< 2 Chronicles 32 >
1 Lẹ́yìn gbogbo èyí ti Hesekiah ti fi òtítọ́ ṣe, Sennakeribu ọba Asiria wá ó sì gbógun ti Juda. Ó gbógun ti àwọn ìlú ààbò, ó ń ronú láti ṣẹ́gun wọn fún ara rẹ̀.
Дупэ ачесте лукрурь ши дупэ ачесте фапте де крединчошие, а венит Санхериб, ымпэратул Асирией, каре а пэтрунс ын Иуда ши а ымпресурат четэциле ынтэрите, ку гынд сэ пунэ мына пе еле.
2 Nígbà tí Hesekiah rí i pé Sennakeribu ti wá, àti pé ó fẹ́ láti dá ogun sílẹ̀ lórí Jerusalẹmu,
Езекия, вэзынд кэ а венит Санхериб ши кэ аре де гынд сэ ынчапэ лупта ымпотрива Иерусалимулуй,
3 Ó gbèrò pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ láti di orísun omi ní ìta ìlú ńlá, wọ́n sì ràn án lọ́wọ́.
с-а сфэтуит ку кэпетенииле сале ши ку оамений луй чей витежь ка сэ аступе извоареле де апэ каре ерау афарэ дин четате. Ши ей ау фост де пэреря луй.
4 Ọ̀pọ̀ ogun ọkùnrin péjọ, wọ́n sì dí gbogbo àwọn orísun àti àwọn omi tó ń sàn tí ó ń sàn gba ti ilẹ̀ náà. “Kí ni ó dé tí àwọn ọba Asiria fi wá tí wọ́n sì rí ọ̀pọ̀ omi?” Wọ́n wí.
С-ау стрынс о мулциме де оамень ши ау аступат тоате извоареле ши пырыул каре курӂе прин мижлокул цинутулуй ачелуя. „Пентру че”, зичяу ей, „сэ гэсяскэ ымпэраций Асирией, ла вениря лор, апе дин белшуг?”
5 Nígbà náà ó ṣiṣẹ́ gidigidi ní títún gbogbo ara ògiri tí ó ti bàjẹ́ ṣe, ó sì ń kọ́ àwọn ilé ìṣọ́ gíga sókè rẹ̀. Ó kọ́ ògiri mìíràn sí ìta. Ó sì tún pẹ̀lú ibi ìtẹ́jú ilé ní ti ìlú ńlá Dafidi. Ó ṣe ọ̀pọ̀ iye ohun ìjà àti àwọn àpáta.
Езекия с-а ымбэрбэтат; а зидит дин ноу зидул каре ера стрикат ши л-а ридикат пынэ ла турнурь. А май зидит ун алт зид ын афарэ, а ынтэрит Мило, ын четатя луй Давид, ши а прегэтит о мулциме де арме ши де скутурь.
6 Ó yan àwọn ìjòyè ológun sórí àwọn ènìyàn, ó sì pè wọ́n jọ, níwájú rẹ̀ ní ìbámu ní ìlú ńlá ti Dafidi. Ó sì ki wọ́n láyà pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí:
А пус кэпетений де рэзбой песте попор ши ле-а адунат ла ел пе локул дескис де ла поарта четэций. Ворбинду-ле инимий, а зис:
7 “Ẹ jẹ́ alágbára, àti kí ẹ sì ní ìgboyà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù tàbí ní ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn nítorí tí ọba Asiria àti ọ̀pọ̀ ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí agbára ńlá wà pẹ̀lú wa ju òun lọ.
„Ынтэрици-вэ ши ымбэрбэтаци-вэ. Ну вэ темець ши ну вэ ынспэймынтаць ынаинтя ымпэратул Асирией ши ынаинтя ынтреӂий мулцимь каре есте ку ел, кэч ку ной сунт май мулць декыт ку ел.
8 Agbára ẹran-ara nìkan ni ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ṣùgbọ́n, Olúwa Ọlọ́run wa pẹ̀lú wa láti ràn wá lọ́wọ́ àti láti ja ìjà wa.” Àwọn ènìyàn sì ní ìgboyà láti ara ohun tí Hesekiah ọba Juda wí.
Ку ел есте ун брац де карне, дар ку ной есте Домнул Думнезеул ностру, каре не ва ажута ши ва лупта пентру ной.” Попорул а авут ынкредере ын кувинтеле луй Езекия, ымпэратул луй Иуда.
