< 2 Chronicles 33 >

1 Manase jẹ́ ọmọ ọdún méjìlá nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún márùndínlọ́gọ́ta.
Twelve years old, was Manasseh when he began to reign, —and, fifty-five years, reigned he in Jerusalem.
2 Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa. Nípa títẹ̀lé ọ̀nà iṣẹ́ ìríra ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli rìn.
And he did the thing that was wicked in the eyes of Yahweh, -according to the abominable ways of the nations, whom Yahweh dispossessed from before the sons of Israel.
3 Ó tún kọ́ àwọn ibi gíga tí baba rẹ̀ Hesekiah ti fọ́ túútúú. Ó sì gbé àwọn pẹpẹ dìde fún àwọn Baali ó sì ṣe àwọn ère Aṣerah. Ó foríbalẹ̀ fún gbogbo àwọn ogun ọ̀run ó sì sìn wọ́n.
And he again built the high places, which Hezekiah his father had thrown down, —and set up altars to the Baalim, and made Sacred Stems, and bowed in prostration unto all the army of the heavens, and served them;
4 Ó kọ́ àwọn pẹpẹ sínú ilé Olúwa ní èyí tí Olúwa ti wí pé, “Orúkọ mi yóò wà ní Jerusalẹmu títí láé.”
and built altars in the house of Yahweh, —as to which Yahweh had said, In Jerusalem, shall be my Name, unto times age-abiding.
5 Nínú ààfin méjèèje ti ilé Olúwa, ó kọ́ àwọn pẹpẹ fún gbogbo àwọn ogun ọ̀run
Yea he built altars unto all the army of the heavens, —in the two courts of the house of Yahweh.
6 Ó sì mú kí àwọn ọmọ ara rẹ̀ kí ó kọjá láàrín iná ní àfonífojì Beni-Hinnomu, ó ń ṣe àkíyèsí àfọ̀ṣẹ, ó sì ń lo àlúpàyídà, ó sì ń bá àwọn òku àti oṣó lò. Ó ṣe ọ̀pọ̀ ohun búburú ní ojú Olúwa láti mú un bínú.
And, he, caused his sons to pass through the fire, in the valley of the son of Hinnom, and practised hidden arts and used divination, and practised sorcery, and appointed a necromancer, and a wizard, —he exceeded in doing the thing that was wicked in the eyes of Yahweh, to provoke him to anger;
7 Ó mú ère gbígbẹ́ tí ó ti gbẹ́ ó sì gbé e sínú ilé Olúwa, ní èyí tí Ọlọ́run ti sọ fún Dafidi àti sí ọmọ rẹ̀ Solomoni, “Nínú ilé Olúwa yìí àti ní Jerusalẹmu, tí mo ti yàn kúrò nínú gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli, èmi yóò fi orúkọ mi síbẹ̀ títí láé.
and he set a resemblance-image which he had made, —in the house of God, as to which God had said unto David, and unto Solomon his son, In this house and in Jerusalem which I have chosen out of all the tribes of Israel, will I put my Name, unto times age-abiding.
8 Èmi kì yóò ṣí ẹsẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli kúrò mọ́ ní ilẹ̀ náà tí èmi ti yàn fún àwọn baba ńlá yín, níwọ̀n bí wọ́n bá ṣe pẹ̀lẹ́ láti ṣe gbogbo ohun tí mo paláṣẹ fún wọn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo òfin, àṣẹ àti àwọn ìlànà tí a fún yín láti ọwọ́ Mose wá.”
So will I not again remove the foot of Israel away from the soil which I appointed for their fathers. Only they must observe to do all that I have commanded them, even all the law and the statutes and the regulations, by the hand of Moses.
9 Ṣùgbọ́n Manase mú kí Juda àti àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu yapa, àti láti ṣe búburú ju àwọn orílẹ̀-èdè lọ, àwọn tí Olúwa ti parun níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
And so Manasseh led astray Judah and the inhabitants of Jerusalem, —to commit wickedness beyond the nations which Yahweh had destroyed from before the sons of Israel.
10 Olúwa bá Manase sọ̀rọ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò kọbi ara sí i.
And Yahweh spake unto Manasseh and unto his people, but they did not give ear.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa mú àwọn alákòóso ọmọ-ogun ọba Asiria láti dojúkọ wọ́n, tí ó mú Manase nígbèkùn, ó fi ìwọ̀ mú un ní imú rẹ̀, ó dè é pẹ̀lú ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ idẹ ó sì mú un lọ sí Babeli.
So Yahweh brought in upon them, the captains of the army that belonged to the king of Assyria, and they captured Manasseh with hooks, —and bound him captive with a pair of bronze fetters, and took him away to Babylon.
12 Nínú ìpọ́njú rẹ̀, ó wá ojúrere Olúwa Ọlọ́run rẹ̀. Ó sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ gidigidi níwájú Ọlọ́run àwọn baba rẹ̀.
