< 2 Chronicles 32 >

1 Lẹ́yìn gbogbo èyí ti Hesekiah ti fi òtítọ́ ṣe, Sennakeribu ọba Asiria wá ó sì gbógun ti Juda. Ó gbógun ti àwọn ìlú ààbò, ó ń ronú láti ṣẹ́gun wọn fún ara rẹ̀.
Po tych sprawach oraz ich ustanowieniu nadciągnął Sennacheryb, król Asyrii, wkroczył do Judy, rozbił obóz naprzeciwko warownych miast i zamierzał je zdobyć dla siebie.
2 Nígbà tí Hesekiah rí i pé Sennakeribu ti wá, àti pé ó fẹ́ láti dá ogun sílẹ̀ lórí Jerusalẹmu,
Gdy Ezechiasz zobaczył, że nadciągnął Sennacheryb i że ma zamiar walczyć przeciw Jerozolimie;
3 Ó gbèrò pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ láti di orísun omi ní ìta ìlú ńlá, wọ́n sì ràn án lọ́wọ́.
Naradzał się ze swoimi książętami i wojownikami, aby zatkać źródła wód, które [były] za miastem, a oni pomogli mu.
4 Ọ̀pọ̀ ogun ọkùnrin péjọ, wọ́n sì dí gbogbo àwọn orísun àti àwọn omi tó ń sàn tí ó ń sàn gba ti ilẹ̀ náà. “Kí ni ó dé tí àwọn ọba Asiria fi wá tí wọ́n sì rí ọ̀pọ̀ omi?” Wọ́n wí.
Zebrał się więc wielki lud, który zatkał wszystkie źródła oraz potok płynący przez środek ziemi, mówiąc: Czemu nadciągający królowie Asyrii mieliby znaleźć tak wiele wody?
5 Nígbà náà ó ṣiṣẹ́ gidigidi ní títún gbogbo ara ògiri tí ó ti bàjẹ́ ṣe, ó sì ń kọ́ àwọn ilé ìṣọ́ gíga sókè rẹ̀. Ó kọ́ ògiri mìíràn sí ìta. Ó sì tún pẹ̀lú ibi ìtẹ́jú ilé ní ti ìlú ńlá Dafidi. Ó ṣe ọ̀pọ̀ iye ohun ìjà àti àwọn àpáta.
Pokrzepił się i odbudował cały zburzony mur, wznosząc go aż do wież, do tego drugi zewnętrzny mur. Umocnił także Millo w mieście Dawida i sporządził wiele włóczni oraz tarcz.
6 Ó yan àwọn ìjòyè ológun sórí àwọn ènìyàn, ó sì pè wọ́n jọ, níwájú rẹ̀ ní ìbámu ní ìlú ńlá ti Dafidi. Ó sì ki wọ́n láyà pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí:
Ustanowił też dowódców wojska nad ludem, których zgromadził przy sobie na placu bramy miejskiej, i mówił do nich łagodnie:
7 “Ẹ jẹ́ alágbára, àti kí ẹ sì ní ìgboyà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù tàbí ní ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn nítorí tí ọba Asiria àti ọ̀pọ̀ ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí agbára ńlá wà pẹ̀lú wa ju òun lọ.
Umacniajcie się i bądźcie mężni, nie bójcie się ani nie lękajcie widoku króla Asyrii ani widoku całego mnóstwa, które jest z nim. Więcej bowiem jest z nami aniżeli z nim.
8 Agbára ẹran-ara nìkan ni ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ṣùgbọ́n, Olúwa Ọlọ́run wa pẹ̀lú wa láti ràn wá lọ́wọ́ àti láti ja ìjà wa.” Àwọn ènìyàn sì ní ìgboyà láti ara ohun tí Hesekiah ọba Juda wí.
Z nim jest ramię cielesne, lecz z nami jest PAN, nasz Bóg, aby nam pomóc, ratować [nas] i prowadzić nasze wojny. Lud więc zaufał słowom Ezechiasza, króla Judy.
