< 2 Chronicles 32 >

1 Lẹ́yìn gbogbo èyí ti Hesekiah ti fi òtítọ́ ṣe, Sennakeribu ọba Asiria wá ó sì gbógun ti Juda. Ó gbógun ti àwọn ìlú ààbò, ó ń ronú láti ṣẹ́gun wọn fún ara rẹ̀.
Après ces choses, et lorsqu'elles furent bien établies, Sanchérib, Roi des Assyriens vint, et entra en Judée, et se campa contre les villes fortes, faisant son compte de les séparer pour les avoir l'une après l'autre.
2 Nígbà tí Hesekiah rí i pé Sennakeribu ti wá, àti pé ó fẹ́ láti dá ogun sílẹ̀ lórí Jerusalẹmu,
Et Ezéchias voyant que Sanchérib était venu, et que sa face était tournée contre Jérusalem pour y faire la guerre;
3 Ó gbèrò pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ láti di orísun omi ní ìta ìlú ńlá, wọ́n sì ràn án lọ́wọ́.
Il prit conseil avec ses principaux [officiers], et ses plus vaillants hommes, de boucher les eaux des fontaines qui étaient hors de la ville; et ils l'aidèrent à le faire.
4 Ọ̀pọ̀ ogun ọkùnrin péjọ, wọ́n sì dí gbogbo àwọn orísun àti àwọn omi tó ń sàn tí ó ń sàn gba ti ilẹ̀ náà. “Kí ni ó dé tí àwọn ọba Asiria fi wá tí wọ́n sì rí ọ̀pọ̀ omi?” Wọ́n wí.
Car un grand-peuple s'assembla, et ils bouchèrent toutes les fontaines, et le torrent qui se répandait par le pays, disant: Pourquoi les Rois des Assyriens trouveraient-ils à leur venue une abondance d'eaux?
5 Nígbà náà ó ṣiṣẹ́ gidigidi ní títún gbogbo ara ògiri tí ó ti bàjẹ́ ṣe, ó sì ń kọ́ àwọn ilé ìṣọ́ gíga sókè rẹ̀. Ó kọ́ ògiri mìíràn sí ìta. Ó sì tún pẹ̀lú ibi ìtẹ́jú ilé ní ti ìlú ńlá Dafidi. Ó ṣe ọ̀pọ̀ iye ohun ìjà àti àwọn àpáta.
Il se fortifia aussi, et bâtit toute la muraille où l'on avait fait brèche, et l'éleva jusqu'aux tours; et il [bâtit] une autre muraille par dehors, et répara Millo en la cité de David, et fit faire beaucoup de javelots, et de boucliers.
6 Ó yan àwọn ìjòyè ológun sórí àwọn ènìyàn, ó sì pè wọ́n jọ, níwájú rẹ̀ ní ìbámu ní ìlú ńlá ti Dafidi. Ó sì ki wọ́n láyà pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí:
Et il ordonna des capitaines de guerre sur le peuple, et les assembla auprès de lui dans la place de la porte de la ville, et leur parla selon leur cœur, en disant:
7 “Ẹ jẹ́ alágbára, àti kí ẹ sì ní ìgboyà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù tàbí ní ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn nítorí tí ọba Asiria àti ọ̀pọ̀ ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí agbára ńlá wà pẹ̀lú wa ju òun lọ.
Fortifiez-vous, et vous renforcez; ne craignez point, et ne soyez point effrayés à cause du Roi des Assyriens, et de toute la multitude qui est avec lui; car un plus puissant que [tout ce qui est] avec lui, est avec nous.
8 Agbára ẹran-ara nìkan ni ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ṣùgbọ́n, Olúwa Ọlọ́run wa pẹ̀lú wa láti ràn wá lọ́wọ́ àti láti ja ìjà wa.” Àwọn ènìyàn sì ní ìgboyà láti ara ohun tí Hesekiah ọba Juda wí.
Le bras de la chair est avec lui, mais l'Eternel notre Dieu est avec nous, pour nous aider, et pour conduire nos batailles; et le peuple se rassura sur les paroles d'Ezéchias Roi de Juda.
