< 2 Chronicles 34 >

1 Josiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì dí ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
Josie was of eiyte yeer, whanne he bigan to regne, and he regnede in Jerusalem oon and thritti yeer.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa, ó sì rìn ọ̀nà baba rẹ̀ Dafidi, kò sì yà sí ọwọ́ ọ̀tún tàbí òsì.
And he dide that, that was riytful in the siyt of the Lord; and yede in the waies of Dauid, his fadir, and bowide not to the riyt side nether to the left side.
3 Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀, nígbà tí ó sì wà ní ọ̀dọ́mọdé, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wá ojú Ọlọ́run baba Dafidi. Ní ọdún kejìlá. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fọ Juda àti Jerusalẹmu mọ́ kúrò ní ibi gíga rẹ̀, ère òrìṣà Aṣerah, àti ère yíyá àti ère dídà.
Forsothe in the eiytethe yeer of the rewme of his empire, whanne he was yit a child, he bigan to seke God of his fadir Dauid; and in the tweluethe yeer after that he bigan, he clenside Juda and Jerusalem fro hiy places, and wodis, and similacris, and grauun ymagis.
4 Lábẹ́ àpẹẹrẹ àwọn pẹpẹ Baali ni a yí lulẹ̀, ó sì fọ́ àwọn ère sí wẹ́wẹ́, ó run àwọn pẹpẹ tí ó wà lórí rẹ̀, wọ́n sì fọ́ túútúú, àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Èyí tí ó fọ́ wọn sì lúúlúú, ó sì gbọ̀n wọ́n sí orí isà òkú àti àwọn tí ó ń rú ẹbọ sí wọn.
And thei destrieden bifor hym the auteris of Baalym, and thei destrieden the symylacris, that weren put aboue. Also he hewide doun the wodis, and grauun ymagis, and brak to smale gobetis; and scateride abrood `the smale gobetis on the birielis of hem, that weren wont to offre `to tho.
5 Ó sì sun àwọn egungun àwọn àlùfáà lórí pẹpẹ wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni ó sì wẹ Juda àti Jerusalẹmu mọ́.
Ferthermore he brente the boonys of preestis in the auteris of idols, and he clenside Juda and Jerusalem.
6 Ní ìlú Manase, Efraimu àti Simeoni, àní títí ó fi dé Naftali, àti nínú àwọn, ó tú ilé wọn yíkákiri.
But also he destriede alle idols in the citees of Manasses, and of Effraym, and of Symeon, `til to Neptalym.
7 Ó sì wó pẹpẹ àti ère Aṣerah lulẹ̀ àti àwọn ère yíyá àti àwọn òrìṣà, ó sì gùn ó sì ti ké gbogbo àwọn ère orí pẹpẹ lulẹ̀ ní gbogbo àyíká Israẹli. Lẹ́yìn náà ó padà sí Jerusalẹmu.
And whanne he hadde scateride the auteris, and hadde al to-broke in to gobetis the wodis, and grauun ymagis, and hadde destried alle templis of ydols fro al the lond of Israel, he turnede ayen in to Jerusalem.
8 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Josiah ni a ti wẹ ilẹ̀ náà mọ́ àti ilé Olúwa, ó sì rán Ṣafani ọmọ Asalia àti Maaseiah olórí ìlú náà, pẹ̀lú Joah, ọmọ Joahasi, akọ̀wé, láti tún ilé Olúwa Ọlọ́run ṣe.
Therfor in the eiytenthe yeer of his rewme, whanne the lond and temple `of the Lord was clensid nowe, he sente Saphan, the sone of Helchie, and Masie, the prince of the citee, and Joa, the sone of Joachaz, chaunceler, that thei schulden reparele the hous `of his Lord God.
9 Wọ́n sì lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, ó sì fún un ní owó náà tí ó mú wá sí inú ilé Ọlọ́run, ti àwọn ọmọ Lefi ẹni tí ó jẹ́ aṣọ́bodè ti gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn Manase Efraimu àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ìyókù Israẹli àti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn Juda àti Benjamini wọ́n sì padà sí Jerusalẹmu.
Whiche camen to Helchie, the grete preest; and whanne thei hadden take of hym the money, which was brouyt in to the hows of the Lord; and which monei the dekenes and porteris hadden gaderid of Manasses, and of Effraym, and of alle the residue men of Israel, and of al Juda and Beniamyn, and of the dwelleris of Jerusalem,
10 Nígbà náà ni wọn sì fi le àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ilé lọ́wọ́, àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ ilé Olúwa. Àwọn ọkùnrin yìí sì san owó fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń túnṣe, tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ní ilé Olúwa.
thei yauen it in the hondis of hem that weren souereyns of the werk men in the hows of the Lord, that thei schulden restore the temple, and reparele alle feble thingis.
