< 2 Chronicles 30 >

1 Hesekiah sì ránṣẹ́ sí gbogbo Israẹli àti Juda, ó sì kọ ìwé sí Efraimu àti Manase, kí wọn kí ó wá sínú ilé Olúwa ní Jerusalẹmu láti pa àjọ ìrékọjá mọ́ sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
حِزِقیای پادشاه، نامه‌هایی به سراسر اسرائیل و یهودا و مخصوصاً قبایل افرایم و منسی فرستاد و همه را دعوت نمود تا به اورشلیم بیایند و در خانهٔ خداوند عید پِسَح را برای خداوند، خدای اسرائیل جشن بگیرند.
2 Nítorí tí ọba ti gbìmọ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀, àti gbogbo ìjọ ènìyàn ní Jerusalẹmu, láti pa àjọ ìrékọjá mọ́ ní oṣù kejì.
پادشاه و مقامات مملکتی و تمام جماعت اورشلیم پس از مشورت با هم تصمیم گرفتند مراسم عید پِسَح را به جای وقت معمول آن در ماه اول، این بار در ماه دوم برگزار نمایند. علّت این بود که کاهنان کافی در این زمان تقدیس نشده بودند و قوم نیز در اورشلیم جمع نشده بودند.
3 Nítorí wọn kò lè pa á mọ́ ní àkókò náà, nítorí àwọn àlùfáà kò tí i ya ara wọn sí mímọ́ tó; bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kò tí ì kó ara wọn jọ sí Jerusalẹmu.
4 Ọ̀rọ̀ náà sí tọ́ lójú ọba àti lójú gbogbo ìjọ ènìyàn.
این تصمیم با توافق پادشاه و تمام جماعت اخذ شد.
5 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fi àṣẹ kan lélẹ̀, láti kéde ká gbogbo Israẹli láti Beerṣeba àní títí dé Dani, láti wá pa àjọ ìrékọjá mọ́ sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ní Jerusalẹmu: nítorí wọn kò pa á mọ́ ní ọjọ́ púpọ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́.
پس به سراسر اسرائیل، از دان تا بئرشبع پیغام فرستادند و همه را دعوت کردند تا به اورشلیم بیایند و عید پِسَح را برای خداوند، خدای اسرائیل جشن بگیرند. زیرا مدت زیادی بود که آن را بر اساس شریعت، به طور دسته جمعی جشن نگرفته بودند.
6 Bẹ́ẹ̀ àwọn oníṣẹ́ tí ń sáré lọ pẹ̀lú ìwé láti ọwọ́ ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀ sí gbogbo Israẹli àti Juda; àti gẹ́gẹ́ bí àṣẹ ọba, wí pé, “Ẹ̀yin ọmọ Israẹli ẹ yí padà sí Olúwa Ọlọ́run Abrahamu, Isaaki, àti Israẹli, òun ó sì yípadà sí àwọn ìyókù nínú yín, tí ó sálà kúrò lọ́wọ́ àwọn ọba Asiria.
قاصدان از طرف پادشاه و مقامات مملکت با نامه‌ها به سراسر اسرائیل و یهودا اعزام شدند. متن نامه‌ها چنین بود: «ای بنی‌اسرائیل، به سوی خداوند، خدای ابراهیم و اسحاق و یعقوب بازگشت کنید، تا او نیز به سوی شما بازماندگان قوم که از چنگ پادشاهان آشور جان به در برده‌اید، بازگشت نماید.
7 Kí ẹ̀yin kí ó má sì ṣe dàbí àwọn baba yín, àti bí àwọn arákùnrin yín tí ó dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn, nítorí náà ní ó ṣe fi wọ́n fún ìdahoro bí ẹ̀yin ti rí.
مانند پدران و برادران خود نباشید که نسبت به خداوند، خدای اجدادشان گناه کردند و به طوری که می‌بینید به شدت مجازات شدند.
8 Ǹjẹ́ kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣe ọlọ́rùn líle, bí àwọn baba yín, ṣùgbọ́n ẹ jọ̀wọ́ ara yín lọ́wọ́ fún Olúwa, kí ẹ sì wọ inú ibi mímọ́ rẹ̀ lọ, ti òun ti ìyàsímímọ́ títí láé. Kí ẹ sì sin Olúwa, Ọlọ́run yín kí gbígbóná ìbínú rẹ̀ kí ó lè yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ yín.
مثل آنها یاغی نباشید، بلکه از خداوند اطاعت نمایید و به خانهٔ او بیایید که آن را تا به ابد تقدیس فرموده است و خداوند، خدای خود را عبادت کنید تا خشم او از شما برگردد.
