< 2 Chronicles 34 >
1 Josiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì dí ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
Josias avait huit ans quand il monta sur le trône, et il régna trente et un ans à Jérusalem.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa, ó sì rìn ọ̀nà baba rẹ̀ Dafidi, kò sì yà sí ọwọ́ ọ̀tún tàbí òsì.
Il fit ce que est droit devant le Seigneur, et il marcha dans les voies de David, son aïeul; il ne s'en écarta ni à droite ni à gauche.
3 Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀, nígbà tí ó sì wà ní ọ̀dọ́mọdé, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wá ojú Ọlọ́run baba Dafidi. Ní ọdún kejìlá. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fọ Juda àti Jerusalẹmu mọ́ kúrò ní ibi gíga rẹ̀, ère òrìṣà Aṣerah, àti ère yíyá àti ère dídà.
Et, dans la huitième année de son règne, il était encore un adolescent quand il commença à chercher le Seigneur Dieu de David; et, dans la douzième année, il se mit à purifier Juda et Jérusalem des hauts lieux, des bois sacrés, des ornements des autels et des idoles jetées en fonte.
4 Lábẹ́ àpẹẹrẹ àwọn pẹpẹ Baali ni a yí lulẹ̀, ó sì fọ́ àwọn ère sí wẹ́wẹ́, ó run àwọn pẹpẹ tí ó wà lórí rẹ̀, wọ́n sì fọ́ túútúú, àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Èyí tí ó fọ́ wọn sì lúúlúú, ó sì gbọ̀n wọ́n sí orí isà òkú àti àwọn tí ó ń rú ẹbọ sí wọn.
Et il renversa, de devant sa face, les autels de Baal et, au-dessus d'eux, les hauts lieux; il abattit les bois sacrés et les statues; il brisa les idoles jetées en fonte, il les réduisit en poudre, et les jeta sur la surface des tombeaux de ceux qui leur avaient sacrifié.
5 Ó sì sun àwọn egungun àwọn àlùfáà lórí pẹpẹ wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni ó sì wẹ Juda àti Jerusalẹmu mọ́.
Et il brûla les ossements de leurs prêtres sur les autels; et il purifia Jérusalem et Juda,
6 Ní ìlú Manase, Efraimu àti Simeoni, àní títí ó fi dé Naftali, àti nínú àwọn, ó tú ilé wọn yíkákiri.
Puis, les villes de Manassé, d'Ephraïm, de Siméon et de Nephthali, et les bourgs qui les environnaient.
7 Ó sì wó pẹpẹ àti ère Aṣerah lulẹ̀ àti àwọn ère yíyá àti àwọn òrìṣà, ó sì gùn ó sì ti ké gbogbo àwọn ère orí pẹpẹ lulẹ̀ ní gbogbo àyíká Israẹli. Lẹ́yìn náà ó padà sí Jerusalẹmu.
Et il détruisit les autels et les bois sacrés, et il réduisit en poudre les idoles, et il renversa tous les hauts lieux d'Israël, et il revint à Jérusalem.
8 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Josiah ni a ti wẹ ilẹ̀ náà mọ́ àti ilé Olúwa, ó sì rán Ṣafani ọmọ Asalia àti Maaseiah olórí ìlú náà, pẹ̀lú Joah, ọmọ Joahasi, akọ̀wé, láti tún ilé Olúwa Ọlọ́run ṣe.
Dans la dix-huitième année de son règne, après avoir purifié la terre et son palais, il envoya Saphan, fils d'Ezélias, Maasa, chef de la ville, et Juach, fils de Joachaz, son secrétaire-archiviste, pour réparer le temple du Seigneur son Dieu.
9 Wọ́n sì lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, ó sì fún un ní owó náà tí ó mú wá sí inú ilé Ọlọ́run, ti àwọn ọmọ Lefi ẹni tí ó jẹ́ aṣọ́bodè ti gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn Manase Efraimu àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ìyókù Israẹli àti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn Juda àti Benjamini wọ́n sì padà sí Jerusalẹmu.
Il se rendirent auprès d'Helcias, le grand prêtre, et ils lui donnèrent l'argent offert au temple de Dieu, recueilli, par les lévites gardiens de la porte, des mains de Manassé, d'Ephraïm, des princes, de tout le reste d'Israël, des fils de Juda et de Benjamin, et des habitants de Jérusalem.
10 Nígbà náà ni wọn sì fi le àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ilé lọ́wọ́, àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ ilé Olúwa. Àwọn ọkùnrin yìí sì san owó fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń túnṣe, tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ní ilé Olúwa.
Et ils donnèrent cet argent à ceux qui faisaient les travaux, qu'on avait établis dans le temple du Seigneur; ils le donnèrent à ceux qui faisaient ce qu'il y avait à faire pour restaurer et raffermir le temple.
