< 2 Chronicles 30 >

1 Hesekiah sì ránṣẹ́ sí gbogbo Israẹli àti Juda, ó sì kọ ìwé sí Efraimu àti Manase, kí wọn kí ó wá sínú ilé Olúwa ní Jerusalẹmu láti pa àjọ ìrékọjá mọ́ sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
Și Ezechia a trimis în tot Israelul și Iuda și a scris scrisori de asemenea lui Efraim și lui Manase, ca să vină la casa DOMNULUI, la Ierusalim, să țină paștele pentru DOMNUL Dumnezeul lui Israel.
2 Nítorí tí ọba ti gbìmọ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀, àti gbogbo ìjọ ènìyàn ní Jerusalẹmu, láti pa àjọ ìrékọjá mọ́ ní oṣù kejì.
Fiindcă împăratul ținuse sfat împreună cu prinții lui și toată adunarea în Ierusalim, să țină paștele în a doua lună.
3 Nítorí wọn kò lè pa á mọ́ ní àkókò náà, nítorí àwọn àlùfáà kò tí i ya ara wọn sí mímọ́ tó; bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kò tí ì kó ara wọn jọ sí Jerusalẹmu.
Fiindcă nu îl puteau ține în acel timp, pentru că preoții nu se sfințiseră destul, nici poporul nu se adunase la Ierusalim.
4 Ọ̀rọ̀ náà sí tọ́ lójú ọba àti lójú gbogbo ìjọ ènìyàn.
Și acest lucru a plăcut împăratului și întregii adunări.
5 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fi àṣẹ kan lélẹ̀, láti kéde ká gbogbo Israẹli láti Beerṣeba àní títí dé Dani, láti wá pa àjọ ìrékọjá mọ́ sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ní Jerusalẹmu: nítorí wọn kò pa á mọ́ ní ọjọ́ púpọ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́.
Astfel au întemeiat o hotărâre să vestească în tot Israelul, de la Beer-Șeba chiar până la Dan, să vină să țină paștele pentru DOMNUL Dumnezeul lui Israel, la Ierusalim, fiindcă nu îl făcuseră de mult timp în acest fel precum era scris.
6 Bẹ́ẹ̀ àwọn oníṣẹ́ tí ń sáré lọ pẹ̀lú ìwé láti ọwọ́ ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀ sí gbogbo Israẹli àti Juda; àti gẹ́gẹ́ bí àṣẹ ọba, wí pé, “Ẹ̀yin ọmọ Israẹli ẹ yí padà sí Olúwa Ọlọ́run Abrahamu, Isaaki, àti Israẹli, òun ó sì yípadà sí àwọn ìyókù nínú yín, tí ó sálà kúrò lọ́wọ́ àwọn ọba Asiria.
Astfel alergătorii au mers cu scrisorile de la împărat și prinții lui prin tot Israelul și Iuda și au spus conform poruncii împăratului: Voi copii ai lui Israel, întoarceți-vă din nou la DOMNUL Dumnezeul lui Avraam, Isaac și Israel, și el se va întoarce la rămășița voastră, care a scăpat din mâna împăraților Asiriei.
7 Kí ẹ̀yin kí ó má sì ṣe dàbí àwọn baba yín, àti bí àwọn arákùnrin yín tí ó dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn, nítorí náà ní ó ṣe fi wọ́n fún ìdahoro bí ẹ̀yin ti rí.
Și nu fiți ca părinții voștri și ca frații voștri, care au încălcat legea împotriva DOMNULUI Dumnezeul părinților voștri, pe care de aceea i-a dat pustiirii, precum vedeți.
8 Ǹjẹ́ kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣe ọlọ́rùn líle, bí àwọn baba yín, ṣùgbọ́n ẹ jọ̀wọ́ ara yín lọ́wọ́ fún Olúwa, kí ẹ sì wọ inú ibi mímọ́ rẹ̀ lọ, ti òun ti ìyàsímímọ́ títí láé. Kí ẹ sì sin Olúwa, Ọlọ́run yín kí gbígbóná ìbínú rẹ̀ kí ó lè yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ yín.
Și nu fiți îndărătnici, cum au fost părinții voștri, ci supuneți-vă DOMNULUI și intrați în sanctuarul său, pe care l-a sfințit pentru totdeauna; și serviți DOMNULUI Dumnezeul vostru, pentru ca înverșunarea furiei lui să se întoarcă de la voi.
