< 2 Chronicles 33 >

1 Manase jẹ́ ọmọ ọdún méjìlá nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún márùndínlọ́gọ́ta.
Manasses was of twelue yeer, whanne he bygan to regne, and he regnyde in Jerusalem fyue and fifti yeer.
2 Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa. Nípa títẹ̀lé ọ̀nà iṣẹ́ ìríra ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli rìn.
Forsothe he dide yuel bifor the Lord bi abhomynaciouns of hethene men, whiche the Lord destriede bifor the sones of Israel.
3 Ó tún kọ́ àwọn ibi gíga tí baba rẹ̀ Hesekiah ti fọ́ túútúú. Ó sì gbé àwọn pẹpẹ dìde fún àwọn Baali ó sì ṣe àwọn ère Aṣerah. Ó foríbalẹ̀ fún gbogbo àwọn ogun ọ̀run ó sì sìn wọ́n.
And he turnede, and restoride the hiye places, whiche Ezechie, his fadir, hadde destried. And he bildide auteris to Baalym, and made wodis, and worschipide al the knyythod of heuene, and heriede it.
4 Ó kọ́ àwọn pẹpẹ sínú ilé Olúwa ní èyí tí Olúwa ti wí pé, “Orúkọ mi yóò wà ní Jerusalẹmu títí láé.”
And he bildide auteris in the hows of the Lord, of which the Lord hadde seid, My name schal be in Jerusalem with outen ende.
5 Nínú ààfin méjèèje ti ilé Olúwa, ó kọ́ àwọn pẹpẹ fún gbogbo àwọn ogun ọ̀run
Sotheli he bildide tho auteris to al the knyythod of heuene in the twei large places of the hows of the Lord.
6 Ó sì mú kí àwọn ọmọ ara rẹ̀ kí ó kọjá láàrín iná ní àfonífojì Beni-Hinnomu, ó ń ṣe àkíyèsí àfọ̀ṣẹ, ó sì ń lo àlúpàyídà, ó sì ń bá àwọn òku àti oṣó lò. Ó ṣe ọ̀pọ̀ ohun búburú ní ojú Olúwa láti mú un bínú.
And he made hise sones to passe thorouy the fier in the valei of Beennon; he kepte dremes; he suede fals diuynyng bi chiteryng of briddis; he seruyde witche craftis; he hadde with hym astronomyeris and enchaunteris, `ethir trigetours, that disseyuen mennus wittis, and he wrouyte many yuelis bifor the Lord to terre hym to wraththe.
7 Ó mú ère gbígbẹ́ tí ó ti gbẹ́ ó sì gbé e sínú ilé Olúwa, ní èyí tí Ọlọ́run ti sọ fún Dafidi àti sí ọmọ rẹ̀ Solomoni, “Nínú ilé Olúwa yìí àti ní Jerusalẹmu, tí mo ti yàn kúrò nínú gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli, èmi yóò fi orúkọ mi síbẹ̀ títí láé.
Also he settide a grauun signe and a yotun signe in the hows of the Lord, of which hows God spak to Dauid, and to Salomon, his sone, and seide, Y schal sette my name with outen ende in this hows and in Jerusalem, which Y chees of alle the lynagis of Israel;
8 Èmi kì yóò ṣí ẹsẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli kúrò mọ́ ní ilẹ̀ náà tí èmi ti yàn fún àwọn baba ńlá yín, níwọ̀n bí wọ́n bá ṣe pẹ̀lẹ́ láti ṣe gbogbo ohun tí mo paláṣẹ fún wọn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo òfin, àṣẹ àti àwọn ìlànà tí a fún yín láti ọwọ́ Mose wá.”
and Y schal not make the foot of Israel to moue fro the lond which Y yaf to her fadris, so oneli if thei kepen to do tho thingis whiche Y comaundide to hem, and al the lawe, and cerymonyes, and domes, bi the hond of Moises.
9 Ṣùgbọ́n Manase mú kí Juda àti àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu yapa, àti láti ṣe búburú ju àwọn orílẹ̀-èdè lọ, àwọn tí Olúwa ti parun níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
Therfor Manasses disseyuede Juda, and the dwelleris of Jerusalem, that thei diden yuel, more than alle hethene men, whiche the Lord hadde distriede fro the face of the sones of Israel.
10 Olúwa bá Manase sọ̀rọ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò kọbi ara sí i.
And the Lord spak to hym, and to his puple; and thei nolden take heed.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa mú àwọn alákòóso ọmọ-ogun ọba Asiria láti dojúkọ wọ́n, tí ó mú Manase nígbèkùn, ó fi ìwọ̀ mú un ní imú rẹ̀, ó dè é pẹ̀lú ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ idẹ ó sì mú un lọ sí Babeli.
Therfor the Lord brouyte on hem the princes of the oost of the kyng of Assiriens; and thei token Manasses, and bounden hym with chaynes, and stockis, and ledden hym in to Babiloyne.
12 Nínú ìpọ́njú rẹ̀, ó wá ojúrere Olúwa Ọlọ́run rẹ̀. Ó sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ gidigidi níwájú Ọlọ́run àwọn baba rẹ̀.
And aftir that he was angwischid, he preiede `his Lord God, and dide penaunce gretli bifor the God of hise fadris.