9 Nítorí bí ẹ̀yin bá tún yípadà sí Olúwa, àwọn arákùnrin yín, àti àwọn ọmọ yín, yóò rí àánú níwájú àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, kí wọn kí ó lè tún padà wá sí ilẹ̀ yí: nítorí Olúwa Ọlọ́run yín, oníyọnu àti aláàánú ni, kì yóò sì yí ojú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ yín, bí ẹ̀yin bá padà sọ́dọ̀ rẹ̀.”
اگر شما به سوی خداوند بازگشت نمایید، برادران و فرزندان شما مورد لطف کسانی قرار می‌گیرند که ایشان را اسیر کرده‌اند و به این سرزمین باز خواهند گشت. زیرا خداوند، خدای شما رحیم و مهربان است و اگر شما به سوی او بازگشت نمایید او شما را خواهد پذیرفت.»
10 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn oníṣẹ́ náà kọjá láti ìlú dé ìlú, ní ilẹ̀ Efraimu àti Manase títí dé Sebuluni, ṣùgbọ́n wọ́n fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà, wọ́n sì gàn wọ́n.
پس قاصدان، شهر به شهر از افرایم و منسی تا زبولون رفتند. ولی در اکثر جاها با ریشخند و اهانت مردم مواجه شدند.
11 Síbẹ̀ òmíràn nínú àwọn ènìyàn Aṣeri àti Manase àti Sebuluni rẹ̀ ara wọn sílẹ̀, wọ́n sì wá sí Jerusalẹmu.
اما از قبیله‌های اشیر، منسی و زبولون عده‌ای اطاعت نمودند و به اورشلیم آمدند.
12 Ní Juda pẹ̀lú, ọwọ́ Ọlọ́run wá láti fún wọn ní ọkàn kan láti pa òfin ọba mọ́ àti tí àwọn ìjòyè, nípa ọ̀rọ̀ Olúwa.
همچنین دست خدا بر یهودا بود و آنها را یکدل ساخت تا آنچه را پادشاه و مقاماتش طبق کلام خداوند فرمان داده بودند، به انجام رسانند.
13 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn sì péjọ ní Jerusalẹmu, láti pa àjọ àkàrà àìwú mọ́ ní oṣù kejì.
گروه عظیمی در ماه دوم در شهر اورشلیم جمع شدند تا عید نان فطیر را جشن بگیرند.
14 Wọ́n sì dìde, wọ́n sì kó gbogbo pẹpẹ tí ó wà ní Jerusalẹmu lọ, àti gbogbo pẹpẹ tùràrí ni wọ́n kó lọ, wọ́n sì dà wọ́n sí odò Kidironi.
ایشان برخاسته، تمام مذبحهای اورشلیم را که روی آنها قربانی و بخور به بتها تقدیم می‌شد در هم کوبیده به درهٔ قدرون ریختند.
15 Nígbà náà ni wọ́n pa ẹran ìrékọjá náà ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kejì: ojú sì ti àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì yà ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì mú ẹbọ sísun wá sínú ilé Olúwa.
در روز چهاردهم ماه دوم، بره‌های عید پِسَح را سر بریدند. کاهنان و لاویانی که برای انجام مراسم آماده نشده بودند، خجالت کشیده، فوری خود را تقدیس کردند و به تقدیم قربانی در خانۀ خداوند مشغول شدند.
16 Wọ́n sì dúró ní ipò wọn, bí ètò wọn gẹ́gẹ́ bí òfin Mose, ènìyàn Ọlọ́run: àwọn àlùfáà wọ́n ẹ̀jẹ̀ náà, tí wọ́n gbà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Lefi.
آنها با ترتیبی که در تورات موسی، مرد خدا آمده است سر خدمت خود ایستادند و کاهنان، خونی را که لاویان به دست ایشان دادند، بر مذبح پاشیدند.
17 Nítorí pé ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó wà nínú ìjọ ènìyàn náà tí kò yà ara wọn sí mímọ́: nítorí náà ni àwọn ọmọ Lefi ṣe ń tọ́jú àti pa ẹran ìrékọjá fún olúkúlùkù ẹni tí ó ṣe aláìmọ́, láti yà á sí mímọ́ sí Olúwa.
عدهٔ زیادی از قوم که از سرزمینهای افرایم، منسی، یساکار و زبولون آمده بودند مراسم طهارت و تقدیس را بجا نیاورده بودند و نمی‌توانستند بره‌های خود را ذبح کنند، پس لاویان مأمور شدند این کار را برای ایشان انجام دهند. حِزِقیای پادشاه نیز برای ایشان دعا کرد تا بتوانند خوراک عید پِسَح را بخورند، هر چند این برخلاف شریعت بود. حِزِقیا چنین دعا کرد: «ای خداوند مهربان، خدای اجداد ما، هر کسی را که قصد دارد تو را پیروی نماید ولی خود را برای شرکت در این مراسم تقدیس نکرده است، بیامرز.»
