< 2 Chronicles 31 >
1 Nígbà tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ti dé òpin, àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà níbẹ̀ jáde lọ sí àwọn ìlú Juda, wọ́n fọ́ àwọn òkúta ìyàsọ́tọ̀ sí wẹ́wẹ́, wọ́n gé àwọn ère Aṣerah lulẹ̀. Wọ́n ba àwọn ibi gíga jẹ́ àti àwọn pẹpẹ jákèjádò Juda àti Benjamini àti ní Efraimu àti Manase. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti pa gbogbo wọn run, àwọn ọmọ Israẹli padà sí ìlú wọn àti sí nǹkan ìní wọn.
Rĩrĩa maũndũ macio mothe maathirire-rĩ, andũ a Isiraeli arĩa maarĩ hau makiumagara magĩthiĩ matũũra-inĩ ma Juda, makĩhehenja mahiga marĩa mamũrĩirwo ngai cia mĩhianano na magĩtemanga itugĩ cia Ashera. Ningĩ makĩananga kũndũ kũrĩa gũtũũgĩru kwahooyagĩrwo o na igongona iria ciarĩ Juda guothe na Benjamini, o na kũu Efiraimu na Manase. Thuutha wa gũcithũkangia ciothe, andũ a Isiraeli magĩcooka matũũra-inĩ mao na o mũndũ agĩcooka igai-inĩ rĩake.
2 Hesekiah fi lé àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi lọ́wọ́ sí àwọn ìpín olúkúlùkù wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà tàbí ará Lefi láti tẹ́ ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀, láti ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ láti fi ọpẹ́ fún àti láti kọ àwọn orin ìyìn ní ẹnu-ọ̀nà ibùgbé Olúwa.
Hezekia agĩkĩiga athĩnjĩri-Ngai na Alawii na ikundi, o gĩkundi kũringana na wĩra wakĩo, marĩ athĩnjĩri-Ngai kana Alawii, marutage maruta ma njino na ma ũiguano, ningĩ matungatage, na macookagie ngaatho, na mainage nyĩmbo cia ũgooci marĩ ihingo-inĩ cia gĩikaro kĩa Jehova.
3 Ọba fi sílẹ̀ láti ara ohun ìní rẹ̀ fun ẹbọ sísun àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ àti fún ẹbọ sísun ní ọjọ́ ìsinmi, òṣùpá tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn gẹ́gẹ́ bi a ti ṣe kọ ọ́ nínú òfin Olúwa.
Mũthamaki nĩaheanire indo ciake mwene cia kũrutagwo maruta ma njino ma rũciinĩ na ma hwaĩ-inĩ, na maruta ma njino ma Thabatũ, na ma Tũrũgamo twa Mweri, na ma ciathĩ-inĩ iria ciatuĩtwo, o ta ũrĩa kwaandĩkĩtwo Watho-inĩ wa Jehova.
4 Ó pàṣẹ fún àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu láti fi ìpín tí ó yẹ fún àlùfáà fún un àti àwọn ará Lefi, kí wọn kí ó lè fi ara wọn jì fún òfin Olúwa.
Agĩatha andũ arĩa maatũũraga Jerusalemu maheage athĩnjĩri-Ngai na Alawii rwĩga rũrĩa rwamagĩrĩire, nĩgeetha nao mahotage kwĩheana harĩ Watho wa Jehova.
5 Ní kété tí àṣẹ náà jáde lọ, àwọn ọmọ Israẹli fi tìfẹ́tìfẹ́ fi àkọ́so ti ọkà wọn, ọtí tuntun, òróró àti oyin àti gbogbo ohun tí pápá mú jáde lélẹ̀. Wọ́n kó ọ̀pọ̀ iye, àti ìdámẹ́wàá gbogbo nǹkan wá.
Na rĩrĩ, hĩndĩ ĩrĩa watho ũcio wamenyekire-rĩ, andũ a Isiraeli makĩheana na ũtaana maciaro mao ma mbere ma ngano, na ma ndibei ya mũhihano, na maguta, na ũũkĩ, na maciaro ma mĩgũnda yao. Makĩrehe indo nyingĩ mũno o na gĩcunjĩ gĩa ikũmi kĩa indo ciothe.
6 Àwọn ọkùnrin Israẹli àti Juda ti gbe inú àwọn ìlú Juda pẹ̀lú mú ìdámẹ́wàá agbo ẹran àti ohun èlò àti ohun ọ̀sìn àti ìdámẹ́wàá ti àwọn nǹkan mímọ́ tí a ti yà sọ́tọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì kó wọn jọ ní òkìtì.
Nao andũ a Isiraeli na Juda arĩa maatũũraga matũũra-inĩ ma Juda o nao makĩrehe gĩcunjĩ gĩa ikũmi kĩa ndũũru ciao cia ngʼombe na ngʼondu, o na gĩcunjĩ gĩa ikũmi kĩa indo iria ciamũrĩirwo Jehova Ngai wao, nao magĩciiga irũndo.