13 Nígbà tí ó sì gbàdúrà sí i, inú Olúwa dùn sí àdúrà rẹ̀, ó sì tẹ́tí sí ẹ̀bẹ̀ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni ó mú un padà wá sí Jerusalẹmu àti sí ìjọba rẹ̀. Nígbà náà Manase mọ̀ wí pé Olúwa ni Ọlọ́run.
And he preiede God, and bisechide ententifli; and God herde his preier, and brouyte hym ayen `in to Jerusalem in to his rewme; and Manasses knew, that the Lord hym silf is God.
14 Ǹjẹ́ lẹ́yìn èyí, ó mọ odi kan lẹ́yìn ìlú Dafidi, ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Gihoni, ní àfonífojì, àní ní àtiwọ ẹnu ibodè ẹja, ó sì yí orí òkè Ofeli ká; ó sì mọ ọ́n ga sókè gidigidi, ó sì fi balógun sínú gbogbo ìlú olódi Juda wọ̀n-ọn-nì.
Aftir these thingis he bildide the wal with out the citee of Dauid, at the west of Gion, in the valei, fro the entryng of the yate of fischis, bi cumpas `til to Ophel; and he reiside it gretli; and he ordeynede princes of the oost in alle the stronge citees of Juda.
15 Ó pa gbogbo àwọn Ọlọ́run àjèjì run. Ó sì hú gbogbo àwọn ère kúrò nínú ilé Olúwa, pẹ̀lú gbogbo àwọn pẹpẹ tí ó ti kọ́ ní òkè ilé Olúwa àti ní Jerusalẹmu; ó sì kó wọn jáde kúrò nínú ìlú.
And he dide awei alien goddis and symylacris fro the hows of the Lord; and he dide awei the auteris, whiche he hadde maad in the hil of the hows of the Lord, and in Jerusalem, and he castide awei alle with out the citee.
16 Nígbà náà ni ó mú àwọn pẹpẹ padà bọ̀ sípò. Ó sì rú ọrẹ ìdàpọ̀ àti ọrẹ-ọpẹ́ lórí rẹ̀. Ó sì sọ fún Juda láti sin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
Certis he restoride the auter of the Lord, and offride theronne slayn sacrifices, and pesible sacrifices, and preisyng; and he comaundide Juda to serue the Lord God of Israel.
17 Àwọn ènìyàn, ko tẹ̀síwájú láti máa rú ẹbọ ní àwọn ibi gíga. Ṣùgbọ́n sí Olúwa Ọlọ́run wọn nìkan.
Netheles the puple offride yit in hiy places to `her Lord God.
18 Àwọn iṣẹ́ yòókù ti ìjọba Manase pẹ̀lú àdúrà rẹ̀ sí Ọlọ́run rẹ̀ àti àwọn ọ̀rọ̀ tí àwọn aríran sọ sí i ní orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, wà nínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli.
Forsothe the residue of dedis of Manasses, and his bisechyng to `his Lord God, and the wordis of profetis, that spaken to hym in the name of the Lord God of Israel, ben conteyned in the wordis of the kyngis of Israel.
19 Àdúrà rẹ̀ àti bí inú Ọlọ́run ṣe dùn sí àdúrà rẹ̀ àti gbogbo àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ àti àìṣòótọ́, àti àwọn òpó níbi tí ó kọ́ àwọn ibi gíga sí, ó sì gbé àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà kí ó tó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, gbogbo rẹ̀ ni a kọ sínú ìwé ìrántí àwọn aríran.
And his preier, and the heryng, and alle synnes, and dispisyng, also the places in whiche he bildide hiy thingis, and made wodis and ymagis, bifor that he dide penaunce, ben writun in the bokis of Ozai.
20 Manase sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín sínú ààfin rẹ̀. Amoni ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Forsothe Manasses slepte with hise fadris, and thei birieden hym in his hows; and Amon, his sone, regnyde for hym.
21 Amoni jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjì.
Amon was of two and twenti yeer, whanne he bigan to regne; and he regnyde twei yeer in Jerusalem.
22 Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Manase ti ṣe. Amoni rú ẹbọ sí gbogbo àwọn òrìṣà tí Manase baba rẹ̀ ti ṣe, ó sì sìn wọ́n.
And he dide yuel in the siyt of the Lord, as Manasses, his fadir, hadde do; and he offride, and seruyde to alle the idols, whiche Manasses hadde maad.
23 Ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i baba rẹ̀ Manase. Kò rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú Olúwa: ṣùgbọ́n ẹ̀ṣẹ̀ Amoni sì ń pọ̀ sì í.
And he reuerenside not the face of the Lord, as Manasses, `his fadir, reuerenside; and he dide mych gretter trespassis.
24 Àwọn oníṣẹ́ Amoni dìtẹ̀ sí i. Wọ́n sì pa á ní ààfin rẹ̀.
And whanne his seruauntis `hadden swore to gyder ayens hym, thei killiden hym in his hows.
25 Nígbà náà, gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pa gbogbo àwọn tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Amoni, wọ́n sì mú Josiah ọmọ rẹ̀ jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Sotheli the residue multitude of the puple, aftir that thei hadden slayn hem that `hadden slayn Amon, ordeyneden Josie, his sone, kyng for hym.

< 2 Chronicles 33 >