< 2 Chronicles 34 >
1 Josiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì dí ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
[was] a son of Eight years Josiah when became king he and thirty and one year[s] he reigned in Jerusalem.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa, ó sì rìn ọ̀nà baba rẹ̀ Dafidi, kò sì yà sí ọwọ́ ọ̀tún tàbí òsì.
And he did the right in [the] eyes of Yahweh and he walked in [the] ways of David ancestor his and not he turned aside right and left.
3 Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀, nígbà tí ó sì wà ní ọ̀dọ́mọdé, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wá ojú Ọlọ́run baba Dafidi. Ní ọdún kejìlá. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fọ Juda àti Jerusalẹmu mọ́ kúrò ní ibi gíga rẹ̀, ère òrìṣà Aṣerah, àti ère yíyá àti ère dídà.
And in eight years of reigning his and he still he [was] a youth he began to seek [the] God of David ancestor his and in two [plus] ten year he began to cleanse Judah and Jerusalem from the high places and the Asherah poles and the idols and the molten images.
4 Lábẹ́ àpẹẹrẹ àwọn pẹpẹ Baali ni a yí lulẹ̀, ó sì fọ́ àwọn ère sí wẹ́wẹ́, ó run àwọn pẹpẹ tí ó wà lórí rẹ̀, wọ́n sì fọ́ túútúú, àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Èyí tí ó fọ́ wọn sì lúúlúú, ó sì gbọ̀n wọ́n sí orí isà òkú àti àwọn tí ó ń rú ẹbọ sí wọn.
And people pulled down before him [the] altars of the Baals and the incense altars which [were] upwards above them he cut down and the Asherah poles and the idols and the molten images he broke in pieces and he pulverized [them] and he sprinkled [them] on [the] surface of the graves who sacrificed to them.
5 Ó sì sun àwọn egungun àwọn àlùfáà lórí pẹpẹ wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni ó sì wẹ Juda àti Jerusalẹmu mọ́.
And [the] bones of priests he burned on (altars their *Q(K)*) and he cleansed Judah and Jerusalem.
6 Ní ìlú Manase, Efraimu àti Simeoni, àní títí ó fi dé Naftali, àti nínú àwọn, ó tú ilé wọn yíkákiri.
And in [the] cities of Manasseh and Ephraim and Simeon and to Naphtali (in [the] hill country of with swords their *Q(K)*) all around.
7 Ó sì wó pẹpẹ àti ère Aṣerah lulẹ̀ àti àwọn ère yíyá àti àwọn òrìṣà, ó sì gùn ó sì ti ké gbogbo àwọn ère orí pẹpẹ lulẹ̀ ní gbogbo àyíká Israẹli. Lẹ́yìn náà ó padà sí Jerusalẹmu.
And he pulled down the altars and the Asherah poles and the idols he crushed to pulverize and all the incense altars he cut down in all [the] land of Israel and he returned to Jerusalem.
8 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Josiah ni a ti wẹ ilẹ̀ náà mọ́ àti ilé Olúwa, ó sì rán Ṣafani ọmọ Asalia àti Maaseiah olórí ìlú náà, pẹ̀lú Joah, ọmọ Joahasi, akọ̀wé, láti tún ilé Olúwa Ọlọ́run ṣe.
And in year eight-teen of reigning his to cleanse the land and the house he sent Shaphan [the] son Azaliah and Maaseiah [the] official of the city and Joah [the] son of Joahaz the recorder to repair [the] house of Yahweh God his.
9 Wọ́n sì lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, ó sì fún un ní owó náà tí ó mú wá sí inú ilé Ọlọ́run, ti àwọn ọmọ Lefi ẹni tí ó jẹ́ aṣọ́bodè ti gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn Manase Efraimu àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ìyókù Israẹli àti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn Juda àti Benjamini wọ́n sì padà sí Jerusalẹmu.
And they went to Hilkiah - the priest great and they gave the money which had been brought [the] house of God which they had gathered the Levites [the] keepers of the threshold from [the] hand of Manasseh and Ephraim and from all [the] remnant of Israel and from all Judah and Benjamin (and they returned of *Q(K)*) Jerusalem.
10 Nígbà náà ni wọn sì fi le àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ilé lọ́wọ́, àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ ilé Olúwa. Àwọn ọkùnrin yìí sì san owó fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń túnṣe, tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ní ilé Olúwa.
And they gave [it] on [the] hand of [the] doer of the work who were appointed in [the] house of Yahweh and they gave it [the] doers of the work who [were] working in [the] house of Yahweh to mend and to repair the house.