9 Lẹ́yìn ìgbà tí Sennakeribu ọba Asiria àti gbogbo àwọn ogun rẹ̀ ń gbógun sí Lakiṣi. Ó rán àwọn ìjòyè rẹ̀ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú iṣẹ́ yí fún Hesekiah ọba Juda àti fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda tí ó wà níbẹ̀:
Дупэ ачея, Санхериб, ымпэратул Асирией, а тримис пе служиторий сэй ла Иерусалим пе кынд ера ынаинтя Лакисулуй ку тоате путериле луй; й-а тримис ла Езекия, ымпэратул луй Иуда, ши ла тоць чей дин Иуда каре ерау ла Иерусалим сэ ле спунэ:
10 “Èyí ni ohun tí Sennakeribu ọba Asiria wí, ‘Lórí kí ni ẹ̀yin gbé ìgbẹ́kẹ̀lé yín lé, tí ẹ̀yin fi dúró sí Jerusalẹmu lábẹ́ ìgbógun sí?’
„Аша ворбеште Санхериб, ымпэратул Асирией: ‘Пе че се бизуеште ынкредеря воастрэ, де стаць ымпресураць ла Иерусалим?
11 Nígbà tí Hesekiah wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run wa yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ ọba Asiria,’ ó ń ṣì yín tọ́ ṣọ́nà, kí ẹ bá lè kú fún ebi àti òǹgbẹ.
Оаре ну вэ амэӂеште Езекия, ка сэ вэ дя морций прин фоамете ши прин сете, кынд зиче: «Домнул Думнезеул ностру не ва скэпа дин мына ымпэратулуй Асирией»?
12 Ṣé Hesekiah fúnra rẹ̀ kò mú àwọn ọlọ́run ibi gíga àti àwọn pẹpẹ kúrò, tí ó ń wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ kan àti láti sun àwọn ẹbọ lórí rẹ̀’?
Оаре ну Езекия а ындепэртат ынэлцимиле ши алтареле Домнулуй ши а дат порунка ачаста луй Иуда ши Иерусалимулуй: «Сэ вэ ынкинаць нумай унуй алтар ши сэ адучець тэмые нумай пе ел»?
13 “Ṣé ẹ̀yin kò mọ̀ ohun tí èmi àti àwọn baba mi ti ṣe sí gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn? Ǹjẹ́ àwọn Ọlọ́run tí àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn ní agbára láti gba ilẹ̀ wọn kúrò lọ́wọ́ mi?
Ну штиць че ам фэкут ной, еу ши пэринций мей, тутурор попоарелор челорлалте цэрь? Думнезеий нямурилор ачестор цэрь ау путут ей сэ ле избэвяскэ цэриле дин мына мя?
14 Ta ni nínú gbogbo àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè wọ̀nyí tí àwọn baba mi ti parun, tí ó le gbà ènìyàn rẹ̀ lọ́wọ́ mi, tí Ọlọ́run yín yóò fi le gbà yín lọ́wọ́ mi?
Каре динтре тоць думнезеий ачестор нямурь пе каре ле-ау нимичит пэринций мей а путут сэ избэвяскэ пе попорул луй дин мына мя, пентру ка сэ вэ поатэ избэви Думнезеул востру дин мына мя?
15 Nísinsin yìí, ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah ó tàn yín àti ṣì yín tọ́ ṣọ́nà báyìí. Ẹ má ṣe gbà á gbọ́, nítorí tí kò sí ọlọ́run orílẹ̀-èdè mìíràn tàbí ìjọba tí ó ní agbára láti gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi tàbí lọ́wọ́ àwọn baba mi, mélòó mélòó wa ni Ọlọ́run yín tí yóò gbà yín kúrò lọ́wọ́ mi!”
Сэ ну вэ амэӂяскэ Езекия дар ши сэ ну вэ ыншеле астфел; ну вэ ынкредець ын ел! Кэч думнезеул ничунуй ням, ничуней ымпэрэций н-а путут сэ избэвяскэ пе попорул луй дин мына мя ши дин мына пэринцилор мей: ку кыт май пуцин вэ ва избэви Думнезеул востру дин мына мя!’”
16 Àwọn ìjòyè Sennakeribu sọ̀rọ̀ síwájú sí i ní ìlòdì sí Olúwa Ọlọ́run àti sí ìránṣẹ́ rẹ̀ Hesekiah.
Служиторий луй Санхериб ау май ворбит ши алте лукрурь ымпотрива Домнулуй Думнезеу ши ымпотрива робулуй Сэу Езекия.