11 Wọ́n sì tún fi owó fún àwọn oníṣọ̀nà àti àwọn olùkọ́lé láti ra òkúta gbígbẹ́ àti ìtì igi fún ìsopọ̀ àti igi rírẹ́ fún ìkọ́lé tí ọba Juda ti gbà láti túnṣe.
Ils ordonnèrent aussi aux charpentiers et aux maçons d'acheter des pierres de taille et des solives pour recouvrir les logements que les rois de Juda avaient abattus.
12 Àwọn ọkùnrin náà ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú òtítọ́, láti darí wọn ní Jahati àti Obadiah, àwọn ọmọ Lefi láti Merari, àti Sekariah àti Meṣullamu, sọ̀kalẹ̀ láti Kohati àwọn ọmọ Lefi gbogbo tí ó ní ọgbọ̀n ohun èlò orin.
Et ces hommes se mirent fidèlement à l'œuvre, et ils furent surveillés par Jeth et Abdias, lévites de la maison de Mérari, par Zacharie et Mosollam, des fils de Caath, et par tous les lévites qui savaient chanter et jouer des instruments,
13 Wọ́n sì ní olórí àwọn aláàárù àti àwọn alábojútó gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ láti ibi iṣẹ́ sí ibi iṣẹ́, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Lefi sì ní akọ̀wé, olùtọ́jú àti olùṣọ́nà.
Et les manœuvres et les ouvriers, chacun en son travail, étaient encore surveillés par les lévites scribes, juges et portiers.
14 Nígbà tí wọ́n mú owó náà tí wọ́n mú wá sí ilé Olúwa, Hilkiah àlùfáà sì rí ìwé òfin Olúwa tí a ti fi fún un láti ọwọ́ Mose.
Or, tandis que l'on transportait l'argent donné pour le temple du Seigneur, Helcias, le prêtre, trouva un livre de la loi du Seigneur donnée par Moïse.
15 Hilkiah sì wí fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi ti rí ìwé òfin nínú ilé Olúwa.” Ó sì fi fún Ṣafani.
Et Helcias prit la parole, et il dit à Saphan, le scribe: J'ai trouvé dans le temple du Seigneur un livre de la loi. Et Helcias donna le livre à Saphan.
16 Nígbà náà Ṣafani sì mú ìwé náà lọ sí ọ̀dọ̀ ọba ó sì ròyìn fún un. “Àwọn ìjòyè rẹ̀ ń ṣe gbogbo nǹkan tí a ti fi lé wọn lọ́wọ́.
Et Saphan porta le livre au roi, et il lui rendit compte, disant: Voici le compte de tout l'argent qui a été remis à tes serviteurs chargés des travaux.
17 Wọ́n ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa wọ́n sì ti fi lé àwọn alábojútó lọ́wọ́ àti àwọn òṣìṣẹ́.”
Or, cet argent, trouvé dans le temple du Seigneur, avait été monnayé et distribué aux surveillants, puis aux ouvriers.
18 Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sì sọ fún ọba, “Hilkiah àlùfáà ti fún mi ní ìwé.” Ṣafani sì kà níwájú ọba.
Et Saphan en rendit compte au roi, et il ajouta: Helcias m'a donné un livre. Et Saphan le lut devant le roi.
19 Nígbà tí ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
Et quand Josias ouït les paroles du livre de la loi, il déchira ses vêtements.
20 Ó sì pa àṣẹ yìí fún Hilkiah, Ahikamu ọmọ Ṣafani, Abdoni ọmọ Mika, Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
Et il donna ses ordres à Helcias, à Achicam, fils de Saphan, à Abdom, fils de Michée, à Saphan, le scribe, à Asaïe, serviteur du roi, et il leur dit:
21 “Ẹ lọ kí ẹ lọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi nípa àwọn ìyókù Israẹli àti Juda nípa ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ti jáde sí orí wa nítorí àwọn baba wa kò ti pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́, wọn kò sì tí ì ṣe gẹ́gẹ́ bí i gbogbo èyí tí a kọ sínú ìwé yìí.”
Allez et interrogez le Seigneur, pour moi et pour tout ce qui reste de Juda et d'Israël, au sujet des paroles du livre qui a été trouvé; car la colère du Seigneur s'est enflammée contre nous, parce que nos pères n'ont point obéi aux commandements du Seigneur, et n'ont point fait ce qui est écrit en ce livre.
22 Hilkiah àti àwọn ènìyàn tí ọba yàn tọ Hulda wòlíì obìnrin láti ba sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tokhati tí a tún ń pè ní Tikfa, ọmọ Harhasi, olùtọ́jú ibi ìkáṣọsí. Ó sì ń gbé ní Jerusalẹmu, ní ìhà kejì.
Or, Helcias et ceux à qui avait parlé le roi, allèrent trouver Olda, la prophétesse, femme de Sellem, file de Thécoé, fils d'Aras; elle observait les commandements, et demeurait à Jérusalem dans le second quartier, et ils lui parlèrent relativement à ces choses.