11 Wọ́n sì tún fi owó fún àwọn oníṣọ̀nà àti àwọn olùkọ́lé láti ra òkúta gbígbẹ́ àti ìtì igi fún ìsopọ̀ àti igi rírẹ́ fún ìkọ́lé tí ọba Juda ti gbà láti túnṣe.
And they gave [it] to the craftsmen and to the builders to buy stones of hewing and wood for the clamps and to make beams for the houses which they had ruined [the] kings of Judah.
12 Àwọn ọkùnrin náà ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú òtítọ́, láti darí wọn ní Jahati àti Obadiah, àwọn ọmọ Lefi láti Merari, àti Sekariah àti Meṣullamu, sọ̀kalẹ̀ láti Kohati àwọn ọmọ Lefi gbogbo tí ó ní ọgbọ̀n ohun èlò orin.
And the men [were] working in faithfulness in the work and over them - [were] appointed Jahath and Obadiah the Levites of [the] descendants of Merari and Zechariah and Meshullam of [the] descendants of the Kohathites to act as overseers and the Levites every [one who] was skilled in instruments of song.
13 Wọ́n sì ní olórí àwọn aláàárù àti àwọn alábojútó gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ láti ibi iṣẹ́ sí ibi iṣẹ́, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Lefi sì ní akọ̀wé, olùtọ́jú àti olùṣọ́nà.
[were] over The burden-bearers and [were] acting as overseers of every doer of work for labor and labor and some of the Levites [were] scribes and officials and gatekeepers.
14 Nígbà tí wọ́n mú owó náà tí wọ́n mú wá sí ilé Olúwa, Hilkiah àlùfáà sì rí ìwé òfin Olúwa tí a ti fi fún un láti ọwọ́ Mose.
And when brought out they the money which had been brought [the] house of Yahweh he found Hilkiah the priest [the] scroll of [the] law of Yahweh by [the] hand of Moses.
15 Hilkiah sì wí fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi ti rí ìwé òfin nínú ilé Olúwa.” Ó sì fi fún Ṣafani.
And he answered Hilkiah and he said to Shaphan the scribe [the] scroll of the law I have found in [the] house of Yahweh and he gave Hilkiah the scroll to Shaphan.
16 Nígbà náà Ṣafani sì mú ìwé náà lọ sí ọ̀dọ̀ ọba ó sì ròyìn fún un. “Àwọn ìjòyè rẹ̀ ń ṣe gbogbo nǹkan tí a ti fi lé wọn lọ́wọ́.
And he brought Shaphan the scroll to the king and he brought back again the king a word saying all that it was given in [the] hand of servants your they [are] doing.
17 Wọ́n ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa wọ́n sì ti fi lé àwọn alábojútó lọ́wọ́ àti àwọn òṣìṣẹ́.”
And they have poured out the money which was found in [the] house of Yahweh and they have put it on [the] hand of those [who] were appointed and on [the] hand of [the] doers of the work.
18 Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sì sọ fún ọba, “Hilkiah àlùfáà ti fún mi ní ìwé.” Ṣafani sì kà níwájú ọba.
And he told Shaphan the scribe to the king saying a scroll he has given to me Hilkiah the priest and he read aloud in it Shaphan before the king.
19 Nígbà tí ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
And it was when heard the king [the] words of the law and he tore clothes his.
20 Ó sì pa àṣẹ yìí fún Hilkiah, Ahikamu ọmọ Ṣafani, Abdoni ọmọ Mika, Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
And he commanded the king Hilkiah and Ahikam [the] son of Shaphan and Abdon [the] son of Micah and - Shaphan the scribe and Asaiah [the] servant of the king saying.
21 “Ẹ lọ kí ẹ lọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi nípa àwọn ìyókù Israẹli àti Juda nípa ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ti jáde sí orí wa nítorí àwọn baba wa kò ti pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́, wọn kò sì tí ì ṣe gẹ́gẹ́ bí i gbogbo èyí tí a kọ sínú ìwé yìí.”
Go consult Yahweh for me and for the remnant among Israel and among Judah on [the] words of the scroll which it has been found for [is] great [the] anger of Yahweh which it has been poured out on us on that not they took care ancestors our [the] word of Yahweh to observe according to every [thing] written on the scroll this.
22 Hilkiah àti àwọn ènìyàn tí ọba yàn tọ Hulda wòlíì obìnrin láti ba sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tokhati tí a tún ń pè ní Tikfa, ọmọ Harhasi, olùtọ́jú ibi ìkáṣọsí. Ó sì ń gbé ní Jerusalẹmu, ní ìhà kejì.
