< 2 Chronicles 34 >
1 Josiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì dí ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
Nyolcz esztendős vala Jósiás, mikor uralkodni kezdett volt, és uralkodott harminczegy esztendeig Jeruzsálemben.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa, ó sì rìn ọ̀nà baba rẹ̀ Dafidi, kò sì yà sí ọwọ́ ọ̀tún tàbí òsì.
És jó dolgot cselekedék az Úr előtt, és jára az ő atyjának Dávidnak útjain, és nem hajolt el sem jobbra, sem balra;
3 Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀, nígbà tí ó sì wà ní ọ̀dọ́mọdé, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wá ojú Ọlọ́run baba Dafidi. Ní ọdún kejìlá. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fọ Juda àti Jerusalẹmu mọ́ kúrò ní ibi gíga rẹ̀, ère òrìṣà Aṣerah, àti ère yíyá àti ère dídà.
Mert az ő királyságának nyolczadik esztendejében, mikor még gyermek volna, kezdé keresni az ő atyjának Dávidnak Istenét; tizenkettedik esztendejében pedig Júdát és Jeruzsálemet kezdé megtisztítani a magaslatoktól, Aseráktól, bálványoktól és öntött képektől.
4 Lábẹ́ àpẹẹrẹ àwọn pẹpẹ Baali ni a yí lulẹ̀, ó sì fọ́ àwọn ère sí wẹ́wẹ́, ó run àwọn pẹpẹ tí ó wà lórí rẹ̀, wọ́n sì fọ́ túútúú, àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Èyí tí ó fọ́ wọn sì lúúlúú, ó sì gbọ̀n wọ́n sí orí isà òkú àti àwọn tí ó ń rú ẹbọ sí wọn.
Leronták ő előtte a Baálok oltárait és az azokon levő szobrokat lehányatá; az Aserákot is a bálványokkal és öntött képekkel egyetembe szétrombolá és apróra töreté, és elhinteté azoknak temetőhelyén, a kik azoknak áldoztak vala.
5 Ó sì sun àwọn egungun àwọn àlùfáà lórí pẹpẹ wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni ó sì wẹ Juda àti Jerusalẹmu mọ́.
A papok csontjait megégeté azoknak oltárain, és megtisztítá Júdát és Jeruzsálemet.
6 Ní ìlú Manase, Efraimu àti Simeoni, àní títí ó fi dé Naftali, àti nínú àwọn, ó tú ilé wọn yíkákiri.
Így cselekedék Manassénak, Efraimnak és Simeonnak városaiban is, mind Nafthaliig, azoknak pusztáiban köröskörül.
7 Ó sì wó pẹpẹ àti ère Aṣerah lulẹ̀ àti àwọn ère yíyá àti àwọn òrìṣà, ó sì gùn ó sì ti ké gbogbo àwọn ère orí pẹpẹ lulẹ̀ ní gbogbo àyíká Israẹli. Lẹ́yìn náà ó padà sí Jerusalẹmu.
Lehányatá azért az oltárokat; az Aserákat és a bálványokat összetördelé mind porrá, és minden naposzlopot elpusztított Izráel egész földén; azután megtére Jeruzsálembe.
8 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Josiah ni a ti wẹ ilẹ̀ náà mọ́ àti ilé Olúwa, ó sì rán Ṣafani ọmọ Asalia àti Maaseiah olórí ìlú náà, pẹ̀lú Joah, ọmọ Joahasi, akọ̀wé, láti tún ilé Olúwa Ọlọ́run ṣe.
Királyságának tizennyolczadik esztendejében pedig, minekutána a földet és a házat megtisztítá, elküldé Sáfánt az Asália fiát, és Maaséját a város előljáróját, és Joát a Joákház fiát, az emlékírót, hogy kijavíttatnák az Úrnak, az ő Istenének házát.
9 Wọ́n sì lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, ó sì fún un ní owó náà tí ó mú wá sí inú ilé Ọlọ́run, ti àwọn ọmọ Lefi ẹni tí ó jẹ́ aṣọ́bodè ti gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn Manase Efraimu àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ìyókù Israẹli àti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn Juda àti Benjamini wọ́n sì padà sí Jerusalẹmu.
És menének Hilkiás főpaphoz, és átadták néki az Isten házába begyült pénzt, a melyet a Léviták, az ajtónállók gyűjtöttek Manassétól, Efraimtól és az egész Izráel maradékaitól, és egész Júdától és Benjámintól, és Jeruzsálem lakóitól.
10 Nígbà náà ni wọn sì fi le àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ilé lọ́wọ́, àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ ilé Olúwa. Àwọn ọkùnrin yìí sì san owó fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń túnṣe, tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ní ilé Olúwa.
És adák a munkavezetőknek, a kik felvigyáztak az Úr házában, hogy adják azt a munkásoknak, a kik dolgoztak az Úr házában, hogy kijavítsák és helyreállítsák a házat.
