó sì mú kí gbogbo ènìyàn ní Jerusalẹmu àti Benjamini dúró nínú ẹ̀rí fún ara wọn, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ṣe èyí gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú Ọlọ́run, Ọlọ́run baba ńlá wọn.
Na meinga ana e ia te hunga katoa i kitea ki Hiruharama, ki Pineamine, kia tu ki tana. Na mahi ana nga tangata o Hiruharama i nga mea o te kawenata a te Atua, a te Atua o o ratou matua.
33 Josiah sì kó gbogbo ohun ìríra kúrò nínú gbogbo ìlú tí ń ṣe ti àwọn tí ó wà ní Israẹli, ó sì mú kí gbogbo àwọn tí ó wà ní Israẹli sin Olúwa Ọlọ́run wọn gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà láyè wọn, kò yà kúrò láti máa tọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn lẹ́yìn.
I whakakahoretia ano e Hohia nga mea whakarihariha katoa o nga whenua katoa i nga tama a Iharaira; a whakamahia ana e ia nga tangata katoa i kitea ki a Iharaira, kia mahi ki a Ihowa, ki to ratou Atua. I ona ra katoa kihai i mahue i a ratou te wh ai i a Ihowa, i te Atua o o ratou matua.

< 2 Chronicles 34 >