11 Wọ́n sì tún fi owó fún àwọn oníṣọ̀nà àti àwọn olùkọ́lé láti ra òkúta gbígbẹ́ àti ìtì igi fún ìsopọ̀ àti igi rírẹ́ fún ìkọ́lé tí ọba Juda ti gbà láti túnṣe.
And thei yauen that monei to the crafti men and masouns, for to bie stoonys hewid out of the `delues, ether quarreris, and trees to the ioynyngis of the bildyng, and to the coupling of housis, whiche the kingis of Juda hadden destried.
12 Àwọn ọkùnrin náà ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú òtítọ́, láti darí wọn ní Jahati àti Obadiah, àwọn ọmọ Lefi láti Merari, àti Sekariah àti Meṣullamu, sọ̀kalẹ̀ láti Kohati àwọn ọmọ Lefi gbogbo tí ó ní ọgbọ̀n ohun èlò orin.
Whiche men diden feithfuli alle thingis. Sotheli the souereyns of worcheris weren Jabath, and Abdie, of the sones of Merari; Zacarie, and Mosallam, of the sones of Caath; whiche hastiden the werk; alle weren dekenes, kunnynge to synge with orguns.
13 Wọ́n sì ní olórí àwọn aláàárù àti àwọn alábojútó gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ láti ibi iṣẹ́ sí ibi iṣẹ́, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Lefi sì ní akọ̀wé, olùtọ́jú àti olùṣọ́nà.
Sotheli ouer them that baren birthuns to dyuerse vsis weren the scribis, and maistris of the dekenes, and porteris.
14 Nígbà tí wọ́n mú owó náà tí wọ́n mú wá sí ilé Olúwa, Hilkiah àlùfáà sì rí ìwé òfin Olúwa tí a ti fi fún un láti ọwọ́ Mose.
And whanne thei baren out the monei, that was borun in to the temple of the Lord, Helchie, `the preest, foond the book of the lawe of the Lord bi the hond of Moises.
15 Hilkiah sì wí fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi ti rí ìwé òfin nínú ilé Olúwa.” Ó sì fi fún Ṣafani.
And he seide to Saphan, the writere, Y haue founde the book of the lawe in the hows of the Lord.
16 Nígbà náà Ṣafani sì mú ìwé náà lọ sí ọ̀dọ̀ ọba ó sì ròyìn fún un. “Àwọn ìjòyè rẹ̀ ń ṣe gbogbo nǹkan tí a ti fi lé wọn lọ́wọ́.
And Helchie took to Saphan, and he bar in the book to the king; and telde to hym, and seide, Lo! alle thingis ben fillid, whiche thou hast youe in to the hondis of thi seruauntis.
17 Wọ́n ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa wọ́n sì ti fi lé àwọn alábojútó lọ́wọ́ àti àwọn òṣìṣẹ́.”
Thei han wellyd togidere the siluere, which is foundun in the hous of the Lord; and it is youun to the souereyns of the crafti men, and makynge dyuerse werkis;
18 Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sì sọ fún ọba, “Hilkiah àlùfáà ti fún mi ní ìwé.” Ṣafani sì kà níwájú ọba.
ferthermore Helchie, the preest, took to me this book. And whanne he hadde rehersid this book in the presence of the kyng,
19 Nígbà tí ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
and he hadde herd the wordis of the lawe, he to-rente hise clothis; and he comaundide to Helchie,
20 Ó sì pa àṣẹ yìí fún Hilkiah, Ahikamu ọmọ Ṣafani, Abdoni ọmọ Mika, Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
and to Aichan, the sone of Saphan, and to Abdon, the sone of Mycha, and to Saphan, the scryuen, and to Asaie, the seruaunt of the kyng,
21 “Ẹ lọ kí ẹ lọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi nípa àwọn ìyókù Israẹli àti Juda nípa ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ti jáde sí orí wa nítorí àwọn baba wa kò ti pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́, wọn kò sì tí ì ṣe gẹ́gẹ́ bí i gbogbo èyí tí a kọ sínú ìwé yìí.”
and seide, Go ye, and preie the Lord for me, and for the resydue men of Israel and of Juda, on alle the wordis of this book, which is foundun. For greet veniaunce of the Lord hath droppid on vs, for oure fadris kepten not the wordis of the Lord, to do alle thingis that ben writun in this book.
22 Hilkiah àti àwọn ènìyàn tí ọba yàn tọ Hulda wòlíì obìnrin láti ba sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tokhati tí a tún ń pè ní Tikfa, ọmọ Harhasi, olùtọ́jú ibi ìkáṣọsí. Ó sì ń gbé ní Jerusalẹmu, ní ìhà kejì.
Therfor Helchie yede, and thei that weren sent togidere of the king, to Olda, the prophetesse, the wijf of Sellum, sone of Thecuath, sone of Asra, kepere of clothis, which Olda dwellide in Jerusalem in the secounde warde; and thei spaken to hir the wordis, whiche we telden bifore.