9 Lẹ́yìn ìgbà tí Sennakeribu ọba Asiria àti gbogbo àwọn ogun rẹ̀ ń gbógun sí Lakiṣi. Ó rán àwọn ìjòyè rẹ̀ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú iṣẹ́ yí fún Hesekiah ọba Juda àti fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda tí ó wà níbẹ̀:
Potem Sennacheryb, król Asyrii, podczas gdy zdobywał Lakisz wraz z całym swoim wojskiem, posłał swoje sługi do Jerozolimy, do Ezechiasza, króla Judy, oraz do wszystkich z Judy, którzy byli w Jerozolimie, aby oznajmić:
10 “Èyí ni ohun tí Sennakeribu ọba Asiria wí, ‘Lórí kí ni ẹ̀yin gbé ìgbẹ́kẹ̀lé yín lé, tí ẹ̀yin fi dúró sí Jerusalẹmu lábẹ́ ìgbógun sí?’
Tak mówi Sennacheryb, król Asyrii: W czym pokładacie swoją ufność, że pozostajecie w oblężonej Jerozolimie?
11 Nígbà tí Hesekiah wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run wa yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ ọba Asiria,’ ó ń ṣì yín tọ́ ṣọ́nà, kí ẹ bá lè kú fún ebi àti òǹgbẹ.
Czy Ezechiasz nie zwodzi was, abyście wydali siebie na śmierć z głodu i pragnienia, mówiąc: PAN, nasz Bóg, wybawi nas z ręki króla Asyrii?
12 Ṣé Hesekiah fúnra rẹ̀ kò mú àwọn ọlọ́run ibi gíga àti àwọn pẹpẹ kúrò, tí ó ń wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ kan àti láti sun àwọn ẹbọ lórí rẹ̀’?
Czy to nie ten Ezechiasz zniósł jego wyżyny i ołtarze, po czym rozkazał Judzie i Jerozolimie: Przed jednym tylko ołtarzem będziecie oddawać pokłon i na nim palić kadzidło?
13 “Ṣé ẹ̀yin kò mọ̀ ohun tí èmi àti àwọn baba mi ti ṣe sí gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn? Ǹjẹ́ àwọn Ọlọ́run tí àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn ní agbára láti gba ilẹ̀ wọn kúrò lọ́wọ́ mi?
Czy nie wiecie, co ja i moi ojcowie uczyniliśmy wszystkim ludom [innych] ziem? Czyż bogowie narodów tych ziem mogli w jakiś sposób wyrwać ich ziemie z mojej ręki?
14 Ta ni nínú gbogbo àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè wọ̀nyí tí àwọn baba mi ti parun, tí ó le gbà ènìyàn rẹ̀ lọ́wọ́ mi, tí Ọlọ́run yín yóò fi le gbà yín lọ́wọ́ mi?
Kto spośród wszystkich bogów tych narodów, które moi ojcowie wytracili, mógł wybawić swój lud z mojej ręki, aby [też] wasz Bóg mógł wyrwać was z mojej ręki?
15 Nísinsin yìí, ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah ó tàn yín àti ṣì yín tọ́ ṣọ́nà báyìí. Ẹ má ṣe gbà á gbọ́, nítorí tí kò sí ọlọ́run orílẹ̀-èdè mìíràn tàbí ìjọba tí ó ní agbára láti gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi tàbí lọ́wọ́ àwọn baba mi, mélòó mélòó wa ni Ọlọ́run yín tí yóò gbà yín kúrò lọ́wọ́ mi!”
Teraz więc nie dajcie się zwodzić Ezechiaszowi i niech was nie łudzi w ten sposób ani mu nie wierzcie, gdyż żaden bóg spośród wszystkich narodów i królestw nie mógł wyrwać swego ludu z mojej ręki i z ręki moich ojców. Tym bardziej wasz Bóg nie wyrwie was z mojej ręki!
16 Àwọn ìjòyè Sennakeribu sọ̀rọ̀ síwájú sí i ní ìlòdì sí Olúwa Ọlọ́run àti sí ìránṣẹ́ rẹ̀ Hesekiah.
Jego słudzy jeszcze [więcej] mówili przeciw PANU Bogu i przeciwko jego słudze Ezechiaszowi.
