< 2 Chronicles 34 >

1 Josiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì dí ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
Josiah was eight years old when he became the king [of Judah]. He ruled from Jerusalem for 31 years.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa, ó sì rìn ọ̀nà baba rẹ̀ Dafidi, kò sì yà sí ọwọ́ ọ̀tún tàbí òsì.
He did things that were pleasing to Yahweh and conducted his life like his ancestor King David had done. He fully obeyed [IDM] all the laws of God.
3 Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀, nígbà tí ó sì wà ní ọ̀dọ́mọdé, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wá ojú Ọlọ́run baba Dafidi. Ní ọdún kejìlá. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fọ Juda àti Jerusalẹmu mọ́ kúrò ní ibi gíga rẹ̀, ère òrìṣà Aṣerah, àti ère yíyá àti ère dídà.
When he had been ruling for almost eight years, while he was still a young man, he began to worship God like his ancestor [King] David had done. Four years later, he began to get rid of all the pagan shrines on hilltops in Jerusalem and in [other places in] Judah, and the poles to [honor the goddess] Asherah, and the carved idols and statues of gods.
4 Lábẹ́ àpẹẹrẹ àwọn pẹpẹ Baali ni a yí lulẹ̀, ó sì fọ́ àwọn ère sí wẹ́wẹ́, ó run àwọn pẹpẹ tí ó wà lórí rẹ̀, wọ́n sì fọ́ túútúú, àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Èyí tí ó fọ́ wọn sì lúúlúú, ó sì gbọ̀n wọ́n sí orí isà òkú àti àwọn tí ó ń rú ẹbọ sí wọn.
While he directed them, his workers tore down the altars where people worshiped Baal. They smashed the altars that were near those altars, where people burned incense. They smashed the poles [honor the goddess] Asherah and the idols and statues. They smashed them to bits and scattered the bits over the graves of those who had offered sacrifices to them.
5 Ó sì sun àwọn egungun àwọn àlùfáà lórí pẹpẹ wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni ó sì wẹ Juda àti Jerusalẹmu mọ́.
They burned the bones of the priests [who had offered sacrifices]; they burned them on their own altars. In that way Josiah caused Jerusalem and other places in Judah to be acceptable places to worship Yahweh again.
6 Ní ìlú Manase, Efraimu àti Simeoni, àní títí ó fi dé Naftali, àti nínú àwọn, ó tú ilé wọn yíkákiri.
In the towns in [the tribes of] Manasseh, Ephraim, and Simeon, and as far [north] as [the tribe of] Naphtali and in the ruins around all those towns,
7 Ó sì wó pẹpẹ àti ère Aṣerah lulẹ̀ àti àwọn ère yíyá àti àwọn òrìṣà, ó sì gùn ó sì ti ké gbogbo àwọn ère orí pẹpẹ lulẹ̀ ní gbogbo àyíká Israẹli. Lẹ́yìn náà ó padà sí Jerusalẹmu.
Josiah’s [workers] tore down the pagan altars and the poles to [honor the goddess] Asherah, and crushed the idols to powder. They also smashed to pieces all the altars for burning incense throughout Israel. Then Josiah returned to Jerusalem.
8 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Josiah ni a ti wẹ ilẹ̀ náà mọ́ àti ilé Olúwa, ó sì rán Ṣafani ọmọ Asalia àti Maaseiah olórí ìlú náà, pẹ̀lú Joah, ọmọ Joahasi, akọ̀wé, láti tún ilé Olúwa Ọlọ́run ṣe.
When Josiah had been ruling for almost 18 years, he [did something else to] cause the land and the temple to be acceptable places to worship Yahweh. He sent Shaphan the son of Azaliah and Maaseiah the governor of the city and Joah the son of Joahaz, who wrote on a scroll what happened in the city, to repair the temple of Yahweh.
9 Wọ́n sì lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, ó sì fún un ní owó náà tí ó mú wá sí inú ilé Ọlọ́run, ti àwọn ọmọ Lefi ẹni tí ó jẹ́ aṣọ́bodè ti gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn Manase Efraimu àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ìyókù Israẹli àti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn Juda àti Benjamini wọ́n sì padà sí Jerusalẹmu.
They went to Hilkiah the Supreme Priest and gave him the money that had been brought to the temple. That was the money that the descendants of Levi who guarded the doors of the temple had collected from the people of [the tribes of] Manasseh and Ephraim and [other places in northern] Israel, and also from all the people in Jerusalem and other places in the tribes of Judah and Benjamin.
10 Nígbà náà ni wọn sì fi le àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ilé lọ́wọ́, àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ ilé Olúwa. Àwọn ọkùnrin yìí sì san owó fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń túnṣe, tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ní ilé Olúwa.
