< 2 Chronicles 32 >

1 Lẹ́yìn gbogbo èyí ti Hesekiah ti fi òtítọ́ ṣe, Sennakeribu ọba Asiria wá ó sì gbógun ti Juda. Ó gbógun ti àwọn ìlú ààbò, ó ń ronú láti ṣẹ́gun wọn fún ara rẹ̀.
După aceste lucruri și întemeierea lor, Sanherib, împăratul Asiriei, a venit și a intrat în Iuda și a așezat tabăra împotriva cetăților întărite și se hotărî a le lua pentru el însuși.
2 Nígbà tí Hesekiah rí i pé Sennakeribu ti wá, àti pé ó fẹ́ láti dá ogun sílẹ̀ lórí Jerusalẹmu,
Și când Ezechia a văzut că Sanherib a venit și că era hotărât să lupte împotriva Ierusalimului,
3 Ó gbèrò pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ láti di orísun omi ní ìta ìlú ńlá, wọ́n sì ràn án lọ́wọ́.
A ținut sfat cu prinții lui și războinicii lui să oprească apele izvoarelor care erau în afara cetății, și ei l-au ajutat.
4 Ọ̀pọ̀ ogun ọkùnrin péjọ, wọ́n sì dí gbogbo àwọn orísun àti àwọn omi tó ń sàn tí ó ń sàn gba ti ilẹ̀ náà. “Kí ni ó dé tí àwọn ọba Asiria fi wá tí wọ́n sì rí ọ̀pọ̀ omi?” Wọ́n wí.
Astfel s-a adunat mult popor, care a oprit toate izvoarele și pârâul care trecea prin mijlocul țării, spunând: De ce să vină împăratul Asiriei și să găsească multă apă?
5 Nígbà náà ó ṣiṣẹ́ gidigidi ní títún gbogbo ara ògiri tí ó ti bàjẹ́ ṣe, ó sì ń kọ́ àwọn ilé ìṣọ́ gíga sókè rẹ̀. Ó kọ́ ògiri mìíràn sí ìta. Ó sì tún pẹ̀lú ibi ìtẹ́jú ilé ní ti ìlú ńlá Dafidi. Ó ṣe ọ̀pọ̀ iye ohun ìjà àti àwọn àpáta.
De asemenea s-a întărit și a construit tot zidul care era dărâmat și l-a ridicat până la turnuri și un alt zid în afară și a reparat Milo în cetatea lui David și a făcut lănci și scuturi în abundență.
6 Ó yan àwọn ìjòyè ológun sórí àwọn ènìyàn, ó sì pè wọ́n jọ, níwájú rẹ̀ ní ìbámu ní ìlú ńlá ti Dafidi. Ó sì ki wọ́n láyà pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí:
Și a așezat căpetenii de război peste popor și i-a adunat la el în strada porții cetății și le-a vorbit inimilor, spunând:
7 “Ẹ jẹ́ alágbára, àti kí ẹ sì ní ìgboyà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù tàbí ní ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn nítorí tí ọba Asiria àti ọ̀pọ̀ ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí agbára ńlá wà pẹ̀lú wa ju òun lọ.
Fiți tari și curajoși, nu vă temeți nici nu vă descurajați din cauza împăratului Asiriei, nici din cauza întregii mulțimi care este cu el, fiindcă sunt mai mulți cu noi decât cu el;
8 Agbára ẹran-ara nìkan ni ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ṣùgbọ́n, Olúwa Ọlọ́run wa pẹ̀lú wa láti ràn wá lọ́wọ́ àti láti ja ìjà wa.” Àwọn ènìyàn sì ní ìgboyà láti ara ohun tí Hesekiah ọba Juda wí.
Cu el este un braț de carne, dar cu noi este DOMNUL Dumnezeul nostru să ne ajute și să lupte bătăliile noastre. Și poporul s-a sprijinit pe cuvintele lui Ezechia, împăratul lui Iuda.