17 Ọba pẹ̀lú sì kọ àwọn ìwé ní bíbú Olúwa Ọlọ́run Israẹli àti ní sísọ èyí ní ìlòdì sí: “Ní gẹ́gẹ́ bí àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn kò ṣe gba àwọn ènìyàn wọn kúrò lọ́wọ́ mi. Bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run Hesekiah kì yóò gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi.”
Ши а тримис о скрисоаре батжокоритоаре пентру Домнул Думнезеул луй Исраел, ворбинд астфел ымпотрива Луй: „Дупэ кум думнезеий нямурилор челорлалте цэрь н-ау путут сэ избэвяскэ пе попорул лор дин мына мя, тот аша нич Думнезеул луй Езекия ну ва избэви пе попорул Сэу дин мына мя.”
18 Lẹ́yìn náà wọ́n pè jáde ní èdè Heberu sí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu tí ó wà lára ògiri, láti dá ọjọ́ fún wọn, ki wọn kí ó lè fi agbára mú ìlú náà.
Служиторий луй Санхериб ау стригат ку глас таре ын лимба евреяскэ, пентру ка сэ арунче гроаза ши спайма ын попорул дин Иерусалим, каре ера пе зид, ши сэ поатэ пуне астфел стэпынире пе четате.
19 Wọ́n sọ̀rọ̀ nípa Ọlọ́run Jerusalẹmu bí wọ́n ti ṣe nípa àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn mìíràn ti àgbáyé, iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn.
Ау ворбит деспре Думнезеул Иерусалимулуй ка деспре думнезеий попоарелор пэмынтулуй, каре сунт лукраря мынилор оменешть.
20 Ọba Hesekiah àti wòlíì Isaiah ọmọ Amosi sọkún jáde nínú àdúrà sí ọ̀run nípa èyí.
Ымпэратул Езекия ши пророкул Исая, фиул луй Амоц, ау ынчепут сэ се роаӂе пентру лукрул ачеста ши ау стригат кэтре чер.
21 Olúwa sì ran angẹli tí ó pa gbogbo àwọn ọmọ-ogun àti àwọn adarí àti àwọn ìjòyè tí ó wà nínú àgọ́ ọba Asiria run. Bẹ́ẹ̀ ni ó padà sí ilẹ̀ rẹ̀ ní ìtìjú. Nígbà tí ó sì lọ sínú ilé ọlọ́run rẹ̀, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ rẹ̀ gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.
Атунч, Домнул а тримис ун ынӂер каре а нимичит ын табэра ымпэратулуй Асирией пе тоць витежий, домниторий ши кэпетенииле. Ши ымпэратул с-а ынторс рушинат ын цара луй. А интрат ын каса думнезеулуй сэу, ши чей че ешисерэ дин коапселе луй л-ау учис аколо ку сабия.
22 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yọ Hesekiah àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ Sennakeribu ọba Asiria àti lọ́wọ́ gbogbo àwọn mìíràn. Ó tọ́jú wọn ní gbogbo ọ̀nà.
Астфел а скэпат Домнул пе Езекия ши пе локуиторий Иерусалимулуй дин мына луй Санхериб, ымпэратул Асирией, ши дин мына тутурор ши й-а окротит ымпотрива челор че-й ымпресурау.
23 Ọ̀pọ̀ mú ọrẹ wá sí Jerusalẹmu fún Olúwa àti àwọn ẹ̀bùn iyebíye fún Hesekiah ọba Juda. Ó sì gbéga lójú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè lẹ́yìn náà.
Мулць ау адус Домнулуй дарурь ын Иерусалим ши ау адус дарурь богате луй Езекия, ымпэратул луй Иуда, каре де атунч с-а ынэлцат ын окий тутурор попоарелор.
24 Ní ọjọ́ wọ́n nì Hesekiah ṣe àárẹ̀, ó sì dójú ikú. Ó gbàdúrà sí Olúwa tí ó dá a lóhùn, tí ó sì fún un ní àmì àgbàyanu.
Ын время ачея, Езекия а фост болнав де моарте. Ел а фэкут о ругэчуне Домнулуй. Домнул й-а ворбит ши й-а дат ун семн.
25 Ṣùgbọ́n ọkàn Hesekiah ṣe ìgbéraga, kò sì kọbi ara sí i inú rere tí a fihàn án. Nítorí náà, ìbínú Olúwa wà lórí rẹ̀ àti lórí Juda àti Jerusalẹmu.
