< 2 Chronicles 32 >

1 Lẹ́yìn gbogbo èyí ti Hesekiah ti fi òtítọ́ ṣe, Sennakeribu ọba Asiria wá ó sì gbógun ti Juda. Ó gbógun ti àwọn ìlú ààbò, ó ń ronú láti ṣẹ́gun wọn fún ara rẹ̀.
Après ces choses et cette fidélité, Sennachérib, roi d'Assyrie, arriva, entra en Juda, campa contre les villes fortifiées et eut l'intention de les gagner pour lui.
2 Nígbà tí Hesekiah rí i pé Sennakeribu ti wá, àti pé ó fẹ́ láti dá ogun sílẹ̀ lórí Jerusalẹmu,
Lorsqu'Ézéchias vit que Sennachérib était venu et qu'il projetait de combattre Jérusalem,
3 Ó gbèrò pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ láti di orísun omi ní ìta ìlú ńlá, wọ́n sì ràn án lọ́wọ́.
il consulta ses princes et ses hommes forts pour arrêter les eaux des sources qui étaient à l'extérieur de la ville, et ils l'aidèrent.
4 Ọ̀pọ̀ ogun ọkùnrin péjọ, wọ́n sì dí gbogbo àwọn orísun àti àwọn omi tó ń sàn tí ó ń sàn gba ti ilẹ̀ náà. “Kí ni ó dé tí àwọn ọba Asiria fi wá tí wọ́n sì rí ọ̀pọ̀ omi?” Wọ́n wí.
Alors beaucoup de gens se rassemblèrent et ils arrêtèrent toutes les sources et le ruisseau qui coulait au milieu du pays, en disant: « Pourquoi les rois d'Assyrie viendraient-ils et trouveraient-ils de l'eau en abondance? »
5 Nígbà náà ó ṣiṣẹ́ gidigidi ní títún gbogbo ara ògiri tí ó ti bàjẹ́ ṣe, ó sì ń kọ́ àwọn ilé ìṣọ́ gíga sókè rẹ̀. Ó kọ́ ògiri mìíràn sí ìta. Ó sì tún pẹ̀lú ibi ìtẹ́jú ilé ní ti ìlú ńlá Dafidi. Ó ṣe ọ̀pọ̀ iye ohun ìjà àti àwọn àpáta.
Il prit courage, rebâtit toute la muraille abattue, l'éleva jusqu'aux tours, avec l'autre muraille en dehors, et renforça Millo dans la ville de David; il fabriqua des armes et des boucliers en abondance.
6 Ó yan àwọn ìjòyè ológun sórí àwọn ènìyàn, ó sì pè wọ́n jọ, níwájú rẹ̀ ní ìbámu ní ìlú ńlá ti Dafidi. Ó sì ki wọ́n láyà pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí:
Il plaça des chefs de guerre à la tête du peuple, les rassembla auprès de lui sur la grande place à la porte de la ville, et leur adressa des paroles d'encouragement en disant:
7 “Ẹ jẹ́ alágbára, àti kí ẹ sì ní ìgboyà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù tàbí ní ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn nítorí tí ọba Asiria àti ọ̀pọ̀ ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí agbára ńlá wà pẹ̀lú wa ju òun lọ.
« Soyez forts et courageux. Ne craignez pas et ne soyez pas effrayés à cause du roi d'Assyrie et de toute la multitude qui est avec lui, car il y a plus grand que lui avec nous.
8 Agbára ẹran-ara nìkan ni ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ṣùgbọ́n, Olúwa Ọlọ́run wa pẹ̀lú wa láti ràn wá lọ́wọ́ àti láti ja ìjà wa.” Àwọn ènìyàn sì ní ìgboyà láti ara ohun tí Hesekiah ọba Juda wí.
Il a avec lui un bras de chair, mais Yahvé notre Dieu est avec nous pour nous secourir et mener nos combats. » Le peuple se reposa sur les paroles d'Ézéchias, roi de Juda.