7 Wọ́n bẹ̀rẹ̀ ṣíṣe èyí ní oṣù kẹta, wọ́n sì parí ní oṣù keje.
Maambĩrĩirie gwĩka ũndũ ũyũ mweri wa ĩtatũ na makĩrĩkia mweri wa mũgwanja.
8 Nígbà tí Hesekiah àti àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ wá, tí wọ́n sì rí òkìtì náà, wọ́n yin Olúwa, pẹ̀lú ìbùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli.
Rĩrĩa Hezekia na anene ake mookire na makĩona irũndo icio, makĩgooca Jehova na makĩrathima andũ ake a Isiraeli.
9 Hesekiah béèrè lọ́wọ́ àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi nípa òkìtì;
Hezekia akĩũria athĩnjĩri-Ngai na Alawii ũhoro wa irũndo icio;
10 àti Asariah olórí àlùfáà ti ìdílé Sadoku sì dáhùn pé, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní mú ìdáwó wọn wá sí ilé Olúwa àti ní èyí tí yóò tó jẹ àti ọ̀pọ̀ láti tọ́jú pamọ́ nítorí Olúwa ti bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀, ó sì ṣẹ́kù lọ́pọ̀lọ́pọ̀.”
nake Azaria mũthĩnjĩri-Ngai ũrĩa mũnene wa kuuma nyũmba ya Zadoku akĩmũcookeria atĩrĩ, “Kuuma andũ maambĩrĩria kũrehe mĩhothi yao hekarũ-inĩ ya Jehova-rĩ, nĩtũkoretwo tũrĩ na irio cia kũigana kũrĩa, o na tũgatigia nyingĩ mũno, nĩ ũndũ Jehova nĩarathimĩte andũ ake, na irio ici nyingĩ ũũ igagĩtigara.”
11 Hesekiah pàṣẹ láti tọ́jú àwọn yàrá ìṣúra nínú ilé Olúwa, wọ́n sì ṣe èyí.
Hezekia agĩathana gwakwo makũmbĩ kũu thĩinĩ wa hekarũ ya Jehova, na gũgĩĩkwo ũguo.
12 Nígbà náà wọ́n mú ọrẹ àti ìdámẹ́wàá àti àwọn ẹ̀bùn tí a yà sí mímọ́ wọ ilé náà wá nítòótọ́. Lórí èyí tí Konaniah ọmọ Lefi, ń ṣe olórí, Ṣimei arákùnrin rẹ̀ ni igbákejì rẹ̀.
Nao magĩcooka makĩrehe mĩhothi na wĩhokeku, na icunjĩ cia ikũmi, na iheo iria nyamũre. Konania ũrĩa Mũlawii nĩwe watuirwo mũrori wa indo icio, nake mũrũ wa ithe Shimei nĩwe warĩ mũnini wake.
13 Jehieli, Asasiah, Nahati, Asaheli, Jerimoti, Josabadi, Elieli, Ismakia, Mahati àti Benaiah jẹ́ àwọn alábojútó lábẹ́ Konaniah àti Ṣimei arákùnrin rẹ̀ nípa ipá ọba Hesekiah àti Asariah olórí ti ó wà ní ìkáwọ́ ilé Ọlọ́run.
Jehieli, na Azazia, na Nahathu, na Asaheli, na Jerimothu, na Jozabadu, na Elieli, na Isimakia, na Mahathu, na Benaia nĩo maarĩ arũgamĩrĩri rungu rwa Konania na mũrũ wa ithe Shimei, ta ũrĩa gwatuĩtwo nĩ Mũthamaki Hezekia na Azaria ũrĩa warĩ mũnene wa hekarũ ya Ngai.
14 Kore ọmọ Imina ará Lefi olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ìlà-oòrùn, wà ní ìkáwọ́ àwọn ọrẹ àtinúwá tí a fi fún Ọlọ́run, o ń pín ìdáwó tí a ṣe fún Olúwa pẹ̀lú àwọn ẹ̀bùn tí a yà sọ́tọ̀
Kore mũrũ wa Imuna ũrĩa Mũlawii, mũikaria wa Kĩhingo kĩa Mwena wa Irathĩro, nĩwe warĩ mũrori wa indo iria ciarutagĩrwo Ngai na kwĩyendera, akagayaga mĩhothi ĩrĩa ĩrutĩirwo Jehova hamwe na iheo iria nyamũre.
15 Edeni, Miniamini, Jeṣua, Ṣemaiah, Amariah àti Ṣekaniah ràn án lọ́wọ́ tọkàntọkàn nínú àwọn ìlú àwọn àlùfáà tí ń dáwó fún àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, àgbà àti kékeré.
