< 2 Chronicles 31 >

1 Nígbà tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ti dé òpin, àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà níbẹ̀ jáde lọ sí àwọn ìlú Juda, wọ́n fọ́ àwọn òkúta ìyàsọ́tọ̀ sí wẹ́wẹ́, wọ́n gé àwọn ère Aṣerah lulẹ̀. Wọ́n ba àwọn ibi gíga jẹ́ àti àwọn pẹpẹ jákèjádò Juda àti Benjamini àti ní Efraimu àti Manase. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti pa gbogbo wọn run, àwọn ọmọ Israẹli padà sí ìlú wọn àti sí nǹkan ìní wọn.
And whanne these thingis weren doon riytfuli, al Israel yede out, that was foundun in the citees of Juda; and thei braken simylacris, and kittiden doun woodis, and wastiden hiy places, and distrieden auteris, not oneli of al Juda and Beniamyn, but also and of Effraym and Manasses, til thei distrieden outirli. And alle the sones of Israel turneden ayen in to her possessiouns and citees.
2 Hesekiah fi lé àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi lọ́wọ́ sí àwọn ìpín olúkúlùkù wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà tàbí ará Lefi láti tẹ́ ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀, láti ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ láti fi ọpẹ́ fún àti láti kọ àwọn orin ìyìn ní ẹnu-ọ̀nà ibùgbé Olúwa.
Forsothe Ezechie ordeynede cumpenyes of preestis and of dekenes bi her departyngis, ech man in his owne office, that is, as wel of preestis as of dekenes, to brent sacrifices and pesible sacrifices, that thei schulden mynystre, and knowleche, and synge in the yatis of the castels of the Lord.
3 Ọba fi sílẹ̀ láti ara ohun ìní rẹ̀ fun ẹbọ sísun àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ àti fún ẹbọ sísun ní ọjọ́ ìsinmi, òṣùpá tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn gẹ́gẹ́ bi a ti ṣe kọ ọ́ nínú òfin Olúwa.
Sotheli the part of the kyng was, that of his owne catel brent sacrifice schulde be offrid euere in the morewtid and euentide, also in sabatis, and calendis, and othere solempnytees, as it is writun in the lawe of Moises.
4 Ó pàṣẹ fún àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu láti fi ìpín tí ó yẹ fún àlùfáà fún un àti àwọn ará Lefi, kí wọn kí ó lè fi ara wọn jì fún òfin Olúwa.
Also he comaundide to the puple of hem that dwelliden in Jerusalem, to yyue partis to the preestis and dekenes, that thei myyten yyue tent to the lawe of the Lord.
5 Ní kété tí àṣẹ náà jáde lọ, àwọn ọmọ Israẹli fi tìfẹ́tìfẹ́ fi àkọ́so ti ọkà wọn, ọtí tuntun, òróró àti oyin àti gbogbo ohun tí pápá mú jáde lélẹ̀. Wọ́n kó ọ̀pọ̀ iye, àti ìdámẹ́wàá gbogbo nǹkan wá.
And whanne this was knowun in the eeris of the multitude, the sones of Israel offriden ful many firste fruytis of wheete, of wyn, of oyle, and of hony; and of alle thingis whiche the erthe bringith forth, thei offriden tithis.
6 Àwọn ọkùnrin Israẹli àti Juda ti gbe inú àwọn ìlú Juda pẹ̀lú mú ìdámẹ́wàá agbo ẹran àti ohun èlò àti ohun ọ̀sìn àti ìdámẹ́wàá ti àwọn nǹkan mímọ́ tí a ti yà sọ́tọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì kó wọn jọ ní òkìtì.
But also the sones of Israel and of Juda, that dwelliden in the citees of Juda, offriden tithis of oxis and of scheep, and the tithis of holi thingis, whiche thei avowiden to `her Lord God, and thei brouyten alle thingis, and maden ful many heepis.
7 Wọ́n bẹ̀rẹ̀ ṣíṣe èyí ní oṣù kẹta, wọ́n sì parí ní oṣù keje.
In the thridde monethe thei bigunnen to leie the foundementis of the heepis, and in the seuenthe monethe thei filliden tho heepis.
8 Nígbà tí Hesekiah àti àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ wá, tí wọ́n sì rí òkìtì náà, wọ́n yin Olúwa, pẹ̀lú ìbùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli.
And whanne Ezechie and hise princes hadden entrid, thei siyen the heepis, and blessiden the Lord, and the puple of Israel.
9 Hesekiah béèrè lọ́wọ́ àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi nípa òkìtì;
And Ezechie axide the preestis and dekenes, whi the heepis laien so.
10 àti Asariah olórí àlùfáà ti ìdílé Sadoku sì dáhùn pé, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní mú ìdáwó wọn wá sí ilé Olúwa àti ní èyí tí yóò tó jẹ àti ọ̀pọ̀ láti tọ́jú pamọ́ nítorí Olúwa ti bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀, ó sì ṣẹ́kù lọ́pọ̀lọ́pọ̀.”
Azarie, the firste preest of the generacioun of Sadoch, answeride to hym, and seide, Sithen the firste fruytis bigunnen to be offrid in the hows of the Lord, we han ete and ben fillid, and ful many thingis ben left; for the Lord hath blessid his puple; sotheli this plentee, which thou seest, is of the relifs.
