< 2 Chronicles 33 >

1 Manase jẹ́ ọmọ ọdún méjìlá nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún márùndínlọ́gọ́ta.
Tizenkét esztendős vala Manasse, mikor uralkodni kezdett volt, és ötvenöt esztendeig uralkodott Jeruzsálemben.
2 Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa. Nípa títẹ̀lé ọ̀nà iṣẹ́ ìríra ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli rìn.
És gonoszul cselekedék az Úr szemei előtt a pogányok útálatosságai szerint, a kiket az Úr az Izráel fiai elől kiűzött vala.
3 Ó tún kọ́ àwọn ibi gíga tí baba rẹ̀ Hesekiah ti fọ́ túútúú. Ó sì gbé àwọn pẹpẹ dìde fún àwọn Baali ó sì ṣe àwọn ère Aṣerah. Ó foríbalẹ̀ fún gbogbo àwọn ogun ọ̀run ó sì sìn wọ́n.
Mert a magaslatokat ismét megépíté, a melyeket Ezékiás az ő atyja azelőtt elrontott vala, és oltárokat emele Baálnak, Aserákat is plántála, és tisztelé az ég minden seregeit, és szolgála azoknak.
4 Ó kọ́ àwọn pẹpẹ sínú ilé Olúwa ní èyí tí Olúwa ti wí pé, “Orúkọ mi yóò wà ní Jerusalẹmu títí láé.”
Sőt az Úr házában is építe oltárokat, a melyről az Úr azt mondotta volt: Jeruzsálemben lészen az én nevem örökké.
5 Nínú ààfin méjèèje ti ilé Olúwa, ó kọ́ àwọn pẹpẹ fún gbogbo àwọn ogun ọ̀run
És építe oltárokat az ég minden seregeinek, az Úr házának mindkét pitvariban.
6 Ó sì mú kí àwọn ọmọ ara rẹ̀ kí ó kọjá láàrín iná ní àfonífojì Beni-Hinnomu, ó ń ṣe àkíyèsí àfọ̀ṣẹ, ó sì ń lo àlúpàyídà, ó sì ń bá àwọn òku àti oṣó lò. Ó ṣe ọ̀pọ̀ ohun búburú ní ojú Olúwa láti mú un bínú.
És fiait átvitte a tűzön a Hinnom fiának völgyében; és az időnek forgására ügyelt, jövendőmondásokat, varázslásokat és szemfényvesztéseket űzött, ördöngösöket és jövendőmondókat szerzett, és sok gonoszságot cselekedett az Úr szemei előtt, hogy őt haragra indítaná.
7 Ó mú ère gbígbẹ́ tí ó ti gbẹ́ ó sì gbé e sínú ilé Olúwa, ní èyí tí Ọlọ́run ti sọ fún Dafidi àti sí ọmọ rẹ̀ Solomoni, “Nínú ilé Olúwa yìí àti ní Jerusalẹmu, tí mo ti yàn kúrò nínú gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli, èmi yóò fi orúkọ mi síbẹ̀ títí láé.
A faragott bálványt, a melyet csináltatott vala, az Úr házában állítá fel, a melyről azt mondá az Isten Dávidnak, és az ő fiának, Salamonnak: E házban és Jeruzsálemben, a melyet választottam az Izráel minden nemzetségei közül, helyheztetem az én nevemet mindörökké;
8 Èmi kì yóò ṣí ẹsẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli kúrò mọ́ ní ilẹ̀ náà tí èmi ti yàn fún àwọn baba ńlá yín, níwọ̀n bí wọ́n bá ṣe pẹ̀lẹ́ láti ṣe gbogbo ohun tí mo paláṣẹ fún wọn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo òfin, àṣẹ àti àwọn ìlànà tí a fún yín láti ọwọ́ Mose wá.”
És nem űzöm ki az Izráelt e földről, melyet adtam volt a ti atyáitoknak; de csak úgy, ha ők is mind megtartándják, a melyeket nékik Mózes által parancsoltam, minden törvényt, rendeléseket és ítéleteket;
9 Ṣùgbọ́n Manase mú kí Juda àti àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu yapa, àti láti ṣe búburú ju àwọn orílẹ̀-èdè lọ, àwọn tí Olúwa ti parun níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
De Manasse elcsábítá Júdát és Jeruzsálem lakóit, hogy még gonoszabbul cselekedjenek, mint a pogányok, a kiket az Úr kigyomlált volt az Izráel fiai elől.
10 Olúwa bá Manase sọ̀rọ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò kọbi ara sí i.
És noha megszólította az Úr Manassét és az ő népét; de nem figyelmezének reá.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa mú àwọn alákòóso ọmọ-ogun ọba Asiria láti dojúkọ wọ́n, tí ó mú Manase nígbèkùn, ó fi ìwọ̀ mú un ní imú rẹ̀, ó dè é pẹ̀lú ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ idẹ ó sì mú un lọ sí Babeli.
Reájok hozá azért az Úr az Assiriabeli király seregének vezéreit, a kik Manassét megfogták és vasba vervén megkötözék őt két lánczczal, és Babilóniába vivék.
12 Nínú ìpọ́njú rẹ̀, ó wá ojúrere Olúwa Ọlọ́run rẹ̀. Ó sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ gidigidi níwájú Ọlọ́run àwọn baba rẹ̀.
Mikor pedig nagy nyomorúságban volna, fohászkodék az Úrhoz az ő Istenéhez, és teljesen megalázta magát az ő atyáinak Istene előtt.