11 Wọ́n sì tún fi owó fún àwọn oníṣọ̀nà àti àwọn olùkọ́lé láti ra òkúta gbígbẹ́ àti ìtì igi fún ìsopọ̀ àti igi rírẹ́ fún ìkọ́lé tí ọba Juda ti gbà láti túnṣe.
És adának pénzt az ácsoknak és a kőműveseknek, hogy vegyenek faragott köveket, és fákat a kapcsolásokra, és a házak gerendázására, a melyeket elrontottak a Júda királyai.
12 Àwọn ọkùnrin náà ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú òtítọ́, láti darí wọn ní Jahati àti Obadiah, àwọn ọmọ Lefi láti Merari, àti Sekariah àti Meṣullamu, sọ̀kalẹ̀ láti Kohati àwọn ọmọ Lefi gbogbo tí ó ní ọgbọ̀n ohun èlò orin.
És az emberek hűségesen végzik vala a munkát; a kikre felügyelének Jáhát és Obádia Léviták, a Mérári fiai közül valók; és Zakariás, Mésullám, a Kéhátiták fiai közül valók, a kik szorgalmazzák vala őket. E Léviták pedig mindnyájan mesterek valának az éneklőszerszámokban.
13 Wọ́n sì ní olórí àwọn aláàárù àti àwọn alábojútó gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ láti ibi iṣẹ́ sí ibi iṣẹ́, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Lefi sì ní akọ̀wé, olùtọ́jú àti olùṣọ́nà.
A teherhordókat pedig (mert voltak felügyelők a munkások felett mindenféle dologban) szorgalmazák a Léviták közül való íródeákok, igazgatók és ajtónállók.
14 Nígbà tí wọ́n mú owó náà tí wọ́n mú wá sí ilé Olúwa, Hilkiah àlùfáà sì rí ìwé òfin Olúwa tí a ti fi fún un láti ọwọ́ Mose.
Mikor pedig kihozák azok a pénzt, a mely az Úr házában gyűlt össze: megtalálá Hilkia pap az Úr törvénykönyvét, a melyet Mózes által adott volt.
15 Hilkiah sì wí fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi ti rí ìwé òfin nínú ilé Olúwa.” Ó sì fi fún Ṣafani.
Szóla pedig Hilkia, és monda Sáfánnak, az íródeáknak: A törvénykönyvet megtalálám az Úr házában. És adá Hilkia a könyvet Sáfánnak.
16 Nígbà náà Ṣafani sì mú ìwé náà lọ sí ọ̀dọ̀ ọba ó sì ròyìn fún un. “Àwọn ìjòyè rẹ̀ ń ṣe gbogbo nǹkan tí a ti fi lé wọn lọ́wọ́.
És vivé Sáfán a könyvet a királyhoz, és elbeszélé néki a dolgot, mondván: Valamit bíztál a te szolgáidra, abban híven eljárnak;
17 Wọ́n ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa wọ́n sì ti fi lé àwọn alábojútó lọ́wọ́ àti àwọn òṣìṣẹ́.”
Mert az Úr házában talált pénzt összeszedvén, adák a felügyelőknek és munkásoknak kezébe.
18 Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sì sọ fún ọba, “Hilkiah àlùfáà ti fún mi ní ìwé.” Ṣafani sì kà níwájú ọba.
Továbbá jelenté Sáfán íródeák a királynak, mondván: Hilkia pap nékem egy könyvet ada; és olvasott abból Sáfán a király előtt.
19 Nígbà tí ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
Mikor pedig a király hallotta a törvény beszédit, ruháit megszaggatá.
20 Ó sì pa àṣẹ yìí fún Hilkiah, Ahikamu ọmọ Ṣafani, Abdoni ọmọ Mika, Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
És parancsola a király Hilkia papnak és Ahikámnak a Sáfán fiának, Abdonnak a Mika fiának, és az íródeáknak Sáfánnak, és Asájának a király szolgájának, mondván:
21 “Ẹ lọ kí ẹ lọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi nípa àwọn ìyókù Israẹli àti Juda nípa ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ti jáde sí orí wa nítorí àwọn baba wa kò ti pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́, wọn kò sì tí ì ṣe gẹ́gẹ́ bí i gbogbo èyí tí a kọ sínú ìwé yìí.”
Menjetek el, és keressétek meg az Urat én érettem, s az Izráel és Júda maradékaiért, a könyv beszédei felől, a mely megtaláltatott, mert nagy az Úr haragja, a mely mi reánk szállott azért, hogy a mi atyáink nem tartották meg az Úrnak beszédét, hogy mind a szerint cselekedtek volna, a mint e könyvben megíratott.
22 Hilkiah àti àwọn ènìyàn tí ọba yàn tọ Hulda wòlíì obìnrin láti ba sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tokhati tí a tún ń pè ní Tikfa, ọmọ Harhasi, olùtọ́jú ibi ìkáṣọsí. Ó sì ń gbé ní Jerusalẹmu, ní ìhà kejì.
Elméne azért Hilkia és a király embere Húlda prófétaasszonyhoz, a Sallum feleségéhez, a ki Thókéhát fia vala, a ki Hasrának, a ruhák gondviselőjének fia vala (ő pedig Jeruzsálemben, a második utczában lakik vala) és a szerint szólának néki.