And he went Hilkiah and [those] whom the king to Huldah the prophetess [the] wife of - Shallum [the] son of (Tokhath *Q(K)*) [the] son of Hasrah [the] keeper of the garments and she [was] dwelling in Jerusalem in the second district and they spoke to her like this.
23 Ó sì wí fún wọn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ti sọ, sọ fún àwọn ọkùnrin tí ó rán ọ sí mi pé,
And she said to them thus he says Yahweh [the] God of Israel say to the man who he sent you to me.
24 ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi yóò sì mú ibi wá sí ìhín yìí àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gbogbo àní ègún tí a kọ sínú ìwé tí wọ́n ti kà níwájú ọba Juda.”
Thus he says Yahweh here I [am] about to bring harm on the place this and on inhabitants its all the curses which are written on the scroll which people have read aloud before [the] king of Judah.
25 Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀ wọ́n sì ti sun tùràrí sí ọlọ́run mìíràn wọ́n sì ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn ṣe, ìbínú yóò tú jáde wá sórí ibí yìí, a kì yóò sì paná rẹ̀.’
Because - that they have forsaken me (and they have made smoke *Q(K)*) to gods other so as to provoke to anger me by all [the] works of hands their so it may pour forth rage my on the place this and not it will be quenched.
26 Sọ fún ọba Juda, ẹni tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa ti sọ, Ọlọ́run Israẹli, sọ nípa ọ̀rọ̀ wọ́n nì tí ìwọ gbọ́.
And to [the] king of Judah who sent you to consult Yahweh thus you will say to him. Thus he says Yahweh [the] God of Israel the words which you have heard.
27 Nítorí ọkàn rẹ̀ dúró, ìwọ sì rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa nígbà tí ó gbọ́ ohun tí ó sọ lórí ibí yìí àti ènìyàn rẹ, nítorí ìwọ rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú mi tí o sì fa aṣọ rẹ ya, tí o sì lọ níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ ni Olúwa wí.
Because it was soft heart your and you humbled yourself - from to before God when hearing you words his on the place this and on inhabitants its and you humbled yourself before me and you tore clothes your and you wept before me and also I I have heard [the] utterance of Yahweh.
28 Nísinsin yìí, Èmi ó kó ọ jọ pọ̀ sọ́dọ̀ àwọn baba rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kò sì ní rí gbogbo ibi tí èmi ó mú wá sórí ibí yìí àti lórí àwọn tí ń gbé ibẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú ìdáhùn rẹ̀ padà sí ọ̀dọ̀ ọba.
Here I [will] gather you to ancestors your and you will be gathered to grave your in peace and not they will look eyes your on all the distress which I [am] about to bring on the place this and on inhabitants its and they brought back the king word.
29 Nígbà náà ni ọba sì pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda jọ àti Jerusalẹmu.
And he sent the king and he gathered all [the] elders of Judah and Jerusalem.
30 Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
And he went up the king [the] house of Yahweh and every person of Judah and [the] inhabitants of Jerusalem and the priests and the Levites and all the people from great and unto small and he read aloud in ears their all [the] words of [the] scroll of the covenant which had been found [the] house of Yahweh.
31 Ọba sì dúró ní ipò rẹ̀ ó sì tún májẹ̀mú dá níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti ẹ̀rí rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo àyà rẹ̀ àti láti pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé yìí.
And he stood the king at place his and he made the covenant before Yahweh to walk after Yahweh and to keep commandments his and testimonies his and statutes his with all heart his and with all being his to observe [the] words of the covenant which was written on the scroll this.
32 Nígbà náà, ó sì mú kí gbogbo ènìyàn ní Jerusalẹmu àti Benjamini dúró nínú ẹ̀rí fún ara wọn, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ṣe èyí gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú Ọlọ́run, Ọlọ́run baba ńlá wọn.
And he made stand every [one who] was found in Jerusalem and Benjamin and they did [the] inhabitants of Jerusalem according to [the] covenant of God [the] God of ancestors their.
33 Josiah sì kó gbogbo ohun ìríra kúrò nínú gbogbo ìlú tí ń ṣe ti àwọn tí ó wà ní Israẹli, ó sì mú kí gbogbo àwọn tí ó wà ní Israẹli sin Olúwa Ọlọ́run wọn gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà láyè wọn, kò yà kúrò láti máa tọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn lẹ́yìn.
And he removed Josiah all the abominations from all the lands which [belonged] to [the] people of Israel and he made to serve every [one who] was found in Israel to serve Yahweh God their all days his not they turned aside from after Yahweh [the] God of ancestors their.