9 Lẹ́yìn ìgbà tí Sennakeribu ọba Asiria àti gbogbo àwọn ogun rẹ̀ ń gbógun sí Lakiṣi. Ó rán àwọn ìjòyè rẹ̀ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú iṣẹ́ yí fún Hesekiah ọba Juda àti fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda tí ó wà níbẹ̀:
După aceasta, Sanherib, împăratul Asiriei, a trimis pe servitorii lui la Ierusalim, (dar el însuși a asediat Lachis și toată puterea lui cu el), la Ezechia, împăratul lui Iuda, și la tot Iuda care era la Ierusalim, spunând:
10 “Èyí ni ohun tí Sennakeribu ọba Asiria wí, ‘Lórí kí ni ẹ̀yin gbé ìgbẹ́kẹ̀lé yín lé, tí ẹ̀yin fi dúró sí Jerusalẹmu lábẹ́ ìgbógun sí?’
Astfel spune Sanherib, împăratul Asiriei: În ce vă încredeți, că stați asediați în Ierusalim?
11 Nígbà tí Hesekiah wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run wa yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ ọba Asiria,’ ó ń ṣì yín tọ́ ṣọ́nà, kí ẹ bá lè kú fún ebi àti òǹgbẹ.
Nu v-a convins Ezechia să vă dați morții prin foame și sete, spunând: DOMNUL Dumnezeul nostru ne va elibera din mâna împăratului Asiriei?
12 Ṣé Hesekiah fúnra rẹ̀ kò mú àwọn ọlọ́run ibi gíga àti àwọn pẹpẹ kúrò, tí ó ń wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ kan àti láti sun àwọn ẹbọ lórí rẹ̀’?
Nu a îndepărtat același Ezechia înălțimile și altarele lui și a poruncit lui Iuda și Ierusalimului, spunând: Vă veți închina înaintea unui singur altar și veți arde tămâie pe el?
13 “Ṣé ẹ̀yin kò mọ̀ ohun tí èmi àti àwọn baba mi ti ṣe sí gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn? Ǹjẹ́ àwọn Ọlọ́run tí àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn ní agbára láti gba ilẹ̀ wọn kúrò lọ́wọ́ mi?
Nu știți ce am făcut eu și părinții mei tuturor popoarelor din alte țări? Au fost dumnezeii națiunilor acelor țări în stare în vreun fel să elibereze țările lor din mâna mea?
14 Ta ni nínú gbogbo àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè wọ̀nyí tí àwọn baba mi ti parun, tí ó le gbà ènìyàn rẹ̀ lọ́wọ́ mi, tí Ọlọ́run yín yóò fi le gbà yín lọ́wọ́ mi?
Cine a fost în stare, printre toți dumnezeii acelor națiuni pe care părinții mei le-au nimicit în întregime, să elibereze poporul lui din mâna mea, încât Dumnezeul vostru să fie în stare să vă elibereze din mâna mea?
15 Nísinsin yìí, ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah ó tàn yín àti ṣì yín tọ́ ṣọ́nà báyìí. Ẹ má ṣe gbà á gbọ́, nítorí tí kò sí ọlọ́run orílẹ̀-èdè mìíràn tàbí ìjọba tí ó ní agbára láti gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi tàbí lọ́wọ́ àwọn baba mi, mélòó mélòó wa ni Ọlọ́run yín tí yóò gbà yín kúrò lọ́wọ́ mi!”
Și acum nu lăsați pe Ezechia să vă înșele sau să vă convingă în acest fel, nici să nu îl credeți, fiindcă niciun dumnezeu al vreunei națiuni sau împărății nu a fost în stare să elibereze pe poporul său din mâna mea și din mâna părinților mei, cu cât mai puțin Dumnezeul vostru vă va elibera din mâna mea!
16 Àwọn ìjòyè Sennakeribu sọ̀rọ̀ síwájú sí i ní ìlòdì sí Olúwa Ọlọ́run àti sí ìránṣẹ́ rẹ̀ Hesekiah.
Și servitorii lui au vorbit și mai mult împotriva DOMNULUI Dumnezeu și împotriva servitorului său, Ezechia.
17 Ọba pẹ̀lú sì kọ àwọn ìwé ní bíbú Olúwa Ọlọ́run Israẹli àti ní sísọ èyí ní ìlòdì sí: “Ní gẹ́gẹ́ bí àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn kò ṣe gba àwọn ènìyàn wọn kúrò lọ́wọ́ mi. Bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run Hesekiah kì yóò gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi.”