18 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú Efraimu àti Manase, Isakari, àti Sebuluni kò sá wẹ̀ ara wọn mọ́ síbẹ̀ wọ́n jẹ ìrékọjá náà, kì í ṣe gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́. Ṣùgbọ́n Hesekiah bẹ̀bẹ̀ fún wọn, wí pé, Olúwa, ẹni rere, dáríjì olúkúlùkù,
19 tí ó múra ọkàn rẹ̀ láti wá Ọlọ́run, Olúwa Ọlọ́run àwọn baba rẹ̀ ṣùgbọ́n tí kì í ṣe nípa ìwẹ̀nùmọ́ mímọ́
20 Olúwa sì gbọ́ ti Hesekiah, ó sì mú àwọn ènìyàn náà láradá.
خداوند دعای حِزِقیا را شنید و قوم را شفا بخشید.
21 Àwọn ọmọ Israẹli tí a rí ní Jerusalẹmu fi ayọ̀ ńlá pa àjọ àkàrà àìwú mọ́ ní ọjọ́ méje: àwọn ọmọ Lefi, àti àwọn àlùfáà yin Olúwa lójoojúmọ́, wọ́n ń fi ohun èlò olóhùn gooro kọrin sí Olúwa.
پس بنی‌اسرائیل هفت روز عید نان فطیر را با شادی فراوان در شهر اورشلیم جشن گرفتند. درضمن لاویان و کاهنان هر روز با آلات موسیقی خداوند را ستایش می‌کردند.
22 Hesekiah sọ̀rọ̀ ìtùnú fún gbogbo àwọn ọmọ Lefi, tí ó lóye ní ìmọ̀ rere Olúwa: ọjọ́ méje ni wọ́n fi jẹ àsè náà wọ́n rú ẹbọ àlàáfíà, wọ́n sì ń fi ohùn rara dúpẹ́ fún Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn.
(حِزِقیای پادشاه از تمام لاویانی که مراسم عبادتی را خوب انجام داده بودند قدردانی کرد.) هفت روز مراسم عید برقرار بود. قوم قربانیهای سلامتی تقدیم کردند و خداوند، خدای اجدادشان را ستایش نمودند.
23 Gbogbo ìjọ náà sì gbìmọ̀ láti pa ọjọ́ méje mìíràn mọ́: wọ́n sì fi ayọ̀ pa ọjọ́ méje mìíràn mọ́.
تمام جماعت پس از مشورت، تصمیم گرفتند عید پِسَح هفت روز دیگر ادامه یابد؛ پس با شادی هفت روز دیگر این عید را جشن گرفتند.
24 Nítorí Hesekiah, ọba Juda, ta ìjọ ènìyàn náà ní ọrẹ, ẹgbẹ̀rún akọ màlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú àwọn àlùfáà sì ya ara wọn sí mímọ́.
حِزِقیا هزار گاو و هفت هزار گوسفند برای قربانی به جماعت بخشید. مقامات مملکتی نیز هزار گاو و ده هزار گوسفند هدیه کردند. در این هنگام عدهٔ زیادی از کاهنان نیز خود را تقدیس نمودند.
25 Gbogbo ìjọ ènìyàn Juda pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó ti inú Israẹli jáde wá, àti àwọn àjèjì tí ó ti ilẹ̀ Israẹli jáde wá, àti àwọn tí ń gbé Juda yọ̀.
تمام مردم یهودا، همراه با کاهنان و لاویان و آنانی که از مملکت اسرائیل آمده بودند، و نیز غریبان ساکن اسرائیل و یهودا، شادی می‌کردند.
26 Bẹ́ẹ̀ ni ayọ̀ ńlá sì wà ní Jerusalẹmu: nítorí láti ọjọ́ Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli, irú èyí kò sí ní Jerusalẹmu.
اورشلیم از زمان سلیمان پسر داوود پادشاه تا آن روز، چنین روز شادی به خود ندیده بود.
27 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi dìde, wọ́n sì súre fún àwọn ènìyàn náà: a sì gbọ́ ohùn wọn, àdúrà wọn sì gòkè lọ si ibùgbé mímọ́ rẹ̀, àní sí ọ̀run.
در خاتمه، کاهنان و لاویان ایستاده، قوم را برکت دادند و خدا دعای آنها را از قدس خود در آسمان شنید و اجابت فرمود.

< 2 Chronicles 30 >