17 Ọba pẹ̀lú sì kọ àwọn ìwé ní bíbú Olúwa Ọlọ́run Israẹli àti ní sísọ èyí ní ìlòdì sí: “Ní gẹ́gẹ́ bí àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn kò ṣe gba àwọn ènìyàn wọn kúrò lọ́wọ́ mi. Bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run Hesekiah kì yóò gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi.”
Napisał też listy, aby znieważać PANA, Boga Izraela, mówiąc przeciwko niemu tymi słowami: Jak bogowie narodów innych ziemi nie wyrwali swego ludu z mojej ręki, tak Bóg Ezechiasza nie wyrwie swego ludu z mojej ręki.
18 Lẹ́yìn náà wọ́n pè jáde ní èdè Heberu sí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu tí ó wà lára ògiri, láti dá ọjọ́ fún wọn, ki wọn kí ó lè fi agbára mú ìlú náà.
Potem wołali donośnym głosem w języku hebrajskim do ludu Jerozolimy, który [był] na murze, aby go przestraszyć i przerazić, i [tak] zdobyć miasto.
19 Wọ́n sọ̀rọ̀ nípa Ọlọ́run Jerusalẹmu bí wọ́n ti ṣe nípa àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn mìíràn ti àgbáyé, iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn.
A mówili o Bogu Jerozolimy jak o bogach narodów ziemi, którzy [są] dziełem rąk ludzkich.
20 Ọba Hesekiah àti wòlíì Isaiah ọmọ Amosi sọkún jáde nínú àdúrà sí ọ̀run nípa èyí.
Z tego powodu król Ezechiasz i prorok Izajasz, syn Amosa, modlili się i wołali do nieba.
21 Olúwa sì ran angẹli tí ó pa gbogbo àwọn ọmọ-ogun àti àwọn adarí àti àwọn ìjòyè tí ó wà nínú àgọ́ ọba Asiria run. Bẹ́ẹ̀ ni ó padà sí ilẹ̀ rẹ̀ ní ìtìjú. Nígbà tí ó sì lọ sínú ilé ọlọ́run rẹ̀, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ rẹ̀ gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.
I PAN posłał Anioła, który wytracił wszystkich dzielnych wojowników, dowódców i naczelników w obozie króla Asyrii. Okryty wstydem, wrócił on do swojej ziemi. A gdy wszedł do domu swojego boga, ci, którzy wyszli z jego bioder, zabili go tam mieczem.
22 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yọ Hesekiah àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ Sennakeribu ọba Asiria àti lọ́wọ́ gbogbo àwọn mìíràn. Ó tọ́jú wọn ní gbogbo ọ̀nà.
Tak więc PAN wybawił Ezechiasza i mieszkańców Jerozolimy z rąk Sennacheryba, króla Asyrii, i z rąk wszystkich innych [wrogów], i zapewnił im pokój ze wszystkich stron.
23 Ọ̀pọ̀ mú ọrẹ wá sí Jerusalẹmu fún Olúwa àti àwọn ẹ̀bùn iyebíye fún Hesekiah ọba Juda. Ó sì gbéga lójú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè lẹ́yìn náà.
Wtedy wielu przynosiło PANU ofiary do Jerozolimy oraz kosztowne dary dla Ezechiasza, króla Judy. A od tego czasu był wielce poważany w oczach wszystkich narodów.
24 Ní ọjọ́ wọ́n nì Hesekiah ṣe àárẹ̀, ó sì dójú ikú. Ó gbàdúrà sí Olúwa tí ó dá a lóhùn, tí ó sì fún un ní àmì àgbàyanu.
W tych dniach Ezechiasz śmiertelnie zachorował. Modlił się do PANA, a on przemówił do niego i dał mu znak.
25 Ṣùgbọ́n ọkàn Hesekiah ṣe ìgbéraga, kò sì kọbi ara sí i inú rere tí a fihàn án. Nítorí náà, ìbínú Olúwa wà lórí rẹ̀ àti lórí Juda àti Jerusalẹmu.
Ezechiasz jednak nie odwdzięczył się za dobrodziejstwa, [które zostały] mu wyświadczone, gdyż jego serce uniosło się pychą. Dlatego powstał gniew przeciw niemu i przeciw Judzie oraz Jerozolimie.