El a scris de asemenea scrisori să defaime pe DOMNUL Dumnezeul lui Israel și să vorbească împotriva lui, spunând: Precum dumnezeii națiunilor altor țări nu au eliberat poporul lor din mâna mea, tot astfel Dumnezeul lui Ezechia nu va elibera pe poporul său din mâna mea.
18 Lẹ́yìn náà wọ́n pè jáde ní èdè Heberu sí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu tí ó wà lára ògiri, láti dá ọjọ́ fún wọn, ki wọn kí ó lè fi agbára mú ìlú náà.
Atunci au strigat cu voce tare în limba evreilor către poporul din Ierusalim care era pe zid, să îi înspăimânte și să îi tulbure, ca să poată lua cetatea.
19 Wọ́n sọ̀rọ̀ nípa Ọlọ́run Jerusalẹmu bí wọ́n ti ṣe nípa àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn mìíràn ti àgbáyé, iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn.
Și au vorbit împotriva Dumnezeului Ierusalimului, ca împotriva dumnezeilor oamenilor pământului, cei făcuți prin lucrarea mâinilor omului.
20 Ọba Hesekiah àti wòlíì Isaiah ọmọ Amosi sọkún jáde nínú àdúrà sí ọ̀run nípa èyí.
Și din această cauză împăratul Ezechia și profetul Isaia, fiul lui Amoț, s-au rugat și au strigat către cer.
21 Olúwa sì ran angẹli tí ó pa gbogbo àwọn ọmọ-ogun àti àwọn adarí àti àwọn ìjòyè tí ó wà nínú àgọ́ ọba Asiria run. Bẹ́ẹ̀ ni ó padà sí ilẹ̀ rẹ̀ ní ìtìjú. Nígbà tí ó sì lọ sínú ilé ọlọ́run rẹ̀, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ rẹ̀ gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.
Și DOMNUL a trimis un înger, care a stârpit pe toți războinicii viteji și conducătorii și căpeteniile din tabăra împăratului Asiriei. Astfel el s-a întors cu rușine pe față în propria lui țară. Și când a intrat în casa dumnezeului său, cei care au ieșit din propriile lui adâncuri l-au ucis acolo cu sabia.
22 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yọ Hesekiah àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ Sennakeribu ọba Asiria àti lọ́wọ́ gbogbo àwọn mìíràn. Ó tọ́jú wọn ní gbogbo ọ̀nà.
Astfel DOMNUL a salvat pe Ezechia și pe locuitorii Ierusalimului din mâna lui Sanherib, împăratul Asiriei, și din mâna tuturor celorlalți și i-a călăuzit de fiecare parte.
23 Ọ̀pọ̀ mú ọrẹ wá sí Jerusalẹmu fún Olúwa àti àwọn ẹ̀bùn iyebíye fún Hesekiah ọba Juda. Ó sì gbéga lójú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè lẹ́yìn náà.
Și mulți au adus ofrande DOMNULUI la Ierusalim și daruri lui Ezechia, împăratul lui Iuda, astfel încât el a fost preamărit înaintea ochilor tuturor națiunilor de atunci înainte.
24 Ní ọjọ́ wọ́n nì Hesekiah ṣe àárẹ̀, ó sì dójú ikú. Ó gbàdúrà sí Olúwa tí ó dá a lóhùn, tí ó sì fún un ní àmì àgbàyanu.
În acele zile Ezechia era bolnav de moarte și s-a rugat DOMNULUI, iar el i-a vorbit și i-a dat un semn.
25 Ṣùgbọ́n ọkàn Hesekiah ṣe ìgbéraga, kò sì kọbi ara sí i inú rere tí a fihàn án. Nítorí náà, ìbínú Olúwa wà lórí rẹ̀ àti lórí Juda àti Jerusalẹmu.
Dar Ezechia nu a răsplătit conform bunătății făcute lui, fiindcă inima lui s-a înălțat; de aceea a fost furie asupra lui și asupra lui Iuda și Ierusalimului.