Дар Езекия н-а рэсплэтит бинефачеря пе каре а примит-о, кэч и с-а ынгымфат инима. Мыния Домнулуй а венит песте ел, песте Иуда ши песте Иерусалим.
26 Nígbà náà ni Hesekiah ronúpìwàdà ní ti ìgbéraga ọkàn rẹ̀, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu sì ṣe bẹ́ẹ̀, nítorí náà, ìbínú Olúwa kò wá sí orí wọn ní ìgbà àwọn ọjọ́ Hesekiah.
Атунч, Езекия с-а смерит дин мындрия луй, ымпреунэ ку локуиторий Иерусалимулуй, ши мыния Домнулуй н-а венит песте ей ын тимпул веций луй Езекия.
27 Hesekiah ní ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ńlá àti ọlá, ó sì ṣe àwọn ilé ìṣúra fún fàdákà àti wúrà rẹ̀ àti fún àwọn òkúta iyebíye rẹ̀, àwọn tùràrí olóòórùn dídùn àwọn àpáta àti gbogbo oríṣìí nǹkan iyebíye.
Езекия а авут мулте богэций ши мултэ славэ. Шь-а фэкут вистиерий де арӂинт, де аур, де петре скумпе, де миродений, де скутурь ши де тоате лукруриле каре се пот дори;
28 Ó kọ́ àwọn ilé pẹ̀lú láti tọ́jú àwọn ọkà àwọn tí wọ́n ka, ọtí tuntun àti òróró; ó sì ṣe àwọn àtíbàbà fún oríṣìí àwọn ẹran ọ̀sìn àti àwọn àṣémọ́ fun àwọn ọ̀wọ̀ ẹran.
хамбаре пентру роаделе де грыу, де муст ши де унтделемн, граждурь пентру тот фелул де вите ши стауле пентру ой.
29 Ó kọ́ àwọn ìletò, ó sì gba ọ̀pọ̀ àwọn ọ̀wọ́ ẹran àti agbo ẹran, nítorí tí Ọlọ́run ti fún un ní ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ńlá.
Шь-а зидит четэць ши а авут белшуг де бой ши де ой, кэч Думнезеу ый дэдусе мулте авуций.
30 Hesekiah ni ó dí ojú ìṣúra apá òkè ti orísun Gihoni. Ó sì gbe gba ìsàlẹ̀ sí ìhà ìwọ oòrùn ìlú ńlá ti Dafidi. Ó ṣe àṣeyọrí rere nínú gbogbo ohun tí ó dáwọ́lé.
Тот Езекия а аступат ши гура де сус а апелор Гихон ши ле-а адус ын жос, спре апус де четатя луй Давид. Езекия а избутит ын тоате лукрэриле луй.
31 Ṣùgbọ́n nígbà tí a rán àwọn oníṣẹ́ ọba wá láti Babeli láti bi í lérè nípa àmì ìyanu tí ó ṣẹlẹ̀ nì, Ọlọ́run fi sílẹ̀ láti dán an wò àti láti mọ gbogbo nǹkan tí ó wà lọ́kàn rẹ̀.
Ынсэ, кынд ау тримис кэпетенииле Бабилонулуй соль ла ел сэ ынтребе де минуня каре авусесе лок ын царэ, Думнезеу л-а пэрэсит ка сэ-л ынчерче, пентру ка сэ куноаскэ тот че ера ын инима луй.
32 Gbogbo iṣẹ́ yòókù ti ìjọba Hesekiah àti àwọn ìṣe rẹ̀, ìfarajì rẹ̀ ni a kọ sínú ìwé ìran wòlíì Isaiah ọmọ Amosi nínú ìwé àwọn ọba Juda àti Israẹli
Челелалте фапте але луй Езекия ши фаптеле луй евлавиоасе сунт скрисе ын ведения пророкулуй Исая, фиул луй Амоц, ын картя ымпэрацилор луй Иуда ши Исраел.
33 Hesekiah sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. A sì sin ín sórí òkè níbi tí àwọn ibojì àwọn àtẹ̀lé Dafidi wà. Gbogbo Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ni ó bu ọlá fún un nígbà tí ó kú. Manase ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Езекия а адормит ку пэринций сэй ши л-ау ынгропат ын чел май бун лок ал морминтелор фиилор луй Давид. Тот Иуда ши локуиторий Иерусалимулуй й-ау дат чинсте ла моарте. Ши, ын локул луй, а домнит фиул сэу Манасе.