26 Nígbà náà ni Hesekiah ronúpìwàdà ní ti ìgbéraga ọkàn rẹ̀, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu sì ṣe bẹ́ẹ̀, nítorí náà, ìbínú Olúwa kò wá sí orí wọn ní ìgbà àwọn ọjọ́ Hesekiah.
Ale Ezechiasz ukorzył się za wyniosłość swojego serca – on i mieszkańcy Jerozolimy – i nie spadł na nich gniew PANA za dni Ezechiasza.
27 Hesekiah ní ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ńlá àti ọlá, ó sì ṣe àwọn ilé ìṣúra fún fàdákà àti wúrà rẹ̀ àti fún àwọn òkúta iyebíye rẹ̀, àwọn tùràrí olóòórùn dídùn àwọn àpáta àti gbogbo oríṣìí nǹkan iyebíye.
Ezechiasz posiadał bardzo dużo bogactwa i wielką sławę. Uczynił sobie skarbce na srebro i złoto, drogie kamienie, wonności, tarcze oraz wszelkie kosztowne przedmioty.
28 Ó kọ́ àwọn ilé pẹ̀lú láti tọ́jú àwọn ọkà àwọn tí wọ́n ka, ọtí tuntun àti òróró; ó sì ṣe àwọn àtíbàbà fún oríṣìí àwọn ẹran ọ̀sìn àti àwọn àṣémọ́ fun àwọn ọ̀wọ̀ ẹran.
[Miał] też spichlerze na zbiory zboża, wina i oliwy, obory dla wszelkiego gatunku bydła i zagrody dla trzód.
29 Ó kọ́ àwọn ìletò, ó sì gba ọ̀pọ̀ àwọn ọ̀wọ́ ẹran àti agbo ẹran, nítorí tí Ọlọ́run ti fún un ní ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ńlá.
Pobudował sobie miasta i [miał] liczne stada owiec i wołów, gdyż Bóg dał mu wielki majątek.
30 Hesekiah ni ó dí ojú ìṣúra apá òkè ti orísun Gihoni. Ó sì gbe gba ìsàlẹ̀ sí ìhà ìwọ oòrùn ìlú ńlá ti Dafidi. Ó ṣe àṣeyọrí rere nínú gbogbo ohun tí ó dáwọ́lé.
To właśnie Ezechiasz zatkał źródło wód w górnym Gichonie i przeprowadził je dołem po zachodniej stronie miasta Dawida. I powodziło się Ezechiaszowi we wszystkich jego działaniach.
31 Ṣùgbọ́n nígbà tí a rán àwọn oníṣẹ́ ọba wá láti Babeli láti bi í lérè nípa àmì ìyanu tí ó ṣẹlẹ̀ nì, Ọlọ́run fi sílẹ̀ láti dán an wò àti láti mọ gbogbo nǹkan tí ó wà lọ́kàn rẹ̀.
Jednak z powodu posłów książąt Babilonu wysłanych do niego, aby dowiedzieć się o znaku, który się wydarzył w ziemi, opuścił go Bóg, aby wystawić go na próbę i poznać wszystko, [co było] w jego sercu.
32 Gbogbo iṣẹ́ yòókù ti ìjọba Hesekiah àti àwọn ìṣe rẹ̀, ìfarajì rẹ̀ ni a kọ sínú ìwé ìran wòlíì Isaiah ọmọ Amosi nínú ìwé àwọn ọba Juda àti Israẹli
Ale pozostałe dzieje Ezechiasza i jego życzliwość są zapisane w widzeniu proroka Izajasza, syna Amosa, i w księdze królów Judy i Izraela.
33 Hesekiah sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. A sì sin ín sórí òkè níbi tí àwọn ibojì àwọn àtẹ̀lé Dafidi wà. Gbogbo Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ni ó bu ọlá fún un nígbà tí ó kú. Manase ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
I Ezechiasz zasnął ze swoimi ojcami, i został pogrzebany w najlepszych grobach synów Dawida. A po śmierci cała Juda oraz mieszkańcy Jerozolimy złożyli mu hołd. I jego syn Manasses królował w jego miejsce.

< 2 Chronicles 32 >