13 Nígbà tí ó sì gbàdúrà sí i, inú Olúwa dùn sí àdúrà rẹ̀, ó sì tẹ́tí sí ẹ̀bẹ̀ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni ó mú un padà wá sí Jerusalẹmu àti sí ìjọba rẹ̀. Nígbà náà Manase mọ̀ wí pé Olúwa ni Ọlọ́run.
És könyörögvén hozzá megkegyelmeze néki, és meghallgatván könyörgését, visszahozá őt Jeruzsálembe, az ő országába. Akkor ismeré meg Manasse, hogy az Úr az igaz Isten.
14 Ǹjẹ́ lẹ́yìn èyí, ó mọ odi kan lẹ́yìn ìlú Dafidi, ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Gihoni, ní àfonífojì, àní ní àtiwọ ẹnu ibodè ẹja, ó sì yí orí òkè Ofeli ká; ó sì mọ ọ́n ga sókè gidigidi, ó sì fi balógun sínú gbogbo ìlú olódi Juda wọ̀n-ọn-nì.
Ezek után a Dávid városának külső kőfalát felépíté Gihontól napnyugat felé a völgyben, a halkapu bemeneteléig; Ofelt is körülvéteté magas kerítéssel, és Júdának minden megerősített városaiba seregvezéreket helyeze.
15 Ó pa gbogbo àwọn Ọlọ́run àjèjì run. Ó sì hú gbogbo àwọn ère kúrò nínú ilé Olúwa, pẹ̀lú gbogbo àwọn pẹpẹ tí ó ti kọ́ ní òkè ilé Olúwa àti ní Jerusalẹmu; ó sì kó wọn jáde kúrò nínú ìlú.
És eltávolítá az idegen isteneket és a bálványt az Úr házából, és minden oltárt, a melyet az Úr házának hegyén és Jeruzsálemben emeltetett, kihányatá azokat a városon kivül.
16 Nígbà náà ni ó mú àwọn pẹpẹ padà bọ̀ sípò. Ó sì rú ọrẹ ìdàpọ̀ àti ọrẹ-ọpẹ́ lórí rẹ̀. Ó sì sọ fún Juda láti sin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
És megépíté az Úr oltárát, és áldozék rajta hálaadó és dicsőítő áldozatokkal, és megparancsolá Júdának, hogy szolgáljanak az Úrnak, Izráel Istenének.
17 Àwọn ènìyàn, ko tẹ̀síwájú láti máa rú ẹbọ ní àwọn ibi gíga. Ṣùgbọ́n sí Olúwa Ọlọ́run wọn nìkan.
Mindazáltal még akkor a nép áldozik vala a magaslatokon; de csak az Úrnak, az ő Istenének.
18 Àwọn iṣẹ́ yòókù ti ìjọba Manase pẹ̀lú àdúrà rẹ̀ sí Ọlọ́run rẹ̀ àti àwọn ọ̀rọ̀ tí àwọn aríran sọ sí i ní orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, wà nínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli.
Manassénak pedig többi dolgai, Istenéhez való könyörgése, a próféták intése, a kik az Úrnak, Izráel Istenének nevében szólának néki, ímé meg vannak írva az Izráel királyainak dolgai között.
19 Àdúrà rẹ̀ àti bí inú Ọlọ́run ṣe dùn sí àdúrà rẹ̀ àti gbogbo àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ àti àìṣòótọ́, àti àwọn òpó níbi tí ó kọ́ àwọn ibi gíga sí, ó sì gbé àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà kí ó tó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, gbogbo rẹ̀ ni a kọ sínú ìwé ìrántí àwọn aríran.
Az ő könyörgése pedig, és hogy az Isten mint kegyelmezett volt meg néki, s az ő minden bűne és vétke; és a helyek, a melyeken magaslatokat épített volt, s Aserákat és bálványokat állított fel, minekelőtte megalázta volna magát: ímé meg vannak írva a Hózai beszédei között.
20 Manase sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín sínú ààfin rẹ̀. Amoni ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
És meghala Manasse az ő atyáival, és eltemeték őt az ő házában; és uralkodék Amon, az ő fia helyette.
21 Amoni jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjì.
Huszonkét esztendős vala Amon, mikor uralkodni kezdett, és két esztendeig uralkodék Jeruzsálemben.
22 Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Manase ti ṣe. Amoni rú ẹbọ sí gbogbo àwọn òrìṣà tí Manase baba rẹ̀ ti ṣe, ó sì sìn wọ́n.
És gonoszul cselekedék az Úr szemei előtt, miként az ő atyja Manasse cselekedett volt, mert áldozék Amon mindama bálványoknak, a melyeket az ő atyja Manasse csináltatott, és azoknak szolgál vala.
23 Ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i baba rẹ̀ Manase. Kò rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú Olúwa: ṣùgbọ́n ẹ̀ṣẹ̀ Amoni sì ń pọ̀ sì í.
Meg sem alázá magát az Úr előtt, mint az ő atyja Manasse megalázta magát; hanem még sokasítá Amon a bűnt.
24 Àwọn oníṣẹ́ Amoni dìtẹ̀ sí i. Wọ́n sì pa á ní ààfin rẹ̀.
Pártot ütének pedig az ő szolgái ő ellene, és őt saját házában megölék.
25 Nígbà náà, gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pa gbogbo àwọn tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Amoni, wọ́n sì mú Josiah ọmọ rẹ̀ jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
A föld népe pedig levágá mindazokat, a kik Amon király ellen pártot ütének, és királylyá tevé a föld népe Jósiást az ő fiát helyette.

< 2 Chronicles 33 >