23 Ó sì wí fún wọn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ti sọ, sọ fún àwọn ọkùnrin tí ó rán ọ sí mi pé,
Ki monda nékik: Így szól az Úr, Izráel Istene: Mondjátok meg a férfinak, a ki titeket hozzám küldött;
24 ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi yóò sì mú ibi wá sí ìhín yìí àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gbogbo àní ègún tí a kọ sínú ìwé tí wọ́n ti kà níwájú ọba Juda.”
Ezt mondja az Úr: Ímé én veszedelmet hozok e helyre és ennek lakosira, mindazokat az átkokat, a melyek meg vannak írva a könyvben, a melyet felolvastak a Júda királya előtt;
25 Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀ wọ́n sì ti sun tùràrí sí ọlọ́run mìíràn wọ́n sì ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn ṣe, ìbínú yóò tú jáde wá sórí ibí yìí, a kì yóò sì paná rẹ̀.’
Mivel elhagytak engem, és idegen isteneknek tömjéneztek, hogy engem haragra gerjeszszenek az ő kezeiknek minden cselekedetei által. Felgerjedt az én haragom e hely ellen, és el sem oltatik.
26 Sọ fún ọba Juda, ẹni tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa ti sọ, Ọlọ́run Israẹli, sọ nípa ọ̀rọ̀ wọ́n nì tí ìwọ gbọ́.
A Júda királyának pedig, a ki titeket küldött, hogy az Urat megkérdjétek, így szóljatok: Így szól az Úr, Izráel Istene: A mi a beszédeket illeti, a melyeket hallottál:
27 Nítorí ọkàn rẹ̀ dúró, ìwọ sì rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa nígbà tí ó gbọ́ ohun tí ó sọ lórí ibí yìí àti ènìyàn rẹ, nítorí ìwọ rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú mi tí o sì fa aṣọ rẹ ya, tí o sì lọ níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ ni Olúwa wí.
Mivel a te szíved meglágyult, és magadat megaláztad az Isten előtt, mikor hallád az ő beszédeit e hely ellen és az ő lakosai ellen; mivel magadat megaláztad előttem, és ruháidat megszaggattad és sírtál előttem: én is meghallgattalak, ezt mondja az Úr.
28 Nísinsin yìí, Èmi ó kó ọ jọ pọ̀ sọ́dọ̀ àwọn baba rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kò sì ní rí gbogbo ibi tí èmi ó mú wá sórí ibí yìí àti lórí àwọn tí ń gbé ibẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú ìdáhùn rẹ̀ padà sí ọ̀dọ̀ ọba.
Ímé én téged a te atyáid közé takarítlak, és tétetel a te sírodba békességben, és nem látják a te szemeid azt a veszedelmet, a melyet én hozok e helyre és ennek lakóira. És e szerint beszélték el ezt a királynak.
29 Nígbà náà ni ọba sì pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda jọ àti Jerusalẹmu.
Akkor a király elkülde, és összegyűjteté Júdának és Jeruzsálemnek minden véneit.
30 Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
És felméne a király az Úr házába, és ő vele Júdának minden férfiai, és Jeruzsálem lakosai, a papok, a Léviták és az egész nép kicsinytől fogva nagyig, és elolvasá fülök hallására a szövetség könyvének minden beszédeit, a melyet találtak vala az Úr házában.
31 Ọba sì dúró ní ipò rẹ̀ ó sì tún májẹ̀mú dá níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti ẹ̀rí rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo àyà rẹ̀ àti láti pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé yìí.
Azután felállván a király az ő helyén, fogadást tőn az Úr előtt, hogy ő az Urat követendi, és hogy parancsolatait, bizonyságtételeit és rendeléseit teljes szívéből és teljes lelkéből megőrzendi, cselekedvén a szövetség beszédeit, a melyek megirattak abban a könyvben.
32 Nígbà náà, ó sì mú kí gbogbo ènìyàn ní Jerusalẹmu àti Benjamini dúró nínú ẹ̀rí fún ara wọn, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ṣe èyí gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú Ọlọ́run, Ọlọ́run baba ńlá wọn.
És felfogadtatá e dolgot mindazokkal, a kik Jeruzsálemből és Benjáminból valók. És Jeruzsálem lakói az Istennek, az ő atyáik Istenének szövetsége szerint cselekedének.
33 Josiah sì kó gbogbo ohun ìríra kúrò nínú gbogbo ìlú tí ń ṣe ti àwọn tí ó wà ní Israẹli, ó sì mú kí gbogbo àwọn tí ó wà ní Israẹli sin Olúwa Ọlọ́run wọn gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà láyè wọn, kò yà kúrò láti máa tọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn lẹ́yìn.
Akkor elpusztított Jósiás minden útálatos bálványt Izráel fiainak egész földjéről, és kényszeríte mindenkit, valaki találtatik vala Izráelben, hogy szolgáljon az Úrnak, az ő Istenöknek; és az ő egész életében nem szakadának el az Úrtól, atyáik Istenétől.