Then Hilkiah gave some of the money to the men who had been appointed to supervise the work of repairing the temple. The supervisors paid the men who did the repair work.
11 Wọ́n sì tún fi owó fún àwọn oníṣọ̀nà àti àwọn olùkọ́lé láti ra òkúta gbígbẹ́ àti ìtì igi fún ìsopọ̀ àti igi rírẹ́ fún ìkọ́lé tí ọba Juda ti gbà láti túnṣe.
They also gave some of the money to the carpenters and builders to buy the cut stones and the timber for the joists and the beams for the buildings that the kings of Judah had allowed to decay.
12 Àwọn ọkùnrin náà ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú òtítọ́, láti darí wọn ní Jahati àti Obadiah, àwọn ọmọ Lefi láti Merari, àti Sekariah àti Meṣullamu, sọ̀kalẹ̀ láti Kohati àwọn ọmọ Lefi gbogbo tí ó ní ọgbọ̀n ohun èlò orin.
The workers did their work faithfully. Their supervisors were Jahath and Obadiah, who were descendants of [Levi’s son] Merari, and Zechariah and Meshullam, who were descendants of [Levi’s son] Kohath. All the other descendants of Levi, those who played musical instruments well,
13 Wọ́n sì ní olórí àwọn aláàárù àti àwọn alábojútó gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ láti ibi iṣẹ́ sí ibi iṣẹ́, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Lefi sì ní akọ̀wé, olùtọ́jú àti olùṣọ́nà.
supervised all the workers as they did their various jobs. Some of the descendants of Levi were secretaries and some kept records and some guarded the gates [of the temple].
14 Nígbà tí wọ́n mú owó náà tí wọ́n mú wá sí ilé Olúwa, Hilkiah àlùfáà sì rí ìwé òfin Olúwa tí a ti fi fún un láti ọwọ́ Mose.
While they were giving to the supervisors the money that had been taken to the temple, Hilkiah the [Supreme] Priest found a scroll on which were written the laws that Yahweh had told Moses to give to the people.
15 Hilkiah sì wí fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi ti rí ìwé òfin nínú ilé Olúwa.” Ó sì fi fún Ṣafani.
So Hilkiah said to Shaphan, “I have found in the temple a scroll on which are written the laws [that God gave to Moses]!” Then Hilkiah gave the scroll to Shaphan.
16 Nígbà náà Ṣafani sì mú ìwé náà lọ sí ọ̀dọ̀ ọba ó sì ròyìn fún un. “Àwọn ìjòyè rẹ̀ ń ṣe gbogbo nǹkan tí a ti fi lé wọn lọ́wọ́.
Shaphan [took the scroll] to the king and said to him, “Your officials are doing everything that you told them to do.
17 Wọ́n ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa wọ́n sì ti fi lé àwọn alábojútó lọ́wọ́ àti àwọn òṣìṣẹ́.”
They have taken the money that was in the temple, and they have given it to the men who will supervise the workers who will repair the temple.”
18 Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sì sọ fún ọba, “Hilkiah àlùfáà ti fún mi ní ìwé.” Ṣafani sì kà níwájú ọba.
Then Shaphan said to the king, “[I have brought to you] a scroll [that] Hilkiah gave to me.” And Shaphan started to read it to the king.
19 Nígbà tí ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
When the king heard the laws [that were written in the scroll], he tore his clothes [because he was very dismayed/worried].
20 Ó sì pa àṣẹ yìí fún Hilkiah, Ahikamu ọmọ Ṣafani, Abdoni ọmọ Mika, Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
Then he gave these instructions to Hilkiah, to Shaphan’s son Ahikam, to Micah’s son Abdon, to Shaphan, and to Asaiah the king’s special advisor:
21 “Ẹ lọ kí ẹ lọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi nípa àwọn ìyókù Israẹli àti Juda nípa ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ti jáde sí orí wa nítorí àwọn baba wa kò ti pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́, wọn kò sì tí ì ṣe gẹ́gẹ́ bí i gbogbo èyí tí a kọ sínú ìwé yìí.”
“Go and ask Yahweh for me, and for all his people who are still alive in Judah and Israel, about what is written in this scroll that has been found. Because [it is clear that] Yahweh is very angry with us because our ancestors disobeyed what Yahweh said; they did not obey the laws that are written on this scroll.”
22 Hilkiah àti àwọn ènìyàn tí ọba yàn tọ Hulda wòlíì obìnrin láti ba sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tokhati tí a tún ń pè ní Tikfa, ọmọ Harhasi, olùtọ́jú ibi ìkáṣọsí. Ó sì ń gbé ní Jerusalẹmu, ní ìhà kejì.