9 Nítorí bí ẹ̀yin bá tún yípadà sí Olúwa, àwọn arákùnrin yín, àti àwọn ọmọ yín, yóò rí àánú níwájú àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, kí wọn kí ó lè tún padà wá sí ilẹ̀ yí: nítorí Olúwa Ọlọ́run yín, oníyọnu àti aláàánú ni, kì yóò sì yí ojú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ yín, bí ẹ̀yin bá padà sọ́dọ̀ rẹ̀.”
Căci dacă vă întoarceți din nou la DOMNUL, frații voștri și copiii voștri vor găsi mângâiere înaintea celor care i-au adus în captivitate, astfel ca ei să se întoarcă în această țară, căci DOMNUL Dumnezeul vostru este cu har și milostiv și nu își va întoarce fața de la voi, dacă vă întoarceți la el.
10 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn oníṣẹ́ náà kọjá láti ìlú dé ìlú, ní ilẹ̀ Efraimu àti Manase títí dé Sebuluni, ṣùgbọ́n wọ́n fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà, wọ́n sì gàn wọ́n.
Astfel alergătorii au trecut din cetate în cetate prin țara lui Efraim și a lui Manase chiar până la Zabulon, dar au râs de ei în batjocură și i-au batjocorit.
11 Síbẹ̀ òmíràn nínú àwọn ènìyàn Aṣeri àti Manase àti Sebuluni rẹ̀ ara wọn sílẹ̀, wọ́n sì wá sí Jerusalẹmu.
Totuși unii din Așer și Manase și din Zabulon s-au umilit și au venit la Ierusalim.
12 Ní Juda pẹ̀lú, ọwọ́ Ọlọ́run wá láti fún wọn ní ọkàn kan láti pa òfin ọba mọ́ àti tí àwọn ìjòyè, nípa ọ̀rọ̀ Olúwa.
De asemenea în Iuda, planul mâinii lui Dumnezeu a fost să le dea o singură inimă pentru a împlini porunca împăratului și a prinților, prin cuvântul DOMNULUI.
13 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn sì péjọ ní Jerusalẹmu, láti pa àjọ àkàrà àìwú mọ́ ní oṣù kejì.
Și mult popor s-a adunat la Ierusalim pentru a ține sărbătoarea azimelor în a doua lună; era o foarte mare adunare.
14 Wọ́n sì dìde, wọ́n sì kó gbogbo pẹpẹ tí ó wà ní Jerusalẹmu lọ, àti gbogbo pẹpẹ tùràrí ni wọ́n kó lọ, wọ́n sì dà wọ́n sí odò Kidironi.
Și s-au ridicat și au îndepărtat altarele care erau în Ierusalim și toate altarele pentru tămâie le-au îndepărtat și le-au aruncat în pârâul Chedron.
15 Nígbà náà ni wọ́n pa ẹran ìrékọjá náà ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kejì: ojú sì ti àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì yà ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì mú ẹbọ sísun wá sínú ilé Olúwa.
Atunci au înjunghiat paștele în a paisprezecea zi a lunii a doua, și preoții și leviții s-au rușinat și s-au sfințit și au adus ofrandele arse în casa DOMNULUI.
16 Wọ́n sì dúró ní ipò wọn, bí ètò wọn gẹ́gẹ́ bí òfin Mose, ènìyàn Ọlọ́run: àwọn àlùfáà wọ́n ẹ̀jẹ̀ náà, tí wọ́n gbà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Lefi.
Și au stat în picioare în locul lor, după felul lor, conform legii lui Moise, omul lui Dumnezeu; preoții au stropit sângele pe care l-au primit din mâna leviților.
17 Nítorí pé ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó wà nínú ìjọ ènìyàn náà tí kò yà ara wọn sí mímọ́: nítorí náà ni àwọn ọmọ Lefi ṣe ń tọ́jú àti pa ẹran ìrékọjá fún olúkúlùkù ẹni tí ó ṣe aláìmọ́, láti yà á sí mímọ́ sí Olúwa.
Fiindcă erau mulți în adunare care nu erau sfințiți, de aceea leviții aveau porunca să înjunghie paștele pentru fiecare ce nu era curat, să îi sfințească pentru DOMNUL.