23 Ó sì wí fún wọn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ti sọ, sọ fún àwọn ọkùnrin tí ó rán ọ sí mi pé,
And sche answeride to hem, The Lord God of Israel seith these thingis, Seie ye to the man, that sente you to me,
24 ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi yóò sì mú ibi wá sí ìhín yìí àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gbogbo àní ègún tí a kọ sínú ìwé tí wọ́n ti kà níwájú ọba Juda.”
The Lord seith these thingis, Lo! Y schal brynge ynne yuels on this place, and on the dwelleris therof, and alle the cursyngis that ben writun in this book, which thei redden bifor the kyng of Juda.
25 Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀ wọ́n sì ti sun tùràrí sí ọlọ́run mìíràn wọ́n sì ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn ṣe, ìbínú yóò tú jáde wá sórí ibí yìí, a kì yóò sì paná rẹ̀.’
For thei han forsake me, and han sacrified to alien goddis, for to terre me to wrathfulnesse in alle the werkis of her hondis; therfor my strong veniaunce schal droppe on this place, and it schal not be quenchid.
26 Sọ fún ọba Juda, ẹni tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa ti sọ, Ọlọ́run Israẹli, sọ nípa ọ̀rọ̀ wọ́n nì tí ìwọ gbọ́.
But speke ye thus to the kyng of Juda, that sente you to preye the Lord, The Lord God of Israel seith these thingis, For thou herdist the wordis of the book,
27 Nítorí ọkàn rẹ̀ dúró, ìwọ sì rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa nígbà tí ó gbọ́ ohun tí ó sọ lórí ibí yìí àti ènìyàn rẹ, nítorí ìwọ rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú mi tí o sì fa aṣọ rẹ ya, tí o sì lọ níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ ni Olúwa wí.
and thin herte is maad neisch, and thou art mekid in the siyt of the Lord of these thingis that ben seide ayens this place and the dwelleris of Jerusalem, and thou hast reuerensid my face, and hast to-rente thi clothis, and hast wepte bifor me; also Y haue herd thee, seith the Lord.
28 Nísinsin yìí, Èmi ó kó ọ jọ pọ̀ sọ́dọ̀ àwọn baba rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kò sì ní rí gbogbo ibi tí èmi ó mú wá sórí ibí yìí àti lórí àwọn tí ń gbé ibẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú ìdáhùn rẹ̀ padà sí ọ̀dọ̀ ọba.
For now Y schal gadere thee to thi fadris, and thou schalt be borun in to thi sepulcre in pees; and thin iyen schulen not se al yuel, which Y schal brynge yn on this place, and on the dwelleris therof. Therfor thei telden to the king alle thingis, whiche Olda hadde seid.
29 Nígbà náà ni ọba sì pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda jọ àti Jerusalẹmu.
And aftir that he hadde clepid togidere alle the eldere men of Juda and of Jerusalem,
30 Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
he stiede in to the hows of the Lord, and togidere alle the men of Juda, `and the dwelleris of Jerusalem, preestis, and dekenes, and al the puple, fro the leeste `til to the moste; to whiche herynge in the hows of the Lord, the kyng redde alle the wordis of the book.
31 Ọba sì dúró ní ipò rẹ̀ ó sì tún májẹ̀mú dá níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti ẹ̀rí rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo àyà rẹ̀ àti láti pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé yìí.
And he stood in his trone, and smoot a boond of pees bifor the Lord, for to `go aftir hym, and to kepe the comaundementis, and witnessyngis, and iustifiyngis of hym, in al his herte and in al his soule; and to do tho thingis that weren writun in that book, which he hadde red.
32 Nígbà náà, ó sì mú kí gbogbo ènìyàn ní Jerusalẹmu àti Benjamini dúró nínú ẹ̀rí fún ara wọn, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ṣe èyí gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú Ọlọ́run, Ọlọ́run baba ńlá wọn.
And he chargide greetli on this thing alle men, that weren foundun in Jerusalem and Beniamyn; and the dwellers of Jerusalem diden aftir the couenaunt of the Lord God of her fadris.
33 Josiah sì kó gbogbo ohun ìríra kúrò nínú gbogbo ìlú tí ń ṣe ti àwọn tí ó wà ní Israẹli, ó sì mú kí gbogbo àwọn tí ó wà ní Israẹli sin Olúwa Ọlọ́run wọn gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà láyè wọn, kò yà kúrò láti máa tọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn lẹ́yìn.
Therfor Josie dide awei alle abhomynaciouns fro alle the cuntreis of the sones of Israel; and he made alle men, that weren residue in Israel, to serue her Lord God; in alle the daies of his lijf thei yeden not awei fro the Lord God of her fadris.

< 2 Chronicles 34 >