9 Lẹ́yìn ìgbà tí Sennakeribu ọba Asiria àti gbogbo àwọn ogun rẹ̀ ń gbógun sí Lakiṣi. Ó rán àwọn ìjòyè rẹ̀ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú iṣẹ́ yí fún Hesekiah ọba Juda àti fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda tí ó wà níbẹ̀:
Après ces choses Sanchérib Roi des Assyriens, étant [encore] devant Lakis, et ayant avec lui toutes les forces de son Royaume, envoya ses serviteurs à Jérusalem, vers Ezéchias Roi de Juda, et vers tous les Juifs qui étaient à Jérusalem, pour leur dire:
10 “Èyí ni ohun tí Sennakeribu ọba Asiria wí, ‘Lórí kí ni ẹ̀yin gbé ìgbẹ́kẹ̀lé yín lé, tí ẹ̀yin fi dúró sí Jerusalẹmu lábẹ́ ìgbógun sí?’
Ainsi a dit Sanchérib Roi des Assyriens: Sur quoi vous assurez-vous, que vous demeuriez à Jérusalem pour y être assiégés?
11 Nígbà tí Hesekiah wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run wa yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ ọba Asiria,’ ó ń ṣì yín tọ́ ṣọ́nà, kí ẹ bá lè kú fún ebi àti òǹgbẹ.
Ezéchias ne vous induit-il pas à vous exposer à la mort par la famine et par la soif, en disant: L'Eternel notre Dieu nous délivrera de la main du Roi des Assyriens?
12 Ṣé Hesekiah fúnra rẹ̀ kò mú àwọn ọlọ́run ibi gíga àti àwọn pẹpẹ kúrò, tí ó ń wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ kan àti láti sun àwọn ẹbọ lórí rẹ̀’?
Cet Ezéchias n'a-t-il pas ôté les hauts lieux et les autels de l'Eternel, et n'a-t-il pas commandé à Juda et à Jérusalem, en disant: Vous vous prosternerez devant un [seul] autel, et vous ferez fumer sur [cet autel] vos sacrifices?
13 “Ṣé ẹ̀yin kò mọ̀ ohun tí èmi àti àwọn baba mi ti ṣe sí gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn? Ǹjẹ́ àwọn Ọlọ́run tí àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn ní agbára láti gba ilẹ̀ wọn kúrò lọ́wọ́ mi?
Ne savez-vous pas ce que nous avons fait moi et mes ancêtres à tous les peuples de divers pays? Les dieux des nations de [divers] pays ont-ils pu en aucune manière délivrer leur pays de ma main?
14 Ta ni nínú gbogbo àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè wọ̀nyí tí àwọn baba mi ti parun, tí ó le gbà ènìyàn rẹ̀ lọ́wọ́ mi, tí Ọlọ́run yín yóò fi le gbà yín lọ́wọ́ mi?
Qui sont ceux de tous les dieux de ces nations que mes ancêtres ont entièrement détruites, qui aient délivré leur peuple de ma main, [pour croire] que votre Dieu vous puisse délivrer de ma main?
15 Nísinsin yìí, ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah ó tàn yín àti ṣì yín tọ́ ṣọ́nà báyìí. Ẹ má ṣe gbà á gbọ́, nítorí tí kò sí ọlọ́run orílẹ̀-èdè mìíràn tàbí ìjọba tí ó ní agbára láti gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi tàbí lọ́wọ́ àwọn baba mi, mélòó mélòó wa ni Ọlọ́run yín tí yóò gbà yín kúrò lọ́wọ́ mi!”
Maintenant donc qu'Ezéchias ne vous abuse point, et qu'il ne vous séduise plus de cette manière, et ne le croyez pas; car si aucun Dieu, de quelque nation, ou de quelque Royaume que ç'ait été, n'a pu délivrer son peuple de ma main, ni de la main de mes ancêtres, combien moins votre Dieu pourra-t-il vous délivrer de ma main?
16 Àwọn ìjòyè Sennakeribu sọ̀rọ̀ síwájú sí i ní ìlòdì sí Olúwa Ọlọ́run àti sí ìránṣẹ́ rẹ̀ Hesekiah.
Ses serviteurs parlèrent encore contre l'Eternel Dieu, et contre Ezéchias son serviteur.