18 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú Efraimu àti Manase, Isakari, àti Sebuluni kò sá wẹ̀ ara wọn mọ́ síbẹ̀ wọ́n jẹ ìrékọjá náà, kì í ṣe gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́. Ṣùgbọ́n Hesekiah bẹ̀bẹ̀ fún wọn, wí pé, Olúwa, ẹni rere, dáríjì olúkúlùkù,
Fiindcă o mulțime de oameni: mulți din Efraim și Manase, Isahar și Zabulon, nu se curățaseră, totuși au mâncat paștele în alt fel decât era scris. Dar Ezechia s-a rugat pentru ei, spunând: DOMNUL cel bun să ierte pe fiecare
19 tí ó múra ọkàn rẹ̀ láti wá Ọlọ́run, Olúwa Ọlọ́run àwọn baba rẹ̀ ṣùgbọ́n tí kì í ṣe nípa ìwẹ̀nùmọ́ mímọ́
Ce își pregătește inima să caute pe Dumnezeu, DOMNUL Dumnezeul părinților lui, chiar dacă nu este curățat conform curățirii sanctuarului.
20 Olúwa sì gbọ́ ti Hesekiah, ó sì mú àwọn ènìyàn náà láradá.
Și DOMNUL a dat ascultare lui Ezechia și a vindecat poporul.
21 Àwọn ọmọ Israẹli tí a rí ní Jerusalẹmu fi ayọ̀ ńlá pa àjọ àkàrà àìwú mọ́ ní ọjọ́ méje: àwọn ọmọ Lefi, àti àwọn àlùfáà yin Olúwa lójoojúmọ́, wọ́n ń fi ohun èlò olóhùn gooro kọrin sí Olúwa.
Și copiii lui Israel care erau prezenți la Ierusalim au ținut sărbătoarea azimelor șapte zile, cu mare veselie; și leviții și preoții au lăudat pe DOMNUL zi de zi, cântând cu instrumente puternice DOMNULUI.
22 Hesekiah sọ̀rọ̀ ìtùnú fún gbogbo àwọn ọmọ Lefi, tí ó lóye ní ìmọ̀ rere Olúwa: ọjọ́ méje ni wọ́n fi jẹ àsè náà wọ́n rú ẹbọ àlàáfíà, wọ́n sì ń fi ohùn rara dúpẹ́ fún Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn.
Și Ezechia a vorbit cu mângâiere inimii tuturor leviților care învățau pe alții buna cunoaștere a DOMNULUI; și au mâncat în toată sărbătoarea de șapte zile, aducând ofrande de pace și făcând mărturisire DOMNULUI Dumnezeul părinților lor.
23 Gbogbo ìjọ náà sì gbìmọ̀ láti pa ọjọ́ méje mìíràn mọ́: wọ́n sì fi ayọ̀ pa ọjọ́ méje mìíràn mọ́.
Și întreaga adunare a ținut sfat să țină alte șapte zile; și au ținut alte șapte zile cu veselie.
24 Nítorí Hesekiah, ọba Juda, ta ìjọ ènìyàn náà ní ọrẹ, ẹgbẹ̀rún akọ màlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú àwọn àlùfáà sì ya ara wọn sí mímọ́.
Fiindcă Ezechia împăratul lui Iuda a dat adunării o mie de tauri și șapte mii de oi; și prinții au dat adunării o mie de tauri și zece mii de oi; și un mare număr de preoți s-au sfințit.
25 Gbogbo ìjọ ènìyàn Juda pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó ti inú Israẹli jáde wá, àti àwọn àjèjì tí ó ti ilẹ̀ Israẹli jáde wá, àti àwọn tí ń gbé Juda yọ̀.
Și toată adunarea lui Iuda, cu toți preoții și leviții și toată adunarea care a venit din Israel și străinii care au venit din țara lui Israel și care locuiau în Iuda, s-au bucurat.
26 Bẹ́ẹ̀ ni ayọ̀ ńlá sì wà ní Jerusalẹmu: nítorí láti ọjọ́ Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli, irú èyí kò sí ní Jerusalẹmu.
Astfel a fost o mare bucurie în Ierusalim, căci din timpul lui Solomon, fiul lui David, împăratul lui Israel, nu a fost ceva asemănător în Ierusalim.
27 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi dìde, wọ́n sì súre fún àwọn ènìyàn náà: a sì gbọ́ ohùn wọn, àdúrà wọn sì gòkè lọ si ibùgbé mímọ́ rẹ̀, àní sí ọ̀run.
Atunci preoții și leviții s-au ridicat și au binecuvântat poporul; și vocea lor s-a auzit și rugăciunea lor s-a ridicat la locul lui sfânt de locuit, la cer.

< 2 Chronicles 30 >