Edeni, na Miniamini, na Jeshua, na Shemaia, na Amaria, na Shekania nĩo maamũteithagĩrĩria marĩ na wĩhokeku kũu matũũra-inĩ ma athĩnjĩri-Ngai, na makagayagĩra athĩnjĩri-Ngai arĩa angĩ o ta ũrĩa ikundi ciao ciatariĩ, makagaĩra arĩa akũrũ na arĩa anini o ũndũ ũmwe.
16 Ní àfikún, wọ́n pín sí àwọn ọkùnrin àgbà ọdún mẹ́ta tàbí ọ̀pọ̀ tí orúkọ wọn wà nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn. Gbogbo àwọn ti yóò wọ ilé Olúwa láti ṣe oríṣìí iṣẹ́ ti a gbà wọ́n fún gẹ́gẹ́ bí ìgbẹ́kẹ̀lé wọn àti ìpín wọn.
Hamwe na ũguo makĩgaĩra arũme arĩa maarĩ na mĩaka ĩtatũ na makĩria arĩa marĩĩtwa mao maarĩ maandĩko-inĩ ma njiarwa, nao nĩo andũ arĩa othe maangĩatoonyire hekarũ-nĩ ya Jehova nĩ ũndũ wa kũruta mawĩra mao ma o mũthenya, ta ũrĩa wĩra wa o mũndũ watariĩ na kũringana na ikundi ciao.
17 Wọ́n sì pín àwọn àlùfáà, wọn kọ orúkọ àwọn ìdílé wọn sínú ìtàn ìdílé àti sí àwọn ará Lefi ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu àti ìpín wọn.
Nao makĩgaĩra athĩnjĩri-Ngai arĩa maandĩkithĩtio nĩ andũ a nyũmba ciao maandĩko-inĩ ma njiarwa ciao, o na Alawii arĩa maarĩ na mĩaka mĩrongo ĩĩrĩ na makĩria, ta ũrĩa wĩra wa o mũndũ watariĩ na kũringana na ikundi ciao.
18 Wọ́n fi gbogbo àwọn ọmọ kéékèèké sí i, àwọn ìyàwó, àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin gbogbo ará ìlú tí a kọ lẹ́sẹẹsẹ sínú ìtàn ìdílé ti baba ńlá wọn fún ìrántí. Nítorí tí wọ́n ṣe òtítọ́ ní yíya ara wọn sí ọ̀tọ̀.
Maataranĩirie ciana ciothe, na atumia, na ariũ ao, na airĩtu a mũingĩ wothe ũrĩa waandĩkĩtwo maandĩko-inĩ ma njiarwa. Nĩgũkorwo maarĩ ehokeku ũhoro-inĩ wao wa gwĩtheria.
19 Ní ti àwọn àlùfáà, àwọn ìran ọmọ Aaroni, tí ń gbé ni àwọn ilẹ̀ oko lẹ́bàá àwọn ìlú wọn tàbí ní àwọn ìlú mìíràn. A yan àwọn ọkùnrin pẹ̀lú orúkọ láti pín ìlú fún gbogbo ọkùnrin láàrín wọn àti sí gbogbo àwọn tí a kọ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá àwọn ará Lefi.
Ha ũhoro wa athĩnjĩri-Ngai, o acio a rũciaro rwa Harũni, arĩa maatũũraga mĩgũnda-inĩ ĩrĩa yathiũrũrũkĩirie matũũra mao kana matũũra mangĩ, nĩ kwarĩ na andũ amwe maathuurĩtwo na makagwetwo marĩĩtwa a kũgaĩra arũme othe arĩa maarĩ gatagatĩ-inĩ kao rũgai rwao, na kũrĩ arĩa othe maandĩkĩtwo maandĩko-inĩ ma njiarwa cia Alawii.
20 Èyí ni Hesekiah ṣe jákèjádò Juda, ó sì ṣe ohun tí ó dára àti tí ó tọ́ àti ohun òtítọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
Ũguo nĩguo Hezekia eekire Juda guothe, agĩĩka maũndũ mega, na magĩrĩire na ma kwĩhokeka mbere ya Jehova Ngai wake.
21 Nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́lé ní ti iṣẹ́ ìsìn nínú ilé Ọlọ́run àti ní ìgbọ́ràn sí òfin àti àwọn àṣẹ. Ó wá Ọlọ́run rẹ̀, ó sì ṣiṣẹ́ tọkàntọkàn. Ó sì ṣe rere.
Maũndũ-inĩ mothe marĩa ekaga ma gũtungata hekarũ-inĩ ya Ngai, na harĩ gwathĩkĩra watho na maathani, nĩarongooragia Ngai wake na akĩruta wĩra na ngoro yake yothe. Na nĩ ũndũ ũcio akĩgaacĩra.