26 Nígbà náà ni Hesekiah ronúpìwàdà ní ti ìgbéraga ọkàn rẹ̀, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu sì ṣe bẹ́ẹ̀, nítorí náà, ìbínú Olúwa kò wá sí orí wọn ní ìgbà àwọn ọjọ́ Hesekiah.
Totuși Ezechia s-a umilit pentru mândria din inima lui, deopotrivă el și locuitorii Ierusalimului, astfel încât furia DOMNULUI nu a venit asupra lor în zilele lui Ezechia.
27 Hesekiah ní ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ńlá àti ọlá, ó sì ṣe àwọn ilé ìṣúra fún fàdákà àti wúrà rẹ̀ àti fún àwọn òkúta iyebíye rẹ̀, àwọn tùràrí olóòórùn dídùn àwọn àpáta àti gbogbo oríṣìí nǹkan iyebíye.
Și Ezechia a avut foarte multe bogății și onoare; și și-a făcut tezaure pentru argint și pentru aur și pentru pietre prețioase și pentru mirodenii și pentru scuturi și pentru tot felul de bijuterii de dorit;
28 Ó kọ́ àwọn ilé pẹ̀lú láti tọ́jú àwọn ọkà àwọn tí wọ́n ka, ọtí tuntun àti òróró; ó sì ṣe àwọn àtíbàbà fún oríṣìí àwọn ẹran ọ̀sìn àti àwọn àṣémọ́ fun àwọn ọ̀wọ̀ ẹran.
Depozite de asemenea pentru venitul din grâne și vin și untdelemn, și iesle pentru tot felul de animale și îngrădituri pentru turme.
29 Ó kọ́ àwọn ìletò, ó sì gba ọ̀pọ̀ àwọn ọ̀wọ́ ẹran àti agbo ẹran, nítorí tí Ọlọ́run ti fún un ní ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ńlá.
Mai mult, și-a făcut cetăți și averi de turme și cirezi din abundență: fiindcă Dumnezeu i-a dat foarte multă bogăție.
30 Hesekiah ni ó dí ojú ìṣúra apá òkè ti orísun Gihoni. Ó sì gbe gba ìsàlẹ̀ sí ìhà ìwọ oòrùn ìlú ńlá ti Dafidi. Ó ṣe àṣeyọrí rere nínú gbogbo ohun tí ó dáwọ́lé.
Și Ezechia, el însuși, a oprit cursul superior al apei Ghihon și l-a adus drept în jos spre partea de vest a cetății lui David. Și Ezechia a prosperat în toate lucrările lui.
31 Ṣùgbọ́n nígbà tí a rán àwọn oníṣẹ́ ọba wá láti Babeli láti bi í lérè nípa àmì ìyanu tí ó ṣẹlẹ̀ nì, Ọlọ́run fi sílẹ̀ láti dán an wò àti láti mọ gbogbo nǹkan tí ó wà lọ́kàn rẹ̀.
Totuși în privința ambasadorilor prinților Babilonului, care au trimis la el să întrebe despre minunea care a fost făcută în țară, Dumnezeu l-a părăsit, să îl încerce, ca să cunoască tot ceea ce era în inima lui.
32 Gbogbo iṣẹ́ yòókù ti ìjọba Hesekiah àti àwọn ìṣe rẹ̀, ìfarajì rẹ̀ ni a kọ sínú ìwé ìran wòlíì Isaiah ọmọ Amosi nínú ìwé àwọn ọba Juda àti Israẹli
Și restul faptelor lui Ezechia și bunătatea lui, iată, sunt scrise în viziunea profetului Isaia, fiul lui Amoț, și în cartea împăraților lui Iuda și Israel.
33 Hesekiah sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. A sì sin ín sórí òkè níbi tí àwọn ibojì àwọn àtẹ̀lé Dafidi wà. Gbogbo Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ni ó bu ọlá fún un nígbà tí ó kú. Manase ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Și Ezechia a adormit cu părinții săi și l-au îngropat în cel mai însemnat dintre mormintele fiilor lui David; și tot Iuda și locuitorii Ierusalimului l-au onorat la moartea lui. Și Manase, fiul său, a domnit în locul său.

< 2 Chronicles 32 >