23 Ó sì wí fún wọn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ti sọ, sọ fún àwọn ọkùnrin tí ó rán ọ sí mi pé,
Et elle leur répondit: Voici ce que dit le Seigneur Dieu d'Israël; dites à l'homme qui vous a envoyés chez moi:
24 ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi yóò sì mú ibi wá sí ìhín yìí àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gbogbo àní ègún tí a kọ sínú ìwé tí wọ́n ti kà níwájú ọba Juda.”
Voici ce que dit le Seigneur: Voilà que j'amène le mal sur ce lieu,' selon les paroles du livre qui a été lu devant le roi de Juda,
25 Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀ wọ́n sì ti sun tùràrí sí ọlọ́run mìíràn wọ́n sì ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn ṣe, ìbínú yóò tú jáde wá sórí ibí yìí, a kì yóò sì paná rẹ̀.’
En punition de ce qu'ils m'ont abandonné, de ce qu'ils ont brûlé de l'encens pour d'autres dieux, afin de m'irriter, par toutes les œuvres de leurs mains; car ma colère s'est enflammée contre ce lieu, et elle ne s'éteindra pas.
26 Sọ fún ọba Juda, ẹni tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa ti sọ, Ọlọ́run Israẹli, sọ nípa ọ̀rọ̀ wọ́n nì tí ìwọ gbọ́.
Quant au roi de Juda qui vous a envoyés chez moi, pour interroger le Seigneur, dites-lui: Voici ce que dit le Seigneur Dieu d'Israël: Aux paroles que tu as entendues,
27 Nítorí ọkàn rẹ̀ dúró, ìwọ sì rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa nígbà tí ó gbọ́ ohun tí ó sọ lórí ibí yìí àti ènìyàn rẹ, nítorí ìwọ rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú mi tí o sì fa aṣọ rẹ ya, tí o sì lọ níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ ni Olúwa wí.
Ton cœur a été rempli de crainte; tu t'es humilié devant moi, lorsque tu as ouï mes menaces contre ce lieu et contre ceux qui l'habitent; tu t'es humilié devant moi; tu as déchiré tes vêtements; tu as pleuré devant moi, et moi aussi j'ai entendu, dit le Seigneur.
28 Nísinsin yìí, Èmi ó kó ọ jọ pọ̀ sọ́dọ̀ àwọn baba rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kò sì ní rí gbogbo ibi tí èmi ó mú wá sórí ibí yìí àti lórí àwọn tí ń gbé ibẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú ìdáhùn rẹ̀ padà sí ọ̀dọ̀ ọba.
Voilà que je te réunis à tes pères; tu seras déposé en paix dans ton sépulcre, et tes yeux ne verront aucun des maux que j'amène sur ce lieu et sur ceux qui l'habitent. Et ils rapportèrent au roi ces paroles.
29 Nígbà náà ni ọba sì pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda jọ àti Jerusalẹmu.
Et le roi envoya des messagers, et il rassembla les anciens de Juda et de Jérusalem.
30 Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
Et le roi monta au temple du Seigneur, avec tout Juda, tous les habitants de Jérusalem, les prêtres, les lévites et le peuple entier, depuis le petit jusqu'au grand, et il lut à leurs oreilles toutes les paroles du livre de l'alliance, trouvé dans le temple du Seigneur.
31 Ọba sì dúró ní ipò rẹ̀ ó sì tún májẹ̀mú dá níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti ẹ̀rí rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo àyà rẹ̀ àti láti pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé yìí.
Et le roi se tint debout sur le piédestal, et il fit une alliance devant le Seigneur, pour marcher devant le Seigneur, garder ses commandements, ses témoignages et ses ordonnances, de tout son cœur et de toute son âme, afin de se conformer à toutes les paroles de l'alliance écrites en ce livre.
32 Nígbà náà, ó sì mú kí gbogbo ènìyàn ní Jerusalẹmu àti Benjamini dúró nínú ẹ̀rí fún ara wọn, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ṣe èyí gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú Ọlọ́run, Ọlọ́run baba ńlá wọn.
Et il fit lever tous ceux qui se trouvaient en Jérusalem; et Benjamin, et les habitants de Jérusalem firent une alliance dans le temple du Seigneur Dieu de leurs pères.
33 Josiah sì kó gbogbo ohun ìríra kúrò nínú gbogbo ìlú tí ń ṣe ti àwọn tí ó wà ní Israẹli, ó sì mú kí gbogbo àwọn tí ó wà ní Israẹli sin Olúwa Ọlọ́run wọn gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà láyè wọn, kò yà kúrò láti máa tọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn lẹ́yìn.
Et Josias expulsa toutes les abominations de toute la terre des fils d'Israël, et il obligea tous ceux qui se trouvaient dans la ville et en Israël à servir, tous les jours de sa vie, le Seigneur leur Dieu; et il ne se détourna point du Seigneur Dieu de ses pères.