9 Lẹ́yìn ìgbà tí Sennakeribu ọba Asiria àti gbogbo àwọn ogun rẹ̀ ń gbógun sí Lakiṣi. Ó rán àwọn ìjòyè rẹ̀ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú iṣẹ́ yí fún Hesekiah ọba Juda àti fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda tí ó wà níbẹ̀:
Après cela, Sennacherib, roi d'Assyrie, envoya ses serviteurs à Jérusalem (il était en train d'attaquer Lachish, et toutes ses forces étaient avec lui), à Ézéchias, roi de Juda, et à tous les Judéens qui étaient à Jérusalem, en disant:
10 “Èyí ni ohun tí Sennakeribu ọba Asiria wí, ‘Lórí kí ni ẹ̀yin gbé ìgbẹ́kẹ̀lé yín lé, tí ẹ̀yin fi dúró sí Jerusalẹmu lábẹ́ ìgbógun sí?’
Sennacherib, roi d'Assyrie, dit: « En qui vous confiez-vous, puisque vous restez assiégés à Jérusalem?
11 Nígbà tí Hesekiah wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run wa yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ ọba Asiria,’ ó ń ṣì yín tọ́ ṣọ́nà, kí ẹ bá lè kú fún ebi àti òǹgbẹ.
Ézéchias ne vous persuade-t-il pas de vous livrer à la mort par la famine et par la soif, en disant: « Yahvé notre Dieu nous délivrera de la main du roi d'Assyrie? »
12 Ṣé Hesekiah fúnra rẹ̀ kò mú àwọn ọlọ́run ibi gíga àti àwọn pẹpẹ kúrò, tí ó ń wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ kan àti láti sun àwọn ẹbọ lórí rẹ̀’?
Le même Ézéchias n'a-t-il pas enlevé ses hauts lieux et ses autels, et n'a-t-il pas donné cet ordre à Juda et à Jérusalem: « Vous vous prosternerez devant un seul autel, et vous y brûlerez des parfums? »
13 “Ṣé ẹ̀yin kò mọ̀ ohun tí èmi àti àwọn baba mi ti ṣe sí gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn? Ǹjẹ́ àwọn Ọlọ́run tí àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn ní agbára láti gba ilẹ̀ wọn kúrò lọ́wọ́ mi?
Ne savez-vous pas ce que moi et mes pères avons fait à tous les peuples du pays? Les dieux des nations de ces pays étaient-ils en mesure de délivrer leur pays de ma main?
14 Ta ni nínú gbogbo àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè wọ̀nyí tí àwọn baba mi ti parun, tí ó le gbà ènìyàn rẹ̀ lọ́wọ́ mi, tí Ọlọ́run yín yóò fi le gbà yín lọ́wọ́ mi?
Qui, parmi tous les dieux de ces nations que mes pères ont dévastées, pouvait délivrer son peuple de ma main, pour que ton Dieu puisse te délivrer de ma main?
15 Nísinsin yìí, ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah ó tàn yín àti ṣì yín tọ́ ṣọ́nà báyìí. Ẹ má ṣe gbà á gbọ́, nítorí tí kò sí ọlọ́run orílẹ̀-èdè mìíràn tàbí ìjọba tí ó ní agbára láti gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi tàbí lọ́wọ́ àwọn baba mi, mélòó mélòó wa ni Ọlọ́run yín tí yóò gbà yín kúrò lọ́wọ́ mi!”
Maintenant, ne vous laissez pas tromper par Ezéchias et ne vous persuadez pas de cette manière. Ne le croyez pas, car aucun dieu d'aucune nation ni d'aucun royaume n'a pu délivrer son peuple de ma main et de la main de mes pères. A combien moins forte raison votre Dieu vous délivrera-t-il de ma main? »
16 Àwọn ìjòyè Sennakeribu sọ̀rọ̀ síwájú sí i ní ìlòdì sí Olúwa Ọlọ́run àti sí ìránṣẹ́ rẹ̀ Hesekiah.
Ses serviteurs parlèrent encore contre l'Éternel Dieu et contre son serviteur Ézéchias.