17 Ọba pẹ̀lú sì kọ àwọn ìwé ní bíbú Olúwa Ọlọ́run Israẹli àti ní sísọ èyí ní ìlòdì sí: “Ní gẹ́gẹ́ bí àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn kò ṣe gba àwọn ènìyàn wọn kúrò lọ́wọ́ mi. Bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run Hesekiah kì yóò gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi.”
Il écrivit aussi des lettres pour blasphémer l'Eternel, le Dieu d'Israël, et pour parler ainsi contre lui: Comme les dieux des nations de [divers] pays n'ont pu délivrer leur peuple de ma main, ainsi le Dieu d'Ezéchias ne pourra point délivrer son peuple de ma main.
18 Lẹ́yìn náà wọ́n pè jáde ní èdè Heberu sí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu tí ó wà lára ògiri, láti dá ọjọ́ fún wọn, ki wọn kí ó lè fi agbára mú ìlú náà.
[Ces envoyés] crièrent aussi à haute voix en Langue Judaïque au peuple de Jérusalem qui était sur les murailles, pour leur donner de la crainte et les épouvanter, afin de prendre la ville.
19 Wọ́n sọ̀rọ̀ nípa Ọlọ́run Jerusalẹmu bí wọ́n ti ṣe nípa àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn mìíràn ti àgbáyé, iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn.
Et ils parlèrent du Dieu de Jérusalem, comme des dieux des peuples de la terre, qui ne sont qu'un ouvrage de mains d'homme.
20 Ọba Hesekiah àti wòlíì Isaiah ọmọ Amosi sọkún jáde nínú àdúrà sí ọ̀run nípa èyí.
C'est pourquoi le Roi Ezéchias et Esaïe le Prophète fils d'Amots prièrent [Dieu] pour ce sujet, et crièrent vers les Cieux.
21 Olúwa sì ran angẹli tí ó pa gbogbo àwọn ọmọ-ogun àti àwọn adarí àti àwọn ìjòyè tí ó wà nínú àgọ́ ọba Asiria run. Bẹ́ẹ̀ ni ó padà sí ilẹ̀ rẹ̀ ní ìtìjú. Nígbà tí ó sì lọ sínú ilé ọlọ́run rẹ̀, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ rẹ̀ gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.
Et l'Eternel envoya un Ange, qui extermina entièrement tous les hommes forts et vaillants, et les Chefs, et les capitaines qui étaient au camp du Roi des Assyriens, de sorte qu'il s'en retourna tout confus en son pays. Et lorsqu'il fut entré dans la maison de son Dieu, ceux qui étaient sortis de ses propres entrailles le tuèrent avec l'épée.
22 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yọ Hesekiah àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ Sennakeribu ọba Asiria àti lọ́wọ́ gbogbo àwọn mìíràn. Ó tọ́jú wọn ní gbogbo ọ̀nà.
Ainsi l'Eternel délivra Ezéchias et les habitants de Jérusalem de la main de Sanchérib Roi des Assyriens, et de la main de tous ces peuples, et leur donna le moyen d'aller partout à l'entour [en sûreté].
23 Ọ̀pọ̀ mú ọrẹ wá sí Jerusalẹmu fún Olúwa àti àwọn ẹ̀bùn iyebíye fún Hesekiah ọba Juda. Ó sì gbéga lójú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè lẹ́yìn náà.
Et plusieurs apportèrent des présents à l'Eternel dans Jérusalem, et des choses exquises à Ezéchias Roi de Juda; de sorte qu'après cela il fut élevé, à la vue de toutes les nations.
24 Ní ọjọ́ wọ́n nì Hesekiah ṣe àárẹ̀, ó sì dójú ikú. Ó gbàdúrà sí Olúwa tí ó dá a lóhùn, tí ó sì fún un ní àmì àgbàyanu.
En ces jours-là Ezéchias fut malade jusqu'à la mort, et il pria l'Eternel, qui l'exauça, et lui donna un signe.
25 Ṣùgbọ́n ọkàn Hesekiah ṣe ìgbéraga, kò sì kọbi ara sí i inú rere tí a fihàn án. Nítorí náà, ìbínú Olúwa wà lórí rẹ̀ àti lórí Juda àti Jerusalẹmu.
Mais Ezéchias ne fut pas reconnaissant du bienfait qu'il avait reçu; car son cœur fut élevé, c'est pourquoi il y eut indignation contre lui, et contre Juda et Jérusalem.