So Hilkiah and the others went to talk with a woman whose name was Huldah, who was a prophetess who lived in the newer part of Jerusalem. Her husband Shallum who was the son of Tikvah, took care of the robes that were worn [in the temple].
23 Ó sì wí fún wọn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ti sọ, sọ fún àwọn ọkùnrin tí ó rán ọ sí mi pé,
[When they told her what the king had said, ] she said to them, “This is what Yahweh, the God whom we Israelis [worship], says: ‘Go back and tell the king who sent you
24 ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi yóò sì mú ibi wá sí ìhín yìí àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gbogbo àní ègún tí a kọ sínú ìwé tí wọ́n ti kà níwájú ọba Juda.”
that this is what Yahweh says: “Listen to this carefully. I am going to cause a disaster to strike Jerusalem and all the people who live here. I will cause them to experience the curses that were written in the scroll that was read to the king of Judah.
25 Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀ wọ́n sì ti sun tùràrí sí ọlọ́run mìíràn wọ́n sì ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn ṣe, ìbínú yóò tú jáde wá sórí ibí yìí, a kì yóò sì paná rẹ̀.’
I will do that because they have rejected me, and they burn incense to [honor] other gods. They have caused me to become very angry because of all the idols that they have made (OR, because of all the wicked things that they have done), [and my anger is like] a fire that will not be extinguished.
26 Sọ fún ọba Juda, ẹni tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa ti sọ, Ọlọ́run Israẹli, sọ nípa ọ̀rọ̀ wọ́n nì tí ìwọ gbọ́.
The king of Judah sent you to ask what I, Yahweh, want. Go and tell him that this is what I, Yahweh, the God whom you Israelis worship, say about what you read:
27 Nítorí ọkàn rẹ̀ dúró, ìwọ sì rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa nígbà tí ó gbọ́ ohun tí ó sọ lórí ibí yìí àti ènìyàn rẹ, nítorí ìwọ rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú mi tí o sì fa aṣọ rẹ ya, tí o sì lọ níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ ni Olúwa wí.
“Because you heeded [what was written in the scroll], and you humbled yourself when you heard what I said to warn [about what would happen to] this city and the people who live here, and because you tore your robes and wept in my presence, I have heard you.
28 Nísinsin yìí, Èmi ó kó ọ jọ pọ̀ sọ́dọ̀ àwọn baba rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kò sì ní rí gbogbo ibi tí èmi ó mú wá sórí ibí yìí àti lórí àwọn tí ń gbé ibẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú ìdáhùn rẹ̀ padà sí ọ̀dọ̀ ọba.
So I will allow you to die and be buried peacefully. I will cause a great disaster to strike this place and the people who live here, but you will not [be alive to] see it.”’” So they reported her reply to the king.
29 Nígbà náà ni ọba sì pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda jọ àti Jerusalẹmu.
Then the king summoned all the elders of Jerusalem and [other places in] Judea.
30 Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
They went up together to the temple with the leaders of Judah and many other people of Jerusalem and the priests and other descendants of Levi, from the least important to the most important ones. And while they listened, the king read to them everything that was in the scroll containing God’s laws that had been found in the temple.
31 Ọba sì dúró ní ipò rẹ̀ ó sì tún májẹ̀mú dá níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti ẹ̀rí rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo àyà rẹ̀ àti láti pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé yìí.
Then the king stood next to the pillar [at the entrance to the temple, where kings stood when they announced something important], and while Yahweh was listening, he repeated his promise to very sincerely and completely obey Yahweh and all his commands and regulations and decrees that were written on the scroll.
32 Nígbà náà, ó sì mú kí gbogbo ènìyàn ní Jerusalẹmu àti Benjamini dúró nínú ẹ̀rí fún ara wọn, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ṣe èyí gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú Ọlọ́run, Ọlọ́run baba ńlá wọn.
Then the king said that everyone who lived in Jerusalem and from [the tribe of] Benjamin should promise that they also would obey those laws. And they did that, agreeing that they would keep the agreement that God, whom their ancestors had worshiped, had made with them.
33 Josiah sì kó gbogbo ohun ìríra kúrò nínú gbogbo ìlú tí ń ṣe ti àwọn tí ó wà ní Israẹli, ó sì mú kí gbogbo àwọn tí ó wà ní Israẹli sin Olúwa Ọlọ́run wọn gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà láyè wọn, kò yà kúrò láti máa tọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn lẹ́yìn.
Josiah [instructed his workers to] remove all the detestable idols from everywhere in the land of the Israeli people, and he commanded that all the people from Israel who were there should worship [only] Yahweh their God. And as long as Josiah was alive, the people did what was pleasing to Yahweh, the God whom their ancestors [worshiped].

< 2 Chronicles 34 >