17 Ọba pẹ̀lú sì kọ àwọn ìwé ní bíbú Olúwa Ọlọ́run Israẹli àti ní sísọ èyí ní ìlòdì sí: “Ní gẹ́gẹ́ bí àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn kò ṣe gba àwọn ènìyàn wọn kúrò lọ́wọ́ mi. Bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run Hesekiah kì yóò gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi.”
Il écrivit aussi des lettres insultant Yahvé, le Dieu d'Israël, et parlant contre lui, disant: « Comme les dieux des nations du pays, qui n'ont pas délivré leur peuple de ma main, ainsi le Dieu d'Ézéchias ne délivrera pas son peuple de ma main. »
18 Lẹ́yìn náà wọ́n pè jáde ní èdè Heberu sí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu tí ó wà lára ògiri, láti dá ọjọ́ fún wọn, ki wọn kí ó lè fi agbára mú ìlú náà.
Ils appelèrent d'une voix forte, dans la langue des Juifs, les habitants de Jérusalem qui étaient sur la muraille, pour les effrayer et les troubler, afin de prendre la ville.
19 Wọ́n sọ̀rọ̀ nípa Ọlọ́run Jerusalẹmu bí wọ́n ti ṣe nípa àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn mìíràn ti àgbáyé, iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn.
Ils parlaient du Dieu de Jérusalem comme des dieux des peuples de la terre, qui sont l'œuvre de mains d'hommes.
20 Ọba Hesekiah àti wòlíì Isaiah ọmọ Amosi sọkún jáde nínú àdúrà sí ọ̀run nípa èyí.
Le roi Ézéchias et le prophète Ésaïe, fils d'Amoz, prièrent à cause de cela et crièrent au ciel.
21 Olúwa sì ran angẹli tí ó pa gbogbo àwọn ọmọ-ogun àti àwọn adarí àti àwọn ìjòyè tí ó wà nínú àgọ́ ọba Asiria run. Bẹ́ẹ̀ ni ó padà sí ilẹ̀ rẹ̀ ní ìtìjú. Nígbà tí ó sì lọ sínú ilé ọlọ́run rẹ̀, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ rẹ̀ gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.
Yahvé envoya un ange qui extermina tous les vaillants hommes, les chefs et les capitaines dans le camp du roi d'Assyrie. Celui-ci s'en retourna, honteux de son visage, dans son pays. Comme il était entré dans la maison de son dieu, ceux qui étaient sortis de son propre corps l'y tuèrent par l'épée.
22 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yọ Hesekiah àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ Sennakeribu ọba Asiria àti lọ́wọ́ gbogbo àwọn mìíràn. Ó tọ́jú wọn ní gbogbo ọ̀nà.
Ainsi Yahvé sauva Ézéchias et les habitants de Jérusalem de la main de Sennacherib, roi d'Assyrie, et de la main de tous les autres, et il les guida de tous côtés.
23 Ọ̀pọ̀ mú ọrẹ wá sí Jerusalẹmu fún Olúwa àti àwọn ẹ̀bùn iyebíye fún Hesekiah ọba Juda. Ó sì gbéga lójú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè lẹ́yìn náà.
Beaucoup apportèrent des présents à Yahvé à Jérusalem et des objets précieux à Ézéchias, roi de Juda, de sorte qu'il fut désormais exalté aux yeux de toutes les nations.
24 Ní ọjọ́ wọ́n nì Hesekiah ṣe àárẹ̀, ó sì dójú ikú. Ó gbàdúrà sí Olúwa tí ó dá a lóhùn, tí ó sì fún un ní àmì àgbàyanu.
En ces jours-là, Ézéchias était en phase terminale, et il pria Yahvé; celui-ci lui parla et lui donna un signe.
25 Ṣùgbọ́n ọkàn Hesekiah ṣe ìgbéraga, kò sì kọbi ara sí i inú rere tí a fihàn án. Nítorí náà, ìbínú Olúwa wà lórí rẹ̀ àti lórí Juda àti Jerusalẹmu.
Mais Ézéchias ne rendit pas le bienfait qui lui avait été fait, parce que son cœur s'élevait. C'est pourquoi il y eut de la colère sur lui, sur Juda et sur Jérusalem.