26 Nígbà náà ni Hesekiah ronúpìwàdà ní ti ìgbéraga ọkàn rẹ̀, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu sì ṣe bẹ́ẹ̀, nítorí náà, ìbínú Olúwa kò wá sí orí wọn ní ìgbà àwọn ọjọ́ Hesekiah.
Mais Ezéchias s'humilia de ce qu'il avait élevé son cœur, tant lui que les habitants de Jérusalem; c'est pourquoi l'indignation de l'Eternel ne vint point sur eux durant les jours d'Ezéchias.
27 Hesekiah ní ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ńlá àti ọlá, ó sì ṣe àwọn ilé ìṣúra fún fàdákà àti wúrà rẹ̀ àti fún àwọn òkúta iyebíye rẹ̀, àwọn tùràrí olóòórùn dídùn àwọn àpáta àti gbogbo oríṣìí nǹkan iyebíye.
Ezéchias donc eut de grandes richesses et une grande gloire, et amassa des trésors d'argent, d'or, de pierres précieuses, de choses aromatiques, de boucliers, et de toute sorte de vaisselle précieuse.
28 Ó kọ́ àwọn ilé pẹ̀lú láti tọ́jú àwọn ọkà àwọn tí wọ́n ka, ọtí tuntun àti òróró; ó sì ṣe àwọn àtíbàbà fún oríṣìí àwọn ẹran ọ̀sìn àti àwọn àṣémọ́ fun àwọn ọ̀wọ̀ ẹran.
Et il fit des magasins pour la récolte du froment, du vin, et de l'huile; et des étables pour toute sorte de bêtes, et des rangées dans les étables.
29 Ó kọ́ àwọn ìletò, ó sì gba ọ̀pọ̀ àwọn ọ̀wọ́ ẹran àti agbo ẹran, nítorí tí Ọlọ́run ti fún un ní ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ńlá.
Il se fit aussi des villes, et il acquit des troupeaux du gros et du menu bétail en abondance; car Dieu lui avait donné de fort grandes richesses.
30 Hesekiah ni ó dí ojú ìṣúra apá òkè ti orísun Gihoni. Ó sì gbe gba ìsàlẹ̀ sí ìhà ìwọ oòrùn ìlú ńlá ti Dafidi. Ó ṣe àṣeyọrí rere nínú gbogbo ohun tí ó dáwọ́lé.
Ezéchias boucha aussi le haut canal des eaux de Guihon, et en conduisit les eaux droit en bas vers l'Occident de la Cité de David. Ainsi Ezéchias prospéra dans tout ce qu'il fit.
31 Ṣùgbọ́n nígbà tí a rán àwọn oníṣẹ́ ọba wá láti Babeli láti bi í lérè nípa àmì ìyanu tí ó ṣẹlẹ̀ nì, Ọlọ́run fi sílẹ̀ láti dán an wò àti láti mọ gbogbo nǹkan tí ó wà lọ́kàn rẹ̀.
Mais lorsque les ambassadeurs des Princes de Babylone, qui avaient envoyé vers lui, pour s'informer du miracle qui était arrivé sur la terre, [furent venus vers lui], Dieu l'abandonna pour l'éprouver, afin de connaître tout ce qui était en son cœur.
32 Gbogbo iṣẹ́ yòókù ti ìjọba Hesekiah àti àwọn ìṣe rẹ̀, ìfarajì rẹ̀ ni a kọ sínú ìwé ìran wòlíì Isaiah ọmọ Amosi nínú ìwé àwọn ọba Juda àti Israẹli
Le reste des actions d'Ezéchias, et ses gratuités, voilà elles sont écrites dans la Vision d'Esaïe le Prophète fils d'Amots, outre ce [qui en est écrit] au Livre des Rois de Juda et d'Israël.
33 Hesekiah sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. A sì sin ín sórí òkè níbi tí àwọn ibojì àwọn àtẹ̀lé Dafidi wà. Gbogbo Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ni ó bu ọlá fún un nígbà tí ó kú. Manase ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Puis Ezéchias s'endormit avec ses pères, et on l'ensevelit au plus haut des sépulcres des fils de David; et tout Juda, et Jérusalem lui firent honneur en sa mort, et Manassé son fils régna en sa place.

< 2 Chronicles 32 >