11 Hesekiah pàṣẹ láti tọ́jú àwọn yàrá ìṣúra nínú ilé Olúwa, wọ́n sì ṣe èyí.
Therfor Ezechie comaundide, that thei schulden make redi bernes in the hows of the Lord; and whanne thei hadden do this thing,
12 Nígbà náà wọ́n mú ọrẹ àti ìdámẹ́wàá àti àwọn ẹ̀bùn tí a yà sí mímọ́ wọ ilé náà wá nítòótọ́. Lórí èyí tí Konaniah ọmọ Lefi, ń ṣe olórí, Ṣimei arákùnrin rẹ̀ ni igbákejì rẹ̀.
thei brouyten in feithfuly bothe the firste fruytis, and tithis, and what euere thingis thei hadden avowid. Forsothe Chonenye, the dekene, was the souereyn of tho; and Semei his brother was the secounde;
13 Jehieli, Asasiah, Nahati, Asaheli, Jerimoti, Josabadi, Elieli, Ismakia, Mahati àti Benaiah jẹ́ àwọn alábojútó lábẹ́ Konaniah àti Ṣimei arákùnrin rẹ̀ nípa ipá ọba Hesekiah àti Asariah olórí ti ó wà ní ìkáwọ́ ilé Ọlọ́run.
aftir whom Jehiel, and Azarie, and Nabath, and Asahel, and Jerimoth, `and Jozabad, and Helyel, and Jesmahie, and Maath, and Banaie, weren souereyns vndur the hondis of Chonenye and Semei, his brother, bi the comaundement of `Ezechie the kyng, and of Azarie, the bischop of the hows of the Lord, to whiche alle thingis perteyneden.
14 Kore ọmọ Imina ará Lefi olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ìlà-oòrùn, wà ní ìkáwọ́ àwọn ọrẹ àtinúwá tí a fi fún Ọlọ́run, o ń pín ìdáwó tí a ṣe fún Olúwa pẹ̀lú àwọn ẹ̀bùn tí a yà sọ́tọ̀
But Chore, the sone of Jemnya, dekene and portere of the eest yate, was souereyn of tho thingis that weren offrid bi fre wille to the Lord, and of the firste fruytis, and of thingis halewid in to hooli thingis of the noumbre of hooli thingis;
15 Edeni, Miniamini, Jeṣua, Ṣemaiah, Amariah àti Ṣekaniah ràn án lọ́wọ́ tọkàntọkàn nínú àwọn ìlú àwọn àlùfáà tí ń dáwó fún àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, àgbà àti kékeré.
and vndur his cure weren Eden, and Beniamyn, Jesue, and Semeye, and Amarie, and Sechenye, in the citees of preestis, that thei schulden departe feithfuli to her britheren the partis, to the lesse and the grettere,
16 Ní àfikún, wọ́n pín sí àwọn ọkùnrin àgbà ọdún mẹ́ta tàbí ọ̀pọ̀ tí orúkọ wọn wà nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn. Gbogbo àwọn ti yóò wọ ilé Olúwa láti ṣe oríṣìí iṣẹ́ ti a gbà wọ́n fún gẹ́gẹ́ bí ìgbẹ́kẹ̀lé wọn àti ìpín wọn.
outakun malis fro three yeer and aboue, these thingis to alle that entriden in to the temple of the Lord, and what euer thing bi ech dai was hirid in the seruyce and obseruaunces bi her departyngis.
17 Wọ́n sì pín àwọn àlùfáà, wọn kọ orúkọ àwọn ìdílé wọn sínú ìtàn ìdílé àti sí àwọn ará Lefi ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu àti ìpín wọn.
To preestis bi meynees, and to dekenes fro `the twentithe yeer and aboue bi her ordris and cumpenyes, and to alle the multitude,
18 Wọ́n fi gbogbo àwọn ọmọ kéékèèké sí i, àwọn ìyàwó, àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin gbogbo ará ìlú tí a kọ lẹ́sẹẹsẹ sínú ìtàn ìdílé ti baba ńlá wọn fún ìrántí. Nítorí tí wọ́n ṣe òtítọ́ ní yíya ara wọn sí ọ̀tọ̀.
bothe to the wyues and fre children of hem of euer either kynde, metis weren youun feithfuli of these thingis that weren halewid.
19 Ní ti àwọn àlùfáà, àwọn ìran ọmọ Aaroni, tí ń gbé ni àwọn ilẹ̀ oko lẹ́bàá àwọn ìlú wọn tàbí ní àwọn ìlú mìíràn. A yan àwọn ọkùnrin pẹ̀lú orúkọ láti pín ìlú fún gbogbo ọkùnrin láàrín wọn àti sí gbogbo àwọn tí a kọ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá àwọn ará Lefi.
But also men of the sones of Aaron weren ordeyned bi the feeldis and subarbis of alle citees, whyche men schulden dele partis to al the male kynde of preestis and dekenes.
20 Èyí ni Hesekiah ṣe jákèjádò Juda, ó sì ṣe ohun tí ó dára àti tí ó tọ́ àti ohun òtítọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
Therfor Ezechie dide alle thingis, whiche we seiden, in al Juda, and he wrouyte that, that was riytful and good and trewe bifor `his Lord God,
21 Nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́lé ní ti iṣẹ́ ìsìn nínú ilé Ọlọ́run àti ní ìgbọ́ràn sí òfin àti àwọn àṣẹ. Ó wá Ọlọ́run rẹ̀, ó sì ṣiṣẹ́ tọkàntọkàn. Ó sì ṣe rere.
in al the religioun of the seruyce of the hows of the Lord, bi the lawe and cerymonyes; and he wolde seke his Lord God in al his herte, and he dide, and hadde prosperite.

< 2 Chronicles 31 >