26 Nígbà náà ni Hesekiah ronúpìwàdà ní ti ìgbéraga ọkàn rẹ̀, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu sì ṣe bẹ́ẹ̀, nítorí náà, ìbínú Olúwa kò wá sí orí wọn ní ìgbà àwọn ọjọ́ Hesekiah.
Cependant, Ézéchias s'humilia à cause de l'orgueil de son cœur, lui et les habitants de Jérusalem, de sorte que la colère de Yahvé ne s'abattit pas sur eux du temps d'Ézéchias.
27 Hesekiah ní ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ńlá àti ọlá, ó sì ṣe àwọn ilé ìṣúra fún fàdákà àti wúrà rẹ̀ àti fún àwọn òkúta iyebíye rẹ̀, àwọn tùràrí olóòórùn dídùn àwọn àpáta àti gbogbo oríṣìí nǹkan iyebíye.
Ézéchias eut des richesses et des honneurs immenses. Il se pourvut de trésors pour l'argent, pour l'or, pour les pierres précieuses, pour les aromates, pour les boucliers, et pour toutes sortes de vases précieux;
28 Ó kọ́ àwọn ilé pẹ̀lú láti tọ́jú àwọn ọkà àwọn tí wọ́n ka, ọtí tuntun àti òróró; ó sì ṣe àwọn àtíbàbà fún oríṣìí àwọn ẹran ọ̀sìn àti àwọn àṣémọ́ fun àwọn ọ̀wọ̀ ẹran.
il se pourvut aussi de magasins pour la production du blé, du vin nouveau et de l'huile, et d'étables pour toutes sortes de bêtes, et de troupeaux en plis.
29 Ó kọ́ àwọn ìletò, ó sì gba ọ̀pọ̀ àwọn ọ̀wọ́ ẹran àti agbo ẹran, nítorí tí Ọlọ́run ti fún un ní ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ńlá.
Il se procura aussi des villes, et des biens en abondance pour le bétail et les troupeaux, car Dieu lui avait donné des biens en abondance.
30 Hesekiah ni ó dí ojú ìṣúra apá òkè ti orísun Gihoni. Ó sì gbe gba ìsàlẹ̀ sí ìhà ìwọ oòrùn ìlú ńlá ti Dafidi. Ó ṣe àṣeyọrí rere nínú gbogbo ohun tí ó dáwọ́lé.
Ce même Ézéchias arrêta aussi la source supérieure des eaux du Gihon, et les fit descendre directement à l'ouest de la ville de David. Ézéchias prospéra dans toutes ses œuvres.
31 Ṣùgbọ́n nígbà tí a rán àwọn oníṣẹ́ ọba wá láti Babeli láti bi í lérè nípa àmì ìyanu tí ó ṣẹlẹ̀ nì, Ọlọ́run fi sílẹ̀ láti dán an wò àti láti mọ gbogbo nǹkan tí ó wà lọ́kàn rẹ̀.
Cependant, à propos des ambassadeurs des princes de Babylone, qui l'envoyèrent s'enquérir du prodige qui se faisait dans le pays, Dieu le laissa pour l'éprouver, afin qu'il sache tout ce qui était dans son cœur.
32 Gbogbo iṣẹ́ yòókù ti ìjọba Hesekiah àti àwọn ìṣe rẹ̀, ìfarajì rẹ̀ ni a kọ sínú ìwé ìran wòlíì Isaiah ọmọ Amosi nínú ìwé àwọn ọba Juda àti Israẹli
Le reste des actes d'Ézéchias et ses bonnes actions, voici, ils sont écrits dans la vision du prophète Ésaïe, fils d'Amoz, dans le livre des rois de Juda et d'Israël.
33 Hesekiah sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. A sì sin ín sórí òkè níbi tí àwọn ibojì àwọn àtẹ̀lé Dafidi wà. Gbogbo Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ni ó bu ọlá fún un nígbà tí ó kú. Manase ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Ézéchias se coucha avec ses pères, et on l'enterra dans la montée des tombeaux des fils de David. Tout Juda et les habitants de Jérusalem l'honorèrent à sa mort. Manassé, son fils, régna à sa place.

< 2 Chronicles 32 >