But, in his distress, he appeased the face of Yahweh his God, —and humbled himself greatly, before the God of his fathers;
13 Nígbà tí ó sì gbàdúrà sí i, inú Olúwa dùn sí àdúrà rẹ̀, ó sì tẹ́tí sí ẹ̀bẹ̀ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni ó mú un padà wá sí Jerusalẹmu àti sí ìjọba rẹ̀. Nígbà náà Manase mọ̀ wí pé Olúwa ni Ọlọ́run.
and, when he prayed unto him, then was he entreated of him, and hearkened unto his supplication, and brought him back to Jerusalem, unto his own kingdom, and so Manasseh came to know, that, Yahweh, is God.
14 Ǹjẹ́ lẹ́yìn èyí, ó mọ odi kan lẹ́yìn ìlú Dafidi, ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Gihoni, ní àfonífojì, àní ní àtiwọ ẹnu ibodè ẹja, ó sì yí orí òkè Ofeli ká; ó sì mọ ọ́n ga sókè gidigidi, ó sì fi balógun sínú gbogbo ìlú olódi Juda wọ̀n-ọn-nì.
And, after this, he built an outer wall to the city of David on the west of the Gihon in the ravine, even to the entering in through the fish-gate, and went round to Ophel, and carried it up very high, —and put captains of valour in all the fortified cities, throughout Judah.
15 Ó pa gbogbo àwọn Ọlọ́run àjèjì run. Ó sì hú gbogbo àwọn ère kúrò nínú ilé Olúwa, pẹ̀lú gbogbo àwọn pẹpẹ tí ó ti kọ́ ní òkè ilé Olúwa àti ní Jerusalẹmu; ó sì kó wọn jáde kúrò nínú ìlú.
And he removed the gods of the foreigner and the image, out of the house of Yahweh, and all the altars that he had built in the mountain of the house of Yahweh, and in Jerusalem, —and he cast them forth outside the city.
16 Nígbà náà ni ó mú àwọn pẹpẹ padà bọ̀ sípò. Ó sì rú ọrẹ ìdàpọ̀ àti ọrẹ-ọpẹ́ lórí rẹ̀. Ó sì sọ fún Juda láti sin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
And he built the altar of Yahweh, and sacrificed thereon peace-offerings, and thanksgiving sacrifices, -and gave word to Judah to serve Yahweh, God of Israel.
17 Àwọn ènìyàn, ko tẹ̀síwájú láti máa rú ẹbọ ní àwọn ibi gíga. Ṣùgbọ́n sí Olúwa Ọlọ́run wọn nìkan.
Howbeit, still were, the people, sacrificing in the high places, —only unto Yahweh their God.
18 Àwọn iṣẹ́ yòókù ti ìjọba Manase pẹ̀lú àdúrà rẹ̀ sí Ọlọ́run rẹ̀ àti àwọn ọ̀rọ̀ tí àwọn aríran sọ sí i ní orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, wà nínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli.
But, the rest of the story of Manasseh, and his prayer unto his God, and the story of the seers who spake unto him in the name of Yahweh God of Israel, there they are, in the story of the kings of Israel:
19 Àdúrà rẹ̀ àti bí inú Ọlọ́run ṣe dùn sí àdúrà rẹ̀ àti gbogbo àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ àti àìṣòótọ́, àti àwọn òpó níbi tí ó kọ́ àwọn ibi gíga sí, ó sì gbé àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà kí ó tó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, gbogbo rẹ̀ ni a kọ sínú ìwé ìrántí àwọn aríran.
both his prayer and how [God] was entreated of him—and all his sin and his treacherous act, and the sites whereon he built high places, and set up the Sacred Stems and the images, before he humbled himself, there they are, written in the story of the seers.
20 Manase sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín sínú ààfin rẹ̀. Amoni ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
And Manasseh slept with his fathers, and they buried him in the garden off his own house, —and Amon his son reigned in his stead.
21 Amoni jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjì.
Twenty-two years old, was Amon when he began to reign, —and, two years, reigned he in Jerusalem.
22 Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Manase ti ṣe. Amoni rú ẹbọ sí gbogbo àwọn òrìṣà tí Manase baba rẹ̀ ti ṣe, ó sì sìn wọ́n.
And he did the thing that was wicked in the eyes of Yahweh, as Manasseh his father had done, —and, unto all the images which Manasseh his father had made, Amon offered sacrifice, and did serve them.
23 Ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i baba rẹ̀ Manase. Kò rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú Olúwa: ṣùgbọ́n ẹ̀ṣẹ̀ Amoni sì ń pọ̀ sì í.
But he did not humble himself before Yahweh as Manasseh his father humbled himself, —for, he, Amon, made guilt abound.
24 Àwọn oníṣẹ́ Amoni dìtẹ̀ sí i. Wọ́n sì pa á ní ààfin rẹ̀.
And his servants conspired against him, and put him to death, in his own house.
25 Nígbà náà, gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pa gbogbo àwọn tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Amoni, wọ́n sì mú Josiah ọmọ rẹ̀ jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
But the people of the land smote all the conspirators against King Amon, —and the people of the land made Josiah his son king in his stead.

< 2 Chronicles 33 >